< Ezechiel 26 >
1 Și s-a întâmplat în al unsprezecelea an, în [ziua] întâi a lunii, [că] a venit cuvântul DOMNULUI la mine, spunând:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kọ́kànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Fiu al omului, pentru că Tirul a spus împotriva Ierusalimului: Aha, el [care era] porțile popoarelor, este frânt, s-a întors la mine; eu voi fi umplut, [acum] el este pustiit;
“Ọmọ ènìyàn, nítorí pé Tire sọ nípa Jerusalẹmu pé, ‘Háà! A fọ́ èyí tí í ṣe bodè àwọn orílẹ̀-èdè, a yí i padà sí mi, èmi yóò di kíkún, òun yóò sì di ahoro,’
3 De aceea astfel spune Domnul DUMNEZEU: Iată, eu [sunt] împotriva ta, Tirule, și voi face multe națiuni să se ridice împotriva ta, precum marea face ca valurile ei să se ridice.
nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, kíyèsi i, èmí dojúkọ ọ́ ìwọ tire, Èmi yóò sì jẹ́ kí Orílẹ̀-èdè púpọ̀ dìde sí ọ, gẹ́gẹ́ bí Òkun tí ru sókè.
4 Și ele vor distruge zidurile Tirului și îi vor dărâma turnurile; eu de asemenea voi rade praful de pe el și îl voi face ca pe vârful unei stânci.
Wọn yóò wó odi tire lulẹ̀, wọn yóò sì wo ilé ìṣọ́ rẹ̀ lulẹ̀, Èmi yóò sì ha erùpẹ̀ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì sọ ọ́ di orí àpáta.
5 Va fi [un loc pentru] întinderea plaselor în mijlocul mării, pentru că eu am vorbit [aceasta], spune Domnul DUMNEZEU; și va deveni o pradă pentru națiuni.
Yóò sì jẹ́ ibi nína àwọ̀n tí wọn fi ń pẹja sí láàrín Òkun, ní Olúwa Olódùmarè wí. Yóò di ìkógun fún àwọn orílẹ̀-èdè.
6 Și fiicele lui care [sunt] în câmp vor fi ucise de sabie; și vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.
Ìlú tí ó tẹ̀dó sí, ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó fi idà sọ ọ́ di ahoro. Nígbà náà ní wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
7 Pentru că astfel spune Domnul DUMNEZEU: Iată, voi aduce asupra Tirului pe Nebucadnețar, împăratul Babilonului, un împărat al împăraților, de la nord, cu cai și cu care și cu călăreți și cete și mult popor.
“Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, láti ìhà àríwá ni èmi yóò ti mú Nebukadnessari ọba Babeli, ọba àwọn ọba, dìde sí Tire pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ológun.
8 Cu sabia el va ucide pe fiicele tale din câmp; și va face o fortificație împotriva ta și va ridica un val de pământ împotriva ta și va ridica pavăza împotriva ta.
Yóò sì fi idà sá àwọn ọmọbìnrin rẹ ní oko, yóò sì kọ́ odi tì ọ́, yóò sì mọ òkìtì tì ọ́, yóò sì gbé àpáta sókè sí ọ.
9 Și va pune mașinăriile lui de război împotriva zidurilor tale și cu topoarele lui îți va dărâma turnurile.
Yóò sì gbé ẹ̀rọ ogun tí odi rẹ, yóò sì fi ohun èlò ogun wó ilé ìṣọ́ rẹ palẹ̀.
10 Din cauza abundenței cailor lui, țărâna lor te va acoperi; zidurile tale se vor zgudui la zgomotul călăreților și al roților și al carelor, când el va intra pe porțile tale, precum oamenii intră într-o cetate în care este făcută o spărtură.
Àwọn ẹṣin rẹ̀ yóò pọ̀ dé bí pé wọn yóò fi eruku bò ọ́ mọ́lẹ̀. Àwọn ògiri rẹ yóò mì tìtì fún igbe àwọn ẹṣin ogun kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kẹ̀kẹ́ ogun nígbà tí ó bá wọ ẹnu-ọ̀nà odi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń wọ ìlú láti inú àwọn ògiri rẹ̀ ti ó di fífọ́ pátápátá.
11 Cu copitele cailor lui îți va călca toate străzile; va ucide pe poporul tău cu sabia, iar ale tale garnizoane tari vor coborî la pământ.
Pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin rẹ̀ ni yóò fi tẹ gbogbo òpópónà rẹ mọ́lẹ̀; yóò fi idà pa àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọ̀wọ́n rẹ ti o lágbára yóò wó palẹ̀.
12 Și ei vor jefui din bogățiile tale și vor prăda marfa ta; și îți vor dărâma zidurile și vor distruge casele tale plăcute; și îți vor pune pietrele și lemnăria și țărâna în mijlocul apei.
