< Ezechiel 43 >
1 După aceasta el m-a dus la poartă, la poarta care dă spre est;
Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà mú mi gba ti ẹnu-ọ̀nà tí ó dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn,
2 Și, iată, gloria Dumnezeului lui Israel venea pe calea dinspre est; și vocea lui [era] ca zgomotul multor ape; și pământul strălucea de gloria sa.
mo sì ri ògo Ọlọ́run Israẹli ń bọ láti ìhà ìlà-oòrùn. Ohùn rẹ̀ dàbí híhó omi, ìtànṣán ògo rẹ̀ sì bo ilẹ̀.
3 Și [aceasta era] conform cu înfățișarea viziunii pe care o văzusem, conform cu viziunea pe care o văzusem când am venit să distrug cetatea; și viziunile [erau] ca viziunea pe care o văzusem la râul Chebar; și am căzut cu fața la pământ.
Ó sì dàbí ìran tí mo rí, gẹ́gẹ́ bí ìran tí mo rí nígbà tí mo wá láti pa ìlú náà run; ìran náà sì dà bí ìran tí mo rí lẹ́bàá odò Kebari, mo sì dojú mi bolẹ̀.
4 Și gloria DOMNULUI a intrat în casă pe calea porții a cărei fețe [este] spre est.
Ògo Olúwa gba ọ̀nà tí o dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn wọ inú ilé Ọlọ́run wá.
5 Astfel duhul m-a ridicat și m-a dus în curtea interioară; și, iată, gloria DOMNULUI a umplut casa.
Mo ni ìrusókè ẹ̀mí, ó sì mú mi lọ inú ilé ìdájọ́, sì kíyèsi ògo Olúwa kún inú ilé Ọlọ́run.
6 Și [l-]am auzit vorbindu-mi din casă; și un bărbat stătea în picioare lângă mine.
Nígbà tí ọkùnrin náà dúró ní ẹ̀gbẹ́ mi, mo gbọ́ ẹnìkan tí ó bá mi sọ̀rọ̀ láti inú ilé Ọlọ́run.
7 Și el mi-a spus: Fiu al omului, locul tronului meu și locul tălpilor picioarelor mele, unde voi locui în mijlocul copiilor lui Israel pentru totdeauna și numele meu sfânt, casa lui Israel nu îl vor mai pângări, [nici] ei, nici împărații lor, prin curvia lor, nici prin trupurile moarte ale împăraților lor pe înălțimile lor.
Ó sì wí pé, “Ọmọ ènìyàn, èyí yìí ni ibi ìgúnwà mi àti ibi tí ó wà fún àtẹ́lẹsẹ̀ mi. Ibi yìí ni èmi yóò máa gbé ní àárín àwọn ọmọ Israẹli títí láéláé. Ilé Israẹli kò ní ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́ mọ́ láéláé àwọn tàbí àwọn ọba wọn nípa àgbèrè àti àwọn ère aláìlẹ́mìí àwọn ọba wọn ní ibi gíga.
8 Prin punerea pragului lor lângă pragurile mele și ușorul lor lângă ușorii mei și zidul dintre mine și ei; ei au pângărit numele meu sfânt prin urâciunile lor pe care le-au făcut, pentru aceea i-am mistuit în mânia mea.
Nígbà tí wọ́n ba gbé ìloro ilé wọn kángun sí ìloro ilé mi àti ìlẹ̀kùn wọn sì ẹ̀gbẹ́ ìlẹ̀kùn mi, pẹ̀lú ògiri nìkan ní àárín èmi pẹ̀lú wọn, wọ́n ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ìwà ìríra wọn. Nígbà náà ni mo pa wọ́n run ní ìbínú mi.
9 Să îndepărteze de mine acum, curvia lor și trupurile moarte ale împăraților lor, și voi locui în mijlocul lor pentru totdeauna.
Nísinsin yìí jẹ́ kí wọn mú ìwà àgbèrè wọn àti àwọn ère aláìlẹ́mìí àwọn ọba wọn kúrò ni iwájú mi, èmi yóò sì gbé àárín wọn láéláé.
