< Eclesiastul 8 >

1 Cine este ca înțeleptul? Și cine cunoaște interpretarea unui lucru? Înțelepciunea unui om îi face fața să strălucească, și cutezanța feței lui va fi schimbată.
Ta ni ó dàbí ọlọ́gbọ́n ènìyàn? Ta ni ó mọ ìtumọ̀ ohun gbogbo? Ọgbọ́n a máa mú ojú ènìyàn dán ó sì máa ń pààrọ̀ ìrínisí rẹ̀.
2 Eu te sfătuiesc să ții poruncile împăratului, și aceasta în privința jurământului lui Dumnezeu.
Mo sọ wí pé, pa òfin ọba mọ́, nítorí pé, ìwọ ti ṣe ìbúra níwájú Ọlọ́run.
3 Nu te grăbi să pleci dinaintea lui; nu stărui într-un lucru rău, fiindcă el face orice îi place.
Má ṣe jẹ́ kí ojú kán ọ láti kúrò ní iwájú ọba, má ṣe dúró nínú ohun búburú, nítorí yóò ṣe ohunkóhun tí ó bá tẹ́ ẹ lọ́rùn.
4 Unde este cuvântul unui împărat, este putere; și cine îi va spune: Ce faci?
Níwọ́n ìgbà tí ọ̀rọ̀ ọba ni àṣẹ, ta ni ó le è sọ fún un wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe?”
5 Oricine ține porunca nu va simți vreun lucru rău, și inima unui înțelept discerne deopotrivă timpul și judecata.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa àṣẹ rẹ̀ mọ́, kò ní wá sí ìpalára kankan, àyà ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò sì mọ àsìkò tí ó tọ́ àti ọ̀nà tí yóò gbà ṣe é.
6 Deoarece pentru fiecare scop este un timp și o judecată, de aceea nenorocirea omului este mare asupra lui.
Ohun gbogbo ni ó ní àsìkò àti ọ̀nà tí ó tọ́ láti ṣe, ṣùgbọ́n, òsì ènìyàn pọ̀ sí orí ara rẹ̀.
7 Fiindcă nu știe ceea ce va fi, căci cine îi poate spune când va fi?
Níwọ́n ìgbà tí kò sí ẹni tí ó mọ ọjọ́-ọ̀lá, ta ni ó le è sọ fún un ohun tí ó ń bọ̀?
8 Nu este om care să aibă stăpânire asupra duhului să păstreze duhul; nici nu are putere în ziua morții și nu este eliberare în acel război; nici stricăciunea nu va elibera pe cei ce îi sunt dați ei.
Kò sí ẹni tí ó lágbára lórí afẹ́fẹ́ láti gbà á dúró, nítorí náà, kò sí ẹni tí ó ní agbára lórí ọjọ́ ikú rẹ̀. Bí ó ti jẹ́ wí pé kò sí ẹni tí a dá sílẹ̀ nígbà ogun, bẹ́ẹ̀ náà ni ìkà kò ní fi àwọn tí ó ń ṣe é sílẹ̀; bí ó ti jẹ́ wí pé kò sí ẹni tí a dá sílẹ̀ nígbà ogun, bẹ́ẹ̀ náà ni ìwà búburú kò le gba àwọn tí ó ń ṣe é sílẹ̀.
9 Toate acestea le-am văzut și mi-am dedicat inima fiecărei lucrări ce se face sub soare, este un timp în care un om stăpânește peste altul spre propria vătămare.
Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni mo ti rí, tí mo sì ń múlò ní ọkàn mi sí gbogbo iṣẹ́ tí a ti ṣe lábẹ́ oòrùn. Ìgbà kan wà tí ẹnìkan ń ṣe olórí àwọn tókù fún ìpalára rẹ̀.
10 Și astfel am văzut pe cei stricați îngropați, care au venit și au plecat din locul cel sfânt și au fost uitați în cetatea în care ei au făcut așa, aceasta este de asemenea deșertăciune.
