< Deuteronomul 6 >

1 Acum acestea sunt poruncile, statutele şi judecăţile, pe care a poruncit DOMNUL Dumnezeul vostru să vă învăţ să le împliniţi în ţara în care mergeţi să o stăpâniţi;
Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí Olúwa Ọlọ́run yín pàṣẹ fún mi láti kọ́ ọ yín kí ẹ lè kíyèsi i, ní ilẹ̀ náà tí ẹ ó ni lẹ́yìn tí ẹ bá kọjá a Jordani.
2 Ca să te temi de DOMNUL Dumnezeul tău, să ţii toate statutele lui şi poruncile lui, pe care ţi le poruncesc, tu şi fiul tău şi fiul fiului tău, în toate zilele vieţii tale; şi ca să ţi se lungească zilele.
Kí ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn, lẹ́yìn wọn bá à lè bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá wà láyé, nípa pípa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ tí mo fún un yín mọ́, kí ẹ bá à lè pẹ́ lórí ilẹ̀.
3 Ascultă de aceea, Israele, şi ia seama să le împlineşti; ca să îţi fie bine şi ca să creşteţi foarte mult, precum ţi-a spus DOMNUL Dumnezeul părinţilor tăi, în ţara în care curge lapte şi miere.
Gbọ́ ìwọ Israẹli, kí o sì ṣọ́ra láti gbọ́rọ̀, kí ó bá à lè dára fún ọ, kí o bá à lè gbilẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ní ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba rẹ ti ṣèlérí fún ọ.
4 Ascultă, Israele, DOMNUL Dumnezeul nostru este un singur DOMN;
Gbọ́ ìwọ Israẹli, Olúwa Ọlọ́run wa, Olúwa kan ni.
5 Şi să iubeşti pe DOMNUL Dumnezeul tău cu toată inima ta şi cu tot sufletul tău şi cu toată puterea ta.
Fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ.
6 Şi aceste cuvinte, pe care ţi le poruncesc astăzi, să fie în inima ta;
Àwọn àṣẹ tí mo fún un yín lónìí gbọdọ̀ máa wà lóókan àyà yín.
7 Şi să le întipăreşti în copiii tăi şi să vorbeşti despre ele când şezi în casa ta şi când mergi pe cale şi când te culci şi când te scoli.
Ẹ fi kọ́ àwọn ọmọ yín gidigidi. Bí ẹ bá jókòó nínú ilé, ẹ jíròrò nípa wọn, àti nígbà tí ẹ bá ń rìn ní ojú ọ̀nà, bí ẹ bá dùbúlẹ̀ àti nígbà tí ẹ bá dìde.
8 Şi să le legi ca semn pe mâna ta şi să îţi fie ca fruntarii între ochii tăi.
Ẹ so wọ́n sí ọwọ́ yín fún àmì, ẹ so ó mọ́ iwájú orí yín.
9 Şi să le scrii pe uşorii casei tale şi pe porţile tale.
Kí ìwọ kí ó kọ wọ́n sára òpó ilé rẹ̀, àti sí ara ìlẹ̀kùn ọ̀nà òde rẹ.
10 Şi se va întâmpla, când DOMNUL Dumnezeul tău te va fi adus în ţara pe care a jurat-o părinţilor tăi, lui Avraam, lui Isaac şi lui Iacob, că îţi va da cetăţi mari şi frumoase, pe care nu tu le-ai zidit,
Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá mú yín dé ilẹ̀ náà tí ó ti búra fún àwọn baba yín, fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu láti fi fún un yín, ilẹ̀ tí ó kún fún àwọn ìlú ńlá ńlá tí kì í ṣe ẹ̀yin ló kọ́ ọ,
11 Şi case pline de toate bunătăţile, pe care nu tu le-ai umplut, şi fântâni săpate, pe care nu tu le-ai săpat, vii şi măslini, pe care nu tu i-ai sădit; după ce vei mânca şi te vei sătura,
àwọn ilé tí ó kún fún gbogbo ohun mèremère tí kì í ṣe ẹ̀yin ló rà wọ́n, àwọn kànga tí ẹ kò gbẹ́, àti àwọn ọgbà àjàrà àti èso olifi tí kì í ṣe ẹ̀yin ló gbìn wọ́n. Nígbà tí ẹ bá jẹ tí ẹ sì yó,
12 Ia seama ca nu cumva să uiţi pe DOMNUL, care te-a scos din ţara Egiptului, din casa robiei.
ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé Olúwa, tí o mú un yín jáde láti Ejibiti wá, kúrò ní oko ẹrú.
