< Esther 4 >
1 Când Mardoheu a priceput tot ce s-a făcut, Mardoheu şi-a sfâşiat hainele şi s-a îmbrăcat în pânză de sac cu cenuşă, şi a ieşit în mijlocul cetăţii, şi a plâns tare şi cu amărăciune.
Nígbà tí Mordekai gbọ́ gbogbo nǹkan tí ó ṣẹlẹ̀, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì fi eérú kun ara, ó jáde lọ sí inú ìlú ó kígbe sókè ó sì sọkún kíkorò.
2 Şi a venit până în faţa porţii împăratului, căci nimeni nu putea intra pe poarta împăratului îmbrăcat cu pânză de sac.
Ṣùgbọ́n ó lọ sí ẹnu-ọ̀nà ọba nìkan, nítorí kò sí ẹnìkan tí ó wọ aṣọ ọ̀fọ̀ tì a gbà láààyè láti wọ ibẹ̀.
3 Şi în fiecare provincie, oriunde ajungea porunca împăratului şi hotărârea sa, a fost mare jale printre iudei, şi post şi plâns şi strigăte; şi mulţi zăceau în pânză de sac şi cenuşă.
Ní gbogbo ìgbèríko tí àṣẹ ikú ọba dé, ọ̀fọ̀ ńlá dé bá àwọn Júù, pẹ̀lú àwẹ̀, ẹkún àti ìpohùnréré ẹkún. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wà nínú aṣọ ọ̀fọ̀ tí wọ́n fi eérú kúnra.
4 Şi servitoarele Esterei şi famenii ei au venit şi i-au spus aceasta. Atunci împărăteasa a fost foarte mâhnită; şi a trimis haine să îl îmbrace pe Mardoheu, şi să îi ia pânza de sac de pe el, dar el nu a primit.
Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ìwẹ̀fà Esteri wá, wọ́n sọ nípa Mordekai fún un, ayaba sì wà nínú ìbànújẹ́ ńlá. Ó fi aṣọ ránṣẹ́ sí i kí ó wọ̀ ọ́ dípò aṣọ ọ̀fọ̀ tí ó wọ̀, ṣùgbọ́n òun kò gbà wọ́n.
5 Atunci Estera a chemat pe Hatac, unul dintre famenii împăratului, pe care l-a rânduit să aibă grijă de ea, şi i-a dat o poruncă pentru Mardoheu, să afle ce este şi de ce.
Nígbà náà ni Esteri pe Hataki, ọ̀kan nínú àwọn ìwẹ̀fà ọba tí a yàn láti máa jíṣẹ́ fún un, ó pàṣẹ fún un pé kí ó béèrè ohun tí ó ń dààmú Mordekai àti ohun tí ó ṣe é.
6 Astfel Hatac a mers la Mardoheu până în piaţa cetăţii, care era înaintea porţii împăratului.
Bẹ́ẹ̀ ni Hataki jáde lọ bá Mordekai ní ìta gbangba ìlú níwájú ẹnu-ọ̀nà ọba.
7 Şi Mardoheu i-a spus tot ceea ce i s-a întâmplat, şi despre suma de bani pe care Haman a promis să o plătească trezoreriilor împăratului pentru iudei, pentru a-i nimici.
Mordekai sọ ohun gbogbo tí ó ṣẹlẹ̀ fún un, papọ̀ pẹ̀lú iye owó tí Hamani ti ṣe ìpinnu láti san sínú àpò ìṣúra ọba fún ìparun àwọn Júù.
8 De asemenea i-a dat copia înscrisului hotărârii, dată în Susa pentru a-i nimici, pentru a fi arătată Esterei, şi să îi spună şi să îi poruncească să intre la împărat, să îl roage şi să facă cerere înaintea lui pentru poporul ei.
Ó sì tún fún un ní ọ̀kan lára ìwé tí ó gbé jáde fún ìparun wọn, èyí tí a tẹ̀ jáde ní Susa, láti fihan Esteri kí ó sì ṣe àlàyé e rẹ̀ fún un, ó sì sọ fún un pé kí ó bẹ̀ ẹ́ kí ó lọ síwájú ọba láti bẹ̀bẹ̀ fún àánú, kí ó bẹ̀bẹ̀ nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀.
