< Ezechiel 12 >
1 Cuvântul DOMNULUI de asemenea a venit la mine, spunând:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Fiu al omului, locuiești în mijlocul unei case răzvrătite, care au ochi să vadă dar nu văd; au urechi să audă dar nu aud, pentru că [sunt] o casă răzvrătită.
“Ọmọ ènìyàn, ìwọ ń gbé ní àárín ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn. Wọ́n lójú láti fi ríran, ṣùgbọ́n wọn kò ríran, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n létí láti fi gbọ́rọ̀ ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́rọ̀, torí pé ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn ni wọ́n.
3 De aceea, tu fiu al omului, pregătește-ți lucrurile pentru strămutare și pleacă ziua înaintea ochilor lor; și să pleci din locul tău într-un alt loc înaintea ochilor lor; poate că vor lua aminte, deși ei [sunt] o casă răzvrătită.
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, palẹ̀ ẹrù rẹ mọ́ láti lọ sí ìgbèkùn, ní ọ̀sán gangan ní ojú wọn, kúrò láti ibi tí ìwọ wà lọ sí ibòmíràn. Bóyá bí wọ́n bá rí ọ, wọn yóò sì ronú bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.
4 Atunci să scoți afară lucrurile tale ziua, înaintea ochilor lor, ca lucrurile pentru strămutare; și să ieși seara înaintea ochilor lor, asemenea celor mergând în captivitate.
Di ẹrù ìgbèkùn rẹ lójú wọn ní ọ̀sán án gangan, nígbà tí ó bá sì di alẹ́, ní ojú wọn, máa lọ sí ìgbèkùn gẹ́gẹ́ bí àwọn tí ó lọ ìgbèkùn ṣe máa ń ṣe.
5 Sapă prin zid înaintea ochilor lor și scoate-le pe acolo.
Dá ògiri lu ní ojú wọn, kí ìwọ sì gba ibẹ̀ kó ẹrù rẹ jáde.
6 Înaintea ochilor lor să [le] porți pe umeri [și] să [le] scoți în amurg; să îți acoperi fața ca să nu vezi pământul, pentru că te-am pus [ca] un semn pentru casa lui Israel.
Gbé ẹrù rẹ lé èjìká ní ojú wọn, bo ojú rẹ, kí ìwọ má ba à rí ilẹ̀, sì ru ẹrù rẹ lọ ní alẹ́ nítorí pé mo fi ọ́ ṣe àmì fún ilé Israẹli.”
7 Și am făcut astfel precum mi se poruncise: Am scos afară lucrurile mele ziua, ca lucrurile pentru captivitate și seara am săpat prin zid cu mâna mea; [le]-am scos în amurg [și le]-am purtat pe umeri înaintea ochilor lor.
Mo ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi. Mo kó ẹrù mi jáde ní ọ̀sán án láti lọ fun ìgbèkùn. Nígbà tó di ìrọ̀lẹ́, mo dá ògiri lu pẹ̀lú ọwọ́ mi. Mo sì gbe ẹrù mi lé èjìká nínú òkùnkùn ní ojú wọn.
8 Și dimineața a venit cuvântul DOMNULUI la mine, spunând:
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
9 Fiu al omului, nu ți-a spus casa lui Israel, casa cea răzvrătită: Ce faci?
“Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli tilẹ̀ bi ọ́ pé, ‘Kí ni ohun tí o ń ṣe túmọ̀ sí?’
10 Spune-le: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Această povară [se referă] la prințul din Ierusalim și la toată casa lui Israel care [este] printre ei.
“Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ yìí kan àwọn ọmọ-aládé Jerusalẹmu àti gbogbo ilé Israẹli tí ó wà ní àárín rẹ.
11 Spune: Eu [sunt] semnul vostru; precum am făcut eu, astfel li se va face lor; ei vor pleca [și] vor merge în captivitate.
Sọ fún wọn pé, Èmi jẹ́ àmì fún yín’. “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí wọn. Wọn ó kó lọ sí ìgbèkùn. Gẹ́gẹ́ bí ẹni ti a dè ní ìgbèkùn.
12 Și prințul care [este] printre ei va purta pe umeri, în amurg, și va ieși; ei vor săpa prin zid pentru a le scoate prin acesta; el își va acoperi fața, ca să nu vadă pământul cu ochii [săi].
“Ọmọ-aládé tí ó wà ní àárín wọn yóò di ẹrù rẹ̀ lé èjìká ní alẹ́ yóò sì jáde lọ, òun náà yóò da ògiri lu kí ó le gba ibẹ̀ jáde. Yóò sì bo ojú rẹ̀ kí ó má ba à rí ilẹ̀.
13 Plasa mea o voi întinde de asemenea peste el și va fi prins în cursa mea; și îl voi aduce la Babilon [în] țara caldeenilor; totuși el nu o va vedea, deși va muri acolo.
Èmi yóò ta àwọ̀n mi lé e lórí, yóò sì kó sínú okùn, Èmi yóò sì mú lọ sí Babeli, ní ilẹ̀ Kaldea, ṣùgbọ́n kò ní fojúrí ilẹ̀ náà ibẹ̀ ni yóò kú sí.
