< Isaia 2 >

1 Cuvântul pe care Isaia, fiul lui Amoţ, l-a văzut referitor la Iuda şi Ierusalim.
Èyí ni ohun tí Isaiah ọmọ Amosi rí nípa Juda àti Jerusalẹmu.
2 Şi se va întâmpla în zilele de pe urmă, că muntele casei DOMNULUI va fi întemeiat pe vârful munţilor şi va fi înălţat peste dealuri; şi toate naţiunile vor curge spre el.
Ní ìgbẹ̀yìn ọjọ́ òkè tẹmpili Olúwa ni a ó fi ìdí rẹ̀ kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olú nínú àwọn òkè, a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì máa sàn sínú un rẹ̀.
3 Şi mulţi oameni vor merge şi vor spune: Veniţi, şi să urcăm la muntele DOMNULUI, la casa Dumnezeului lui Iacob, şi el ne va învăţa despre căile lui, noi vom merge pe cărările lui, căci din Sion va ieşi legea şi din Ierusalim cuvântul DOMNULUI.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni yóò wá, wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa, àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu. Òun yóò kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀, kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.” Òfin yóò jáde láti Sioni wá, àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
4 Şi el va judeca între naţiuni şi va mustra mulţi oameni; şi îşi vor bate din săbii fiare de plug şi din suliţele lor, prăjini de curăţat pomi; nu va ridica naţiune sabie împotriva altei naţiuni, nici nu vor mai învăţa războiul.
Òun ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, yóò sì parí aáwọ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn. Wọn yóò fi idà wọn rọ ọkọ́ ìtulẹ̀, wọn yóò sì fi ọ̀kọ̀ wọn rọ dòjé. Orílẹ̀-èdè kì yóò sì gbé idà sí orílẹ̀-èdè mọ́, bẹ́ẹ̀ ní wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
5 Casă a lui Iacob, veniţi şi să umblăm în lumina DOMNULUI.
Wá, ẹ̀yìn ará ilé e Jakọbu, ẹ jẹ́ kí a rìn nínú ìmọ́lẹ̀ Olúwa.
6 De aceea ai părăsit pe poporul tău, pe casa lui Iacob, fiindcă sunt umpluţi de ceea ce vine din est şi sunt ghicitori ca filistenii şi se complac în copiii străinilor.
Ìwọ ti kọ àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀, ìwọ ilé Jakọbu. Wọ́n kún fún ìgbàgbọ́ tí kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ tí ó ti ìlà-oòrùn wá, wọ́n ń wo iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn Filistini, wọ́n ń pa ọwọ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn abọ̀rìṣà.
7 Ţara lor de asemenea este plină de aur şi argint, şi nu este sfârşit al tezaurelor lor; ţara lor este de asemenea plină de cai, şi nu este sfârşit al carelor lor;
Ilẹ̀ wọn kún fún fàdákà àti wúrà, ìṣúra wọn kò sì ní òpin. Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lópin.
8 Ţara lor este de asemenea plină de idoli; se închină la lucrarea propriilor mâini, pe care degetele lor au făcut-o;
Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ère, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn, èyí tí ìka ọwọ́ àwọn tìkára wọn ti ṣe.
9 Şi omul de rând se îndoaie şi bărbatul de vază se umileşte; de aceea nu îi ierta!
Nítorí náà ni a ó ṣe rẹ ènìyàn sílẹ̀ ìran ọmọ ènìyàn ni yóò sì di onírẹ̀lẹ̀, má ṣe dáríjì wọ́n.
10 Intră în stâncă şi ascunde-te în ţărână, de frica DOMNULUI şi de gloria maiestăţii lui.
Wọ inú àpáta lọ, fi ara pamọ́ nínú erùpẹ̀ kúrò nínú ìpayà Olúwa, àti ògo ọláńlá rẹ̀!
11 Privirile îngâmfate ale omului vor fi umilite şi trufia oamenilor va fi aplecată şi numai DOMNUL va fi înălţat în acea zi.
Ojú agbéraga ènìyàn ni a ó rẹ̀ sílẹ̀ a ó sì tẹrí ìgbéraga ènìyàn ba, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà.
12 Căci ziua DOMNULUI oştirilor va fi peste fiecare ce este mândru şi îngâmfat şi peste fiecare ce este înălţat, şi îl va înjosi;
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan ní ìpamọ́ fún gbogbo agbéraga àti ọlọ́kàn gíga nítorí gbogbo àwọn tí a gbéga (ni a ó rẹ̀ sílẹ̀),
13 Şi peste toţi cedrii Libanului, care sunt înalţi şi înălţaţi şi peste toţi stejarii Basanului,
nítorí gbogbo igi kedari Lebanoni, tó ga tó rìpó àti gbogbo óákù Baṣani,
14 Şi peste toţi munţii înalţi şi peste toate dealurile înălţate,
nítorí gbogbo òkè gíga ńlá ńlá àti àwọn òkè kéékèèké,
15 Şi peste fiecare turn înalt şi peste fiecare zid întărit,
fún ilé ìṣọ́ gíga gíga àti àwọn odi ìdáàbòbò,
16 Şi peste toate corăbiile Tarsisului şi peste toate imaginile plăcute.
fún gbogbo ọkọ̀ àwọn oníṣòwò àwọn ọkọ̀ tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
17 Şi îngâmfarea omului va fi încovoiată, şi trufia oamenilor va fi înjosită şi numai DOMNUL va fi înălţat în acea zi.
Ìgbéraga ènìyàn ni a ó tẹ̀ lórí ba a ó sì rẹ ìgbéraga ènìyàn sílẹ̀, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà,
18 Şi pe idoli el îi va aboli în întregime.
gbogbo ère òrìṣà yóò pòórá.
19 Şi vor intra în găurile stâncilor şi în peşterile pământului, de frica DOMNULUI şi de gloria maiestăţii lui, când se va ridica el să scuture înfricoşător pământul.
Àwọn ènìyàn yóò sálọ sínú ihò àpáta àti sínú ihò ilẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
20 În acea zi un om îşi va arunca idolii de argint şi idolii de aur, care şi i-au făcut fiecare pentru el însuşi să se închine, cârtiţelor şi liliecilor;
Ní ọjọ́ náà ni àwọn ènìyàn yóò máa sọ àwọn ère fàdákà àti ère wúrà tí wọ́n ti yá fún bíbọ sí èkúté àti àwọn àdán.
21 Pentru a merge în crăpăturile stâncilor şi în vârfurile stâncilor zdrenţuite, de frica DOMNULUI şi de gloria maiestăţii lui, când se va ridica el să scuture înfricoşător pământul.
Wọn yóò sálọ sínú ihò ìsàlẹ̀ àpáta àti sínú ihò pàlàpálá àpáta kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
22 Părăsiţi omul a cărui suflare este în nările lui, căci în ce este el socotit de încredere?
Dẹ́kun à ń gba ènìyàn gbọ́, èémí ẹni tó wà ní ihò imú rẹ̀. Nítorí nínú kín ni a lè kà á sí?

< Isaia 2 >