< 2 Samuel 9 >

1 Și David a spus: Mai este cineva care să fi rămas din casa lui Saul, ca să îi arăt bunătate din cauza lui Ionatan?
Dafidi sì béèrè pé, ọ̀kan nínú àwọn ẹni tí ń ṣe ìdílé Saulu kù síbẹ̀ bí? Kí èmi lè ṣe oore fún un nítorí Jonatani.
2 Și era din casa lui Saul un servitor al cărui nume era Țiba. Și când l-au chemat la David, împăratul i-a spus: Ești tu Țiba? Și el a spus: Al tău servitor.
Ìránṣẹ́ kan sì ti wà ní ìdílé Saulu, orúkọ rẹ̀ sí ń jẹ́ Ṣiba, wọ́n sì pè é wá sọ́dọ̀ Dafidi, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ìwọ ni Ṣiba bí?” Ó sì dáhùn wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni.”
3 Și împăratul a spus: Mai este cineva din casa lui Saul, ca să îi arăt bunătatea lui Dumnezeu? Și Țiba a spus împăratului: Ionatan mai are încă un fiu, care este șchiop de picioare.
Ọba sì wí pé, “Kò ha sí ọ̀kan nínú ìdílé Saulu síbẹ̀, kí èmi ṣe oore Ọlọ́run fún un?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Jonatani ní ọmọ kan síbẹ̀ tó ya arọ.”
4 Și împăratul i-a spus: Unde este el? Și Țiba a spus împăratului: Iată, el este în casa lui Machir, fiul lui Amiel, în Lodebar.
Ọba sì wí fún un pé, “Níbo ni ó gbé wà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, òun wà ní ilé Makiri, ọmọ Ammieli, ní Lo-Debari.”
5 Atunci împăratul David a trimis și l-a scos din casa lui Machir, fiul lui Amiel, din Lodebar.
Dafidi ọba sì ránṣẹ́, ó sì mú un láti ilé Makiri ọmọ Ammieli láti Lo-Debari wá.
6 Acum, când Mefiboșet, fiul lui Ionatan, fiul lui Saul, a venit la David, a căzut cu fața la pământ și s-a prosternat. Și David a spus: Mefiboșet. Iar el a răspuns: Iată, pe servitorul tău!
Mefiboṣeti ọmọ Jonatani ọmọ Saulu sì tọ Dafidi wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì bú ọlá fún un. Dafidi sì wí pé, “Mefiboṣeti!” Òun sì dáhùn wí pé, “Wò ó, ìránṣẹ́ rẹ!”
7 Și David i-a spus: Nu te teme, pentru că îți voi arăta într-adevăr bunătate, de dragul lui Ionatan, tatăl tău, și îți voi da înapoi tot pământul lui Saul, tatăl tău; și tu vei mânca pâine la masa mea continuu.
Dafidi sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé nítòótọ́ èmi ó ṣe oore fún ọ nítorí Jonatani baba rẹ, èmi ó sì tún fi gbogbo ilé Saulu baba rẹ fún ọ, ìwọ ó sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.”
8 Și el s-a plecat și a spus: Ce este servitorul tău, ca să privești la un astfel de câine mort cum sunt eu?
Mefiboṣeti sì tẹríba, ó sì wí pé, “Kí ni ìránṣẹ́ rẹ jásí, tí ìwọ ó fi máa wo òkú ajá bí èmi.”
9 Atunci împăratul l-a chemat pe Țiba, servitorul lui Saul, și i-a spus: Am dat fiului stăpânului tău tot ce a aparținut lui Saul și întregii sale case.
Ọba sì pe Ṣiba ìránṣẹ́ Saulu, ó sì wí fún un pé, “Gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Saulu, àti gbogbo èyí tí í ṣe ti ìdílé rẹ̀ ni èmi fi fún ọmọ olúwa rẹ.
10 Tu, de aceea, și fiii tăi și servitorii tăi, veți ara pământul pentru el și tu vei aduce roadele, ca fiul stăpânului tău să aibă mâncare să mănânce; dar Mefiboșet, fiul stăpânului tău, va mânca pâine întotdeauna la masa mea. Acum Țiba avea cincisprezece fii și douăzeci de servitori.
Ìwọ, àti àwọn ọmọ rẹ, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni yóò sì máa ro ilẹ̀ náà fún un, ìwọ ni yóò sì máa mú ìkórè wá, ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa rí oúnjẹ jẹ, ṣùgbọ́n Mefiboṣeti ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.” (Ṣiba sì ní ọmọ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti ogún ìránṣẹ́kùnrin.)
11 Atunci Țiba a spus împăratului: Conform cu toate câte a poruncit domnul meu, împăratul, servitorului său, astfel va face servitorul tău. Cât despre Mefiboșet, a spus împăratul, el va mânca la masa mea, ca unul dintre fiii împăratului.
Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí olúwa mi ọba ti pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ náà ni ìránṣẹ́ rẹ ó ṣe.” Ọba sì wí pé, “Ní ti Mefiboṣeti, yóò máa jẹun ní ibi oúnjẹ mi, gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọba.”
12 Și Mefiboșet avea un fiu tânăr, al cărui nume era Mica. Și toți câți au locuit în casa lui Țiba erau servitori lui Mefiboșet.
Mefiboṣeti sì ní ọmọ kékeré kan, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika. Gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilé Ṣiba ni ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Mefiboṣeti.
13 Astfel Mefiboșet a locuit în Ierusalim, fiindcă mânca la masa împăratului continuu; și el era șchiop la ambele picioare.
Mefiboṣeti sì ń gbé ní Jerusalẹmu, òun a sì máa jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ ọba; òun sì yarọ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì.

< 2 Samuel 9 >