14 Și voi împrăștia spre fiecare vânt pe toți cei ce [sunt] lângă el pentru a-l ajuta și pe toate cetele lui; și voi scoate sabia după ei.
Gbogbo àwọn tó yí i ká láti ràn án lọ́wọ́ ọ̀pá ìtẹ̀lẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ni Èmi yóò túká sí afẹ́fẹ́, èmi yóò sì tún fi idà lé wọn kiri.
15 Și ei vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL, când îi voi împrăștia printre națiuni și îi voi răspândi prin țări.
“Wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa nígbà tí mo bá tú wọn ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì fọ́n wọn ká sí ilẹ̀ káàkiri.
16 Dar voi lăsa câțiva oameni dintre ei, de la sabie, de la foamete și de la ciumă; ca ei să vestească toate urâciunile acestora printre păgânii unde vor ajunge; și ei vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.
Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ díẹ̀ kù lára wọn, ní ọwọ́ idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, kí wọn le jẹ́wọ́ gbogbo ìṣe ìríra wọn ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè yìí. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
17 Mai mult, cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
18 Fiu al omului, mănâncă-ți pâinea cu frică și bea-ți apa cu tremur și cu grijă;
“Ọmọ ènìyàn, jẹ oúnjẹ rẹ pẹ̀lú ìwárìrì, sì mu omi rẹ pẹ̀lú ìwárìrì àti àìbalẹ̀ àyà.
19 Și spune poporului țării: Astfel spune Domnul DUMNEZEU despre locuitorii Ierusalimului [și] despre țara lui Israel: Ei își vor mânca pâinea cu grijă și își vor bea apa cu înmărmurire, pentru ca țara lor să fie pustiită de tot ce este în ea, din cauza violenței tuturor celor care locuiesc în ea.
Sọ fún àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti ilẹ̀ Israẹli pé, pẹ̀lú àìbalẹ̀ àyà ni wọn yóò máa jẹun wọn, wọn yóò sì mu omi pẹ̀lú àìnírètí, kí ilẹ̀ wọn lè di ahoro torí ìwà ipá àwọn tó ń gbé ibẹ̀.
20 Și cetățile care sunt locuite vor fi risipite și țara va fi pustiită și veți cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.
Ìlú tó jẹ́ ibùgbé ènìyàn tẹ́lẹ̀ yóò di òfo, ilẹ̀ náà yóò sì di ahoro. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
21 Și cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
22 Fiu al omului, ce [este] acel proverb [pe care] voi îl aveți în țara lui Israel, spunând: Zilele sunt prelungite și orice viziune se sfârșește?
“Ọmọ ènìyàn, irú òwe wo ni ẹ pa nílẹ̀ Israẹli pé: ‘A fa ọjọ́ gùn, gbogbo ìran di asán’?
23 Spune-le de aceea: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Eu voi face acest proverb să înceteze și nu îl vor mai folosi ca proverb în Israel; ci spune-le: Zilele sunt aproape și împlinirea fiecărei viziuni.
Nítorí náà wí fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò fi òpin sí òwe yìí, wọn kò ní ipa mọ́ ní Israẹli.’ Sọ fún wọn, ‘Ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí nígbà tí gbogbo ìran àti ìsọtẹ́lẹ̀ yóò sì wá sí ìmúṣẹ.
24 Fiindcă nu va mai fi vreo viziune deșartă, nici ghicire lingușitoare în casa lui Israel.
Nítorí kò ní sí ìran asán tàbí àfọ̀ṣẹ tí ó ń pọ́n ni mọ́ ní àárín ilé Israẹli.
25 Fiindcă eu [sunt] DOMNUL; voi vorbi și cuvântul pe care îl voi vorbi se va întâmpla; acesta nu va mai fi prelungit, pentru că în zilele voastre, casă răzvrătită, voi spune cuvântul și îl voi împlini, spune Domnul DUMNEZEU.
Ṣùgbọ́n, Èmi Olúwa yóò sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò sì ṣẹ láì falẹ̀. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ní àsìkò yín, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀ ilé ni Èmi yóò mú ọ̀rọ̀ yówù tí mo bá sọ ṣẹ.’”
26 Din nou cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
27 Fiu al omului, iată, [cei din] casa lui Israel spun: Viziunea pe care el o vede [este] pentru multe zile [ce au să vină] și el profețește despre timpuri îndepărtate.
“Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ń wí pé, ‘Ìran ọjọ́ pípẹ́ ni ìwọ rí, ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ nípa àsìkò tó jìnnà réré.’
28 De aceea spune-le: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Niciunul din cuvintele mele nu va mai fi prelungit, ci cuvântul pe care l-am vorbit va fi împlinit, spune Domnul DUMNEZEU.
“Nítorí náà sọ fún wọn, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, kò sí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ mi tí yóò sún síwájú mọ́; ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ tí mo bá sọ yóò ṣẹ.’”