< Exod 23 >

1 Să nu ridici vorbire falsă; nu da mâna ta cu cel stricat pentru a fi martor nedrept.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ tan ìròyìn èké kalẹ̀. Ìwọ kò gbọdọ̀ ran ènìyàn búburú lọ́wọ́ láti jẹ́rìí èké.
2 Să nu urmezi o mulțime pentru a face rău; nici nu vorbi într-o cauză abătându-te după mulți ca să strâmbi judecata,
“Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀pọ̀ ènìyàn láti ṣe aburú. Nígbà tí ìwọ bá jẹ́rìí sí ẹjọ́, ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po nípa gbígbé lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ènìyàn.
3 Nici nu favoriza un om sărac în cauza lui.
Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú sí tálákà nínú ẹjọ́ rẹ̀.
4 Dacă întâlnești boul dușmanului tău sau măgarul lui rătăcind, adu-l negreșit înapoi la el.
“Bí ìwọ bá ṣe alábàápàdé akọ màlúù tàbí akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ọ̀tá rẹ tí ó ṣìnà lọ, rí i dájú pé o mú un padà wá fún un.
5 Dacă vezi măgarul celui ce te urăște zăcând sub sarcina lui și te-ai feri să îl ajuți, ajută negreșit împreună cu el.
Bí ìwọ bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹnìkan tí ó kórìíra rẹ tí ẹrù ṣubú lé lórí, má ṣe fi í sílẹ̀ bẹ́ẹ̀; rí i dájú pé o ran án lọ́wọ́ nípa rẹ.
6 Să nu strâmbi judecata săracului tău în cauza lui.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ du aláìní ní ìdájọ́ òdodo.
7 Ține-te departe de orice lucru fals; și pe cel nevinovat și pe cel drept nu îl ucide, pentru că nu voi declara drept pe cel stricat.
Má ṣe lọ́wọ́ nínú ẹ̀sùn èké, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ pa aláìṣẹ̀ tàbí olódodo ènìyàn, nítorí Èmi kò ní dá ẹlẹ́bi láre.
8 Și nu lua niciun dar, pentru că darul orbește pe cel înțelept și pervertește cuvintele celui drept.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
9 De asemenea să nu oprimi pe străin, căci voi știți inima unui străin, întrucât și voi ați fost străini în țara Egiptului.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ pọ́n àjèjì kan lójú, ẹ̀yin sa ti mọ inú àjèjì, nítorí ẹ̀yin náà ti jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ Ejibiti.
10 Și șase ani să îți semeni pământul și să îi aduni roadele;
“Ní ọdún mẹ́fà ni ìwọ yóò gbin oko rẹ, ìwọ yóò sì kóre èso rẹ̀.
11 Dar al șaptelea an lasă-l să se odihnească și să stea nelucrat; ca săracii poporului tău să mănânce; și ce lasă ei, animalele câmpului să mănânce. În același fel să faci cu via ta și cu livada ta de măslini.
Ṣùgbọ́n ní ọdún keje, jẹ́ kí ilẹ̀ náà wà ní àìkọ àti ní àìlò, jẹ́ kí ilẹ̀ náà kí ó sinmi. Nígbà náà ni tálákà láàrín yín yóò rí oúnjẹ láti ibẹ̀. Ẹranko igbó yóò sì jẹ èyí tí wọ́n fi sílẹ̀. Ìwọ ṣe bákan náà pẹ̀lú ọgbà àjàrà rẹ àti ọgbà olifi rẹ.
12 Fă lucrarea ta șase zile și în a șaptea zi odihnește-te, ca boul tău și măgarul tău să se poată odihni, și fiul roabei tale și străinul să fie înviorați.
“Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣe iṣẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì sinmi ní ọjọ́ keje, kí akọ màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ bá à lè ní ìsinmi, kí a sì tú ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àlejò ti ń gbé ni ilé rẹ lára.