10 Tu fiu al omului, arată casei lui Israel casa, ca ei să se rușineze de nelegiuirile lor, și să îi măsoare modelul.
“Ọmọ ènìyàn, ṣàpèjúwe ilé Ọlọ́run náà fún àwọn ènìyàn Israẹli kí ojú ẹ̀ṣẹ̀ wọn, lè tì wọ́n sì jẹ́ kí wọn wo àwòrán ilé náà,
11 Și dacă se vor rușina de tot ce au făcut, arată-le forma casei și modelul ei și ieșirile ei și intrările ei și toate formele ei și toate rânduielile ei și toate formele ei și toate legile ei; și scrie-[le] înaintea ochilor lor, ca să păzească toată forma ei și toate rânduielile ei și să le împlinească.
tí ojú gbogbo ohun tí wọn ti ṣe bá tì wọ́n, jẹ́ kí wọ́n mọ̀ àwòrán ilé Ọlọ́run náà bí wọ́n ṣe tò ó lẹ́sẹẹsẹ, àbájáde àti àbáwọlé rẹ̀ gbogbo àwòrán àti gbogbo òfin àti ìlànà rẹ̀. Kọ ìwọ̀nyí sílẹ̀ ní iwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ́ olóòtítọ́ si àwòrán rẹ̀, kí wọ́n sì tẹ̀lé gbogbo òfin rẹ̀.
12 Aceasta [este] legea casei: Pe vârful muntelui, întreg cuprinsul [muntelui] de jur împrejur [va fi] preasfânt. Iată, aceasta [este] legea casei.
“Èyí yìí ní òfin ilé Ọlọ́run náà. Gbogbo àyíká lórí òkè gíga ní yóò jẹ́ ibi mímọ́ jùlọ. Bí èyí ni òfin tẹmpili náà.
13 Și acestea [sunt] măsurile altarului în coți: Cotul [este] un cot și un lat de palmă; chiar partea de jos [va fi] de un cot și lățimea de un cot și marginea lui pe muchia lui de jur împrejur [va fi] o palmă; și acesta [va fi] locul mai înalt al altarului.
“Ìwọ̀nyí ni wíwọ̀n pẹpẹ ìrúbọ ní gígùn ìgbọ̀nwọ́, ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ni jíjìn, ó sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ni ìbú, igun rẹ̀ yípo àti etí rẹ̀ jẹ́ ìbú àtẹ́lẹwọ́ kan. Èyí yìí sì ni gíga pẹpẹ ìrúbọ náà.
14 Și de la partea de jos [de pe] pământ până la pervazul de jos [vor fi] doi coți și lățimea de un cot; și de la pervazul mai mic până la pervazul mai mare [vor fi] patru coți și lățimea de [un] cot.
Láti ìsàlẹ̀ rẹ̀ ni ilẹ̀ títí dé ìsàlẹ̀ igun rẹ̀, ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjì ni gíga o sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ní ìbú. Láti igun rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ títí dé igun rẹ̀ ti òkè tí ó yípo pẹpẹ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin ní gíga, igun náà sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ní ìbú.
15 Astfel, altarul [va fi] de patru coți; și de la altar în sus [vor fi] patru coarne.
Ibi ìdáná pẹpẹ ìrúbọ náà jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin ní gíga, ìwo mẹ́rẹ̀ẹ̀rin sì yọrí jáde sókè láti ibi ìdáná.
16 Și altarul [va fi] de doisprezece [coți] în lungime, doisprezece în lățime, pătrat pe cele patru colțuri ale lui.
Ibi ìdáná pẹpẹ náà jẹ́ igun mẹ́rin mẹ́rin lọ́gbọọgba, ìgbọ̀nwọ́ méjìlá ní gígùn, o sì jẹ ìgbọ̀nwọ́ méjìlá ní ìbú.
17 Și pervazul [va fi] de paisprezece [coți] în lungime și paisprezece în lățime în cele patru colțuri ale lui; și marginea de jur împrejurul lui [va fi] de o jumătate de cot; și partea de jos a lui [va fi] de un cot de jur împrejur; și treptele lui vor da spre est.
Igun ni apá òkè náà jẹ́ igun mẹ́rin lọ́gbọọgba, ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rìnlá ní gígùn, ó sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rìnlá ní ìbú, pẹ̀lú etí tí ó jẹ́ ìdajì ìgbọ̀nwọ́, ìsàlẹ̀ rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan yípo. Àtẹ̀gùn pẹpẹ ìrúbọ náà dojúkọ ìlà-oòrùn.”
18 Și el mi-a spus: Fiu al omului, astfel spune Domnul DUMNEZEU: Acestea [sunt] rânduielile altarului în ziua în care îl vor face ca să ofere pe el ofrande arse și să stropească sânge pe el.