13 Să te temi de DOMNUL Dumnezeul tău şi să îi serveşti şi să juri pe numele lui.
Bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ, Òun nìkan ni kí o sì máa sìn, búra ní orúkọ rẹ̀ nìkan.
14 Să nu umblaţi după alţi dumnezei, dintre dumnezeii popoarelor care sunt împrejurul vostru;
Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run àwọn tí ó yí i yín ká;
15 (Pentru că DOMNUL Dumnezeul tău este un Dumnezeu gelos printre voi) ca nu cumva să se aprindă mânia DOMNULUI Dumnezeul tău împotriva ta şi să te nimicească de pe faţa pământului.
torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run owú ni, ìbínú rẹ̀ yóò sì run yín kúrò ní ilẹ̀ náà.
16 Să nu ispitiţi pe DOMNUL Dumnezeul vostru, precum l-aţi ispitit la Masa.
Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run yín wò bí ẹ̀yin ti dán wò ní Massa.
17 Să păziţi cu atenţie poruncile DOMNULUI Dumnezeul vostru şi mărturiile lui şi statutele lui, pe care ţi le-a poruncit.
Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń pa àwọn òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́ àti àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà tí ó ti fún un yín.
18 Şi să faci ce este drept şi bine înaintea ochilor DOMNULUI, ca să îţi fie bine şi să intri şi să stăpâneşti ţara cea bună, pe care DOMNUL a jurat-o părinţilor tăi,
Ẹ ṣe èyí tí ó dára tí ó sì tọ́ lójú Olúwa, kí ó bá à lè dára fún un yín, kí ẹ̀yin bá à lè lọ láti gba ilẹ̀ dáradára náà tí Ọlọ́run ti fi ìbúra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín.
19 Alungând pe toţi duşmanii tăi dinaintea ta, precum a vorbit DOMNUL.
Ẹ̀yin yóò sì ti àwọn ọ̀tá yín jáde níwájú u yín bí Olúwa ti ṣèlérí.
20 Şi când te va întreba fiul tău în viitor, spunând: Ce înseamnă mărturiile şi statutele şi judecăţile pe care vi le-a poruncit DOMNUL Dumnezeul nostru?
Ní ọjọ́ iwájú, bí ọmọ rẹ bá béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin wọ̀nyí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún ọ?”
21 Atunci să spui fiului tău: Eram robi ai lui Faraon în Egipt; şi DOMNUL ne-a scos din Egipt cu mână puternică,
Sọ fún un pé: “Ẹrú Farao ní ilẹ̀ Ejibiti ni wá tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa fi ọwọ́ agbára ńlá yọ wá jáde lóko ẹrú Ejibiti.
22 Şi înaintea ochilor noştri DOMNUL a arătat semne şi minuni mari şi grozave asupra Egiptului, asupra lui Faraon şi asupra întregii lui case,
Lójú wa ni Olúwa tí ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu: tí ó lágbára tí ó sì ba ni lẹ́rù: lórí Ejibiti àti Farao, àti gbogbo ènìyàn rẹ̀.
23 Şi ne-a scos de acolo, ca să ne aducă aici, să ne dea ţara pe care a jurat-o părinţilor noştri.
Ṣùgbọ́n ó mú wa jáde láti ibẹ̀ wá láti mú wa wọ inú àti láti fún wa ní ilẹ̀ tí ó ti fì búra fún àwọn baba ńlá wa.
24 Şi DOMNUL ne-a poruncit să împlinim toate aceste statute, să ne temem de DOMNUL Dumnezeul nostru, spre binele nostru totdeauna, ca să ne păstreze în viaţă, ca în ziua aceasta.
Olúwa pàṣẹ fún wa láti ṣe ìgbọ́ràn sí gbogbo ìlànà wọ̀nyí, láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, kí ó ba à lè máa dára fún wa nígbà gbogbo, kí a sì lè wà láyé, bí a ṣe wà títí di òní.
25 Şi aceasta va fi dreptatea noastră, dacă vom lua seama să împlinim toate aceste porunci înaintea DOMNULUI Dumnezeul nostru, precum ne-a poruncit.
Bí a bá ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin wọ̀nyí mọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, bí ó ti pàṣẹ fún wa, èyí ni yóò máa jẹ́ òdodo wa.”

< Deuteronomul 6 >