13 Și în toate lucrurile pe care vi le-am spus fiți chibzuiți; și nu amintiți numele altor dumnezei, nici să nu fie auzite acestea din gura voastră.
“Ẹ máa ṣọ́ra, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo wí fún un yín. Ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà, kí a má ṣe gbọ́ orúkọ wọn ní ẹnu yín.
14 De trei ori pe an ține-mi o sărbătoare.
“Ní ìgbà mẹ́ta ni ìwọ yóò ṣe àjọ fún mi nínú ọdún.
15 Ține sărbătoarea azimelor (să mănânci azimă șapte zile, așa cum ți-am poruncit, în timpul rânduit al lunii Abib; căci în această lună ai ieșit din Egipt; și nimeni să nu se arate înaintea mea cu mâna goală);
“Ṣe àjọ àkàrà àìwú; jẹ àkàrà ti kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje, bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní àkókò tí a ti yàn ní oṣù Abibu, nítorí ni oṣù yìí ni ìwọ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú mi ní ọwọ́ òfo.
16 Și sărbătoarea secerișului, primele roade ale ostenelilor tale, pe care le-ai semănat în câmp; și sărbătoarea culesului, care este la sfârșitul anului, după ce ai adunat ostenelile tale din câmp.
“Ṣe àjọ ìkórè pẹ̀lú èso àkọ́so ọ̀gbìn oko rẹ. “Ṣe àjọ àkójọ oko rẹ ní òpin ọdún, nígbà tí ìwọ bá kó ìre oko rẹ jọ tan.
17 De trei ori pe an toți cei de parte bărbătească să se prezinte înaintea Domnului DUMNEZEU.
“Ní ìgbà mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni àwọn ọkùnrin yín yóò máa wá fi ara hàn ní iwájú Olúwa Olódùmarè.
18 Să nu oferi sângele sacrificiului meu cu pâine dospită; nici grăsimea sacrificiului meu să nu rămână până dimineața.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ rú ẹbọ ẹ̀jẹ̀ sí mi ti òun ti àkàrà tó ní ìwúkàrà. “Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rá ẹbọ àjọ mi ni kò gbọdọ̀ kù títí di òwúrọ̀.
19 Primul dintre primele roade ale pământului tău, să-l aduci în casa DOMNULUI Dumnezeul tău. Să nu fierbi un ied în laptele mamei lui.
“Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.
20 Iată, trimit un Înger înaintea ta, pentru a te ține pe cale și pentru a te aduce în locul pe care l-am pregătit.
“Kíyèsi èmi rán angẹli kan lọ ní iwájú rẹ, láti ṣọ́ ọ ni ọ̀nà àti láti mú ọ dé ibi ti mo ti pèsè sílẹ̀ fún.
21 Ia seama la el și ascultă de vocea lui; nu îl provoca, fiindcă el nu va ierta fărădelegile voastre, pentru că numele meu este în el.
Fi ara balẹ̀, kí o sì fetísílẹ̀ sí i, kí o sì gba ohùn rẹ̀ gbọ́; má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí i, nítorí kò ní fi àìṣedéédéé yín jì yín, orúkọ mi wà lára rẹ̀.
22 Dar dacă într-adevăr vei asculta de vocea lui și vei face tot ceea ce eu voi spune, atunci voi fi dușman dușmanilor tăi și potrivnic potrivnicilor tăi.
Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí ohùn rẹ̀ tí ẹ sì ṣe ohun gbogbo ti mo ní kí ẹ ṣe, èmi yóò jẹ́ ọ̀tá àwọn ọ̀tá yín. Èmi yóò sì fóòro àwọn tí ń fóòro yín.
23 Pentru că Îngerul meu va merge înaintea ta și te va duce în țara amoriților și hitiților și periziților și canaaniților, hiviților și iebusiților, și îi voi stârpi.
Angẹli mi yóò lọ níwájú rẹ, yóò sì mú ọ dé ọ̀dọ̀ àwọn ará: Amori, Hiti, Peresi, Kenaani, Hifi àti Jebusi, èmi a sì gé wọn kúrò.
