< Deuteronomul 5 >

1 Şi Moise a chemat tot Israelul şi le-a spus: Ascultă, Israele, statutele şi judecăţile pe care le vorbesc astăzi în urechile voastre, ca să le învăţaţi şi să le ţineţi şi să le împliniţi.
Mose sì pe gbogbo Israẹli jọ, ó sì wí pé, Gbọ́ ìwọ Israẹli, gbọ́ ìlànà àti òfin tí mo mú wá sí etí ìgbọ́ ọ yín lónìí. Ẹ kọ wọ́n, kí ẹ sì ri dájú pé ẹ̀ ń ṣe wọ́n.
2 DOMNUL Dumnezeul nostru a făcut cu noi un legământ în Horeb.
Olúwa Ọlọ́run wa bá wa dá májẹ̀mú ní Horebu.
3 Nu cu părinţii noştri a făcut DOMNUL acest legământ, ci cu noi, adică cu noi, toţi aceştia care suntem în viaţă astăzi.
Kì í ṣe àwọn baba wa ni Olúwa bá dá májẹ̀mú yìí bí kò ṣe àwa, àní pẹ̀lú gbogbo àwa tí a wà láààyè níbí lónìí.
4 DOMNUL a vorbit cu voi faţă în faţă pe munte, din mijlocul focului,
Olúwa bá a yín sọ̀rọ̀ lójúkojú láàrín iná lórí òkè.
5 (Eu stăteam în timpul acela între DOMNUL şi voi, ca să vă arăt cuvântul DOMNULUI, pentru că vă temeaţi din cauza focului şi nu v-aţi urcat pe munte), spunând:
(Ní ìgbà yìí, mo wà láàrín ẹ̀yin pẹ̀lú Ọlọ́run láti sọ ọ̀rọ̀ Olúwa fún un yín torí pé ẹ̀rù Ọlọ́run ń bà yín, ẹ kò sì lè kọjá lọ sórí òkè.) Ó sì wí pé,
6 Eu sunt DOMNUL Dumnezeul tău care te-am scos din ţara Egiptului, din casa robiei.
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
7 Să nu ai alţi dumnezei în afară de mine.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
8 Să nu îţi faci chip cioplit sau vreo asemănare a ceea ce este sus în cer, sau a ceea ce este jos pe pământ sau a ceea ce este în apele de sub pământ,
Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
9 Să nu te prosterni înaintea lor, nici să nu le serveşti, pentru că eu, DOMNUL Dumnezeul tău, sunt un Dumnezeu gelos, pedepsind nelegiuirea părinţilor peste copii până la a treia şi a patra generaţie a celor care mă urăsc,
Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
10 Şi arătând milă la mii dintre cei care mă iubesc şi păzesc poruncile mele.
Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
11 Să nu iei în deşert numele DOMNULUI Dumnezeul tău, pentru că DOMNUL nu îl va considera nevinovat pe cel care ia în deşert numele lui.
Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
12 Ţine ziua sabatului ca să o sfinţeşti, precum ţi-a poruncit DOMNUL Dumnezeul tău.
Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín.
13 Lucrează şase zile şi fă toată munca ta;
Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ.
14 Dar ziua a şaptea este sabatul pentru DOMNUL Dumnezeul tău; să nu faci nicio lucrare, nici tu, nici fiul tău, nici fiica ta, nici servitorul tău, nici servitoarea ta, nici boul tău, nici măgarul tău, nici vreuna dintre vitele tale, nici străinul tău care este înăuntrul porţilor tale, ca să se odihnească şi servitorul tău şi servitoarea ta, la fel ca tine.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti akọ màlúù rẹ, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, àti ohun ọ̀sìn rẹ kan, àti àlejò tí ń bẹ nínú ibodè rẹ; kí ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin kí ó lè sinmi gẹ́gẹ́ bí ìwọ.
15 Şi aminteşte-ţi că ai fost servitor în ţara Egiptului şi că DOMNUL Dumnezeul tău te-a scos de acolo cu mână tare şi cu braţ întins; de aceea ţi-a poruncit DOMNUL Dumnezeul tău să ţii ziua sabatului.
Sì rántí pé, ìwọ ti jẹ́ ẹrú ní Ejibiti rí, àti pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yọ ọ́ kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá, àti nína ọwọ́ rẹ̀. Torí èyí ni Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe pàṣẹ fún ọ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́.
16 Onorează pe tatăl tău şi pe mama ta, precum ţi-a poruncit DOMNUL Dumnezeul tău, ca să ţi se lungească zilele şi ca să îţi meargă bine, în ţara pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău.
Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún ọ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́, àti kí ó lè dára fún ọ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
17 Să nu ucizi.
Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
18 Nici să nu comiţi adulter.
Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
19 Nici să nu furi.
Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
20 Nici să nu depui mărturie falsă împotriva aproapelui tău.
Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
21 Nici să nu doreşti soţia aproapelui tău, nici să nu pofteşti casa aproapelui tău, câmpul său, sau servitorul lui sau servitoarea lui, boul lui sau măgarul lui, sau ceva din ce este al aproapelui tău.
Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéji rẹ, oko rẹ̀, àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéji rẹ.”
22 Aceste cuvinte le-a vorbit DOMNUL către toată adunarea voastră, pe munte, din mijlocul focului, din nor şi din întuneric gros, cu voce tare, şi nu a mai adăugat nimic. Şi le-a scris pe două table de piatră şi mi le-a dat mie.
Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ Olúwa tí a kéde rẹ̀ sí gbogbo ìpéjọpọ̀ ọ yín, níbẹ̀ ní orí òkè, láàrín iná, ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri, kò sì fi ohunkóhun kún un mọ́. Ó sì kọ wọ́n sínú wàláà méjì, Ó sì fi wọ́n lé mi lọ́wọ́.
23 Şi s-a întâmplat, când aţi auzit vocea din mijlocul întunericului, (fiindcă muntele ardea cu foc), că v-aţi apropiat de mine, adică toţi capii triburilor voastre şi bătrânii voştri;
Nígbà tí ẹ gbóhùn láti inú òkùnkùn wá, nígbà tí iná náà ń yọ iná lala, àwọn aṣáájú ẹ̀yà a yín àti àwọn àgbàgbà yín tọ̀ mí wá.
24 Şi aţi spus: Iată, DOMNUL Dumnezeul nostru ne-a arătat gloria sa şi măreţia sa şi i-am auzit vocea din mijlocul focului; am văzut astăzi că Dumnezeu vorbeşte cu omul şi omul trăieşte.
Ẹ sì sọ pé, “Olúwa Ọlọ́run wa ti fi ògo rẹ̀ hàn wá, àti títóbi rẹ̀ a sì ti gbóhùn rẹ̀ láti àárín iná wá. A ti rí i lónìí pé, ènìyàn sì lè wà láààyè lẹ́yìn tí Ọlọ́run bá bá a sọ̀rọ̀.
25 Şi acum pentru ce să murim? Pentru că acest foc mare ne va mistui, dacă vom mai auzi vocea DOMNULUI Dumnezeul nostru vom muri.
Ṣùgbọ́n èéṣe tí àwa yóò fi kú? Iná ńlá yìí yóò jó wa run, bí àwa bá sì tún gbọ́ ohun Olúwa Ọlọ́run wa, àwa ó kú.
26 Fiindcă cine este acela, ca noi, din toată făptura, care a auzit vocea Dumnezeului cel viu vorbind din mijlocul focului, şi a trăit?
Ta ni nínú ẹlẹ́ran ara tí ó ti gbọ́ ohun Ọlọ́run alààyè láti inú iná rí, bí àwa ti gbọ́ ọ, tí a sì wà láyé?
27 Apropie-te tu şi auzi tot ce va spune DOMNUL Dumnezeul nostru şi vorbeşte-ne tu, tot ce îţi va vorbi DOMNUL Dumnezeul nostru; şi vom auzi şi vom face.
Súnmọ́ tòsí ibẹ̀ kí o sì gbọ́ gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò sọ, nígbà náà sọ ohunkóhun tí Olúwa Ọlọ́run wa sọ fún ọ fún wa. A ó sì fetísílẹ̀, a ó sì gbọ́rọ̀.”
28 Şi DOMNUL a auzit vocea cuvintelor voastre, când mi-aţi vorbit, şi DOMNUL mi-a spus: Am auzit vocea cuvintelor acestui popor, pe care le-a spus către tine, bine au spus tot ce au spus.
Olúwa ń gbọ́ nígbà tí ẹ̀yin ń bá mi sọ̀rọ̀, Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti gbọ́ ohun tí àwọn ènìyàn yí sọ fún ọ. Gbogbo ohun tí wọ́n sọ dára,
29 O, de ar fi în ei o astfel de inimă, ca să se teamă de mine şi să păzească întotdeauna toate poruncile mele, ca să le fie bine, lor şi copiilor lor, pentru totdeauna!
ìbá ti dára tó, bí ọkàn wọn bá lè bẹ̀rù mi, tí ó sì ń pa gbogbo òfin mi mọ́ nígbà gbogbo, kí ó bá à lè dára fún wọn, àti àwọn ọmọ wọn láéláé.
30 Du-te, spune-le: Întoarceţi-vă la corturile voastre.
“Lọ sọ fún wọn kí wọn padà sínú àgọ́ wọn.
31 Dar cât despre tine, stai aici lângă mine şi îţi voi spune toate poruncile şi statutele şi judecăţile care să îi înveţi să le împlinească în ţara pe care le-o dau să o stăpânească.
Ṣùgbọ́n ìwọ túbọ̀ dúró síbí pẹ̀lú mi, kí n bá à lè fún ọ ní àwọn àṣẹ tí o gbọdọ̀ fi kọ́ wọn láti máa tẹ̀lé ní ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún wọn láti ní.”
32 Să luaţi seama să faceţi de aceea precum v-a poruncit DOMNUL Dumnezeul vostru, să nu vă abateţi la dreapta sau la stânga.
Torí èyí, ẹ ṣọ́ra láti máa ṣe ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín tí pa ní àṣẹ fún un yín; ẹ má ṣe yà sọ́tùn ún tàbí sósì.
33 Să umblaţi în toate căile pe care vi le-a poruncit DOMNUL Dumnezeul vostru, ca să trăiţi şi să vă fie bine şi să vă lungiţi zilele în ţara pe care o veţi stăpâni.
Ẹ rìn ní gbogbo ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín, kí ẹ bá à le yè, kí ó sì dára fún un yín, kí ọjọ́ ọ yín bá à lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin yóò gbà.

< Deuteronomul 5 >