< Geneză 21 >

1 Şi DOMNUL a vizitat-o pe Sara aşa cum a spus; şi DOMNUL a făcut Sarei aşa cum el a vorbit.
Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
2 Căci Sara a rămas însărcinată şi a născut un fiu lui Avraam la bătrâneţile lui, la timpul cuvenit despre care Dumnezeu îi vorbise.
Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
3 Şi Avraam i-a pus fiului său, care i-a fost născut, pe care Sara i l-a născut, numele Isaac.
Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
4 Şi Avraam a circumcis pe fiul său Isaac când pruncul avea opt zile, aşa cum Dumnezeu i-a poruncit.
Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
5 Şi Avraam era în vârstă de o sută de ani când i s-a născut fiul său Isaac.
Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
6 Şi Sara a spus: Dumnezeu m-a făcut să râd, aşa că toţi cei ce vor auzi vor râde împreună cu mine.
Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
7 Şi ea a spus: Cine ar fi spus lui Avraam, că Sara ar alăpta copii? Pentru că i-am născut un fiu la bătrâneţile sale.
Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
8 Şi copilul a crescut şi a fost înţărcat şi Avraam a făcut un mare ospăţ în ziua în care Isaac a fost înţărcat.
Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
9 Şi Sara a văzut pe fiul lui Hagar, egipteanca, pe care aceasta îl născuse lui Avraam, batjocorind.
Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
10 De aceea i-a spus lui Avraam: Alungă pe această roabă şi pe fiul ei, pentru că fiul acestei roabe nu va fi moştenitor împreună cu fiul meu, cu Isaac.
ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
11 Şi lucrul a fost foarte dureros înaintea ochilor lui Avraam, din cauza fiului său.
Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
12 Şi Dumnezeu i-a spus lui Avraam: Să nu fie acest lucru dureros înaintea ochilor tăi din cauza băiatului şi din cauza roabei tale; în tot ce Sara ţi-a spus, dă ascultare vocii ei, pentru că în Isaac se va chema sămânţa ta.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
13 Şi de asemenea din fiul roabei voi face o naţiune, pentru că el este sămânţa ta.
Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
14 Şi Avraam s-a sculat devreme dimineaţa şi a luat pâine şi un burduf de apă şi copilul şi l-a dat lui Hagar, punându-l pe umărul ei; şi a trimis-o şi ea a plecat şi a rătăcit în pustia Beer-Şeba.
Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
15 Şi apa s-a terminat din burduf şi ea a lepădat copilul sub unul dintre tufişuri.
Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
16 Şi a mers şi s-a aşezat jos înaintea lui la depărtare de el, cam cât ar trage un arcaş, pentru că spunea: Să nu văd moartea copilului. Şi s-a aşezat înaintea lui şi şi-a înălţat vocea şi a plâns.
Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
17 Şi Dumnezeu a auzit vocea băiatului; şi îngerul lui Dumnezeu a chemat pe Hagar din cer şi i-a spus: Ce îţi este, Hagar? Nu te teme, pentru că Dumnezeu a auzit vocea băiatului acolo unde este el.
Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
18 Scoală-te, ridică băiatul şi ţine-l în mână, pentru că îl voi face o mare naţiune.
Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
19 Şi Dumnezeu i-a deschis ochii şi ea a văzut o fântână de apă; şi s-a dus şi a umplut burduful cu apă şi a dat băiatului să bea.
Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
20 Şi Dumnezeu a fost cu băiatul; şi a crescut şi a locuit în pustie şi a devenit arcaş.
Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
21 Şi a locuit în pustia Paran şi mama lui i-a luat o soţie din ţara Egiptului.
Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
22 Şi s-a întâmplat în acel timp, că Abimelec şi Picol, căpetenia oştirii sale, i-au vorbit lui Avraam, spunând: Dumnezeu este cu tine în tot ceea ce faci;
Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
23 De aceea acum jură-mi aici pe Dumnezeu că nu mă vei înșela nici pe mine, nici pe fiul meu, nici pe fiul fiului meu, ci conform bunătăţii pe care ţi-am făcut-o, îmi vei face şi tu mie şi ţării în care ai locuit temporar.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
24 Şi Avraam a spus: Jur.
Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
25 Şi Avraam a mustrat pe Abimelec din cauza unei fântâni de apă, pe care servitorii lui Abimelec au luat-o cu violenţă.
Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
26 Şi Abimelec a spus: Nu am ştiut cine a făcut acest lucru, nici tu nu mi-ai spus, nici nu am auzit de aceasta, decât astăzi.
Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
27 Şi Avraam a luat oi şi boi şi le-a dat lui Abimelec; şi amândoi au făcut un legământ.
Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
28 Şi Avraam a pus şapte mieluşele din turmă la o parte.
Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
29 Şi Abimelec i-a spus lui Avraam: Ce înseamnă aceste şapte mieluşele pe care le-ai pus la o parte?
Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
30 Iar el a spus: Aceste şapte mieluşele le vei lua din mâna mea, ca ele să fie o mărturie pentru mine, că am săpat această fântână.
Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
31 Pentru aceasta el a numit acel loc Beer-Şeba, pentru că acolo au jurat amândoi.
Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
32 Astfel au făcut un legământ la Beer-Şeba, apoi Abimelec s-a ridicat şi Picol, căpetenia oştirii sale, şi s-au întors în ţara filistenilor.
Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
33 Şi Avraam a sădit un crâng în Beer-Şeba şi a chemat acolo numele DOMNULUI, Dumnezeul cel veşnic.
Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
34 Şi Avraam a locuit temporar în ţara filistenilor multe zile.
Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.

< Geneză 21 >