< Exod 13 >

1 Și DOMNUL i-a spus lui Moise, zicând:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Sfințiți-mi pe fiecare întâi născut, pe oricine deschide pântecele printre copiii lui Israel, deopotrivă al omului și al vitei: acesta este al meu.
“Ẹ ya àwọn àkọ́bí yín ọkùnrin sọ́tọ̀ fún mi. Èyí ti ó bá jẹ́ àkọ́bí láàrín àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ tèmi, ìbá à ṣe ènìyàn tàbí ẹranko.”
3 Și Moise a spus poporului: Amintiți-vă această zi, în care ați ieșit din Egipt, din casa robiei, pentru că prin tăria mâinii DOMNUL v-a scos din acest loc: nu se va mânca pâine dospită.
Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ rántí ọjọ́ òní, ọjọ́ ti ẹ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin ti ń ṣe ẹrú, nítorí Olúwa mú un yín jáde kúrò ni inú rẹ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára. Ẹ má ṣe jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú.
4 Astăzi ați ieșit în luna Abib.
Òní, ní oṣù Abibu (oṣù kẹta ọdún tiwa) lónìí ẹ̀yin ń jáde kúrò ní Ejibiti.
5 Și va fi, când DOMNUL te va aduce în țara canaaniților și a hitiților și a amoriților și a hiviților și a iebusiților, pe care el a jurat părinților tăi să ți-o dea, o țară în care curge lapte și miere, că în această lună vei ține acest serviciu.
Ní ìgbà tí Olúwa mú un yín jáde wá sí ilẹ̀ Kenaani, Hiti, Amori, Hifi àti ilẹ̀ àwọn Jebusi; ilẹ̀ tí ó ti ṣe búra láti fi fún àwọn baba ńlá yín, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ẹ ni láti pa ìsìn yìí mọ́ ní oṣù yìí.
6 Șapte zile să mănânci azime și în a șaptea zi să fie o sărbătoare pentru DOMNUL.
Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà nínú àti pé ní ọjọ́ keje ni àjọ yóò wà fún Olúwa.
7 Azime să fie mâncate șapte zile; și să nu fie văzută pâine dospită la tine, nici nu va fi văzută dospeală cu tine în toate hotarele tale.
Kí ẹ̀yin ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje yìí; kó má ṣe sí ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe ní sàkání yín.
8 Și să arăți fiului tău în acea zi, spunând: Aceasta se face din cauza a ceea ce DOMNUL mi-a făcut când eu am ieșit afară din Egipt.
Ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò sì sọ fún àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin, ‘Mo ń ṣe èyí nítorí ohun tí Olúwa ṣe fún mi nígbà tí èmi jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.’
9 Și aceasta să îți fie ca semn pe mâna ta și pentru o amintire între ochii tăi, ca legea DOMNULUI să fie în gura ta, căci cu mână puternică DOMNUL te-a scos din Egipt.
Ṣíṣe èyí yóò wà fún àmì ní ọwọ́ rẹ, àti bí àmì ìrántí ni iwájú orí rẹ, tí yóò máa rán ọ létí òfin Olúwa ní ẹnu rẹ. Nítorí Olúwa mú ọ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá rẹ̀.
10 De aceea ține această rânduială la timpul ei din an în an.
Ìwọ gbọdọ̀ pa òfin náà mọ́ ní àkókò tí a yàn bí ọdún tí ń gorí ọdún.
11 Și va fi, când DOMNUL te va aduce în țara canaaniților, precum a jurat părinților tăi și ți-o va da,
“Lẹ́yìn tí Olúwa tí mú ọ wá sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani tí ó sì fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí pẹ̀lú ìbúra fún ọ àti fún àwọn baba ńlá rẹ̀,
12 Că vei pune deoparte pentru DOMNUL tot ceea ce deschide pântecele și fiecare întâi născut care vine de la un animal pe care îl ai; cei de parte bărbătească vor fi ai DOMNULUI.
ìwọ yóò fi àkọ́bí inú rẹ fún Olúwa. Gbogbo àkọ́bí ti ó jẹ́ akọ ti ẹran ọ̀sìn rẹ ní ó jẹ́ ti Olúwa.
13 Și pe fiecare întâi născut al unui măgar să îl răscumperi cu un miel; și dacă refuzi să îl răscumperi, atunci să îi rupi gâtul; să îl răscumperi și pe fiecare întâi născut al omului dintre copiii tăi.
