< Geneză 34 >

1 Şi Dina, fiica Leei, pe care i-a născut-o lui Iacob, a ieşit să vadă fiicele ţării.
Ní ọjọ́ kan, Dina ọmọbìnrin tí Lea bí fún Jakọbu jáde lọ bẹ àwọn ọmọbìnrin ilẹ̀ náà wò.
2 Şi când Sihem, fiul lui Hamor, hivitul, prinţ al ţinutului, a văzut-o, a luat-o şi s-a culcat cu ea şi a pângărit-o.
Nígbà tí Ṣekemu ọmọ ọba Hamori ará Hifi rí i, ó mú un, ó sì fi ipá bá a lo pọ̀.
3 Şi sufletul lui s-a lipit de Dina, fiica lui Iacob, şi a iubit fata şi a vorbit frumos fetei.
Ọkàn rẹ sì fà sí Dina ọmọ Jakọbu gan an, ó sì fẹ́ràn rẹ̀ ó sì bá ọmọbìnrin náà sọ̀rọ̀ ìfẹ́.
4 Şi Sihem i-a vorbit tatălui său, Hamor, spunând: Ia-mi această fată de soţie.
Ṣekemu sì wí fún Hamori baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ọmọbìnrin yìí fún mi bí aya.”
5 Şi Iacob a auzit că el a pângărit pe Dina, fiica sa; acum fiii lui erau cu vitele lui în câmp; şi Iacob a tăcut până ce au venit.
Nígbà tí Jakọbu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ pé a fi ipá bá Dina ọmọbìnrin òun ní ògo jẹ́, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀ wà nínú pápá níbi tí wọ́n ti ń daran nítorí náà ó mú sùúrù títí tí wọ́n fi dé.
6 Şi Hamor, tatăl lui Sihem, a ieşit la Iacob să vorbească îndeaproape cu el.
Hamori baba Ṣekemu sì jáde wá láti bá Jakọbu sọ̀rọ̀.
7 Şi fiii lui Iacob au venit din câmp după ce au auzit aceasta şi bărbaţii erau îndureraţi şi s-au înfuriat, deoarece el lucrase prosteşte în Israel, culcându-se cu fiica lui Iacob, lucru care nu trebuia făcut.
Àwọn ọmọ Jakọbu sì ti oko dé, wọ́n sì gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ inú wọn sì bàjẹ́, ó sì ń bí wọn nínú gidigidi, nítorí tí ó ṣe ohun búburú ní Israẹli, ní ti ó bá ọmọbìnrin ọmọ Jakọbu lòpọ̀—irú ohun tí kò yẹ kí ó ṣẹlẹ̀ rárá.
8 Şi Hamor a vorbit îndeaproape cu ei, spunând: Sufletul fiului meu Sihem tânjeşte după fiica voastră. Vă rog daţi-o lui de soţie.
Hamori sì bá wọn sọ̀rọ̀ pé, “Ọkàn ọmọ mi Ṣekemu fà sí ọmọ rẹ. Jọ̀wọ́ fi fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
9 Şi încuscriţi-vă cu noi şi daţi-ne fiicele voastre şi luaţi pe fiicele noastre pentru voi.
Ẹ jẹ́ kí a máa ṣe ìgbéyàwó láàrín ara wa, kí àwọn ọmọ yín kó máa fẹ́ àwọn ọmọ wa.
10 Şi veţi locui cu noi şi ţara va fi înaintea voastră; locuiţi şi faceţi comerţ în ea şi dobândiţi-vă stăpâniri în ea.
Ẹ lè máa gbé láàrín wa, ibikíbi tí ó bá tẹ́ yín lọ́rùn láàrín wa ni ẹ lè gbé, ẹ máa ṣe òwò yín kí ẹ sì kó ọrọ̀ jọ fún ara yín.”
11 Şi Sihem a spus tatălui ei şi fraţilor ei: Să găsesc har în ochii voştri şi ce îmi veţi spune vă voi da.
