< 2 Samuel 7 >
1 Și s-a întâmplat, când împăratul a șezut în casa lui și DOMNUL i-a dat odihnă de toți dușmanii lui de jur împrejur,
Ó sì ṣe, nígbà tí ọba ń gbé ní ilé rẹ̀, tí Olúwa sì fún un ní ìsinmi yíkákiri kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀.
2 Că împăratul a spus profetului Natan: Vezi acum, eu locuiesc într-o casă de cedru, dar chivotul lui Dumnezeu locuiește înăuntrul covoarelor.
Ọba sì wí fún Natani wòlíì pé, “Sá wò ó, èmi ń gbé inú ilẹ̀ tí a fi kedari kọ́, ṣùgbọ́n àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ń gbé inú ibi tí a fi aṣọ gé.”
3 Și Natan a spus împăratului: Du-te, fă tot ce este în inima ta, fiindcă DOMNUL este cu tine.
Natani sì wí fún ọba pé, “Lọ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn rẹ, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
4 Și s-a întâmplat că, în acea noapte cuvântul DOMNULUI a venit la Natan, spunând:
Ó sì ṣe ní òru náà, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Natani wá pé,
5 Du-te și spune servitorului meu David: Astfel spune DOMNUL: Îmi vei zidi tu o casă ca să locuiesc în ea?
“Lọ, sọ fún ìránṣẹ́ mi, fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ó ha kọ́ ilé fún mi tí èmi yóò gbé.
6 Pentru că eu nu am locuit în vreo casă de când am scos pe copiii lui Israel din Egipt, chiar până în această zi, ci am umblat într-un cort și într-un tabernacol.
Nítorí pé, èmi kò ì ti gbé inú ilé kan láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ọmọ Israẹli gòkè ti ilẹ̀ Ejibiti wá, títí di òní yìí, ṣùgbọ́n èmi ti ń rìn nínú àgọ́, fún ibùgbé mi.
7 În toate locurile în care am umblat cu toți copiii lui Israel, am vorbit eu un cuvânt vreunuia din triburile lui Israel, căruia i-am poruncit să pască pe poporul meu Israel, spunând: De ce nu îmi zidiți o casă de cedru?
Ní ibi gbogbo tí èmi ti ń rìn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ǹjẹ́ èmi ti bá ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli, tí èmi pa àṣẹ fún láti máa bọ́ àwọn ènìyàn mi àní Israẹli, sọ̀rọ̀ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi kedari kọ́ ilé fún mi.”’
8 De aceea acum, astfel să îi spui servitorului meu David: Astfel spune DOMNUL oștirilor: Te-am luat de la staulul oilor, de la a urma oile, pentru a fi conducător peste poporul meu, peste Israel;
“Ǹjẹ́, nítorí náà, báyìí ni ìwọ yóò sì wí fún ìránṣẹ́ mi àní Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, Èmi ti mú ìwọ kúrò láti inú agbo àgùntàn wá láti má tẹ̀lé àwọn àgùntàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli.
9 Și am fost cu tine oriunde ai mers și am stârpit pe toți dușmanii tăi dinaintea ochilor tăi și ți-am făcut un nume mare, ca numele oamenilor mari care sunt pe pământ.
Èmi sì wà pẹ̀lú rẹ níbikíbi tí ìwọ ń lọ, èmi sá à gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ, èmi sì ti sọ orúkọ rẹ di ńlá, gẹ́gẹ́ bí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá tí ó wà ní ayé.
10 Mai mult, voi rândui un loc pentru poporul meu Israel și îl voi sădi, ca ei să locuiască într-un loc al lor și să nu se mai mute; iar copiii stricăciunii nu îl vor mai chinui ca înainte,
Èmi ó sì yan ibìkan fún àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi ó sì gbìn wọ́n, wọn ó sì má gbé bí ibùjókòó tiwọn, wọn kì yóò sì sípò padà mọ́; àwọn ọmọ ènìyàn búburú kì yóò sì pọ́n wọn lójúmọ́, bí ìgbà àtijọ́.