Lẹ́yìn náà, ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ̀nyí yóò jẹ́ òfin fún ìrúbọ ẹbọ sísun àti wíwọ̀n ẹ̀jẹ̀ sórí pẹpẹ nígbà tí a bá mọ pẹpẹ tán.
19 Și să dai preoților, leviților, care sunt din sămânța lui Țadoc, care se apropie de mine ca să îmi servească, un taur tânăr ca ofrandă pentru păcat, spune Domnul DUMNEZEU.
Ẹ̀yin ní láti mú ọ̀dọ́ akọ màlúù gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrékọjá fún àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Lefi, tí ìdílé Sadoku tí ó wá sí agbègbè láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ fún mi ní Olúwa Olódùmarè wí.
20 Și să iei din sângele lui și să [îl] pui pe cele patru coarne ale lui și pe cele patru colțuri ale pervazului și pe margine de jur împrejur, astfel să îl cureți și să îl purifici.
Ẹ ni láti mú lára ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, kí ẹ sì fi sórí ìwo mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà lórí pẹpẹ, àti lórí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ìjókòó náà àti sí gbogbo etí rẹ̀ yípo, ìwọ yóò sì sọ pẹpẹ di mímọ́, ìwọ yóò sì ṣe ètùtù rẹ̀.
21 Să iei de asemenea taurul pentru ofranda pentru păcat și el să îl ardă în locul rânduit al casei, în afara sanctuarului.
Ìwọ gbọdọ̀ mú akọ màlúù fún ìrékọjá, ìwọ yóò sì sun ún ní apá ibi tí a sàmì sí ní agbègbè ilé Ọlọ́run ní ìta ibi mímọ́.
22 Și în ziua a doua să oferi un ied dintre capre, fără cusur, ca ofrandă pentru păcat; și ei să curețe altarul, precum [l]-au curățit cu taurul.
“Ní ọjọ́ kejì ìwọ yóò fi ewúrẹ́, òbúkọ aláìlábàwọ́n fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, a sì gbọdọ̀ sọ pẹpẹ di mímọ́ gẹ́gẹ́ bí a ti ṣọ́ di mímọ́ pẹ̀lú akọ màlúù.
23 După ce vei termina curățirea [lui], să oferi un taur tânăr fără cusur și un berbec, fără cusur, din turmă.
Nígbà tí ìwọ bá parí ìsọdimímọ́, ìwọ yóò fi ọ̀dọ́ akọ màlúù àti ọ̀dọ́ àgbò aláìlábàwọ́n láti inú agbo fún ìrúbọ.
24 Și să îi oferi înaintea DOMNULUI și preoții să arunce sare pe ei și să îi ofere [ca] ofrandă arsă DOMNULUI.
Ìwọ yóò mú wọn lọ sí iwájú Olúwa, àwọn àlùfáà ni yóò fi iyọ̀ wọ́n wọn, wọn yóò sì fi wọ́n rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
25 Șapte zile să pregătești în fiecare zi un țap [ca] ofrandă pentru păcat; ei să pregătească de asemenea un taur tânăr și un berbec, fără cusur, din turmă.
“Fún ọjọ́ méje, ìwọ ní láti pèsè akọ ewúrẹ́ kan lójoojúmọ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀; ìwọ yóò sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù àti àgbò láti inú agbo, méjèèjì yóò sì jẹ́ aláìlábàwọ́n.
26 Șapte zile să curețe altarul și să îl purifice; și ei să se consacre.
Fún ọjọ́ méje wọn yóò jẹ́ ètùtù fún pẹpẹ, wọn yóò sì sọ ọ́ di mímọ́; nípa bẹ́ẹ̀ wọn yóò yà á sọ́tọ̀.
27 Și după ce vor fi trecut aceste zile, se va întâmpla [că, ] în ziua a opta și mai departe, preoții să pregătească ofrandele voastre arse pe altar și ofrandele voastre de pace; și vă voi primi, spune Domnul DUMNEZEU.
Ní ìparí ọjọ́ wọ̀nyí, láti ọjọ́ mẹ́jọ síwájú, àwọn àlùfáà ni yóò gbé àwọn ẹbọ sísun rẹ àti ẹbọ ìdàpọ̀ rẹ̀ kalẹ̀ lórí pẹpẹ. Lẹ́yìn náà, èmi yóò tẹ́wọ́gbà yín ní Olúwa Olódùmarè wí.”