Ṣekemu sì wí fún baba àti arákùnrin Dina pé, “Ẹ jọ̀wọ́, ẹ jẹ́ kí n rí ojúrere yín, èmi yóò sì fún yín ní ohunkóhun tí ẹ̀yin bá fẹ́ gbà.
12 Cereţi de la mine zestre mare şi dar şi voi da conform cu ceea ce îmi veţi spune, dar daţi-mi fata de soţie.
Iyekíye tí owó orí rẹ̀ bá jẹ́ àti ẹ̀bùn gbogbo tí ẹ bá fẹ́, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó, èmi yóò san án, kí ẹ sá à jẹ́ kí ń fi ọmọ náà ṣe aya.”
13 Şi fiii lui Iacob au răspuns lui Sihem şi Hamor, tatăl lui, în mod înşelător şi au spus, deoarece el o pângărise pe Dina sora lor,
Àwọn ọmọ Jakọbu sì fi ẹ̀tàn dá Ṣekemu àti Hamori baba rẹ̀ lóhùn, wọ́n sì wí pé, nítorí tí ó ti ba ògo Dina arábìnrin wọn jẹ́.
14 Şi le-au spus: Nu putem face acest lucru, să dăm pe sora noastră unui necircumcis; căci aceasta ar fi ocară pentru noi;
Wọ́n wí fún wọn pé, “Àwa kò le ṣe nǹkan yìí láti fi arábìnrin wa fún aláìkọlà, nítorí àbùkù ni èyí yóò jẹ́ fún wa.
15 Dar în aceasta vă vom da acordul: dacă voi veţi fi precum suntem noi, ca fiecare parte bărbătească dintre voi să fie circumcis;
Àwa yóò fi ara mọ́ ọn bí ẹ̀yin yóò bá gbà láti dàbí i tiwa, wí pé ẹ̀yin pẹ̀lú yóò kọ gbogbo ọkùnrin yín ní ilà.
16 Atunci vi le vom da pe fiicele noastre şi le vom lua pe fiicele voastre pentru noi şi vom locui cu voi şi vom deveni un singur popor.
Nígbà náà ni àwa yóò le máa fún yín ní ọmọ wa, tí àwa náà yóò máa fẹ́ ẹ yín. A ó máa gbé láàrín yín, a ó sì di ara kan pẹ̀lú yín.
17 Dar dacă nu ne veţi da ascultare, pentru a fi circumcişi, atunci o vom lua pe fiica noastră şi vom pleca.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá kọ̀ láti kọlà, àwa yóò mú arábìnrin wa, á ó sì máa lọ.”
18 Şi cuvintele lor au plăcut lui Hamor şi lui Sihem, fiul lui Hamor.
Àbá náà sì dùn mọ́ Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀.
19 Şi tânărul nu a întârziat să facă aceasta, deoarece a avut desfătare în fiica lui Iacob şi el era demn de mai multă cinste decât toată casa tatălui său.
Ọ̀dọ́mọkùnrin náà, ẹni tí ó jẹ́ ẹni iyì jùlọ ní ilé baba rẹ̀, kò jáfara láti ṣe ohun tí wọ́n wí. Nítorí tí ó fẹ́ràn ọmọbìnrin Jakọbu.
20 Şi Hamor şi Sihem, fiul lui, au venit la poarta cetăţii lor şi au vorbit îndeaproape cu oamenii cetăţii lor, spunând:
Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀ sì wá sí ẹnu ibodè ìlú náà wọn sì bá àwọn ará ìlú náà sọ̀rọ̀.
21 Aceşti oameni sunt paşnici cu noi; de aceea lăsaţi-i să locuiască în ţară şi să facă comerţ în ea, pentru că ţara, iată, este destul de mare şi pentru ei; să luăm pe fiicele lor de soţii pentru noi şi să le dăm pe fiicele noastre.
Wí pé, “Ìwà àwọn ọkùnrin wọ̀nyí dára, ẹ jẹ́ kí wọn máa gbé ní àárín wa, kí wọn sì máa ṣòwò, ilẹ̀ kúkú wà rẹpẹtẹ tó gba ààyè dáradára. A lè fẹ́ àwọn ọmọ wọ́n, ki wọn sì fẹ́ tiwa pẹ̀lú.
