< Geneză 31 >

1 Şi a auzit cuvintele fiilor lui Laban, spunând: Iacob a luat tot ce era al tatălui nostru; şi din ceea ce era al tatălui nostru el a dobândit toată această glorie.
Jakọbu sì gbọ́ pé àwọn ọmọ Labani ń wí pé, “Jakọbu ti gba gbogbo ohun ìní baba wa, ó sì ti kó ọrọ̀ jọ fún ara rẹ̀ lára àwọn ohun tí í ṣe ti baba wa.”
2 Şi Iacob a privit înfăţişarea lui Laban şi, iată, aceasta nu mai era faţă de el ca înainte.
Jakọbu sì ṣàkíyèsí pé ìwà Labani sí òun ti yí padà sí ti àtẹ̀yìnwá.
3 Şi DOMNUL i-a spus lui Iacob: Întoarce-te în ţara părinţilor tăi şi la rudele tale; şi eu voi fi cu tine.
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Jakọbu pé, “Padà lọ sí ilẹ̀ àwọn baba à rẹ, sí ọ̀dọ̀ àwọn ará rẹ, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ.”
4 Şi Iacob a trimis şi a chemat pe Rahela şi Leea la câmp, la turma sa,
Jakọbu sì ránṣẹ́ pe Rakeli àti Lea sí pápá níbi tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ wà.
5 Şi le-a spus: Văd înfăţişarea tatălui vostru, că aceasta nu mai este faţă de mine ca înainte; dar Dumnezeul părinţilor mei a fost cu mine.
Ó sì wí fún wọn pé, “Mo rí i wí pé ìwà baba yín sí mi ti yí padà sí ti tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Ọlọ́run baba mi wà pẹ̀lú mi.
6 Şi voi ştiţi că eu, cu toată puterea mea, am servit pe tatăl vostru.
Ẹ sá à mọ̀ pé, mo ti fi gbogbo agbára mi ṣiṣẹ́ fún baba yín,
7 Şi tatăl vostru m-a înşelat şi a schimbat plăţile mele de zece ori; dar Dumnezeu nu i-a permis să mă vatăme.
síbẹ̀síbẹ̀ baba yín ti rẹ́ mi jẹ ní ẹ̀ẹ̀mẹwàá ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni ó sì ti yí owó iṣẹ́ mi padà. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò jẹ́ kí ó le è pa mi lára.
8 Dacă el a spus astfel: Cele pestriţe vor fi plăţile tale; atunci toate vitele au născut pestriţe; şi dacă el a spus astfel: Cele vărgate vor fi plata ta; atunci toate vitele au născut vărgate.
Tí ó bá wí pé, ‘Àwọn ẹran onílà ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo àwọn ẹran ń bí onílà; bí ó bá sì wí pé, ‘Àwọn ẹran onítótòtó ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo ẹran ń bi onítótòtó.
9 Astfel Dumnezeu a luat vitele tatălui vostru şi mi le-a dat mie.
Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run gba ẹran baba yín, ó sì fi fún mi.
10 Şi s-a întâmplat în acel timp, când vitele zămisleau, că mi-am ridicat ochii şi am văzut într-un vis şi, iată, berbecii care săreau pe oi erau vărgaţi, pestriţi şi bălţaţi.
“Ní àsìkò tí àwọn ẹran ń gùn, mo la àlá mo sì ri pé àwọn òbúkọ tí wọ́n ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì.
11 Şi îngerul lui Dumnezeu mi-a vorbit într-un vis, spunând: Iacob; iar eu am spus: Iată-mă.
Angẹli Ọlọ́run wí fún mi nínú àlá náà pé, ‘Jakọbu.’ Mo sì wí pé, ‘Èmi nìyí.’
12 Şi a spus: Ridică-ţi acum ochii şi vezi, toţi berbecii care sar pe vite sunt vărgaţi, pestriţi şi bălţaţi, pentru că am văzut tot ceea ce Laban îţi face.
Ó sì wí pé, ‘Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wò ó, gbogbo àwọn òbúkọ tí ó ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì, nítorí mo ti rí gbogbo ohun ti Labani ń ṣe sí ọ.
13 Eu sunt Dumnezeul din Betel, unde ai uns stâlpul şi unde mi-ai făcut o promisiune; acum ridică-te, ieşi din această ţară şi întoarce-te în ţara rudelor tale.