Nígbà náà ni mo tún rí ìsìnkú ènìyàn búburú—àwọn tí wọ́n máa ń wá tí wọ́n sì ń lọ láti ibi mímọ́ kí wọn sì gba ìyìn ní ìlú tàbí tí wọ́n ti ṣe èyí. Eléyìí pẹ̀lú kò ní ìtumọ̀.
11 Pentru că sentința împotriva unei lucrări rele nu se execută în grabă, de aceea inima fiilor oamenilor este deplin așezată în ei pentru a face rău.
Nígbà tí a kò bá tètè ṣe ìdájọ́ fún ẹlẹ́ṣẹ̀ kíákíá, ọkàn àwọn ènìyàn a máa kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìmọ̀ láti ṣe ibi.
12 Deși un păcătos face rău de o sută de ori și zilele lui sunt prelungite, totuși eu știu cu siguranță că le va fi bine celor ce se tem de Dumnezeu, care se tem înaintea lui,
Bí ènìyàn búburú tó dẹ́ṣẹ̀ nígbà ọgọ́rùn-ún tilẹ̀ wà láààyè fún ìgbà pípẹ́, mo mọ̀ wí pé yóò dára fún ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó bẹ̀rù níwájú rẹ̀.
13 Dar nu îi va fi bine celui stricat, nici nu își va prelungi zilele, care sunt ca o umbră, pentru că el nu se teme înaintea lui Dumnezeu.
Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dára fún ènìyàn búburú, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fa ọjọ́ rẹ̀ gún tí ó dà bí òjìji, nítorí tí kò bẹ̀rù níwájú Ọlọ́run.
14 Este o deșertăciune făcută pe pământ: că sunt drepți, cărora li se întâmplă conform lucrării celor stricați; și sunt stricați, cărora li se întâmplă conform lucrării celor drepți; am spus că și aceasta este deșertăciune.
Ohun mìíràn tún wà tí kò ní ìtumọ̀, tí ó ń ṣẹlẹ̀ láyé olódodo tí ó ń gba ohun tí ó tọ́ sí òṣìkà àti ènìyàn búburú tí ó ń gba ohun tí ó tọ́ sí olódodo. Mo sọ wí pé eléyìí gan an kò ní ìtumọ̀.
15 Atunci am lăudat veselia, pentru că un om nu are ceva mai bun sub soare, decât să mănânce și să bea și să fie fericit, pentru că aceasta va rămâne cu el din munca lui în zilele vieții sale, pe care Dumnezeu i le dă sub soare.
Nítorí náà mo kan sáárá sí ìgbádùn ayé, nítorí pé kò sí ohun tí ó dára fún ènìyàn ní abẹ́ oòrùn ju pé kí ó jẹ, kí ó mu, kí inú rẹ̀ sì dùn lọ. Nígbà náà ni ìdùnnú yóò bá a rìn nínú iṣẹ́ ẹ rẹ̀, ní gbogbo ọjọ́ ayé ti Ọlọ́run tí fi fún un lábẹ́ oòrùn.
16 Când mi-am dedicat inima să cunosc înțelepciunea și să văd lucrarea făcută pe pământ; (fiindcă de asemenea nici zi nici noapte nu vede somn cu ochii lui),
Nígbà tí mo lo ọkàn mi láti mọ ọgbọ́n àti láti wo wàhálà ènìyàn ní ayé.
17 Atunci am privit toată lucrarea lui Dumnezeu, că un om nu poate afla lucrarea ce este făcută sub soare, deși un om se ostenește să o caute, nu o va găsi; da, mai mult, oricât ar gândi un înțelept pentru a o cunoaște, nu va fi în stare să o găsească.
Nígbà náà ni mo rí gbogbo ohun tí Ọlọ́run tí ṣe, kò sí ẹnìkan tí ó le è mòye ohun tí ó ń lọ lábẹ́ oòrùn. Láìbìkítà gbogbo ìyànjú rẹ̀ láti wá rí jáde, ènìyàn kò le è mọ ìtumọ̀ rẹ̀, kódà bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn rò wí pé òun mọ̀ ọ́n, kò le è ní òye rẹ̀ ní pàtó.

< Eclesiastul 8 >