< Exod 31 >

1 Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, spunând:
Olúwa wí fún Mose pé,
2 Vezi, am chemat pe nume pe Bețaleel, fiul lui Uri, fiul lui Hur, din tribul lui Iuda;
“Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
3 Și l-am umplut cu duhul lui Dumnezeu, în înțelepciune și în înțelegere și în cunoaștere și în orice fel de meșteșug,
Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
4 Pentru a concepe lucruri iscusite, pentru a lucra în aur și în argint și în aramă,
Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
5 Și în tăierea pietrelor, pentru a fi montate și în sculptarea lemnăriei, pentru a lucra în orice fel de meșteșug.
láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
6 Și eu, iată, eu l-am dat împreună cu el pe Aholiab, fiul lui Ahisama, din tribul lui Dan; și în inimile tuturor celor ce sunt înțelepți în inimă am pus înțelepciune, ca ei să poată face tot ce ți-am poruncit;
Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
7 Tabernacolul întâlnirii și chivotul mărturiei și șezământul milei care este pe ea și tot mobilierul tabernacolului,
“àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
8 Și masa și vasele ei și sfeșnicul pur cu toate vasele lui și altarul tămâiei,
tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
9 Și altarul ofrandei arse cu toate vasele lui și ligheanul și piciorul lui,
pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
10 Și hainele serviciului și veșmintele sfinte pentru preotul Aaron și veșmintele fiilor săi, pentru a servi în serviciul de preot,
àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
11 Și untdelemnul pentru ungere și tămâia dulce pentru locul sfânt: să facă conform cu tot ceea ce ți-am poruncit.
òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
12 Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, spunând:
Olúwa wí fún Mose pé,
13 Vorbește de asemenea copiilor lui Israel, spunând: Negreșit să țineți sabatele mele, căci acesta este un semn între mine și voi prin generațiile voastre; ca să știți că eu sunt DOMNUL care vă sfințește.
“Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
14 Țineți sabatul, căci el vă este sfânt; oricine îl pângărește să fie negreșit dat la moarte, pentru că oricine face vreo lucrare în el, acel suflet să fie stârpit din poporul său.
“‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
15 Șase zile să se facă muncă; dar în a șaptea este sabatul odihnei, sfânt pentru DOMNUL; oricine face vreo muncă în ziua de sabat, negreșit să fie dat la moarte.
Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
16 De aceea copiii lui Israel să țină sabatul, ca să țină sabatul prin generațiile lor, ca legământ continuu.
Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
17 Acesta este un semn între mine și copiii lui Israel pentru totdeauna, pentru că în șase zile DOMNUL a făcut cerul și pământul și în a șaptea zi s-a odihnit și a fost înviorat.
Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
18 Și i-a dat lui Moise, când el a sfârșit de vorbit îndeaproape cu el pe muntele Sinai, două table ale mărturiei, table de piatră, scrise cu degetul lui Dumnezeu.
Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.

< Exod 31 >