< Geneză 4 >

1 Şi Adam a cunoscut-o pe Eva, soţia lui, şi ea a rămas însărcinată şi a născut pe Cain şi a spus: Am primit un bărbat de la DOMNUL.
Adamu sì bá aya rẹ̀ Efa lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Kaini. Ó wí pé, “Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Olúwa ni mo bí ọmọ ọkùnrin.”
2 Şi ea a mai născut pe fratele lui, Abel. Şi Abel era păzitor de oi, dar Cain era lucrător al pământului.
Lẹ́yìn náà, ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn tí a pè ní Abeli. Abeli jẹ́ darandaran, Kaini sì jẹ́ àgbẹ̀.
3 Şi s-a întâmplat că, după un timp, Cain a adus un dar DOMNULUI, din rodul pământului.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Kaini mú ọrẹ wá fún Olúwa nínú èso ilẹ̀ rẹ̀.
4 Şi Abel, de asemenea, a adus din întâii născuţi ai turmei sale şi din grăsimea lor. Şi DOMNUL s-a uitat cu plăcere la Abel şi la darul său.
Ṣùgbọ́n Abeli mú ẹran tí ó sanra wá fún Olúwa nínú àkọ́bí ẹran ọ̀sìn rẹ̀. Olúwa sì fi ojúrere wo Abeli àti ọrẹ rẹ̀,
5 Dar la Cain şi la darul său nu s-a uitat cu plăcere. Şi Cain s-a înfuriat tare şi i s-a posomorât faţa.
ṣùgbọ́n Olúwa kò fi ojúrere wo Kaini àti ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà inú bí Kaini gidigidi, ojú rẹ̀ sì fàro.
6 Şi DOMNUL i-a spus lui Cain: De ce te-ai înfuriat? Şi de ce ţi s-a posomorât faţa?
Nígbà náà ni Olúwa bi Kaini pé, “Èéṣe tí ìwọ ń bínú? Èéṣe tí ojú rẹ sì fàro?
7 Dacă faci bine, nu vei fi acceptat? Iar dacă nu faci bine, păcatul pândeşte la uşă. Şi dorinţa lui se ţine de tine, dar tu să stăpâneşti peste el.
Bí ìwọ bá ṣe ohun tí ó tọ́, ṣé ìwọ kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà? Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ṣe ohun tí ó tọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ ní ẹnu-ọ̀nà rẹ, ó fẹ́ ní ọ ní ìní, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ ṣe àkóso rẹ̀.”
8 Iar Cain a vorbit cu Abel, fratele său, şi a fost aşa: când erau ei pe câmp, Cain s-a ridicat împotriva lui Abel, fratele său, şi l-a ucis.
Kaini wí fún Abeli arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ kí a lọ sí oko.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti wà ní oko; Kaini da ojú ìjà kọ Abeli arákùnrin rẹ̀, ó sì pa á.
9 Şi DOMNUL i-a spus lui Cain: Unde este Abel, fratele tău? Iar el a spus: Nu ştiu; sunt eu păzitorul fratelui meu?
Nígbà náà ni Olúwa béèrè lọ́wọ́ Kaini pé, “Níbo ni Abeli arákùnrin rẹ wà?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi kò mọ ibi tí ó wà, èmí ha ń ṣe olùṣọ́ arákùnrin mi bí?”
10 Iar el a spus: Ce ai făcut? Vocea sângelui fratelui tău strigă din pământ către mine.
Olúwa wí pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ṣe yìí? Gbọ́! Ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ ń kígbe pè mí láti ilẹ̀ wá.
11 Şi acum eşti blestemat de pe pământul care şi-a deschis gura să primească sângele fratelui tău din mâna ta.
Láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ ti wà lábẹ́ ègún, a sì ti lé ọ lórí ilẹ̀ tí ó ya ẹnu gba ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ lọ́wọ́ rẹ.
12 Când lucrezi pământul, acesta nu îţi va mai da de aici înainte puterea lui; un fugar şi un rătăcitor vei fi pe pământ.
Bí ìwọ bá ro ilẹ̀, ilẹ̀ kì yóò fi agbára rẹ̀ so èso rẹ̀ fún ọ mọ́. Ìwọ yóò sì jẹ́ ìsáǹsá àti alárìnkiri ni orí ilẹ̀ ayé.”
13 Şi Cain a spus DOMNULUI: Pedeapsa mea este mai mare decât o pot purta.
Kaini wí fún Olúwa pé, “Ẹrù ìyà ẹ̀ṣẹ̀ mi pọ̀ ju èyí tí mo le rù lọ.
14 Iată, tu m-ai alungat astăzi de pe faţa pământului şi de la faţa ta voi fi ascuns şi voi fi un fugar şi un rătăcitor pe pământ şi se va întâmpla că oricine mă găseşte mă va ucide.
