< 2 Samuel 24 >

1 Și din nou mânia DOMNULUI s-a aprins împotriva lui Israel și el l-a mișcat pe David împotriva lor pentru a spune: Du-te, numără pe Israel și pe Iuda.
Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli, ó sì ti Dafidi sí wọn, pé, “Lọ ka iye Israẹli àti Juda!”
2 Fiindcă împăratul i-a spus lui Ioab, căpetenia oștirii, care era cu el: Du-te acum prin toate triburile lui Israel, de la Dan până la Beer-Șeba și numărați poporul, ca să știu numărul poporului.
Ọba sì wí fún Joabu olórí ogun, tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ ní ìsinsin yìí sí gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba, kí ẹ sì ka iye àwọn ènìyàn, kí èmi lè mọ iye àwọn ènìyàn náà!”
3 Și Ioab a spus împăratului: Acum, DOMNUL Dumnezeul tău să adauge la popor, oricâți sunt ei, însutit și ochii domnului meu împăratul, să vadă aceasta; dar de ce domnul meu împăratul găsește plăcere în acest lucru?
Joabu sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi kún iye àwọn ènìyàn náà, iyekíye tí ó wù kí wọn jẹ́, ní ọ̀rọ̀ọ̀rún, ojú olúwa mi ọba yóò sì rí i, ṣùgbọ́n èétiṣe tí olúwa mi ọba fi fẹ́ nǹkan yìí?”
4 Totuși cuvântul împăratului a învins împotriva lui Ioab și împotriva căpeteniilor oștirii. Și Ioab și căpeteniile oștirii au ieșit din prezența împăratului pentru a număra pe poporul lui Israel.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí ti Joabu, àti ti àwọn olórí ogun. Joabu àti àwọn olórí ogun sì jáde lọ kúrò níwájú ọba, láti lọ ka àwọn ènìyàn Israẹli.
5 Și au trecut Iordanul și și-au înălțat corturile în Aroer, pe partea dreaptă a cetății care se găsește în mijlocul râului lui Gad și spre Iaezer;
Wọ́n sì kọjá odò Jordani, wọ́n sì pàgọ́ ní Aroeri, ní ìhà apá ọ̀tún ìlú tí ó wà láàrín àfonífojì Gadi, àti sí ìhà Jaseri.
6 Atunci ei au venit la Galaad și la țara lui Tahtim-Hodși; și au venit la Dan-Iaan și împrejur la Sidon.
Wọ́n sì wá sí Gileadi, àti sí ilé Tatimi Hodṣi; wọ́n sì wá sí Dani Jaani àti yíkákiri sí Sidoni.
7 Și au venit la întăritura Tirului și la toate cetățile hiviților și ale canaaniților; și au ieșit la sud de Iuda, la Beer-Șeba.
Wọ́n sì wá sí ìlú olódi Tire, àti sí gbogbo ìlú àwọn Hifi, àti ti àwọn ará Kenaani, wọ́n sì jáde lọ síhà gúúsù ti Juda, àní sí Beerṣeba.
8 Astfel, după ce au trecut prin toată țara, au venit la Ierusalim la sfârșitul a nouă luni și douăzeci de zile.
Wọ́n sì la gbogbo ilẹ̀ náà já, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu ní òpin oṣù kẹsànán àti ogúnjọ́.
9 Și Ioab a dat împăratului suma numărătorii poporului; și erau acolo în Israel opt sute de mii de bărbați viteji care scoteau sabia; și bărbații lui Iuda erau cinci sute de mii de bărbați.
Joabu sì fi iye tí àwọn ènìyàn náà jásí lé ọba lọ́wọ́. Ó sì jẹ́ ogójì ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára ní Israẹli, àwọn onídà, àwọn ọkùnrin Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn.
10 Și lui David i-a bătut inima după ce a numărat poporul. Și David a spus DOMNULUI: Am păcătuit mult în ceea ce am făcut; și acum, te implor, DOAMNE, îndepărtează nelegiuirea servitorului tău, pentru că am lucrat foarte prostește.
Àyà Dafidi sì gbọgbẹ́ lẹ́yìn ìgbà tí ó ka àwọn ènìyàn náà tán. Dafidi sì wí fún Olúwa pé, “Èmi ṣẹ̀ gidigidi ní èyí tí èmi ṣe, ṣùgbọ́n, èmi bẹ̀ ọ, Olúwa, fi ẹ̀ṣẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ jì ní, nítorí pé èmi hùwà aṣiwèrè gidigidi!”
11 Și atunci când David s-a trezit dimineața, cuvântul DOMNULUI a venit la profetul Gad, văzătorul lui David, spunând:
Dafidi sì dìde ní òwúrọ̀, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Gadi wòlíì wá, aríran Dafidi wí pé,
12 Du-te și spune lui David: Astfel spune DOMNUL: Îți ofer trei lucruri; alege-ți unul dintre ele, ca să ți-l fac.
“Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
13 Astfel Gad a venit la David și i-a istorisit și i-a spus: Să vină șapte ani de foamete la tine în țara ta? Sau să fugi trei luni dinaintea dușmanilor tăi, în timp ce ei te urmăresc? Sau să fie trei zile ciumă în țara ta? Acum sfătuiește-te și vezi ce răspuns să întorc celui care m-a trimis.
