< Isaia 30 >

1 Vai copiilor răzvrătiţi, spune DOMNUL, care primesc sfat, dar nu de la mine; şi care se acoperă cu o acoperitoare, dar nu din duhul meu, pentru a adăuga păcat la păcat.
“Ègbé ni àwọn ọmọ fún orílẹ̀-èdè alágídí,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi, tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi, tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;
2 Care umblă să coboare în Egipt şi nu au întrebat de gura mea; pentru a se întări în tăria lui Faraon şi pentru a se încrede în umbra Egiptului!
tí wọ́n lọ sí Ejibiti láìṣe fún mi, tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Farao fún ààbò, sí òjìji Ejibiti fún ibi ìsádi.
3 De aceea tăria lui Faraon va fi ruşinea voastră şi încrederea în umbra Egiptului confuzia voastră.
Ṣùgbọ́n ààbò Farao yóò jásí ìtìjú fún un yín, òjìji Ejibiti yóò mú àbùkù bá a yín.
4 Căci prinţii lui au fost la Ţoan şi ambasadorii lui au venit la Hanes.
Bí àwọn olórí rẹ tilẹ̀ wà ní Ṣoani, tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hanisi,
5 Toţi au fost ruşinaţi de un popor care nu le-a folosit, nici nu sunt de ajutor nici de folos, ci o ruşine şi, de asemenea, ocară.
gbogbo wọn ni a ó dójútì, nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn, tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá, bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”
6 Povara fiarelor sudului: în ţara tulburării şi chinului, de unde vin leul tânăr şi bătrân, vipera şi şarpele zburător înfocat, îşi vor căra bogăţiile pe umerii măgarilor tineri şi tezaurele lor pe cocoaşele cămilelor, la un popor care nu le va fi de folos.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ sí àwọn ẹranko tí ó wà ní gúúsù. Láàrín ilẹ̀ ìnira àti ìpọ́njú, ti kìnnìún àti abo kìnnìún ti paramọ́lẹ̀ àti ejò olóró, àwọn ikọ̀ náà kó ẹrù àti ọrọ̀ wọn lẹ́yìn àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ohun ìní wọn ní orí àwọn ìbákasẹ, sí orílẹ̀-èdè aláìlérè,
7 Fiindcă egiptenii vor ajuta în zadar şi fără folos, de aceea am strigat referitor la aceasta: Tăria lor este să stea liniştiţi!
sí Ejibiti tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ kò wúlò rárá. Nítorí náà mo pè é ní Rahabu aláìlẹ́ṣẹ̀ nǹkan kan.
8 Du-te acum, scrie aceasta înaintea lor pe o tăbliţă şi noteaz-o într-o carte, ca să fie pentru timpul ce va veni, pentru totdeauna şi întotdeauna,
Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara wàláà fún wọn, tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká, pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀ kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
9 [Scrie] că acesta este un popor răzvrătit, copii mincinoşi, copii ce nu vor asculta legea DOMNULUI,
Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn àti ẹlẹ́tanu ọmọ, àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí sí ìtọ́ni Olúwa.
10 Care spun văzătorilor: Să nu vedeţi; şi profeţilor: Să nu ne profeţiţi lucruri drepte, vorbiţi-ne lucruri măgulitoare, profeţiţi înşelăciuni,
Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé, “Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!” Àti fún àwọn wòlíì, “Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́! Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa, ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
11 Ieşiţi de pe cale, abateţi-vă de pe cărare, faceţi-l pe Cel Sfânt al lui Israel să plece din faţa noastră.
Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀, ẹ kúrò ní ọ̀nà yìí ẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọ wá pẹ̀lú Ẹni Mímọ́ Israẹli!”
12 De aceea astfel spune Cel Sfânt al lui Israel: Pentru că dispreţuiţi acest cuvânt şi vă încredeţi în oprimare şi perversiune şi rămâneţi în aceasta,
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni Mímọ́ Israẹli wí: “Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀, ẹ gbára lé ìnilára kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ẹ̀tàn,
13 De aceea această nelegiuire vă va fi ca o spărtură gata să cadă, lărgindu-se într-un zid înalt, a cărui prăbuşire vine într-o clipă, dintr-odată.
ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọ gẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fì tí ó sì wó lójijì, àti ní ìṣẹ́jú kan.
14 Iar el îl va sfărâma ca spargerea vasului olarului care este spart în bucăţi; nu va cruţa, astfel încât nu se va găsi în plesnirea acestuia o bucată pentru a lua foc din vatră, sau pentru a lua apă din groapă.