24 Să nu te prosterni înaintea dumnezeilor lor, nici să nu le servești, nici să nu faci conform lucrării lor, ci dărâmă-i complet și sparge idolii lor în întregime.
Ìwọ kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ fún òrìṣà wọn, bẹ́ẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n, tàbí kí ẹ tẹ̀lé ìṣe wọn. Kí ìwọ kí ó si wó wọn lulẹ̀, kí ìwọ kí ó sì fọ́ ère òkúta wọ́n túútúú.
25 Și veți servi DOMNULUI Dumnezeul vostru și el va binecuvânta pâinea ta și apa ta; și voi înlătura boala din mijlocul tău.
Ẹ̀yin yóò sí máa sin Olúwa Ọlọ́run yin, òun yóò si bùsi oúnjẹ rẹ. Èmi yóò mú àìsàn kúrò láàrín rẹ.
26 Nimic nu își va lepăda pruncii, nici nu vor fi sterpe în țara ta; numărul zilelor tale îl voi împlini.
Oyún kò ní bàjẹ́ lára obìnrin kan, bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan kì yóò yàgàn ni ilẹ̀ rẹ. Èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.
27 Voi trimite frica mea înaintea ta și voi nimici toate popoarele la care vei ajunge și voi face pe toți dușmanii tăi să își întoarcă spatele spre tine.
“Èmi yóò rán ẹ̀rù mi lọ ṣáájú rẹ, ìdàrúdàpọ̀ yóò sì wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ bá da ojú kọ. Èmi yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ yí ẹ̀yìn padà sí ọ, kí wọn sì sá ní iwájú rẹ.
28 Și voi trimite viespi înaintea ta, care vor alunga pe hivit, pe canaanit și pe hitit, de dinaintea ta.
Èmi yóò rán oyin ṣáájú rẹ láti lé àwọn ará: Hifi, Kenaani àti Hiti kúrò ni ọ̀nà rẹ.
29 Nu îi voi alunga de dinaintea ta într-un an, ca nu cumva țara să devină pustie și fiarele câmpului să se înmulțească împotriva ta.
Ṣùgbọ́n, Èmi kò ni lé gbogbo wọn jáde ni ọdún kan ṣoṣo, ki ilẹ̀ náà má ba à di ahoro, àwọn ẹranko búburú yóò sì ti pọ̀jù fún ọ.
30 Puțin câte puțin îi voi alunga de dinaintea ta, până când te vei fi înmulțit și vei moșteni pământul.
Díẹ̀díẹ̀ ni èmi yóò máa lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ, títí ìwọ yóò fi pọ̀ tó láti gba gbogbo ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ìní.
31 Și voi așeza granițele tale de la Marea Roșie până la marea filistenilor și de la deșert până la râu, căci voi preda pe locuitorii acelui pământ în mâna voastră, ca să îi alungi de dinaintea ta.
“Èmi yóò fi ìdí òpin ààlà ilẹ̀ rẹ lélẹ̀ láti etí Òkun Pupa títí dé òkun àwọn ara Filistini, láti aṣálẹ̀ títí dé etí odò Eufurate, Èmi yóò fa àwọn ènìyàn ti ń gbé ilẹ̀ náà lé ọ lọ́wọ́, ìwọ yóò sì lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ.
32 Nu fă legământ cu ei, nici cu dumnezeii lor.
Ìwọ kò gbọdọ̀ dá májẹ̀mú kankan pẹ̀lú wọn tàbí pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn.
33 Nu vor locui în țara ta, ca nu cumva să te facă să păcătuiești împotriva mea; căci dacă servești dumnezeii lor, cu adevărat aceasta va fi o cursă pentru tine.
Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn gbé ni ilẹ̀ rẹ, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn yóò mú ọ dẹ́ṣẹ̀ sí mi: nítorí bí ìwọ bá sin òrìṣà wọn, èyí yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fun ọ nítòótọ́.”

< Exod 23 >