Èmi ni Ọlọ́run Beteli, níbi tí ìwọ ti ta òróró sí ọ̀wọ́n, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti sìn mi. Nísinsin yìí, kúrò ní ilẹ̀ yìí kíákíá kí o sì padà sí ilẹ̀ ibi tí a gbé ti bí ọ.’”
14 Şi Rahela şi Leea au răspuns şi i-au zis: Este totuşi vreo parte sau moştenire pentru noi în casa tatălui nostru?
Nígbà náà ni Rakeli àti Lea dáhùn pé, “Ìpín wo ní a ní nínú ogún baba wa?
15 Nu suntem socotite de el ca străine? Căci ne-a vândut şi ne-a mâncat în întregime şi banii.
Àjèjì ha kọ́ ni ó kà wá sí? Kì í ṣe torí pé ó tà wá nìkan, ṣùgbọ́n ó ti ná gbogbo owó tí ó gbà lórí wa tán.
16 Pentru că toată bogăţia pe care Dumnezeu a luat-o de la tatăl nostru este a noastră şi a copiilor noştri, acum aşadar, fă orice ţi-a spus Dumnezeu.
Dájúdájú gbogbo ọrọ̀ ti Ọlọ́run gbà lọ́wọ́ baba wa fún ọ, tiwa àti ti àwọn ọmọ wa ní í ṣe. Nítorí náà ohun gbogbo tí Ọlọ́run bá pàṣẹ fun ọ láti ṣe ni kí ìwọ kí ó ṣe.”
17 Atunci Iacob s-a ridicat şi a aşezat pe fiii săi şi pe soţiile sale pe cămile;
Nígbà náà ni Jakọbu gbé àwọn ọmọ àti aya rẹ̀ gun ìbákasẹ.
18 Şi a dus toate vitele sale şi toate bunurile sale pe care le dobândise, vitele agoniselii sale, pe care le dobândise în Padanaram, pentru a merge la Isaac, tatăl său, în ţara lui Canaan.
Ó sì da gbogbo agbo ẹran rẹ̀ ṣáájú pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ tí ó ti kójọ ni Padani-Aramu, láti lọ sí ọ̀dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni ilẹ̀ Kenaani.
19 Şi Laban s-a dus să-şi tundă oile şi Rahela furase idolii care erau ai tatălui ei.
Nígbà tí Labani sì lọ láti rẹ́run àgùntàn, Rakeli sì jí àwọn ère òrìṣà ilé baba rẹ̀.
20 Şi Iacob s-a furişat pe neştiute de la Laban sirianul, în aceea că nu i-a spus că a fugit.
Síwájú sí i, Jakọbu tan Labani ará Aramu, nítorí kò sọ fún un wí pé òun ń sálọ.
21 Aşa că a fugit cu tot ce a avut; şi s-a ridicat şi a trecut dincolo de râu şi el şi-a îndreptat faţa spre muntele Galaad.
Ó sì sálọ pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ni, ó sì la odò kọjá (Eufurate), ó sì kọrí sí àwọn ilẹ̀ olókè ti Gileadi.
22 Şi în a treia zi i s-a spus lui Laban că Iacob fugise.
Ní ọjọ́ kẹta ni Labani gbọ́ pé Jakọbu ti sálọ.
23 Şi a luat pe fraţii săi cu el şi l-a urmărit şapte zile de călătorie; şi l-au ajuns în muntele Galaad.
Ó sì mú àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì lépa Jakọbu, ó sì lépa wọn fún ọjọ́ méje, ó sì bá wọn ní òkè Gileadi.
24 Şi Dumnezeu a venit la Laban sirianul într-un vis, noaptea, şi i-a spus: Ia seamă să nu vorbeşti lui Iacob nici bine nici rău.
Ọlọ́run sì yọ sí Labani ará Aramu lójú àlá ní òru, ó sì wí fun un pé, “Ṣọ́ra, má ṣe sọ ohunkóhun fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.”
25 Atunci Laban a ajuns pe Iacob. Şi Iacob şi-a ridicat cortul în munte şi Laban, cu fraţii săi, şi l-au ridicat în muntele Galaad.
Jakọbu ti pa àgọ́ rẹ̀ si orí òkè kan, nígbà tí Labani bá a. Labani àti àwọn tí ó wá pẹ̀lú rẹ̀ sì pàgọ́ tì wọ́n sí ilẹ̀ òkè Gileadi.
26 Şi Laban i-a spus lui Iacob: Ce ai făcut, că te-ai furişat pe neştiute de la mine şi ai dus pe fiicele mele ca pe captivi luaţi cu sabia?