Yóò sì fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ bí àpáàdì tí a fọ́ pátápátá àti pé a kò ní rí ẹ̀rún kan nínú àfọ́kù rẹ̀, fún mímú èédú kúrò nínú ààrò tàbí gbígbọ́n omi jáde kúrò nínú àmù.” (questioned)
15 Fiindcă astfel spune Domnul DUMNEZEU, Cel Sfânt al lui Israel: În întoarcere şi odihnă veţi fi salvaţi; în linişte şi în încredere va fi tăria voastră; şi aţi refuzat.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli wí: “Nínú ìrònúpìwàdà àti ìsinmi ni ìgbàlà rẹ wà, ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé ni agbára rẹ wà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò ní ọ̀kankan nínú wọn.
16 Dar aţi spus: Nu; ci vom fugi călare pe cai; de aceea veţi fugi; şi: Vom călări pe cei iuţi; de aceea cei ce vă vor urmări vor fi iuţi.
Ẹ̀yin wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò sálọ lórí ẹṣin.’ Nítorí náà ẹ̀yin yóò sá! Ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa yóò gun àwọn ẹṣin tí ó yára lọ.’ Nítorí náà àwọn tí ń lé e yín yóò yára!
17 O mie vor fugi la mustrarea unuia; veţi fugi la mustrarea a cinci, până când veţi fi lăsaţi ca un far pe vârful unui munte şi ca un însemn pe un deal.
Ẹgbẹ̀rún yóò sá nípa ìdẹ́rùbà ẹnìkan; nípa ìdẹ́rùbà ẹni márùn-ún gbogbo yín lẹ ó sálọ, títí a ó fi yín sílẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí igi àsíá ní orí òkè, gẹ́gẹ́ bí àsíá lórí òkè.”
18 Şi de aceea DOMNUL va aştepta, ca să aibă har fața de voi şi de aceea va fi înălţat, ca să aibă milă de voi, fiindcă DOMNUL este un Dumnezeu al judecăţii; binecuvântaţi sunt toţi cei care îl aşteaptă.
Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ síjú àánú wò ọ́; ó dìde láti ṣàánú fún ọ. Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!
19 Fiindcă poporul va locui în Sion, la Ierusalim, tu nu vei mai plânge; el va avea mult har către tine la vocea strigătului tău; când îl va auzi, îţi va răspunde.
Ẹ̀yin ènìyàn Sioni, tí ń gbé ní Jerusalẹmu, ìwọ kì yóò sọkún mọ́. Báwo ni àánú rẹ̀ yóò ti pọ̀ tó nígbà tí ìwọ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́! Bí ó bá ti gbọ́, òun yóò dá ọ lóhùn.
20 Şi, deşi Domnul îţi dă pâinea în restrişte şi apa în necaz, totuşi învăţătorii tăi nu vor mai fi înlăturaţi într-un colţ, ci ochii tăi îi vor vedea pe învăţătorii tăi.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fún ọ ní àkàrà ìyà àti omi ìpọ́njú, àwọn olùkọ́ rẹ kì yóò fi ara sin mọ́; pẹ̀lú ojú rẹ ni ìwọ ó rí wọn.
21 Şi urechile tale vor auzi un cuvânt în urma ta, spunând: Aceasta este calea, umblaţi în ea, când vă întoarceţi la dreapta şi când vă întoarceţi la stânga.
Bí o bá yí sápá ọ̀tún tàbí apá òsì, etí rẹ yóò máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn rẹ, wí pé, “Ọ̀nà nìyìí, máa rìn nínú rẹ̀.”
22 Veţi pângări de asemenea acoperitoarea chipurilor voastre cioplite din argint şi ornamentul chipurilor voastre turnate din aur, aruncă-i precum o zdreanţă murdară; spune-i: Du-te de aici.
Lẹ́yìn náà ni ẹ ó ba àwọn ère yín jẹ́ àwọn tí ẹ fi fàdákà bò àti àwọn ère tí ẹ fi wúrà bò pẹ̀lú, ẹ ó sọ wọ́n nù bí aṣọ tí obìnrin fi ṣe nǹkan oṣù ẹ ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kúrò níbí!”
23 Atunci va da ploaie seminţei tale, cu care să semeni pământul; şi pâine din venitul pământului, şi acesta va fi gras şi roditor; în acea zi vitele tale vor paşte în păşuni largi.
Òun yóò sì rọ òjò fún un yín sí àwọn irúgbìn tí ẹ gbìn sórí ilẹ̀, oúnjẹ tí yóò ti ilẹ̀ náà wá yóò ní ọ̀rá yóò sì pọ̀. Ní ọjọ́ náà ni àwọn ẹran ọ̀sìn yín yóò máa jẹ koríko ní pápá oko tútù tí ó tẹ́jú.
24 Boii de asemenea şi măgarii tineri care ară pământul vor mânca nutreţ curat, vânturat cu lopata şi cu furca.
Àwọn màlúù àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ń tú ilẹ̀ yóò jẹ oúnjẹ àdídùn tí a fi àmúga àti ṣọ́bìrì fọ́nkálẹ̀.
