< 2 Regii 9 >
1 Și profetul Elisei a chemat pe unul dintre copiii profeților și i-a spus: Încinge-ți coapsele și ia acest vas cu untdelemn în mâna ta și du-te în Ramot-Galaad;
Wòlíì Eliṣa fi àṣẹ pe ọkùnrin kan láti ẹgbẹ́ àwọn wòlíì, ó sì wí fún un pé, “Ki agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè rẹ, gba ṣágo kékeré òróró yìí pẹ̀lú rẹ, kí o sì lọ sí Ramoti Gileadi.
2 Și când ajungi acolo, uită-te acolo după Iehu, fiul lui Iosafat, fiul lui Nimși, și intră și fă-l să se ridice din mijlocul fraților săi și du-l în camera dinăuntru.
Nígbà tí o bá dé bẹ̀, wá Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi kiri. Lọ sí ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀, mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, kí o sì mú un wọ inú yàrá lọ́hùn ún lọ.
3 Atunci ia vasul cu untdelemn și toarnă-l pe capul său și zi: Astfel spune DOMNUL: Te-am uns împărat peste Israel. Apoi deschide ușa și fugi și nu întârzia.
Nígbà náà, mú ṣágo kékeré yìí, kí o sì da òróró náà lé e lórí, kí o sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’ Nígbà náà, ṣí ìlẹ̀kùn, kí o sì sáré, má ṣe jáfara!”
4 Astfel tânărul, profetul tânăr, a mers la Ramot-Galaad.
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti Gileadi.
5 Și după ce a intrat, iată, căpeteniile oștirii erau așezate, iar el a spus: Am o vorbă către tine, căpetenie. Și Iehu a zis: Către care dintre noi toți? Iar el a spus: Către tine, căpetenie.
Nígbà tí ó dé, ó rí àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí wọ́n jókòó papọ̀. “Èmi ní iṣẹ́ fún ọ, olórí,” Ó wí. “Sí ta ni nínú wa?” Jehu béèrè. Òun sì wí pé, “Sí ọ, balógun,” Ó dáhùn.
6 Iar el s-a ridicat și a intrat în casă, și el a turnat untdelemnul pe capul lui și i-a zis: Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Te-am uns împărat peste poporul DOMNULUI, peste Israel.
Jehu dìde sókè, ó sì wọ inú ilé lọ. Nígbà náà, wòlíì náà da òróró náà sórí Jehu; ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn Olúwa Israẹli.
7 Și tu vei lovi casa lui Ahab, stăpânul tău, pentru a răzbuna sângele servitorilor mei, profeții, și sângele tuturor servitorilor DOMNULUI din mâna Izabelei.
Kí ìwọ kí ó pa ilé Ahabu ọ̀gá à rẹ̀ run, Èmi yóò sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Olúwa tí a ta sílẹ̀ látọwọ́ ọ Jesebeli.
8 Pentru că toată casa lui Ahab va pieri; și voi stârpi din Ahab pe cel care urinează la perete și pe cel închis și pe cel rămas în Israel;
Gbogbo ilé Ahabu yóò ṣègbé. Èmi yóò gé e kúrò láti orí Ahabu gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó gbẹ̀yìn ni Israẹli, ẹrú tàbí òmìnira.
9 Și voi face casa lui Ahab precum casa lui Ieroboam, fiul lui Nebat, și precum casa lui Baașa, fiul lui Ahiia.
Èmi yóò ṣe ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati àti ilé Baaṣa ọmọ Ahijah.
10 Și câinii o vor mânca pe Izabela în moștenirea lui Izreel și nu va fi nimeni să o îngroape. Și el a deschis ușa și a fugit.
Fún Jesebeli, ajá ni yóò jẹ ẹ́ ní oko Jesreeli, kò sì sí ẹni tí yóò sin òkú rẹ̀.’” Nígbà náà ó ṣí ìlẹ̀kùn, ó sì sálọ.
11 Atunci Iehu a ieșit la servitorii domnului său; și unul i-a spus: Este totul bine? Pentru ce a venit acest nebun la tine? Și el le-a zis: Cunoașteți pe om și vorbirea lui.
