< Galateni 4 >

1 Dar spun: Cât timp moștenitorul este copil, nu diferă cu nimic de rob, măcar că este domn al tuturor,
Ǹjẹ́ ohun tí mo ń wí ni pé, níwọ̀n ìgbà tí àrólé náà bá wà ní èwe, kò yàtọ̀ nínú ohunkóhun sí ẹrú bí ó tilẹ̀ jẹ́ Olúwa ohun gbogbo.
2 Ci este sub tutori și administratori, până la timpul stabilit de tată.
Ṣùgbọ́n ó wà lábẹ́ olùtọ́jú àti ìríjú títí àkókò tí baba ti yàn tẹ́lẹ̀.
3 Așa și noi, când eram copii, eram în robie sub principiile elementare ale lumii.
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni àwa, nígbà tí àwa wà ní èwe, àwa wà nínú ìdè lábẹ́ ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé.
4 Dar când a venit plinătatea timpului, Dumnezeu a trimis pe Fiul său, venit din femeie, venit sub lege,
Ṣùgbọ́n nígbà tí àkókò kíkún náà dé, Ọlọ́run rán ọmọ rẹ̀ jáde wá, ẹni tí a bí nínú obìnrin tí a bí lábẹ́ òfin.
5 Să răscumpere pe cei ce erau sub lege, ca să primim adopția fiilor.
Láti ra àwọn tí ń bẹ lábẹ́ òfin padà, kí àwa lè gba ìsọdọmọ.
6 Și pentru că sunteți fii, Dumnezeu a trimis Duhul Fiului său în inimile voastre, care strigă: Abba, Tată!
Àti nítorí tí ẹ̀yin jẹ́ ọmọ, Ọlọ́run sì ti rán Ẹ̀mí Ọmọ rẹ̀ wá sínú ọkàn yín, tí ń ké pé, “Ábbà, Baba.”
7 De aceea nu mai ești rob, ci fiu; iar dacă ești fiu, ești și moștenitor al lui Dumnezeu prin Cristos.
Nítorí náà ìwọ kì í ṣe ẹrú, bí kò ṣe ọmọ; àti bí ìwọ bá ń ṣe ọmọ, ǹjẹ́ ìwọ di àrólé Ọlọ́run nípasẹ̀ Kristi.
8 Atunci însă, când nu cunoșteați pe Dumnezeu, ați servit celor ce prin natură nu sunt dumnezei.
Tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀, nígbà tí ẹ̀yin kò tí i mọ Ọlọ́run, ẹ̀yin ti ṣe ẹrú fún àwọn tí kì í ṣe Ọlọ́run nípa ìṣẹ̀dá.
9 Dar acum, după ce ați cunoscut pe Dumnezeu, sau mai degrabă, fiind cunoscuți de Dumnezeu, cum vă întoarceți din nou la slabele și sărăcăcioasele principii elementare, cărora doriți din nou să le fiți robi în robie?
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà tí ẹ̀yin ti mọ Ọlọ́run tan tàbí kí a sá kúkú wí pé ẹ di mímọ́ fún Ọlọ́run, èéha ti rí tí ẹ tún fi yípadà sí aláìlera àti agbára ìpilẹ̀ṣẹ̀ ẹ̀dá, lábẹ́ èyí tí ẹ̀yin tún fẹ́ padà wá ṣe ẹrú?
10 Voi țineți zile și luni și timpuri și ani.
Ẹ̀yin ń kíyèsi ọjọ́ àti àkókò, àti ọdún.
11 Mă tem pentru voi, ca nu cumva să fi muncit în zadar pentru voi.
Ẹ̀rù yin ń bà mí, kí o má bà ṣe pé lásán ni mo ṣe làálàá lórí yín.
12 Fraților, vă implor, fiți ca mine, pentru că eu sunt ca voi; nu m-ați nedreptățit cu nimic.
Ará, mo bẹ̀ yín, ẹ dàbí èmi: nítorí èmi dàbí ẹ̀yin: ẹ̀yin kò ṣe mí ní ibi kan.
13 Dar știți cum prin neputința cărnii v-am predicat evanghelia la început.
Ẹ̀yin mọ̀ pé nínú àìlera ni mo wàásù ìyìnrere fún yín ní àkọ́kọ́.
14 Și nu ați disprețuit, nici nu ați respins ispita mea care era în carnea mea, ci m-ați primit ca pe un înger al lui Dumnezeu, ca pe Cristos Isus.
Èyí tí ó sì jẹ́ ìdánwò fún yín ní ara mi ni ẹ kò kẹ́gàn, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò sì kọ̀; ṣùgbọ́n ẹ̀yin gbà mí bí angẹli Ọlọ́run, àní bí Kristi Jesu.
15 Unde este, așadar, binecuvântarea despre care ați vorbit? Fiindcă vă aduc mărturie, că, dacă ar fi fost posibil, v-ați fi scos propriii ochi și mi i-ați fi dat.
Ǹjẹ́ ayọ̀ yín ìgbà náà ha dà? Nítorí mo gba ẹ̀rí yín pé, bi o bá ṣe é ṣe, ẹ̀ ò bá yọ ojú yín jáde, ẹ̀ bá sì fi wọ́n fún mi.