Gadi sì tọ Dafidi wá, ó sì bi í léèrè pé, “Kí ìyàn ọdún méje ó tọ̀ ọ́ wá ní ilẹ̀ rẹ bí? Tàbí kí ìwọ máa sá ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, nígbà tí wọn ó máa lé ọ? Tàbí kí ààrùn ìparun ọjọ́ mẹ́ta ó wá sí ilẹ̀ rẹ? Rò ó nísinsin yìí, kí o sì mọ èsì tí èmi ó mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
14 Și David i-a spus lui Gad: Eu sunt într-o mare strâmtorare; să cădem acum în mâna DOMNULUI, pentru că îndurările lui sunt mari; și nu mă lăsa să cad în mâna omului.
Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí a fi ara wa lé Olúwa ní ọwọ́; nítorí pé àánú rẹ̀ pọ̀; kí ó má sì ṣe fi mí lé ènìyàn ní ọwọ́.”
15 Astfel DOMNUL a trimis o ciumă peste Israel de dimineață până la timpul rânduit; și au murit din popor de la Dan până la Beer-Șeba șaptezeci de mii de bărbați.
Olúwa sì rán ààrùn ìparun sí Israẹli láti òwúrọ̀ títí dé àkókò tí a dá, ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn sì kú nínú àwọn ènìyàn náà láti Dani títí fi dé Beerṣeba.
16 Și când îngerul și-a întins mâna peste Ierusalim ca să îl distrugă, DOMNUL s-a pocăit de rău și a spus îngerului care nimicea poporul: Este destul; oprește-ți acum mâna. Și îngerul DOMNULUI era lângă aria lui Aravna iebusitul.
Nígbà tí angẹli náà sì nawọ́ rẹ̀ sí Jerusalẹmu láti pa á run, Olúwa sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì sọ fún angẹli tí ń pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó tó, dá ọwọ́ rẹ dúró wàyí!” Angẹli Olúwa náà sì wà níbi ìpakà Arauna ará Jebusi.
17 Și David a vorbit DOMNULUI când a văzut pe îngerul care lovea poporul și a spus: Iată, eu am păcătuit și am lucrat cu stricăciune; dar aceste oi, ce au făcut ele? Fie mâna ta, te rog, împotriva mea și împotriva casei tatălui meu.
Dafidi sì wí fún Olúwa nígbà tí ó rí angẹli tí ń kọlu àwọn ènìyàn pé, “Wò ó, èmi ti ṣẹ̀, èmi sì ti hùwà búburú ṣùgbọ́n àwọn àgùntàn wọ̀nyí, kín ni wọ́n ha ṣe? Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, kí ó wà lára mi àti ìdílé baba mi.”
18 Și Gad a venit în acea zi la David și i-a spus: Urcă, ridică un altar DOMNULUI în aria lui Aravna iebusitul.
Gadi sì tọ Dafidi wá ní ọjọ́ náà, ó sì wí fún un pé, “Gòkè, tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.”
19 Și David, după cuvântul lui Gad, s-a urcat precum DOMNUL poruncise.
Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Gadi, Dafidi sì gòkè lọ bí Olúwa ti pa á ní àṣẹ.
20 Și Aravna a privit și l-a văzut pe împărat și pe servitorii lui venind spre el; și Aravna a ieșit și s-a plecat înaintea împăratului cu fața la pământ.
Arauna sì wò, ó sì rí ọba àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ wá lọ́dọ̀ rẹ̀, Arauna sì jáde, ó sì wólẹ̀ níwájú ọba ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀.
21 Și Aravna a spus: Pentru ce a venit domnul meu împăratul la servitorul său? Și David a spus: Pentru a cumpăra aria de la tine, ca să zidesc un altar DOMNULUI, ca plaga să fie oprită de la popor.
Arauna sì wí pé, “Nítorí kín ni olúwa mi ọba ṣe tọ ìránṣẹ́ rẹ̀ wá?” Dafidi sì dáhùn pé, “Láti ra ibi ìpakà rẹ lọ́wọ́ rẹ, láti tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa, kí ààrùn ìparun lè dá lára àwọn ènìyàn náà.”
22 Și Aravna i-a spus lui David: Să ia și să ofere domnul meu împăratul ce i se pare bun; iată, aici sunt boi pentru sacrificiu ars și uneltele de vânturat și alte unelte ale boilor în loc de lemne.
Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba ó mú èyí tí ó dára lójú rẹ̀, kí o sì fi í rú ẹbọ, wò ó, màlúù nìyìí láti fi ṣe ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà, àti ohun èlò mìíràn ti màlúù fún igi.
23 Toate aceste lucruri, Aravna, ca un împărat, le-a dat împăratului. Și Aravna a spus împăratului: DOMNUL Dumnezeul tău să te primească.
Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni Arauna fi fún ọba, bí ọba.” Arauna sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ ó gba ọrẹ rẹ.”
24 Și împăratul i-a spus lui Aravna: Nu, ci într-adevăr o voi cumpăra de la tine cu un preț, pentru că nu voi oferi ofrande arse DOMNULUI Dumnezeul meu din ceea ce nu mă costă nimic. Astfel David a cumpărat aria și boii cu cincizeci de șekeli de argint.
Ọba sì wí fún Arauna pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n èmi ó rà á ní iye kan lọ́wọ́ rẹ, bí ó ti wù kí ó ṣe; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi èyí tí èmi kò náwó fún, rú ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run mi.” Dafidi sì ra ibi ìpakà náà, àti àwọn màlúù náà ní àádọ́ta ṣékélì fàdákà.
25 Și David a zidit acolo un altar DOMNULUI și a oferit ofrande arse și ofrande de pace. Astfel DOMNUL a fost implorat pentru țară și plaga a fost oprită de peste Israel.
Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ sí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ti ìlàjà. Olúwa sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ fún ilẹ̀ náà, ààrùn náà sì dá kúrò ní Israẹli.

< 2 Samuel 24 >