Nígbà tí Jehu jáde lọ bá àwọn ọgbà ìjòyè e rẹ̀, ọ̀kan nínú wọn sì bi í pé, “Ṣé gbogbo nǹkan dára?” Kí ni ó dé tí aṣiwèrè fi tọ̀ ọ́ wá, “Ìwọ mọ ọkùnrin náà àti irú nǹkan tí ó ń sọ,” Jehu fèsì.
12 Iar ei au zis: Minciună, spune-ne acum. Iar el a zis: Așa și așa mi-a vorbit, spunând: Așa zice DOMNUL: Te-am uns împărat peste Israel.
“Ìyẹn kì í ṣe òótọ́!” Wọ́n wí. “Sọ fún wa.” Jehu wí, “Èyí ni ohun tí ó sọ fún mi: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’”
13 Atunci s-au grăbit și și-au luat fiecare haina sa și le-au pus sub el la capătul de sus al treptelor, și au sunat din trâmbițe, spunând: Iehu este împărat.
Wọ́n ṣe gírí, wọ́n sì mú agbádá a wọn, wọ́n sì tàn wọ́n sí abẹ́ rẹ̀ ní orí àtẹ̀gùn. Nígbà náà, wọ́n fọn ìpè, wọ́n sì kígbe, “Jehu jẹ ọba!”
14 Astfel Iehu, fiul lui Iosafat, fiul lui Nimși, a uneltit împotriva lui Ioram. (Și Ioram păzea Ramot-Galaadul, el și tot Israelul, din cauza lui Hazael, împăratul Siriei.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi, dìtẹ̀ sí Joramu. (Nísinsin yìí Joramu àti gbogbo Israẹli ti ń dáàbò bo Ramoti Gileadi nítorí Hasaeli ọba Aramu.
15 Dar împăratul Ioram s-a întors să se vindece în Izreel de rănile pe care i le făcuseră sirienii, când se lupta împotriva lui Hazael, împăratul Siriei.) Și Iehu a zis: Dacă este voia voastră, să nu lăsați pe nimeni să iasă sau să scape din cetate pentru a merge să spună aceasta în Izreel.
ṣùgbọ́n ọba Joramu ti padà sí Jesreeli láti lọ sàn nínú ọgbẹ́ tí àwọn ará Aramu ti dá sí i lára nínú ogun pẹ̀lú ọba Hasaeli ti Aramu.) Jehu wí pé, “Tí èyí bá jẹ́ ọ̀nà tí ò ń rò, má ṣe jẹ́ kí ẹnìkankan kí ó yọ jáde nínú ìlú ńlá láti lọ sọ ìròyìn náà ní Jesreeli.”
16 Astfel Iehu s-a urcat în car și a mers la Izreel, pentru că Ioram zăcea acolo. Și Ahazia, împăratul lui Iuda, coborâse să îl vadă pe Ioram.
Nígbà náà Jehu wọ inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó sì gùn ún lọ sí Jesreeli, nítorí Joramu ń sinmi níbẹ̀ àti Ahasiah ọba Juda sì sọ̀kalẹ̀ láti wá wò Joramu.
17 Și acolo stătea în picioare un paznic pe turnul din Izreel și a văzut ceata lui Iehu pe când venea și a spus: Văd o ceată. Și Ioram a zis: Ia un călăreț și trimite-l să îi întâmpine și să spună: Este pace?
Nígbà tí olùṣọ́ kan tí ó dúró ní ilé ìṣọ́ ní Jesreeli, rí ọ̀wọ́ ogun Jehu tí wọ́n ń súnmọ́ tòsí, ó pè jáde, “Mo rí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí ó ń bọ̀.” “Mú ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kan,” Joramu pa á láṣẹ. “Rán an lọ sí ọ̀dọ̀ wọn kí o sì béèrè pé, ‘Ṣé ẹ̀yin wá pẹ̀lú àlàáfíà?’”
18 Astfel, a mers unul călare să îl întâmpine și a zis: Astfel spune împăratul: Este pace? Și Iehu a zis: Ce ai tu a face cu pacea? Treci înapoia mea. Și paznicul a spus, zicând: Mesagerul a mers la ei, dar nu se întoarce.
Ọkùnrin ẹlẹ́ṣin náà, lọ láti lọ bá Jehu ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba wí: ‘Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?’” “Kí ni ìwọ ní ṣe pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu sì dáhùn. “Bọ́ sí ẹ̀yìn mi.” Olùṣọ́ náà sì wí fún un pé, “Ìránṣẹ́ náà ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́.”