11 Ca atunci când am poruncit judecătorilor să fie peste poporul meu Israel și te-am făcut să te odihnești de toți dușmanii tăi. De asemenea DOMNUL îți spune că îți va face o casă.
Àti gẹ́gẹ́ bí àkókò ìgbà tí èmi ti fi àṣẹ fún àwọn onídàájọ́ lórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi fi ìsinmi fún ọ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ. “‘Olúwa sì wí fún ọ pé Olúwa yóò kọ ilé kan fún ọ.
12 Și când zilele tale se vor fi împlinit și vei adormi cu părinții tăi, voi așeza sămânța ta după tine, care va ieși din adâncurile tale și îi voi întemeia împărăția.
Nígbà tí ọjọ́ rẹ bá pé, tí ìwọ ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ, èmi yóò sì gbé irú-ọmọ rẹ lékè lẹ́yìn rẹ, èyí tí ó ti inú rẹ jáde wá, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀.
13 El va zidi o casă pentru numele meu și eu voi întări tronul împărăției lui pentru totdeauna.
Òun ó sì kọ́ ilé fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀ láéláé.
14 Eu îi voi fi tată și el îmi va fi fiu. Dacă va face nelegiuire, îl voi mustra cu nuiaua oamenilor și cu loviturile copiilor oamenilor;
Èmi ó máa ṣe baba fún un, òun yóò sì máa jẹ́ ọmọ mi. Bí òun bá dẹ́ṣẹ̀, èmi yóò sì fi ọ̀pá ènìyàn nà án, àti ìnà àwọn ọmọ ènìyàn.
15 Dar mila mea nu se va depărta de la el, precum am luat-o de la Saul, pe care l-am îndepărtat dinaintea ta.
Ṣùgbọ́n àánú mi kì yóò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú un kúrò lọ́dọ̀ Saulu, tí èmi ti mú kúrò níwájú rẹ.
16 Și casa ta și împărăția ta vor fi întemeiate pentru totdeauna înaintea ta; tronul tău va fi întemeiat pentru totdeauna.
A ó sì fi ìdílé rẹ àti ìjọba rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ títí láé, a ó sì fi ìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ títí láé.’”
17 Conform tuturor acestor cuvinte și conform acestei întregi viziuni, astfel i-a vorbit Natan lui David.
Gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, àti gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìran yìí, bẹ́ẹ̀ ni Natani sì sọ fún Dafidi.
18 Atunci împăratul David a intrat și a șezut înaintea DOMNULUI și a spus: Cine sunt eu, Doamne DUMNEZEULE? Și ce este casa mea, că m-ai adus până aici?
Dafidi ọba sì wọlé lọ, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, “Olúwa Olódùmarè, ta ni èmi, àti kí sì ni ìdílé mi, tí ìwọ fi mú mi di ìsinsin yìí?
19 Și acesta încă a fost un lucru mic înaintea ochilor tăi, DOAMNE DUMNEZEULE; dar tu ai vorbit de asemenea despre casa servitorului tău pentru mult timp înainte. Și este aceasta felul omului, Doamne DUMNEZEULE?
Nǹkan kékeré ni èyí sá à jásí lójú rẹ, Olúwa Olódùmarè; ìwọ sì ti sọ nípa ìdílé ìránṣẹ́ rẹ pẹ̀lú ní ti àkókò tí o jìnnà. Èyí ha ṣe ìwà ènìyàn bí, Olúwa Olódùmarè?
20 Și ce poate David să îți mai spună? Pentru că tu DOAMNE DUMNEZEULE, cunoști pe servitorul tău.
“Àti kín ní ó tún kù tí Dafidi ìbá tún máa wí fún ọ? Ìwọ, Olúwa Olódùmarè mọ̀ ìránṣẹ́ rẹ.
21 De dragul cuvântului tău și conform inimii tale, ai făcut toate aceste lucruri mărețe, pentru a le face cunoscute servitorului tău.
Nítorí ọ̀rọ̀ rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ, ni ìwọ ṣe ṣe gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí, kí ìránṣẹ́ rẹ lè mọ̀.