22 Doar prin aceasta ne vor da acordul bărbaţii pentru a locui cu noi, pentru a fi un singur popor, dacă fiecare parte bărbătească între noi ar fi circumcisă, precum sunt ei circumcişi.
Ṣùgbọ́n kín ní kan ni a lè ṣe kí wọn tó gbà láti gbé pẹ̀lú wa, ìyẹn sì ni pé àwọn ọkùnrin wa yóò kọlà bí i tiwọn.
23 Nu vor fi turmele lor şi averea lor şi fiecare vită a lor, ale noastre? Doar să le dăm acordul şi vor locui cu noi.
Ṣe bí àwọn ẹran wọn àti ẹrú wọn àti àwọn ohun ọ̀sìn wọn ni yóò di tiwa bí a bá lè gbà bẹ́ẹ̀, wọn yóò sì máa gbé ni àárín wa.”
24 Şi lui Hamor şi lui Sihem, fiul lui, au dat ascultare toţi cei care ieşeau pe poarta cetăţii sale; şi fiecare parte bărbătească a fost circumcisă, toţi cei care au ieşit pe poarta cetăţii sale.
Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ń jáde ní ẹnu-bodè ìlú náà sì gbọ́ ti Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀. Gbogbo ọkùnrin ìlú náà sì kọlà.
25 Şi s-a întâmplat în a treia zi, când erau în dureri, că doi dintre fiii lui Iacob, Simeon şi Levi, fraţii Dinei, şi-a luat fiecare bărbat sabia şi au venit peste cetate în mod cutezător şi au ucis toată partea bărbătească.
Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta, nígbà tí gbogbo wọn sì wà nínú ìrora. Àwọn ọmọ Jakọbu méjì, Simeoni àti Lefi tí ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n fún Dina, sì mú idà wọn pẹ̀lú ìgboyà, wọ́n sì pa gbogbo ọkùnrin ìlú náà.
26 Şi au ucis pe Hamor şi pe Sihem, fiul lui, cu tăişul sabiei şi au luat pe Dina din casa lui Sihem şi au ieşit.
Wọ́n sì fi idà pa Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀, wọ́n mú Dina kúrò ní ilé wọn, wọ́n sì jáde.
27 Fiii lui Iacob au venit peste cei ucişi şi au prădat cetatea, din cauză că au pângărit pe sora lor.
Àwọn ọmọ Jakọbu sì wọlé àwọn tí a pa, wọ́n sì kó ẹrù ìlú tí a ti ba ògo arábìnrin wọn jẹ́.
28 Ei le-au luat oile şi boii lor şi măgarii lor şi ceea ce era în cetate şi ceea ce era în câmp.
Wọ́n kó màlúù wọn àti agbo ẹran wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìlú àti ní oko.
29 Şi toată averea lor şi pe toţi micuţii lor şi pe soţiile lor i-au luat captivi şi au prădat de asemenea tot ce era în casă.
Gbogbo ọrọ̀ wọn, gbogbo obìnrin ìlú àti àwọn ọmọ wẹẹrẹ pátápátá ni wọ́n kó. Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé wọn bí ìkógun.
30 Şi Iacob le-a spus lui Simeon şi lui Levi: Voi m-aţi tulburat să mă faceţi să put printre locuitorii ţării, printre canaaniţi şi periziţi; şi eu, fiind mic la număr, se vor aduna împreună împotriva mea şi mă vor ucide; şi voi fi nimicit, eu şi casa mea.
Nígbà náà ni Jakọbu wí fún Simeoni àti Lefi wí pé, “Ẹ̀yin ti kó ìyọnu bá mi nípa sísọ mí di olóòórùn láàrín ará Kenaani àti Peresi, tí ó ń gbé ilẹ̀ yìí. Àwa kò pọ̀, bí wọn bá wá parapọ̀ ṣígun sí wa, gbogbo wa pátápátá ni wọn yóò parun.”
31 Iar ei au spus: Trebuia să se poarte el cu sora noastră precum cu o curvă?
Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí ó ṣe arábìnrin wa bí panṣágà?”

< Geneză 34 >