< Geneză 19 >

1 Şi pe seară, doi îngeri au venit la Sodoma; şi Lot şedea în poarta Sodomei; şi Lot, văzându-i, s-a ridicat să îi întâmpine şi s-a aplecat cu faţa sa la pământ;
Ní àṣálẹ́, àwọn angẹli méjì sì wá sí ìlú Sodomu, Lọti sì jókòó ní ẹnu ibodè ìlú. Bí ó sì ti rí wọn, ó sì dìde láti pàdé wọn, ó kí wọn, ó sì foríbalẹ̀ fún wọn.
2 Şi a spus: Iată acum, domnii mei, abateţi-vă, vă rog, în casa servitorului vostru şi rămâneţi toată noaptea şi spălaţi-vă picioarele şi vă veţi trezi devreme să mergeţi pe căile voastre. Iar ei au spus: Nu, ci vom sta în stradă toată noaptea.
Ó wí pé, “Ẹ̀yin olúwa mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ yà sí ilé ìránṣẹ́ yín kí ẹ sì wẹ ẹsẹ̀ yín, kí n sì gbà yín lálejò, ẹ̀yin ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ láti máa bá ìrìnàjò yín lọ.” Wọ́n sì wí pé, “Rárá o, àwa yóò dúró ní ìgboro ní òru òní.”
3 Dar el a insistat pe lângă ei foarte mult şi s-au abătut la el şi au intrat în casa lui şi a făcut pentru ei un ospăţ şi a copt azimă şi au mâncat.
Ṣùgbọ́n Lọti rọ̀ wọ́n gidigidi tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n gbà láti bá a lọ sì ilé. Ó sì ṣe àsè fún wọn, ó sì dín àkàrà aláìwú fún wọ́n, wọ́n sì jẹ.
4 Dar înainte să se culce, bărbaţii cetăţii, bărbaţii din Sodoma, au încercuit casa, deopotrivă bătrâni şi tineri, tot poporul din fiecare parte a cetăţii;
Ṣùgbọ́n kí ó tó di pé wọ́n lọ sùn, àwọn ọkùnrin ìlú Sodomu tọmọdé tàgbà yí ilé náà ká.
5 Şi au chemat pe Lot şi i-au spus: Unde sunt bărbaţii care au venit la tine în această noapte? Scoate-i afară la noi să îi cunoaştem.
Wọ́n pe Lọti pé, “Àwọn ọkùnrin tí ó wọ̀ sí ilé rẹ lálẹ́ yìí ń kọ́? Mú wọn jáde fún wa, kí a le ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú wọn.”
6 Şi Lot a ieşit la uşă la ei şi a închis uşa după el.
Lọti sì jáde láti pàdé wọn, ó sì ti ìlẹ̀kùn lẹ́yìn rẹ̀ bí ó ti jáde.
7 Şi a spus: Vă rog, fraţilor, nu faceţi o astfel de stricăciune.
Ó sì wí pé, “Rárá, ẹ̀yin ará mi, ẹ má ṣe ṣe ohun búburú yìí,
8 Iată acum, am două fete care nu au cunoscut bărbat; lăsaţi-mă, vă rog, să le scot la voi şi faceţi-le precum este bine în ochii voştri, numai acestor bărbaţi nu le faceţi nimic, căci pentru aceasta au venit sub umbra acoperişului meu.
kíyèsi i, mo ní ọmọbìnrin méjì tí kò mọ ọkùnrin rí, ẹ jẹ́ kí n mú wọn tọ̀ yín wá kí ẹ sì ṣe ohun tí ẹ fẹ́ pẹ̀lú wọn. Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣe àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ní ibi kan nítorí wọ́n wá wọ̀ lábẹ́ ààbò ní ilé mi.”
9 Dar ei au spus: Dă-te înapoi. Şi au spus din nou: Acesta a venit să locuiască temporar şi voieşte să fie judecător, acum ne vom purta mai rău cu tine decât cu ei. Şi împingeau cu putere asupra bărbatului, adică Lot, şi s-au apropiat să spargă uşa.
