< 2 Regii 3 >

1 Și Ioram, fiul lui Ahab, a început să domnească peste Israel în Samaria în al optsprezecelea an al lui Iosafat, împăratul lui Iuda, și a domnit doisprezece ani.
Jehoramu ọmọ Ahabu sì di ọba Israẹli ní Samaria ní ọdún kejìdínlógún ti Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjìlá.
2 Și a făcut ce este rău înaintea ochilor DOMNULUI; dar nu ca tatăl său și ca mama sa, pentru că a îndepărtat chipul lui Baal, pe care tatăl său îl făcuse.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí ti ìyá àti baba rẹ̀ ti ṣe. Ó gbé òkúta ère ti Baali tí baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
3 Totuși s-a alipit de păcatele lui Ieroboam, fiul lui Nebat, care făcuse pe Israel să păcătuiască; nu s-a depărtat de ele.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ara mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ti fi Israẹli bú láti dẹ́ṣẹ̀; kò sì yí kúrò lọ́dọ̀ wọn.
4 Și Meșa, împăratul Moabului, era un stăpân de oi și a dat împăratului lui Israel o sută de mii de miei și o sută de mii de berbeci, cu lână.
Nísinsin yìí Meṣa ọba Moabu ń sin àgùntàn, ó sì gbọdọ̀ fi fún ọba Israẹli pẹ̀lú ọ̀kẹ́ márùn-ún ọ̀dọ́-àgùntàn àti pẹ̀lú irun ọ̀kẹ́ márùn-ún àgbò.
5 Dar s-a întâmplat, după ce a murit Ahab, că împăratul Moabului s-a răzvrătit împotriva împăratului lui Israel.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ikú Ahabu, ọba Moabu ṣọ̀tẹ̀ lórí ọba Israẹli.
6 Și împăratul Ioram a ieșit din Samaria în același timp și a numărat tot Israelul.
Lásìkò ìgbà yìí ọba Jehoramu jáde kúrò ní Samaria ó sì yí gbogbo Israẹli ní ipò padà.
7 Și a mers și a trimis la Iosafat, împăratul lui Iuda, spunând: Împăratul Moabului s-a răzvrătit împotriva mea, vei merge cu mine împotriva Moabului la bătălie? Iar el a spus: Mă voi urca; eu sunt precum ești tu, poporul meu precum poporul tău și caii mei precum caii tăi.
Ó sì ránṣẹ́ yìí sí Jehoṣafati ọba Juda pé, “Ọba Moabu sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi láti lọ bá Moabu jà?” Ọba Juda sì dáhùn pé, “Èmi yóò lọ pẹ̀lú rẹ. Èmi jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà, ènìyàn rẹ bí ènìyàn mi, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
8 Și a zis: Pe ce cale să ne urcăm? Iar el a răspuns: Pe calea pustiului Edomului.
“Nípa ọ̀nà wo ni àwa yóò gbà dojúkọ wọ́n?” Ó béèrè. “Lọ́nà aginjù Edomu,” ó dáhùn.
9 Astfel împăratul lui Israel a mers împreună cu împăratul lui Iuda și împăratul Edomului; și au făcut un ocol de șapte zile de călătorie; și nu era apă pentru oștire și pentru vitele care îi urmau.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli jáde lọ pẹ̀lú ọba Juda àti ọba Edomu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n yíká fún ọjọ́ méje. Àwọn ọmọ-ogun wọn kò ní omi púpọ̀ fún ara wọn tàbí fún ẹranko tí ó wà pẹ̀lú wọn.
10 Și împăratul lui Israel a spus: Vai, pentru că DOMNUL a chemat pe acești trei împărați împreună, pentru a-i da în mâna Moabului!
“Kí ni?” ọba Israẹli kígbe sókè. “Ṣé Olúwa pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́?”