Lónìí, ìwọ lé mi kúrò lórí ilẹ̀, mó sì di ẹni tí ó fi ara pamọ́ kúrò ní ojú rẹ, èmi yóò sì di ìsáǹsá àti alárìnkiri ní ayé, ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi, yóò sì pa mí.”
15 Şi DOMNUL i-a spus: De aceea, oricine ucide pe Cain, răzbunare va fi asupra lui de şapte ori. Şi DOMNUL a pus un semn pe Cain, ca nu cumva cineva, găsindu-l, să îl ucidă.
Ṣùgbọ́n, Olúwa wí fún pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ẹnikẹ́ni bá pa Kaini, èmi yóò gbẹ̀san ní ara onítọ̀hún ní ìgbà méje.” Nígbà náà ni Ọlọ́run fi àmì sí ara Kaini, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá ri má ba à pa á.
16 Şi Cain a ieşit din prezența DOMNULUI şi a locuit în ţara Nod, la est de Eden.
Kaini sì kúrò níwájú Olúwa, ó sì ń gbé ilẹ̀ Nodi ní ìhà ìlà-oòrùn Edeni.
17 Şi Cain a cunoscut-o pe soţia sa şi ea a rămas însărcinată şi a născut pe Enoh; şi a zidit o cetate şi a pus numele cetăţii după numele fiului său, Enoh.
Kaini sì bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Enoku. Kaini sì tẹ ìlú kan dó, ó sì fi orúkọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Enoku sọ ìlú náà.
18 Şi lui Enoh i s-a născut Irad; şi Irad a născut pe Mehuiael; şi Mehuiael a născut pe Metuşael; şi Metuşael a născut pe Lameh.
Enoku sì bí Iradi, Iradi sì ni baba Mehujaeli, Mehujaeli sì bí Metuṣaeli, Metuṣaeli sì ni baba Lameki.
19 Şi Lameh şi-a luat două soţii: numele uneia era Ada şi numele celeilalte, Ţila.
Lameki sì fẹ́ aya méjì, orúkọ èkínní ni Adah, àti orúkọ èkejì ni Silla.
20 Şi Ada a născut pe Iabal: el a fost tatăl celor ce locuiesc în corturi şi au vite.
Adah sì bí Jabali, òun ni baba irú àwọn tí ń gbé inú àgọ́, tí wọ́n sì ń sin ẹran ọ̀sìn.
21 Şi numele fratelui său era Iubal: el a fost tatăl tuturor celor ce mânuiesc harpa şi instrumentul de suflat.
Orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Jubali, òun ni baba irú àwọn tí ń tẹ dùùrù tí wọ́n sì ń fọn fèrè.
22 Şi Ţila, de asemenea, a născut pe Tubal-Cain, instructor al fiecărui meşteşugar în aramă şi fier; şi sora lui Tubal-Cain a fost Naama.
Silla náà sì bí ọmọkùnrin tí ń jẹ́ Tubali-Kaini, tí ó ń rọ oríṣìíríṣìí ohun èlò láti ara idẹ àti irin. Arábìnrin Tubali-Kaini ni Naama.
23 Şi Lameh a spus soţiilor lui, Ada şi Ţila: Auziţi vocea mea, voi soţiile lui Lameh, daţi ascultare la vorbirea mea: pentru că am ucis un om pentru rănirea mea şi un tânăr pentru vânătaia mea.
Lameki wí fún àwọn aya rẹ̀, “Adah àti Silla, ẹ tẹ́tí sí mi; ẹ̀yin aya Lameki, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi. Mo ti pa ọkùnrin kan tí ó kọlù mí, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó pa mí lára.
24 Dacă va fi răzbunat Cain de şapte ori, cu adevărat, Lameh de şaptezeci şi şapte de ori.
Bí a ó bá gbẹ̀san Kaini ní ìgbà méje, ǹjẹ́ kí a gba ti Lameki nígbà mẹ́tàdínlọ́gọ́rin.”
25 Şi Adam a cunoscut-o din nou pe soţia lui şi ea a născut un fiu şi i-a pus numele Set: Pentru că Dumnezeu, a spus ea, mi-a rânduit o altă sămânţă în locul lui Abel, pe care l-a ucis Cain.
Adamu sì tún bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Seti, tí ó túmọ̀ sí pé, “Ọlọ́run fún mi ní ọmọkùnrin mìíràn ní ipò Abeli tí Kaini pa.”
26 Şi lui Set, de asemenea, i s-a născut un fiu şi i-a pus numele Enos: atunci au început oamenii să cheme numele DOMNULUI.
Seti náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Enoṣi. Láti àkókò náà lọ ni àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ké pe orúkọ Olúwa.

< Geneză 4 >