Wọ́n sì wí fún pé, “Bì sẹ́yìn fún wa. Èyí yìí wá ṣe àtìpó láàrín wa, òun sì fẹ́ ṣe onídàájọ́! Aburú tí a ó fi ṣe ọ́ yóò pọ̀ ju tí wọn lọ.” Wọn rọ́ lu Lọti, wọ́n sì súnmọ́ ọn láti fọ́ ìlẹ̀kùn.
10 Dar bărbaţii şi-au întins mâna şi l-au tras pe Lot în casă la ei şi au închis uşa.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà nawọ́ fa Lọti wọlé, wọ́n sì ti ìlẹ̀kùn.
11 Şi au lovit pe bărbaţii care erau la uşa casei cu orbire, deopotrivă pe mici şi mari, astfel că se osteneau să găsească uşa.
Wọ́n sì bu ìfọ́jú lu àwọn ọkùnrin tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà ilé náà, àti èwe àti àgbà: wọ́n kò sì rí ẹnu-ọ̀nà mọ́.
12 Şi bărbaţii i-au spus lui Lot: Mai ai pe cineva aici? Ginere şi fiii tăi şi fiicele tale şi pe oricine ai în cetate, scoate-i din acest loc,
Àwọn ọkùnrin náà sì wí fún Lọti pé, “Ǹjẹ́ ó ní ẹlòmíràn ní ìlú yìí bí? Àna rẹ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ lọ́kùnrin àti lóbìnrin, tàbí ẹnikẹ́ni tí ìwọ ní ní ìlú yìí, kó wọn jáde kúrò ní ibí yìí,
13 Pentru că vom distruge acest loc, deoarece strigătul lor a crescut mult înaintea feţei DOMNULUI şi DOMNUL ne-a trimis să îl distrugem.
nítorí a ó pa ìlú yìí run, nítorí igbe iṣẹ́ búburú wọn ń dí púpọ̀ níwájú Olúwa, Olúwa sì rán wa láti pa á run.”
14 Şi Lot a ieşit şi a vorbit ginerilor săi, care erau căsătoriţi cu fiicele lui, şi a spus: Ridicaţi-vă, ieşiţi din acest loc, pentru că DOMNUL va distruge această cetate. Dar el părea înaintea ginerilor săi ca unul care batjocorea.
Nígbà náà ni Lọti jáde, ó sì wí fún àwọn àna rẹ̀ ọkùnrin tí ó ti bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fẹ́ àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ ṣe kánkán, kí ẹ jáde ní ìlú yìí, nítorí Olúwa fẹ́ pa ìlú yìí run!” Ṣùgbọ́n àwọn ọkọ ọmọ rẹ̀ wọ̀nyí rò pé àwàdà ló ń ṣe.
15 Şi când s-a făcut dimineaţa, atunci îngerii au grăbit pe Lot, spunând: Ridică-te, ia pe soţia ta şi pe cele două fiice ale tale, care sunt aici, ca să nu fii mistuit în nelegiuirea cetăţii.
Ní àfẹ̀mọ́júmọ́, àwọn angẹli náà rọ Lọti pé, “Ṣe wéré, mú aya rẹ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì tí ó wà níhìn-ín, àìṣe bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò parun pẹ̀lú ìlú yìí nígbà tí wọ́n bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
16 Şi în timp ce el întârzia, bărbaţii au apucat mâna lui şi mâna soţiei lui şi mâna celor două fiice ale lui, DOMNUL fiind milostiv cu el, şi l-au scos şi l-au aşezat în afara cetăţii.
Nígbà tí ó ń jáfara, àwọn ọkùnrin náà nawọ́ mú un lọ́wọ́, wọ́n sì nawọ́ mú aya rẹ̀ náà lọ́wọ́ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ méjèèjì, wọ́n sì mú wọn jáde sẹ́yìn odi ìlú, nítorí Olúwa ṣàánú fún wọn.
17 Şi s-a întâmplat, după ce i-au scos afară, că a spus: Scapă-ţi viaţa; nu privi înapoia ta, nici nu sta în câmpie deschisă, scapă la munte ca nu cumva să fii mistuit.