19 Atunci a trimis pe un al doilea călare, care a venit la ei și a zis: Astfel spune împăratul: Este pace? Și Iehu a răspuns: Ce ai tu a face cu pacea? Treci înapoia mea.
Bẹ́ẹ̀ ni, ọba rán ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kejì. Nígbà náà ó wá sí ọ̀dọ̀ wọn, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba sọ: “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu dáhùn, “Dúró sí ẹ̀yìn mi.”
20 Și paznicul a spus, zicând: El a mers la ei și nu se întoarce; și mânatul este ca mânatul lui Iehu, fiul lui Nimși, pentru că mână furios.
Olùṣọ́ náà sì fi sùn. “Ó ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́ pẹ̀lú. Wíwá rẹ̀ sì dàbí ti Jehu ọmọ Nimṣi, ó ń wa kẹ̀kẹ́ bí ti aṣiwèrè.”
21 Și Ioram a spus: Pregătiți! Și carul său a fost pregătit. Și Ioram, împăratul lui Israel, și Ahazia, împăratul lui Iuda, au ieșit fiecare în carul său și au mers să întâmpine pe Iehu și l-au întâlnit la câmpul lui Nabot izreelitul.
“Fi ìwọ̀ kọ́ kẹ̀kẹ́ ogun mi.” Joramu pa á láṣẹ. Àti nígbà tí a fi kọ́, Joramu ọba Israẹli àti Ahasiah ọba Juda, gun kẹ̀kẹ́ lọ, olúkúlùkù nínú kẹ̀kẹ́ ogun tirẹ̀, láti lọ bá Jehu. Wọ́n bá a pàdé ní ibi oko tí ó ti jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli.
22 Și s-a întâmplat, după ce Ioram l-a văzut pe Iehu, că a zis: Este pace, Iehu? Iar el a răspuns: Ce pace, atât timp cât curviile mamei tale Izabela și vrăjitoriile ei sunt atât de multe?
Nígbà tí Joramu rí Jehu, ó béèrè pé, “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà, Jehu?” “Báwo ni àlàáfíà yóò ṣe wà,” Jehu dáhùn, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí gbogbo ìbọ̀rìṣà àti iṣẹ́ àjẹ́ ti màmá rẹ Jesebeli di púpọ̀?”
23 Și Ioram și-a întors mâinile și a fugit și i-a spus lui Ahazia: Trădare, Ahazia.
Joramu yí ọwọ́ rẹ̀ padà, ó sì sálọ, ó sì ń pe Ahasiah, “Ọ̀tẹ̀ dé, Ahasiah!”
24 Și Iehu a încordat arcul cu toată tăria lui și l-a lovit pe Ioram între brațe și săgeata i-a trecut prin inimă iar el a căzut în carul său.
Nígbà náà, Jehu fa ọrun rẹ̀, ó sì yin Joramu láàrín èjìká méjèèjì. Ọfà náà sì wọ inú ọkàn rẹ̀, ó sì ṣubú lulẹ̀ láti orí kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
25 Atunci Iehu i-a zis lui Bidcar, căpetenia sa: Ia-l și aruncă-l în bucata de pământ a lui Nabot izreelitul, pentru că, adu-ți aminte, când noi doi mânam împreună în urma lui Ahab, tatăl său, că DOMNUL a pus această povară asupra lui;
Jehu sọ fún Bidikari, balógun kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Gbé e sókè kí ó sì jù ú sí orí oko tí ó jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli. Rántí bí èmi àti ìwọ ti ń gun kẹ̀kẹ́ papọ̀ lẹ́yìn Ahabu baba à rẹ nígbà tí Olúwa sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀,
26 Într-adevăr, am văzut ieri sângele lui Nabot și sângele fiilor săi, spune DOMNUL; și îți voi răsplăti în această bucată de pământ, spune DOMNUL. Acum de aceea, ridică-l și aruncă-l în această bucată de pământ, conform cuvântului DOMNULUI.
‘Ní àná, mo rí ẹ̀jẹ̀ Naboti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ni Olúwa wí.’ Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ gbé e sókè, kí o sì jù ú sí orí ilẹ̀ oko náà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa.”
27 Dar când Ahazia, împăratul lui Iuda, a văzut aceasta, a fugit pe calea casei din grădină. Și Iehu l-a urmărit și a zis: Loviți-l și pe el în car. Și l-au lovit la suișul spre Gur, care este lângă Ibleam. Și el a fugit la Meghido și a murit acolo.