25 Şi vor fi peste fiecare munte înalt şi peste fiecare deal înalt, râuri şi pâraie de ape, în ziua marelui măcel, când turnurile vor cădea.
Ní ọjọ́ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò sọ ẹ̀mí wọn nù nígbà tí ilé ìṣọ́ yóò wó lulẹ̀, odò omi yóò sàn lórí òkè gíga àti lórí àwọn òkè kékeré.
26 Mai mult, lumina lunii va fi ca lumina soarelui şi lumina soarelui va fi înşeptită, ca lumina a şapte zile, în ziua în care DOMNUL leagă spărtura poporului său şi vindecă lovitura rănii lui.
Òṣùpá yóò sì tàn bí oòrùn, àti ìtànṣán oòrùn yóò mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po méje, gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ odidi ọjọ́ méje, nígbà tí Olúwa yóò di ojú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ tí yóò sì wo ọgbẹ́ tí ó ti dá sí wọn lára sàn.
27 Iată, numele DOMNULUI vine de departe, arzând în mânia lui şi povara lui este grea; buzele lui sunt pline de indignare şi limba lui [este] ca un foc mistuitor,
Kíyèsi i, orúkọ Olúwa ti òkèèrè wá pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti kurukuru èéfín tí ó nípọn; ètè rẹ̀ kún fún ìbínú ahọ́n rẹ̀ sì jẹ́ iná ajónirun.
28 Şi suflarea lui, ca pârâu ce inundă, va ajunge la mijlocul gâtului, pentru a cerne naţiunile cu sita zădărniciei şi [va fi] un frâu în fălcile poporului, făcându-l să rătăcească.
Èémí rẹ̀ sì dàbí òjò alágbára, tí ó rú sókè dé ọ̀run. Ó jọ àwọn orílẹ̀-èdè nínú kọ̀ǹkọ̀sọ̀; ó sì fi sí ìjánu ní àgbọ̀n àwọn ènìyàn láti ṣì wọ́n lọ́nà.
29 Veţi avea un cântec, ca în noaptea când este ţinută o solemnitate sfântă; şi veselie a inimii, ca atunci când unul merge cu fluier pentru a veni la muntele DOMNULUI, la Cel tare al lui Israel.
Ẹ̀yin ó sì kọrin gẹ́gẹ́ bí i ti alẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe àjọyọ̀ àpéjọ mímọ́, ọkàn yín yóò yọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ènìyàn gòkè lọ pẹ̀lú fèrè sí orí òkè Olúwa, àní sí àpáta Israẹli.
30 Şi DOMNUL va face vocea lui glorioasă să fie auzită şi va arăta aşezarea braţului său cu indignarea mâniei lui şi cu flacăra unui foc mistuitor, cu împrăştiere şi vijelie şi pietre de grindină.
Olúwa yóò jẹ́ kí wọn ó gbọ́ ohùn ògo rẹ̀ yóò sì jẹ́ kí wọ́n rí apá rẹ̀ tí ó ń bọ̀ wálẹ̀ pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti iná ajónirun, pẹ̀lú mọ̀nàmọ́ná, àrá àti yìnyín.
31 Căci prin vocea DOMNULUI vor fi bătuţi asirienii, care au lovit cu o nuia.
Ohùn Olúwa yóò fọ́ Asiria túútúú, pẹ̀lú ọ̀pá aládé rẹ̀ ni yóò lù wọ́n bolẹ̀.
32 Şi în fiecare loc pe unde va trece toiagul înrădăcinat, pe care DOMNUL îl va pune peste el, va trece cu tamburine şi harpe; şi în bătălii ale cutremurării va lupta el cu acesta.
Ẹgba kọ̀ọ̀kan tí Olúwa bá gbé lé wọn pẹ̀lú ọ̀pá ìjẹníyà rẹ̀ yóò jẹ́ ti ṣaworo àti ti dùùrù, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń bá wọn jà lójú ogun pẹ̀lú ìkùùkuu láti apá rẹ̀.
33 Căci Tofetul este rânduit din vechime; da, pentru împărat este pregătit; el [l]-a făcut adânc şi larg; grămada lui este foc şi mult lemn; suflarea DOMNULUI o aprinde ca un râu de pucioasă.
A ti tọ́jú Tofeti sílẹ̀ tipẹ́tipẹ́, a ti tọ́jú rẹ̀ sílẹ̀ fún ọba. Ojú ààrò rẹ̀ ni a ti gbẹ́ jì tí ó sì fẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ iná àti igi ìdáná; èémí Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìṣàn sulfuru ń jó ṣe mú un gbiná.

< Isaia 30 >