Ìwọ yóò fi ọ̀dọ́-àgùntàn ra àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, ǹjẹ́ kí ìwọ ṣẹ́ ẹ ní ọrùn, gbogbo àkọ́bí ọkùnrin ni kí ìwọ kí ó rà padà.
14 Și va fi, când fiul tău te va întreba în timpul care vine, spunând: Ce este aceasta? Că îi vei zice: DOMNUL ne-a scos cu mână tare din Egipt, din casa robiei:
“Yóò sí ṣe ní àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín yóò béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni èyí túmọ̀ sí?’ Kí ìwọ kí ó sọ fún wọn pé, ‘Pẹ̀lú ọwọ́ agbára ní Olúwa fi mú wa jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní oko ẹrú.
15 Și s-a întâmplat, când Faraon se încăpățâna să ne lase să plecăm, că DOMNUL a ucis pe toți întâii-născuți din țara Egiptului, deopotrivă întâii-născuți ai oamenilor și întâii-născuți ai animalelor; de aceea eu sacrific DOMNULUI tot ceea ce deschide pântecele, fiind de parte bărbătească; dar pe toți întâii-născuți ai copiilor mei îi răscumpăr.
Ní ìgbà ti Farao ṣe orí kunkun, ti ó kọ̀ láti jẹ́ kí a lọ, Olúwa pa gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, àti ènìyàn àti ẹranko. Ìdí èyí ni àwa fi ń fi gbogbo àkọ́bí tí í ṣe akọ rú ẹbọ sí Olúwa láti fi ṣe ìràpadà fún àwọn àkọ́bí wa ọkùnrin.’
16 Și va fi ca semn pe mâna ta și ca fruntarii între ochii tăi; căci prin puterea mâinii DOMNUL ne-a scos din Egipt.
Èyí yóò sì jẹ́ àmì ni ọwọ́ yín àti àmì ní iwájú orí yín pé Olúwa mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá.”
17 Și s-a întâmplat, când Faraon a lăsat poporul să plece, că Dumnezeu nu i-a condus pe calea țării filistenilor, deși aceea era aproape; fiindcă Dumnezeu a spus: Nu cumva să se întâmple ca poporul să se pocăiască văzând război și să se întoarcă în Egipt;
Ní ìgbà tí Farao jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ, Ọlọ́run kò mú wọn tọ ojú ọ̀nà ti ó la orílẹ̀-èdè àwọn Filistini kọjá, bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀nà náà kúrú. Nítorí Ọlọ́run sọ pé, “Bí wọ́n bá dojúkọ ogun, wọ́n lè yí ọkàn wọn padà kí wọ́n padà sí ilẹ̀ Ejibiti.”
18 Ci Dumnezeu a condus poporul pe calea pustiei Mării Roșii; și copiii lui Israel au urcat înarmați din Egipt.
Nítorí náà Ọlọ́run darí àwọn ènìyàn rọkọ gba ọ̀nà aginjù ní apá Òkun Pupa. Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ìmúra fún ogun.
19 Și Moise a luat oasele lui Iosif cu el, pentru că acesta luase jurământ copiilor lui Israel, spunând: Dumnezeu cu adevărat vă va vizita; și veți urca cu voi oasele mele de aici.
Mose kó egungun Josẹfu pẹ̀lú rẹ̀ nítorí Josẹfu tí mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra. Ó ti wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò dìde fún ìrànlọ́wọ́ yín ẹ sì gbọdọ̀ kó egungun mi lọ pẹ̀lú yín kúrò níhìn-ín yìí.”
20 Și au început călătoria lor de la Sucot și au așezat tabără în Etam, în marginea pustiei.
Wọ́n sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n láti Sukkoti lọ, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu ní etí aginjù.
21 Și DOMNUL a mers înaintea lor ziua într-un stâlp de nor, pentru a le conduce calea; și noaptea într-un stâlp de foc, pentru a le dea lumină; pentru a merge zi și noapte;
Olúwa sì ń lọ níwájú wọn, nínú ọ̀wọ̀n ìkùùkuu ní ọ̀sán láti máa ṣe amọ̀nà wọn àti ní òru nínú ọ̀wọ̀n iná láti máa tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn, kí wọn lè máa lọ nínú ìrìnàjò wọn ní tọ̀sán tòru.
22 El nu a depărtat stâlpul de nor ziua, nici stâlpul de foc noaptea, dinaintea poporului.
Ìkùùkuu náà kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ní ọ̀sán, bẹ́ẹ̀ ni, ọ̀wọ̀n iná kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ni òru, ní iwájú àwọn ènìyàn náà.

< Exod 13 >