22 De aceea tu ești mare, DOAMNE Dumnezeule, pentru că nu este nimeni ca tine, nici nu este vreun Dumnezeu în afară de tine, conform cu toate câte am auzit cu urechile noastre.
“Ìwọ sì tóbi, Olúwa Olódùmarè! Kò sì sí ẹni tí ó dàbí rẹ, kò sì sí Ọlọ́run kan lẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí àwa fi etí wá gbọ́.
23 Și ce națiune pe pământ este ca poporul tău, ca Israel, pe care Dumnezeu a mers să îl răscumpere ca popor pentru el însuși și să îi facă un nume și să facă pentru voi lucruri mari și înfricoșătoare, pentru țara ta, înaintea poporului tău, pe care ți l-ai răscumpărat din Egipt, de la națiuni și de la dumnezeii lor?
Orílẹ̀-èdè kan wo ni ó sì ń bẹ ní ayé tí ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli, àwọn tí Ọlọ́run lọ rà padà láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ̀, àti láti sọ wọ́n ní orúkọ, àti láti ṣe nǹkan ńlá fún un yín, àti nǹkan ìyanu fún ilé rẹ̀, níwájú àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ ti rà padà fún ara rẹ láti Ejibiti wá, àní àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn òrìṣà wọn.
24 Fiindcă ți-ai întărit pe poporul tău Israel să îți fie un popor pentru totdeauna; și tu, DOAMNE, ai devenit Dumnezeul lor.
Ìwọ sì fi ìdí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli kalẹ̀ fún ara rẹ láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ títí láé; ìwọ Olúwa sì wá di Ọlọ́run fún wọn.
25 Și acum, DOAMNE Dumnezeule, cuvântul pe care l-ai spus referitor la servitorul tău și referitor la casa lui, întemeiază-l pentru totdeauna și fă precum ai spus.
“Ǹjẹ́, Olúwa Ọlọ́run, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ náà tí ìwọ sọ ní ti ìránṣẹ́ rẹ, àti ní ti ìdílé rẹ̀, kí ó dúró títí láé, kí ó sí ṣe bí ìwọ ti wí.
26 Și numele tău să fie mărit pentru totdeauna, spunând: DOMNUL oștirilor este Dumnezeu peste Israel; și să fie întemeiată, casa servitorului tău David înaintea ta.
Jẹ́ kí orúkọ rẹ ó ga títí láé, pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run lórí Israẹli!’ Sì jẹ́ kí a fi ìdílé Dafidi ìránṣẹ́ rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ.
27 Pentru că tu, DOAMNE al oștirilor, Dumnezeul lui Israel, i-ai revelat servitorului tău, spunând: Îți voi zidi o casă; de aceea a găsit servitorul tău în inima sa să se roage această rugăciune către tine.
“Nítorí pé ìwọ, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli ti sọ létí ìránṣẹ́ rẹ, pé, ‘Èmí ó kọ́ ilé kan fún ọ.’ Nítorí náà ni ìránṣẹ́ rẹ sì ṣe ní i lọ́kàn rẹ̀ láti gbàdúrà yìí sí ọ.
28 Și acum, Doamne DUMNEZEULE, tu ești acel Dumnezeu și cuvintele tale sunt adevărate și tu ai promis această bunătate servitorului tău;
Ǹjẹ́, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni Ọlọ́run náà, àwọn ọ̀rọ̀ rẹ sì jásí òtítọ́, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ nǹkan rere yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
29 De aceea acum, să îți placă să binecuvântezi casa servitorului tău, ca să continue pentru totdeauna înaintea ta, pentru că tu, Doamne DUMNEZEULE, ai vorbit aceasta; și cu binecuvântarea ta să fie casa servitorului tău binecuvântată pentru totdeauna.
Ǹjẹ́, jẹ́ kí ó wù ọ́ láti bùkún ìdílé ìránṣẹ́ rẹ, kí ó wà títí láé níwájú rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa Olódùmarè, ni ó ti sọ ọ́: sì jẹ́ kí ìbùkún wà ní ìdílé ìránṣẹ́ rẹ títí láé, nípasẹ̀ ìbùkún rẹ.”