11 Dar Iosafat a spus: Nu este aici un profet al DOMNULUI, ca să întrebăm pe DOMNUL prin el? Și unul dintre servitorii împăratului lui Israel a răspuns și a zis: Aici este Elisei, fiul lui Șafat, care turna apă pe mâinile lui Ilie.
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì wí pé, “Ṣé kò sí wòlíì Olúwa níbí, tí àwa ìbá ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?” Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ ọba Israẹli dáhùn pé, “Eliṣa ọmọ Ṣafati wà níbí. Ó máa sábà bu omi sí ọwọ́ Elijah.”
12 Și Iosafat a spus: Cuvântul DOMNULUI este cu el. Astfel, împăratul lui Israel și Iosafat și împăratul Edomului au coborât la el.
Jehoṣafati wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati àti ọba Edomu sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ.
13 Și Elisei i-a spus împăratului lui Israel: Ce am eu a face cu tine? Du-te la profeții tatălui tău și la profeții mamei tale. Și împăratul lui Israel i-a zis: Nu, pentru că DOMNUL a chemat pe acești trei împărați împreună, pentru a-i da în mâna Moabului.
Eliṣa wí fún ọba Israẹli pé, “Kí ni àwa ní ṣe pẹ̀lú ara wa? Lọ sọ́dọ̀ wòlíì baba rẹ àti wòlíì ti ìyá rẹ.” Ọba Israẹli dá a lóhùn, “Rárá, nítorí Olúwa ni ó pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́.”
14 Și Elisei a zis: Precum DOMNUL oștirilor trăiește, înaintea căruia stau în picioare, într-adevăr, dacă nu aș lua aminte la fața lui Iosafat, împăratul lui Iuda, nu m-aș uita la tine, nici nu te-aș vedea.
Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà láyé, ẹni tí mo ń sìn tí èmi kò bá ní ọ̀wọ̀ fún ojú Jehoṣafati ọba Juda, èmi kò ní wò ó tàbí èmi kì bá ti rí ọ.
15 Dar acum aduceți-mi un cântăreț cu harpă. Și s-a întâmplat, în timp ce cânta cântărețul cu harpă, că mâna DOMNULUI a venit peste el.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú wá fún mi ohun èlò orin olókùn.” Nígbà tí akọrin náà n kọrin, ọwọ́ Olúwa wá sórí Eliṣa.
16 Și el a spus: Astfel spune DOMNUL: Faceți în această vale groapă lângă groapă.
Ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Jẹ́ kí àfonífojì kún fún ọ̀gbun.’
17 Fiindcă astfel spune DOMNUL: Nu veți vedea vânt, nici nu veți vedea ploaie; totuși această vale va fi umplută cu apă, ca voi să beți, deopotrivă voi și vitele voastre și animalele voastre.
Nítorí èyí ni Olúwa wí, o kò ní í rí afẹ́fẹ́ tàbí òjò, bẹ́ẹ̀ ni àfonífojì yìí yóò kún pẹ̀lú omi, àti ìwọ àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹran yóò mu.
18 Și acesta este doar un lucru ușor înaintea ochilor DOMNULUI, el va da de asemenea pe moabiți în mâna voastră.
Èyí jẹ́ ohun tí kò lágbára níwájú Olúwa, yóò sì fi Moabu lé e yín lọ́wọ́ pẹ̀lú.
19 Și veți lovi fiecare cetate întărită și fiecare cetate aleasă și veți tăia fiecare copac bun și veți astupa toate fântânile de apă și veți strica cu pietre fiecare bucată bună de pământ.
Ìwọ yóò sì bi gbogbo ìlú olódi àti gbogbo àgbà ìlú ṣubú. Ìwọ yóò sì gé gbogbo igi dáradára ṣubú, dá gbogbo orísun omi dúró, kí o sì pa gbogbo pápá dáradára pẹ̀lú òkúta run.”
20 Și s-a întâmplat dimineața, când darul de mâncare era oferit că, iată, a venit apă de pe calea Edomului și țara s-a umplut cu apă.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ní àsìkò ẹbọ, níbẹ̀ ni omí sàn láti ọ̀kánkán Edomu! Ilé náà sì kún pẹ̀lú omi.