Ní kété tí wọ́n mú wọn jáde sẹ́yìn odi tán, ọ̀kan nínú wọn wí pé, “Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe wo ẹ̀yìn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó má ṣe dúró ní gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀! Sá àsálà lọ sí orí òkè, kí ìwọ ó má ba ṣègbé!”
18 Şi Lot le-a spus: Nu! Te rog, Domnul meu;
Ṣùgbọ́n Lọti wí fún wọn pé, “Rárá, ẹ̀yin Olúwa mi, ẹ jọ̀wọ́!
19 Iată acum, servitorul tău a găsit har înaintea ochilor tăi şi ai preamărit mila ta, pe care mi-ai arătat-o salvându-mi viaţa; şi nu pot să scap la munte, ca nu cumva ceva rău să mă prindă şi să mor;
Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ ti rí ojúrere rẹ, tí o sì ti fi àánú rẹ hàn nípa gbígba ẹ̀mí mi là, èmi kò le è sálọ sórí òkè, kí búburú yìí má ba à lé mi bá, kí n sì kú.
20 Iată acum, această cetate este aproape, să scap la ea şi aceasta este una mică: Te rog, lasă-mă să scap într-acolo, (nu este aceasta una mică?) şi sufletul meu va trăi.
Wò ó, ìlú kékeré kan nìyí ní tòsí láti sá sí: jẹ́ kí n sálọ síbẹ̀, ìlú kékeré ha kọ́? Ẹ̀mí mi yóò sì yè.”
21 Iar el i-a spus: Vezi, te-am acceptat şi în acest lucru, că nu voi dărâma această cetate, pentru care ai vorbit.
Ó sì wí fún un pé, “Ó dára, mo gba ẹ̀bẹ̀ rẹ. Èmi kì yóò run ìlú náà tí ìwọ sọ̀rọ̀ rẹ̀.
22 Grăbeşte-te, scapă într-acolo, pentru că nu pot face nimic până ce vei fi ajuns acolo. De aceea s-a pus numele cetăţii, Ţoar.
Tètè! Sálọ síbẹ̀, nítorí èmi kò le ṣe ohun kan àyàfi tí ó bá dé ibẹ̀.” (ìdí nìyí tí a fi ń pe ìlú náà ní Soari).
23 Soarele se ridica deasupra pământului când Lot a intrat în Ţoar.
Nígbà tí Lọti yóò fi dé ìlú Soari, oòrùn ti yọ.
24 Atunci DOMNUL a plouat peste Sodoma şi peste Gomora pucioasă şi foc de la DOMNUL din cer;
Nígbà náà ni Olúwa rọ̀jò iná àti sulfuru sórí Sodomu àti Gomorra láti ọ̀run lọ́dọ̀ Olúwa wá.
25 Şi a dărâmat acele cetăţi şi toată câmpia şi pe toţi locuitorii cetăţilor şi ceea ce creştea pe pământ.
Báyìí ni ó run àwọn ìlú náà àti gbogbo ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó wà ní ìlú ńlá ńlá wọ̀n-ọn-nì àti ohun gbogbo tí ó hù jáde nílẹ̀.
26 Dar soţia lui a privit înapoi din spatele lui şi a devenit un stâlp de sare.
Ṣùgbọ́n aya Lọti bojú wo ẹ̀yìn, ó sì di ọ̀wọ́n iyọ̀.
27 Şi Avraam s-a sculat devreme dimineaţa şi a mers spre locul unde a stat în picioare înaintea DOMNULUI;
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Abrahamu sì dìde ó sì padà lọ sí ibi tí ó gbé dúró níwájú Olúwa.
28 Şi a privit spre Sodoma şi Gomora şi spre tot ţinutul câmpiei; şi a privit şi, iată, fumul ţinutului se ridica precum fumul unui cuptor.
Ó sì wo ìhà Sodomu àti Gomorra àti àwọn ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, ó sì rí èéfín tí ń ti ibẹ̀ jáde bí èéfín iná ìléru.