Nígbà náà ni Labani wí fún Jakọbu pé, “Èwo ni ìwọ ṣe yìí? Tí ìwọ sì tàn mi, ó sì kó àwọn ọmọbìnrin mi bi ìgbèkùn tí a fi idà mú.
27 Pentru ce ai fugit în secret şi te-ai furişat de la mine; şi nu mi-ai spus, ca să te fi trimis cu bucurie şi cu cântece, cu tamburină şi cu harpă?
Èéṣe tí ìwọ yọ́ lọ tí ìwọ sì tàn mi? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé ìwọ ń lọ, kí èmi fi ayọ̀ àti orin, pẹ̀lú ìlù àti ohun èlò orin sìn ọ́.
28 Şi nu m-ai lăsat să sărut pe fiii mei şi pe fiicele mele? Acum ai lucrat prosteşte făcând astfel.
Ìwọ kò tilẹ̀ jẹ́ kí èmi fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ mi lẹ́nu, pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin mi pé ó dìgbà? Ìwọ ṣiwèrè ní ohun tí ìwọ ṣe yìí.
29 Este în puterea mâinii mele să îţi fac rău, dar Dumnezeul tatălui tău mi-a vorbit azi-noapte, spunând: Ia seamă să nu vorbeşti lui Iacob nici bine nici rău.
Mo ní agbára láti ṣe ọ ni ibi, ṣùgbọ́n ní òru àná, Ọlọ́run baba rẹ sọ fún mi pé, kí èmi ṣọ́ra, kí èmi má ṣe sọ ohun kan fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.
30 Şi acum, deşi ai dori să fii plecat, pentru că tânjeşti aprins după casa tatălui tău, totuşi pentru ce ai furat dumnezeii mei?
Nísinsin yìí, ìwọ ti lọ nítorí ìwọ fẹ́ láti padà lọ sí ilé baba rẹ, ṣùgbọ́n èéṣe tí ìwọ fi jí àwọn òrìṣà mi?”
31 Şi Iacob a răspuns şi a spus lui Laban: Pentru că m-am temut, căci spuneam: S-ar putea să iei cu forţa pe fiicele tale de la mine.
Jakọbu dá Labani lóhùn pé, “Ẹ̀rù ni ó bà mi nítorí, mo rò pé ìwọ le fi tipátipá gba àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ́wọ́ mi.
32 La oricine găseşti dumnezeii tăi, nu îl lăsa să trăiască, înaintea fraţilor noştri să recunoşti ce este al tău la mine şi ia aceasta la tine. Pentru că Iacob nu ştia că Rahela i-a furat.
Ṣùgbọ́n bí o bá ri ẹnikẹ́ni pẹ̀lú ère rẹ, kí ẹni náà di òkú. Ó tún wí pé, níwájú gbogbo ìbátan wa báyìí, wò ó fúnra rẹ̀, bí o bá rí ohunkóhun tí í ṣe tìrẹ, mú un.” Jakọbu kò sì mọ̀ pé, Rakeli ni ó jí àwọn òrìṣà náà.
33 Şi Laban a intrat în cortul lui Iacob şi în cortul Leei şi în corturile celor două servitoare, dar nu i-a găsit. Atunci a ieşit din cortul Leei şi a intrat în cortul Rahelei.
Labani sì lọ sínú àgọ́ Jakọbu àti ti Lea àti ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì, kò sì rí ohunkóhun. Lẹ́yìn ìgbà tí ó jáde nínú àgọ́ Lea ni ó lọ sí àgọ́ Rakeli.
34 Acum Rahela luase idolii şi îi pusese în şeaua cămilei şi stătea peste ei. Şi Laban a căutat în tot cortul, dar nu i-a găsit.
Rakeli sì gbé àwọn òrìṣà náà sínú gàárì ìbákasẹ, ó sì jókòó lé e lórí. Labani sì wá gbogbo inú àgọ́, kò sì rí ohunkóhun.
35 Şi ea a spus tatălui ei: Să nu fie cu supărare domnului meu că nu pot să mă ridic înaintea ta; căci rânduiala femeilor este asupra mea. Iar el a căutat, dar nu a găsit idolii.
Rakeli sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Má ṣe bínú pé èmi ò le dìde dúró níwájú rẹ baba à mi, ohun tí ó fà á ni pé, mò ń ṣe nǹkan oṣù lọ́wọ́.” Ó sì wá àgọ́ kiri, kò sì rí àwọn òrìṣà ìdílé náà.