21 Și când toți moabiții au auzit că împărații s-au urcat să lupte împotriva lor, s-au adunat toți cei care erau în stare să poarte armură, și mai vârstnici, și au stat în picioare la graniță.
Nísinsin yìí gbogbo ará Moabu gbọ́ pé àwọn ọba tí dé láti bá wọn jà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn, ọmọdé àti àgbà tí ó lè ja ogun wọn pè wọ́n sókè wọ́n sì dúró ní etí ilẹ̀.
22 Și s-au sculat dis-de-dimineață și soarele a strălucit peste apă și moabiții au văzut apa roșie ca sângele de cealaltă parte;
Nígbà tí wọ́n dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, oòrùn ti tàn sí orí omi náà sí àwọn ará Moabu ní ìkọjá ọ̀nà, omi náà sì pupa bí ẹ̀jẹ̀.
23 Și au spus: Acesta este sânge; împărații sunt nimiciți cu desăvârșire și s-au lovit unul pe altul; și acum, Moabule, la pradă.
“Ẹ̀jẹ̀ ni èyí!” wọ́n wí pé, “Àwọn ọba wọ̀nyí lè ti jà kí wọn sì pa ara wọn ní ìpakúpa. Nísinsin yìí sí àwọn ìkógun Moabu!”
24 Și, când au ajuns la tabăra lui Israel, israeliții s-au ridicat și au lovit pe moabiți, astfel încât ei au fugit dinaintea lor; dar ei au mers înainte lovind pe moabiți, chiar în țara lor.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ará Moabu dé sí ibùdó ti Israẹli, àwọn ará Israẹli dìde, wọ́n sì kọlù wọ́n títí tí wọ́n fi sálọ. Àwọn ará Israẹli gbógun sí ilẹ̀ náà wọ́n sì pa Moabu run.
25 Și au dărâmat cetățile și pe fiecare bucată bună de pământ și-a aruncat fiecare om piatra lui și l-au umplut; și au astupat toate fântânile de apă și au tăiat fiecare copac bun; doar în Chir-Hareset au lăsat pietrele; totuși aruncătorii cu praștia l-au înconjurat și l-au lovit.
Wọ́n sì wọ gbogbo ìlú náà olúkúlùkù ènìyàn, wọ́n ju òkúta sí gbogbo ohun dáradára orí pápá títí tí ó fi run. Wọ́n sì dá gbogbo orísun omi dúró wọ́n sì gé gbogbo orísun dáradára. Kiri-Hareseti nìkan ni wọ́n fi òkúta rẹ̀ sílẹ̀ ní ààyè rẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ológun pẹ̀lú kànnàkànnà yíká, wọ́n sì kọlù ìlú náà.
26 Și când împăratul Moabului a văzut că bătălia era prea aspră pentru el, a luat cu el șapte sute de bărbați care scoteau săbiile, pentru a pătrunde până la împăratul Edomului; dar nu au putut.
Nígbà tí ọba Moabu rí i wí pé ogun náà le ju ti òun lọ, ó mú idà pẹ̀lú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ọkùnrin onídà láti jà pẹ̀lú ọba Edomu, ṣùgbọ́n wọn kò yege.
27 Atunci a luat pe cel mai în vârstă fiu al său care trebuia să domnească în locul său și l-a oferit ca ofrandă arsă pe zid. Și a fost mare indignare împotriva lui Israel; și au plecat de la el și s-au întors în țara lor.
Nígbà náà ó mú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀, tí kò bá jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọba, ó sì fi rú ẹbọ sísun ní orí ògiri ìlú. Wọ́n sì bínú lórí Israẹli púpọ̀púpọ̀; wọ́n yọ́ kúrò wọ́n sì padà sí ìlú wọn.

< 2 Regii 3 >