Nígbà tí Ahasiah ọba, Juda rí ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀, ó sálọ sójú ọ̀nà sí Beti-Haggani. Jehu sì lépa rẹ̀, ó ń kígbe, “Pa á pẹ̀lú!” Wọ́n ṣá a ní ọgbẹ́ nínú kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Guri lẹ́bàá a Ibleamu, ṣùgbọ́n ó sálọ sí Megido, ó sì kú síbẹ̀.
28 Și servitorii săi l-au dus într-un car la Ierusalim și l-au îngropat în mormântul său cu părinții săi în cetatea lui David.
Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì gbé e pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lọ sí Jerusalẹmu, ó sì sin ín pẹ̀lú, baba a rẹ̀ nínú ibojì rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi.
29 Și în al unsprezecelea an al lui Ioram, fiul lui Ahab, Ahazia a început să domnească peste Iuda.
(Ní ọdún kọkànlá ti Joramu ọmọ Ahabu, Ahasiah ti di ọba Juda.)
30 Și după ce Iehu a venit în Izreel, Izabela a auzit de aceasta; și și-a vopsit fața și și-a împodobit capul și s-a uitat pe fereastră.
Nígbà náà Jehu lọ sí Jesreeli. Nígbà tí Jesebeli gbọ́ nípa rẹ̀, ó kun ojú u rẹ̀, ó to irun rẹ̀, ó sì wò jáde láti ojú fèrèsé.
31 Și pe când Iehu intra pe poartă, ea a spus: A avut Zimri pace, cel care l-a ucis pe stăpânul său?
Bí Jehu ti wọ ẹnu ìlẹ̀kùn, ó béèrè, “Ṣé ìwọ wá ní àlàáfíà, Simri, ìwọ olùpa ọ̀gá à rẹ?”
32 Și el și-a ridicat fața spre fereastră și a zis: Cine este de partea mea? Cine? Și s-au uitat la el doi sau trei fameni.
Ó gbójú sókè láti wo fèrèsé, ó sì pè jáde, “Ta ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ mi? Ta ni?” Ìwẹ̀fà méjì tàbí mẹ́ta bojú wò ó nílẹ̀.
33 Și el a spus: Aruncați-o jos. Astfel, ei au aruncat-o jos; și din sângele ei a fost stropit pe zid și pe cai; și el a călcat-o în picioare.
Jehu sọ wí pé, “Gbé e jù sílẹ̀!” Wọ́n sì jù ú sílẹ̀. Díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì fọ́n sí ara ògiri àti àwọn ẹṣin bí wọ́n ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ wọn.
34 Și după ce el a intrat, a mâncat și a băut și a spus: Duceți-vă, vedeți acum pe această femeie blestemată și îngropați-o, pentru că este fiică de împărat.
Jehu wọ inú ilé lọ, ó jẹ, ó sì mu. “Tọ́jú obìnrin yẹn tí a fi bú,” Ó wí, “Kí o sì sin ín, nítorí ọmọbìnrin ọba ni ó jẹ́.”
35 Și au mers să o îngroape; dar nu au mai găsit din ea decât craniul și labele picioarelor și palmele mâinilor ei.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde lọ láti lọ sin ín, wọn kò rí nǹkan kan àyàfi agbárí i rẹ̀, ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì àti ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
36 De aceea s-au întors și i-au spus. Iar el a zis: Acesta este cuvântul DOMNULUI, pe care l-a vorbit prin servitorul său, Ilie tișbitul, spunând: Câinii vor mânca în moștenirea lui Izreel carnea Izabelei;
Wọ́n padà lọ sọ fún Jehu, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah ará Tiṣibi wí pé, ‘Ní orí oko Jesreeli ni àwọn ajá yóò ti jẹ ẹran-ara Jesebeli.
37 Și trupul mort al Izabelei va fi ca balega pe fața câmpului în moștenirea lui Izreel; astfel încât ei nu vor putea spune: Aceasta este Izabela.
Òkú Jesebeli yóò dàbí ohun ẹ̀gbin ní orí oko Jesreeli, dé bi pé, ẹnikẹ́ni kì yóò lè sọ pé, “Jesebeli ni èyí.”’”