< Isaia 29 >
1 Vai lui Ariel, lui Ariel, cetatea unde a locuit David! Adăugaţi an la an, lăsaţi sărbătorile să îşi înjunghie [animalele] sacrificiilor lor.
Ègbé ni fún ọ, Arieli, Arieli, ìlú níbi tí Dafidi tẹ̀dó sí! Fi ọdún kún ọdún sì jẹ́ kí àwọn àkọlùkọgbà àjọ̀dún un rẹ tẹ̀síwájú.
2 Totuşi voi strâmtora pe Ariel şi va fi jelire şi întristare şi îmi va fi ca Ariel.
Síbẹ̀síbẹ̀ èmi yóò dó ti Arieli òun yóò ṣọ̀fọ̀ yóò sì sọkún, òun yóò sì dàbí pẹpẹ ọkàn sí mi.
3 Şi voi aşeza tabăra împotriva ta de jur împrejur şi te voi asedia cu un munte şi voi ridica fortăreţe împotriva ta.
Èmi yóò sì wà ní bùba yí ọ ká níbi gbogbo, Èmi yóò sì fi ilé ìṣọ́ yí ọ ká, Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìdó ti ni mi dojúkọ ọ́.
4 Şi vei fi înjosit [şi] vei vorbi din pământ şi vorbirea ta va fi de jos din ţărână şi vocea ta va fi ca a unuia care are demon, din pământ şi vorbirea ta va şopti din ţărână.
Ní ìrẹ̀sílẹ̀, ìwọ ó sì máa sọ̀rọ̀ láti ilẹ̀ wá; ọ̀rọ̀ rẹ yóò sì máa kùn jáde láti inú erùpẹ̀. Ohun rẹ yóò máa jáde bí i ti ẹnìkan tó ní ẹ̀mí àfọ̀ṣẹ láti ilẹ̀ jáde wá, láti inú erùpẹ̀ ni ohùn rẹ yóò máa wá wúyẹ́wúyẹ́.
5 Mai mult, mulţimea străinilor tăi va fi ca ţărâna măruntă şi mulţimea tiranilor va fi ca pleava care trece, da, va fi într-o clipă, dintr-odată.
Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá rẹ, yóò dàbí yanrìn kíkúnná, agbo àwọn aláìláàánú bí ìyàngbò tí a fẹ́ dànù. Lójijì, ní ìṣẹ́jú kan,
6 Vei fi cercetat de DOMNUL oştirilor cu tunet şi cutremur şi mare zgomot, cu furtună şi vijelie şi flacăra focului mistuitor.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò wá pẹ̀lú àrá àti ilẹ̀-rírì àti ariwo ńlá, àti ẹ̀fúùfù líle àti iná ajónirun.
7 Şi mulţimea tuturor naţiunilor care luptă împotriva lui Ariel, chiar toţi cei ce luptă împotriva ei şi a întăriturilor ei şi care o tulbură, va fi ca visul unei viziuni de noapte.
Lẹ́yìn náà, ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ ènìyàn tí gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó bá Arieli jà, tí ó dojú ìjà kọ òun àti ilé olódi rẹ̀ tí ó sì dó tì í, yóò dàbí ẹni pé nínú àlá, bí ìran ní òru
8 Va fi ca atunci când un flămând visează şi, iată, mănâncă; dar se trezeşte şi sufletul său este gol; sau ca atunci când un însetat visează şi, iată, bea; dar se trezeşte şi, iată, este leşinat şi sufletul său pofteşte, astfel va fi mulţimea tuturor naţiunilor care luptă împotriva muntelui Sion.
àti bí ìgbà tí ẹni tí ebi ń pa ń lá àlá pé òun ń jẹun, ṣùgbọ́n ó jí, ebi rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀; tàbí bí ìgbà tí ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ lá àlá pé òun ń mu omi, ṣùgbọ́n nígbà tí ó jí, sì wò ó, ó dákú, òǹgbẹ sì ń gbẹ ọkàn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè tí ń bá òkè Sioni jà.
9 Opriţi-vă şi minunaţi-vă; ţipaţi şi strigaţi, ei sunt beţi, dar nu de vin; şovăie, dar nu de băutură tare.
Ẹ bẹ̀rù kí ẹnu kí ó yà yín, ẹ fọ́ ara yín lójú kí ẹ má sì ríran; ẹ mutí yó kì í ṣe ọtí wáìnì, ẹ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n, ṣùgbọ́n kì í ṣe ti ọtí líle.
10 Fiindcă DOMNUL a turnat peste voi duhul unui somn adânc şi v-a închis ochii, pe profeţii şi conducătorii voştri, pe văzători i-a acoperit.
Olúwa ti mú oorun ìjìká wá sórí i yín: ó ti dì yín lójú ẹ̀yin wòlíì; ó ti bo orí yín ẹ̀yin aríran.
11 Şi viziunea tuturor v-a devenit precum cuvintele unei cărţi sigilate, dată unui învăţat, spunând: Citeşte-o, te rog; iar el spune: Nu pot, fiindcă este sigilată;
Fún un yín gbogbo ìran yìí kò yàtọ̀ sí àwọn ọ̀rọ̀ tí a fi èdìdì dì sínú ìwé kíká. Bí ẹ bá sì fún ẹni tí ó lè ka ìwé kíká náà, tí ẹ sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò lè kà á; a ti dì í ní èdìdì.”
12 Şi cartea este dată unui neînvăţat, spunând: Citeşte-o, te rog; iar el spune: Nu sunt învăţat.