36 Şi Iacob s-a înfuriat şi s-a certat cu Laban; şi Iacob a răspuns şi i-a zis lui Laban: Care îmi este fărădelegea? Care îmi este păcatul, că aşa aprins m-ai urmărit?
Inú sì bí Jakọbu, ó sì pe Labani ní ìjà pé, “Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ tí ìwọ fi ń lépa mi bí ọ̀daràn?
37 Cu toate că ai căutat în toate lucrurile mele, ce ai găsit din toate lucrurile casei tale? Pune-le aici înaintea fraţilor mei şi a fraţilor tăi, ca ei să judece între noi doi.
Nísinsin yìí tí ìwọ ti tú gbogbo ẹrù mi wò, kí ni ohun tí í ṣe tirẹ̀ tí ìwọ rí? Kó wọn kalẹ̀ báyìí níwájú gbogbo ìbátan rẹ àti tèmi, kí wọn kí ó sì ṣe ìdájọ́ láàrín àwa méjèèjì.
38 Aceşti douăzeci de ani am fost cu tine; oile tale şi caprele tale nu au lepădat puii lor şi berbecii turmei tale nu i-am mâncat.
“Mo ti wà lọ́dọ̀ rẹ fún ogún ọdún, àwọn àgùntàn tàbí ewúrẹ́ rẹ kò sọnù bẹ́ẹ̀ n kò pa ọ̀kan jẹ rí nínú àwọn àgbò rẹ.
39 Ce a fost sfâşiat de fiare nu am adus la tine; eu am purtat pierderea aceea; din mâna mea ai cerut-o, fie că a fost furată ziua sau furată noaptea.
Èmi kò mú ọ̀kankan wá fún ọ rí nínú èyí tí ẹranko búburú fàya, èmi ni ó fi ara mọ́ irú àdánù bẹ́ẹ̀. Ẹrankẹ́ran tí wọ́n bá sì jí lọ, lọ́sàn án tàbí lóru, ìwọ ń gba owó rẹ̀ lọ́wọ́ mi.
40 Astfel am fost; în timpul zilei seceta mă mistuia şi bruma în timpul nopţii; şi somnul mi s-a depărtat de la ochii mei.
Báyìí ni mo wà; oòrùn ń pa mi lọ́sàn án, òtútù ń pa mi lóru, mo sì ń ṣe àìsùn.
41 Astfel am fost eu douăzeci de ani în casa ta; ţi-am servit paisprezece ani pentru cele două fiice ale tale şi şase ani pentru vitele tale; şi ai schimbat plăţile mele de zece ori.
Báyìí ni ohun gbogbo rí fún ogún ọdún tí mo fi wà nínú ilé rẹ. Ọdún mẹ́rìnlá ni mo fi sìn ọ́ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì, mo sì sìn ọ fún ọdún mẹ́fà fún àwọn ẹran ọ̀sìn, lẹ́ẹ̀mẹ́wàá ni o sì yí owó iṣẹ́ mi padà.
42 Dacă Dumnezeul tatălui meu, Dumnezeul lui Avraam şi teama lui Isaac, nu ar fi fost cu mine, cu adevărat m-ai fi trimis acum gol. Dumnezeu a văzut necazul meu şi munca mâinilor mele şi te-a mustrat aseară.
Bí ó bá ṣe pé Ọlọ́run àwọn baba mi, Ọlọ́run Abrahamu àti ẹ̀rù Isaaki kò wà pẹ̀lú mi ni, ìwọ ìbá ti lé mi jáde lọ́wọ́ òfo. Ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ti rí gbogbo ìpọ́njú mi àti iṣẹ́ àṣekára tí mo fi ọwọ́ mi ṣe, ó sì kìlọ̀ fún ọ lóru àná.”
43 Şi Laban a răspuns şi i-a zis lui Iacob: Aceste fiice sunt fiicele mele şi aceşti copii sunt copiii mei şi aceste vite sunt vitele mele şi tot ceea ce vezi este al meu şi ce pot face în această zi acestor fiice ale mele, sau copiilor lor pe care i-au născut?
Labani sì dá Jakọbu lóhùn, “Tèmi ni àwọn obìnrin wọ̀nyí, ọmọ mi ni àwọn ọmọ wọ̀nyí pẹ̀lú, àwọn agbo ẹran yìí, tèmi ni wọ́n pẹ̀lú. Gbogbo ohun tí o rí wọ̀nyí, tèmi ni. Kí ni mo wá le ṣe sí àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí àti àwọn ọmọ wọn tí wọn bí?