9 Şi Hatac a venit şi a spus Esterei cuvintele lui Mardoheu.
Hataki padà ó sì lọ ṣàlàyé fún Esteri ohun tí Mordekai sọ.
10 Estera a vorbit din nou lui Hatac şi i-a dat porunca pentru Mardoheu.
Nígbà náà ni Esteri pàṣẹ fún Hataki pé kí ó sọ fún Mordekai,
11 Toţi servitorii împăratului şi oamenii din provinciile împăratului, ştiu că oricine, fie bărbat, fie femeie, care va intra la împărat în curtea dinăuntru, fără să fie chemat, este o singură lege a împăratului, să fie ucis, cu excepţia celui căruia împăratul îi întinde sceptrul său aurit, ca el să trăiască; iar eu nu am fost chemată la împărat în aceste treizeci de zile.
“Gbogbo àwọn ìjòyè ọba àti àwọn ènìyàn agbègbè ìjọba rẹ̀ mọ̀ wí pé: fún ẹnikẹ́ni ọkùnrin tàbí obìnrin kan tàbí tí ó bá bá ọba sọ̀rọ̀ láìjẹ́ pé a ránṣẹ́ pè é (ọba ti gbé òfin kan kalẹ̀ pé) kíkú ni yóò kú. Ohun kan tí ó le yẹ èyí ni pé, kí ọba na ọ̀pá wúrà rẹ̀ sí i kí ó sì dá ẹ̀mí rẹ sí. Ṣùgbọ́n, ọgbọ̀n ọjọ́ ti kọjá tí a ti pè mí láti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba.”
12 Şi i-au spus lui Mardoheu cuvintele Esterei.
Nígbà tí a sọ ọ̀rọ̀ Esteri fún Mordekai,
13 Atunci Mardoheu i-a poruncit să răspundă Esterei: Nu gândi în tine însuţi că numai tu vei scăpa în casa împăratului dintre toţi iudeii.
nígbà náà ni Mordekai sọ kí a dá Esteri lóhùn pé, “Má ṣe rò nínú ara rẹ pé nítorí pé ìwọ wà ní ilé ọba ìwọ nìkan là láàrín gbogbo àwọn Júù.
14 Căci dacă tu vei tăcea cu totul în acest timp, ajutorul şi eliberarea iudeilor se va ridica din altă parte; dar tu şi casa tatălui tău veţi fi nimiciţi; şi cine ştie dacă nu ai venit la împărăţie tocmai pentru un timp ca acesta?
Nítorí bí ìwọ bá dákẹ́ ní àkókò yìí, ìrànlọ́wọ́ àti ìtúsílẹ̀ fún àwọn Júù yóò dìde láti ibòmíràn, ṣùgbọ́n ìwọ àti àwọn ìdílé baba à rẹ yóò ṣègbé. Ta ni ó mọ̀ wí pé nítorí irú àkókò yìí ni o ṣe wà ní ipò ayaba?”
15 Apoi Estera le-a cerut să ducă acest răspuns înapoi lui Mardoheu.
Nígbà náà ni Esteri rán iṣẹ́ yìí sí Mordekai:
16 Du-te, adună toţi iudeii care se află în Susa şi postiţi pentru mine, şi nici nu mâncaţi nici nu beţi trei zile, noapte sau zi; de asemenea eu şi servitoarele mele vom posti la fel; şi astfel voi merge la împărat, ceea ce nu este conform legii: şi dacă voi pieri, voi pieri.
“Lọ, kí o kó gbogbo àwọn Júù tí ó wà ní Susa jọ, kí ẹ sì gbààwẹ̀ fún mi. Ẹ má ṣe jẹun tàbí omi fún ọjọ́ mẹ́ta, ní òru àti ní ọ̀sán. Èmi àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi náà yóò gbààwẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin náà ti ṣe. Nígbà tí ẹ bá ṣe èyí, èmi yóò tọ ọba lọ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó lòdì sí òfin. Bí mo bá sì ṣègbé, mo ṣègbé.”
17 Şi Mardoheu a plecat pe drumul lui, şi a făcut conform cu tot ceea ce Estera i-a poruncit.
Bẹ́ẹ̀ ni Mordekai lọ, ó sì sọ gbogbo ohun tí Esteri pàṣẹ fún un.