Tàbí bí ẹ bá fún ẹni tí kò lè ka ìwé kíká náà tí ẹ sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n kà.”
13 De aceea Domnul a spus: Întrucât acest popor se apropie de mine cu gura lor şi cu buzele lor mă onorează, [totuşi] şi-au depărtat inima de mine şi temerea lor faţă de mine este învăţată printr-un precept omenesc;
Olúwa wí pé: “Àwọn ènìyàn yìí súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹnu wọn, wọ́n sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ètè wọn, ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà sí mi. Ìsìn wọn si mi ni a gbé ka orí òfin tí àwọn ọkùnrin kọ́ ni.
14 De aceea, iată, voi continua să fac o lucrare minunată în mijlocul acestui popor, o lucrare minunată şi o minune; fiindcă înţelepciunea înţelepţilor lor va pieri şi înţelegerea celor chibzuiţi ai lui va fi ascunsă.
Nítorí náà lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò ya àwọn ènìyàn yìí lẹ́nu pẹ̀lú ìyanu lórí ìyanu; ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ni yóò ṣègbé, ìmọ̀ àwọn onímọ̀ ni yóò pòórá.”
15 Vai celor ce merg adânc pentru a-şi ascunde sfatul de DOMNUL şi faptele lor sunt în întuneric şi spun: Cine ne vede? Şi: Cine ne cunoaşte?
Ègbé ni fún àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun láti fi ètò wọn pamọ́ kúrò lójú Olúwa, tí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ẹ wọn nínú òkùnkùn tí wọ́n sì rò pé, “Ta ló rí wa? Ta ni yóò mọ̀?”
16 Cu siguranţă perversitatea voastră va fi socotită ca lutul olarului; căci va spune lucrarea despre cel care a făcut-o: Nu el m-a făcut? Sau lucrul alcătuit va spune despre cel care l-a alcătuit: Nu a avut înţelegere?
Ẹ̀yin dojú nǹkan délẹ̀, bí ẹni pé wọ́n rò pé amọ̀kòkò dàbí amọ̀! Ǹjẹ́ ohun tí a ṣe le sọ fún olùṣe pé, “Òun kọ́ ló ṣe mí”? Ǹjẹ́ ìkòkò lè sọ nípa amọ̀kòkò pé, “Kò mọ nǹkan”?
17 Nu este decât foarte puţin timp şi Libanul se va schimba într-un câmp roditor şi câmpul roditor va fi socotit ca o pădure.
Ní àìpẹ́ jọjọ, ǹjẹ́ a kò ní sọ Lebanoni di pápá ẹlẹ́tù lójú àti pápá ẹlẹ́tù lójú yóò dàbí aginjù?
18 Şi în acea zi surzii vor auzi cuvintele cărţii şi ochii orbilor vor vedea din întunecime şi din întuneric.
Ní ọjọ́ náà adití yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ìwé kíká náà, láti inú fìrífìrí àti òkùnkùn ni àwọn ojú afọ́jú yóò ríran.
19 Cei blânzi de asemenea îşi vor creşte bucuria în DOMNUL şi cei săraci între oameni se vor bucura în Cel Sfânt al lui Israel.
Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóò yọ̀ nínú Olúwa: àwọn aláìní yóò yọ̀ nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
20 Fiindcă tiranul este făcut de nimic şi batjocoritorul este mistuit şi toţi care caută să vadă nelegiuirea sunt stârpiţi,
Aláìláàánú yóò pòórá, àwọn tí ń ṣẹlẹ́yà yóò di àwátì, gbogbo àwọn tí ó ní ojú ibi ni a ó ké lulẹ̀—
21 Care fac pe om vinovat pentru un cuvânt şi pun o capcană pentru cel care mustră la poartă şi abat pe cel drept pentru un lucru de nimic.
àwọn tí wọ́n fi ọ̀rọ̀ kan mú ẹnìkan di ẹlẹ́bi, ẹni tí ń dẹkùn mú olùgbèjà ní ilé ẹjọ́ tí ẹ fi ẹ̀rí èké dun aláìṣẹ̀ ní ìdájọ́.
22 De aceea astfel spune DOMNUL, care a răscumpărat pe Avraam, referitor la casa lui Iacob: Iacob nu va fi acum ruşinat, nici nu-i va păli acum faţa.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa, ẹni tí ó ra Abrahamu padà sọ sí ilé Jakọbu: “Ojú kì yóò ti Jakọbu mọ́; ojú wọn kì yóò sì rẹ̀wẹ̀sì mọ́.
23 Dar când îşi va vedea copiii, lucrarea mâinilor mele, în mijlocul lui, ei vor sfinţi numele meu şi vor sfinţi pe Cel Sfânt al lui Iacob şi se vor teme de Dumnezeul lui Israel.
Nígbà tí wọ́n bá rí i láàrín àwọn ọmọ wọn, àwọn iṣẹ́ ọwọ́ mi, wọn yóò ya orúkọ mi sí mímọ́, wọn yóò tẹ́wọ́gbà mímọ́ Ẹni Mímọ́ Jakọbu wọn yóò dìde dúró ní ìbọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Israẹli.
24 De asemenea cei care au rătăcit în duh, vor ajunge la cunoştinţa înţelegerii şi cei care au cârtit vor învăţa doctrină.
Gbogbo àwọn tí ń rìn ségesège ní yóò jèrè ìmọ̀; gbogbo àwọn tí ń ṣe àròyé yóò gba ìtọ́sọ́nà.”