29 Şi s-a întâmplat, când Dumnezeu a distrus cetăţile câmpiei, că Dumnezeu şi-a amintit de Avraam şi a trimis pe Lot afară din mijlocul dărâmării, când el a dărâmat cetăţile în care Lot a locuit.
Ọlọ́run sì rántí Abrahamu, nígbà tí ó run ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì tan, ó sì mú Lọti jáde kúrò láàrín ìparun náà, tí ó kọlu ìlú tí Lọti ti gbé.
30 Şi Lot s-a urcat din Ţoar şi a locuit în munte şi cele două fiice ale lui cu el, pentru că s-a temut să locuiască în Ţoar şi a locuit într-o peşteră, el şi cele două fiice ale lui.
Lọti àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin méjèèjì sì kúrò ní Soari, wọ́n sì ń lọ gbé ní orí òkè ní inú ihò àpáta, nítorí ó bẹ̀rù láti gbé ní ìlú Soari.
31 Şi cea întâi născută i-a spus celei mai tinere: Tatăl nostru este bătrân şi nu este un bărbat pe pământ să intre la noi, după obiceiul întregului pământ;
Ní ọjọ́ kan, èyí ẹ̀gbọ́n sọ fún àbúrò rẹ̀ pé, “Baba wa ti dàgbà, kò sì sí ọkùnrin kankan ní agbègbè yìí tí ìbá bá wa lòpọ̀, bí ìṣe gbogbo ayé.
32 Vino, să facem pe tatăl nostru să bea vin şi ne vom culca cu el, ca să păstrăm o sămânţă a tatălui nostru.
Wá, jẹ́ kí a mú baba wa mu ọtí yó, kí ó ba à le bá wa lòpọ̀, kí àwa kí ó lè bí ọmọ, kí ìran wa má ba à parẹ́.”
33 Şi ele au făcut pe tatăl lor să bea vin în acea noapte şi cea întâi născută a intrat şi s-a culcat cu tatăl ei; şi el nu şi-a dat seama când s-a culcat ea, nici când s-a ridicat.
Ní òru ọjọ́ náà, wọ́n rọ baba wọn ní ọtí yó. Èyí ẹ̀gbọ́n sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a lòpọ̀, baba wọn kò mọ̀ ìgbà tí ó sùn ti òun àti ìgbà tí ó dìde.
34 Şi s-a întâmplat a doua zi, că cea întâi născută i-a spus celei mai tinere: Iată, m-am culcat noaptea trecută cu tatăl meu; hai să îl facem să bea vin şi în această noapte şi intră şi culcă-te cu el, ca să păstrăm o sămânţă a tatălui nostru.
Ní ọjọ́ kejì èyí ẹ̀gbọ́n wí fún àbúrò rẹ̀ pé, “Ní àná mo sùn ti baba mi. Jẹ́ kí a tún wọlé tọ̀ ọ́, kí a lè ní irú-ọmọ láti ọ̀dọ̀ baba wa.”
35 Şi ele au făcut pe tatăl lor să bea vin şi în acea noapte; şi cea tânără s-a ridicat şi s-a culcat cu el; şi el nu şi-a dat seama când ea s-a culcat, nici când s-a ridicat.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún fún baba wọn ní ọtí mu yó ni alẹ́ ọjọ́ náà, èyí àbúrò náà sì wọlé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, kò sì tún mọ ìgbà tí ó wọlé sùn ti òun tàbí ìgbà tí ó dìde.
36 Astfel au fost amândouă fiicele lui Lot însărcinate prin tatăl lor.
Àwọn ọmọbìnrin Lọti méjèèjì sì lóyún fún baba wọn.
37 Şi cea întâi născută a născut un fiu şi i-a pus numele Moab; el este tatăl moabiţilor până în această zi.
Èyí ẹ̀gbọ́n sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Moabu. Òun ni baba ńlá àwọn ará Moabu lónìí.
38 Şi cea mai tânără de asemenea a născut un fiu şi i-a pus numele Ben-ami; el este tatăl copiilor lui Amon până în această zi.
Èyí àbúrò náà sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Bene-Ami. Òun ni baba ńlá àwọn ará Ammoni lónìí.

< Geneză 19 >