Wọn yóò kó ọrọ̀ rẹ, wọn yóò sì fi òwò rẹ ṣe ìjẹ ogun; wọn yóò sì wó odi rẹ lulẹ̀, wọn yóò sì ba àwọn ilé rẹ dídára jẹ́, wọn yóò sì kó àwọn òkúta rẹ̀, àti igi ìtì ìkọ́lé rẹ̀, àti erùpẹ̀ rẹ̀, dà sí inú Òkun.
13 Și voi face să înceteze zgomotul cântărilor tale; și sunetul harpelor tale nu va mai fi auzit.
Èmi yóò sì mú ariwo orin rẹ̀ dákẹ́ àti ìró dùùrù orin rẹ̀ ni a kì yóò gbọ́ mọ́.
14 Și te voi face ca vârful unei stânci; vei fi [un loc] pentru întinderea plaselor; nu vei mai fi construit, pentru că eu DOMNUL am vorbit [aceasta], spune Domnul DUMNEZEU.
Èmi yóò sọ ọ di àpáta lásán, ìwọ yóò sì di ibi tí a ń sá àwọ̀n ẹja sí. A kì yóò sì tún ọ mọ nítorí Èmi Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ ní Olúwa Olódùmarè wí.
15 Astfel spune Tirului, Domnul DUMNEZEU: Nu vor tremura insulele la sunetul căderii tale, când răniții strigă, când se face măcel în mijlocul tău?
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Tire: Ǹjẹ́ àwọn erékùṣù kì yóò ha wárìrì nípa ìṣubú rẹ, nígbà tí ìkórìíra ìpalára àti rírẹ́ni lọ́run bá ń ṣẹlẹ̀ ní inú rẹ?
16 Atunci toți prinții mării vor coborî de pe tronurile lor și își vor pune deoparte robele și se vor dezbrăca de hainele lor brodate; ei se vor îmbrăca cu tremurare; vor ședea pe pământ și vor tremura în [fiecare] moment și vor fi înmărmuriți din [cauza] ta.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn ọmọ-aládé etí Òkun yóò sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ wọn, wọn yóò sì pa àwọn aṣọ ìgúnwà wọn da, tì wọn yóò sì bọ́ àwọn aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ kúrò. Ẹ̀rù yóò bò wọ́n, wọn yóò sì jókòó lórí ilẹ̀ pẹ̀pẹ̀, wọn yóò sì máa wárìrì ní gbogbo ìgbà, ẹnu yóò sì yà wọ́n sí ọ́.
17 Și vor înălța o plângere pentru tine și îți vor spune: Cum ești distrusă, tu [care erai] locuită de marinari, cetatea renumită, care era puternică pe mare, ea și locuitorii ei, care făceau ca teroarea lor [să fie] asupra tuturor celor ce o vizitează!
Nígbà náà wọn yóò gbóhùn ẹkún sókè nítorí rẹ, wọn yóò sì wí fún ọ pé: “‘Báwo ni a ṣe pa ọ́ run, ìwọ ìlú olókìkí ìwọ tí àwọn èrò okun ti gbé inú rẹ̀! Ìwọ jẹ alágbára lórí okun gbogbo òun àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; ìwọ gbé ẹ̀rù rẹ lórí gbogbo olùgbé ibẹ̀.
18 Acum insulele vor tremura în ziua căderii tale; da, insulele care [sunt] în mare vor fi tulburate la plecarea ta.
Nísinsin yìí erékùṣù wárìrì ní ọjọ́ ìṣubú rẹ; erékùṣù tí ó wà nínú Òkun ni ẹ̀rù bà torí ìṣubú rẹ.’
19 Pentru că astfel spune Domnul DUMNEZEU: Când te voi face o cetate pustiită, ca pe cetățile nelocuite; când voi aduce adâncul asupra ta și mari ape te vor acoperi;
“Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí mo bá sọ ọ́ di ìlú ahoro, gẹ́gẹ́ bi àwọn ìlú tí a kò gbé inú wọn mọ́, àti nígbà tí èmi yóò mú ibú agbami Òkun wá sí orí rẹ, omi ńlá yóò sì bò ọ́,
20 Când te voi coborî cu cei care coboară în groapă, cu poporul din vechime și te voi pune în părțile de jos ale pământului, în locuri părăsite din vechime, cu cei care coboară în groapă, ca să nu [mai] fii locuită; și eu voi pune gloria în țara celor vii;
nígbà tí èmi yóò mú ọ wálẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, pẹ̀lú àwọn ènìyàn àtijọ́. Èmi yóò sì gbé ọ lọ si bi ìsàlẹ̀, ní ibi ahoro àtijọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, ìwọ kì yóò sì padà gbé inú rẹ̀ mọ́, èmi yóò sì gbé ògo kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
21 Te voi face o teroare, iar tu nu [vei mai fi]; deși vei fi căutată, totuși nu vei mai fi găsită niciodată, spune Domnul DUMNEZEU.
Èmi yóò ṣe ọ ní ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́. Bí a tilẹ̀ wá ọ, síbẹ̀ a kì yóò tún rí ọ mọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.”