16 Am devenit atunci dușmanul vostru, pentru că vă spun adevărul?
Ǹjẹ́ mo ha di ọ̀tá yín nítorí mo sọ òtítọ́ fún yín bí?
17 Ei cu zel vă influențează, dar nu spre bine; da, ei voiesc să vă excludă, ca la rândul vostru să îi influențați cu zel.
Wọ́n ń fi ìtara wá yin, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún rere; wọ́n ń fẹ́ já yin kúrò, kí ẹ̀yin lè máa wá wọn.
18 Dar totdeauna este bine să fiți influențați cu zel în ce este bine și nu doar când sunt prezent cu voi.
Ṣùgbọ́n ó dára láti máa fi ìtara wá ni fún ohun rere nígbà gbogbo, kì í sì í ṣe nígbà tí mo wà pẹ̀lú yín nìkan.
19 Copilașii mei, pentru care din nou simt durerile nașterii până când Cristos este format în voi,
Ẹ̀yin ọmọ mi kéékèèké, ẹ̀yin tí mo tún ń rọbí títí a ó fi ṣe ẹ̀dá Kristi nínú yín.
20 Doresc să fiu prezent acum cu voi și să îmi schimb tonul vocii, pentru că sunt nedumerit cu privire la voi.
Ìbá wù mí láti wà lọ́dọ̀ yín nísinsin yìí, kí èmi sì yí ohùn mi padà nítorí pé mo dààmú nítorí yín.
21 Spuneți-mi, voi, care doriți să fiți sub lege, nu auziți legea?
Ẹ wí fún mi, ẹ̀yin tí ń fẹ́ wà lábẹ́ òfin, ẹ ko ha gbọ́ òfin ohun ti òfin sọ.
22 Fiindcă este scris că Avraam a avut doi fii, unul din femeia roabă și celălalt din femeia liberă.
Nítorí a ti kọ ọ́ pé, Abrahamu ní ọmọ ọkùnrin méjì, ọ̀kan láti ọ̀dọ̀ ẹrúbìnrin, àti ọ̀kan láti ọ̀dọ̀ òmìnira obìnrin.
23 Dar cel din femeia roabă a fost născut conform cărnii, iar cel din femeia liberă, prin promisiune.
Ṣùgbọ́n a bí èyí tí ṣe ti ẹrúbìnrin nípa ti ara, ṣùgbọ́n èyí ti òmìnira obìnrin ni a bí nípa ìlérí.
24 Lucrurile acestea sunt o alegorie, fiindcă acestea sunt cele două legăminte, unul, de la muntele Sinai, care naște pentru robie și care este Agar.
Nǹkan wọ̀nyí jẹ́ àpẹẹrẹ: nítorí pé àwọn obìnrin wọ̀nyí ní májẹ̀mú méjèèjì; ọ̀kan láti orí òkè Sinai wá, tí a bí lóko ẹrú, tí í ṣe Hagari.
25 Fiindcă această Agar este muntele Sinai în Arabia și corespunde Ierusalimului de acum și este în robie cu copiii săi.
Nítorí Hagari yìí ni òkè Sinai Arabia, tí ó sì dúró fún Jerusalẹmu tí ó wà nísinsin yìí, tí ó sì wà lóko ẹrú pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀.
26 Dar Ierusalimul cel de sus este liber, cel ce este mama noastră a tuturor.
Ṣùgbọ́n Jerusalẹmu ti òkè jẹ́ òmìnira, èyí tí í ṣe ìyá wa.
27 Fiindcă este scris: Bucură-te, stearpo, care nu naști. Izbucnește și strigă tu care nu ești în durerile nașterii, pentru că cea pustiită are mai mulți copii decât cea care are soț.
Nítorí a ti kọ ọ́ pé, “Máa yọ̀, ìwọ obìnrin àgàn tí kò bímọ, bú sí ayọ̀ kí o sì kígbe sókè, ìwọ tí kò rọbí rí; nítorí àwọn ọmọ obìnrin náà tí a kọ̀sílẹ̀ yóò pọ̀ ju ti obìnrin tó ní ọkọ lọ.”
28 Iar noi, fraților, suntem copiii promisiunii așa cum a fost Isaac.
Ǹjẹ́ ará, ọmọ ìlérí ni àwa gẹ́gẹ́ bí Isaaki.
29 Dar așa cum atunci, cel ce fusese născut conform cărnii persecuta pe cel născut conform Duhului, tot așa [și] acum.
Ṣùgbọ́n bí èyí tí a bí nípa ti ara ti ṣe inúnibíni nígbà náà sí èyí tí a bí nípa ti Ẹ̀mí, bẹ́ẹ̀ sì ni nísinsin yìí.
30 Totuși ce spune scriptura? Alungă femeia roabă și pe fiul ei, pentru că fiul femeii roabe nicidecum nu va fi moștenitor cu fiul femeii libere.
Ṣùgbọ́n ìwé mímọ́ ha ti wí, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrúbìnrin kì yóò bá ọmọ òmìnira obìnrin jogún pọ̀.”
31 Așa că, fraților, nu suntem copii ai femeii roabe, ci ai femeii libere.
Nítorí náà, ará, àwa kì í ṣe ọmọ ẹrúbìnrin bí kò ṣe ti òmìnira obìnrin.

< Galateni 4 >