44 De aceea vino acum, să facem un legământ, eu şi tu; şi să fie acesta pentru o mărturie între mine şi tine.
Wá, jẹ́ kí a dá májẹ̀mú pẹ̀lú ara wa, èyí yóò sì jẹ́ ẹ̀rí ní àárín wa.”
45 Şi Iacob a luat o piatră şi a aşezat-o drept stâlp.
Jakọbu sì mú òkúta kan ó sì gbé e dúró bí ọ̀wọ́n.
46 Şi Iacob le-a spus fraţilor săi: Adunaţi pietre; şi au luat pietre şi au făcut o movilă şi au mâncat acolo pe movilă.
Ó sì wí fún àwọn ìbátan rẹ̀ pé, “Ẹ kó àwọn òkúta díẹ̀ jọ.” Wọ́n sì kó òkúta náà jọ bí òkìtì wọ́n sì jẹun níbẹ̀.
47 Şi Laban a numit-o Iegarsahaduta, dar Iacob a numit-o Galed.
Labani sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jegari-Sahaduta, ṣùgbọ́n Jakọbu pè é ni Galeedi.
48 Şi Laban a spus: Această movilă este o mărturie între mine şi tine în această zi. De aceea a fost pus numele acesteia, Galed;
Labani sì wí pé, “Òkìtì yìí jẹ́ ẹ̀rí láàrín èmi àti ìwọ ní òní.” Ìdí nìyí tí a fi pe orúkọ rẹ̀ ni Galeedi.
49 Şi Miţpa, căci el a spus: DOMNUL să vegheze între mine şi tine, în timp ce suntem absenţi unul faţă de celalalt.
Ó tún pè é ni Mispa nítorí, ó wí pé, “Kí Olúwa kí ó máa ṣọ́ èmi àti ìwọ nígbà tí a bá yà kúrò lọ́dọ̀ ara wa tán.
50 Dacă vei chinui pe fiicele mele, sau dacă vei lua alte soţii pe lângă fiicele mele, niciun bărbat nu este cu noi; vezi, Dumnezeu este martor între mine şi tine.
Bí o bá fìyà jẹ àwọn ọmọbìnrin mi, tàbí tí o fẹ́ aya mìíràn yàtọ̀ sí wọn, rántí pé, Ọlọ́run ń bẹ láàrín wa bí ẹlẹ́rìí bí ẹnikẹ́ni kò tilẹ̀ sí.”
51 Şi Laban i-a spus lui Iacob: Iată, această movilă şi, iată, acest stâlp, pe care l-am aruncat între mine şi tine;
Labani tún sọ síwájú fún Jakọbu pé, “Òkìtì àti ọ̀wọ̀n tí mo gbé kalẹ̀ láàrín èmi àti ìwọ yìí,
52 Această movilă fie mărturie şi acest stâlp fie mărturie, că nu voi trece peste această movilă la tine şi că nu vei trece peste această movilă şi peste acest stâlp la mine, pentru a face rău.
yóò jẹ́ ẹ̀rí wí pé èmi kò ni ré ọ̀wọ̀n àti òkìtì yìí kọjá láti bá ọ jà àti pé ìwọ pẹ̀lú kì yóò kọjá òkìtì tàbí ọ̀wọ̀n yìí láti ṣe mí ní ibi.
53 Dumnezeul lui Avraam şi Dumnezeul lui Nahor, Dumnezeul Tatălui lor, să judece între noi. Şi Iacob a jurat pe teama tatălui său Isaac.
Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run Abrahamu àti Ọlọ́run Nahori, àti Ọlọ́run baba wọn ṣe ìdájọ́ láàrín wa.” Jakọbu sì fi ẹ̀rù Isaaki baba rẹ̀ búra.
54 Atunci Iacob a oferit sacrificii pe munte şi a chemat pe fraţii săi să mănânce pâine şi au mâncat pâine şi au rămas toată noaptea pe munte.
Jakọbu sì rú ẹbọ níbẹ̀ ni orí òkè, ó sì pe àwọn ẹbí rẹ̀ láti jẹun. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹun, ibẹ̀ náà ni wọ́n sùn ní ọjọ́ náà.
55 Şi devreme dimineaţa Laban s-a ridicat şi a sărutat pe fiii săi şi pe fiicele sale şi i-a binecuvântat; şi Laban a plecat şi s-a întors la locul său.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Labani fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ lẹ́nu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì súre fún wọn. Labani sì padà lọ sí ilé.

< Geneză 31 >