< 2 Regii 22 >

1 Iosia era în vârstă de opt ani când a început să domnească și a domnit treizeci și unu de ani în Ierusalim. Și numele mamei lui era Iedida, fiica lui Adaia, din Boțcat.
Josiah jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jedida ọmọbìnrin Adaiah; ó wá láti Boskati.
2 Și el a făcut ce este drept înaintea ochilor DOMNULUI și a umblat în toată calea lui David, tatăl său, și nu s-a abătut la dreapta sau la stânga.
Ó sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Dafidi baba a rẹ̀, kò sì yípadà sí apá ọ̀tún tàbí sí apá òsì.
3 Și s-a întâmplat, în anul al optsprezecelea al împăratului Iosia, că împăratul a trimis pe Șafan, fiul lui Ațalia, fiul lui Meșulam, scribul, la casa DOMNULUI, spunând:
Ní ọdún kejìdínlógún tí ó fi jẹ ọba. Ọba Josiah rán akọ̀wé, Ṣafani ọmọ Asalia, ọmọ Meṣullamu, sí ilé Olúwa. Ó wí pé,
4 Urcă-te la Hilchia, marele preot, ca el să socotească argintul adus în casa DOMNULUI, pe care păzitorii ușii l-au adunat de la popor;
“Gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, kí o sì jẹ́ kí ó ṣírò iye owó tí a mú wá sí ilé Olúwa, tí àwọn olùṣọ́nà ti gbà lọ́wọ́ àwọn ènìyàn.
5 Și să îi dea în mâna celor ce fac lucrarea, care au supravegherea casei DOMNULUI; și ei să îi dea celor ce fac lucrarea care este în casa DOMNULUI, pentru a repara spărturile casei,
Ẹ sì jẹ́ kí wọn ó fi lé àwọn ọkùnrin tí a ti yàn láti bojútó iṣẹ́ náà lórí ilé Olúwa. Kí ẹ sì jẹ́ kí àwọn ọkùnrin san án fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń tún ilé Olúwa ṣe.
6 Tâmplarilor și constructorilor și pietrarilor și pentru a cumpăra lemnărie și piatră cioplită pentru a repara casa.
Àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn akọ́lé. Bákan náà ni wọ́n ra igi àti òkúta ọlọ́ṣọ̀ọ́ láti fi tún tẹmpili ṣe.
7 Totuși nu a fost o numărătoare făcută cu ei despre banii dați în mâna lor, căci se purtau cu credincioșie.
Ṣùgbọ́n wọn kò ní láti ṣe ìṣirò fún owó náà tí a fi fún wọn, nítorí wọ́n ṣe òtítọ́.”
8 Și Hilchia, marele preot, i-a spus lui Șafan scribul: Am găsit cartea legii în casa DOMNULUI. Și Hilchia i-a dat lui Șafan cartea și el a citit-o.
Hilkiah olórí àlùfáà sọ fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi rí ìwé òfin nílé Olúwa.” Ó fi fún Ṣafani, ẹni tí ó kà á.
9 Și scribul Șafan a venit la împărat și a adus din nou cuvânt împăratului și a spus: Servitorii tăi au adunat banii care au fost găsiți în casă și i-au dat în mâna celor ce fac lucrarea, care au supravegherea casei DOMNULUI.
Nígbà náà, Ṣafani akọ̀wé lọ sí ọ̀dọ̀ ọba. Ó sì sọ fún un pé, “Àwọn ìjòyè rẹ ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa. Èmi sì ti fi lé ọwọ́ àwọn tí ó ń ṣe iṣẹ́ náà àti àwọn alábojútó nílé Olúwa.”
10 Și scribul Șafan i-a arătat împăratului, spunând: Preotul Hilchia mi-a dat o carte. Și Șafan a citit-o înaintea împăratului.
Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sọ fún ọba pé, “Hilkiah àlùfáà ti fún un ní ìwé kan.” Ṣafani kà lára rẹ̀ níwájú ọba.
11 Și s-a întâmplat, când împăratul a auzit cuvintele cărții legii, că și-a rupt hainele.
Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
12 Și împăratul i-a poruncit preotului Hilchia și lui Ahicam, fiul lui Șafan, și lui Acbor, fiul lui Micaia, și lui Șafan, scribul, și lui Asaia, un servitor al împăratului, spunând:
Ó pa àṣẹ yìí fún Ahikamu àlùfáà, Hilkiah ọmọ Ṣafani, Akbori ọmọ Mikaiah, àti Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
13 Mergeți, întrebați pe DOMNUL pentru mine și pentru popor și pentru tot Iuda referitor la cuvintele acestei cărți care a fost găsită, pentru că mare este furia DOMNULUI care s-a aprins împotriva noastră, pentru că părinții noștri nu au dat ascultare cuvintelor acestei cărți, pentru a face conform cu tot ce este scris despre noi.
“Lọ, ẹ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi àti fún àwọn ènìyàn àti fún gbogbo Juda nípa ohun tí a kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ń jó sí wa nítorí àwọn baba wa kò tẹ̀lé ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí; wọn kò ṣe ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ níbẹ̀ nípa wa.”
14 Astfel preotul Hilchia și Ahicam și Acbor și Șafan și Asaia au mers la profetesa Hulda, soția lui Șalum, fiul lui Ticva, fiul lui Harhas, păzitorul garderobei; (și ea locuia în Ierusalim în școala profeților) și au vorbit îndeaproape cu ea.
Hilkiah àlùfáà, Ahikamu àti Akbori Ṣafani pẹ̀lú Asaiah, lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin Hulda láti lọ bá a sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tikfa ọmọ Harhasi alábojútó ibi ìpa aṣọ mọ́ sí. Ó ń gbé ní Jerusalẹmu ní ìdàkejì.
15 Și ea le-a zis: Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Spuneți omului care v-a trimis la mine;
Ó wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Sọ fún ọkùnrin tí ó rán an yín sí mi,
16 Astfel spune DOMNUL: Iată, voi aduce răul asupra acestui loc și asupra locuitorilor lui, toate cuvintele cărții pe care împăratul lui Iuda le-a citit;
‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò mú ibi wá sí ibí àti àwọn ènìyàn rẹ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú ìwé tí ọba Juda ti kà.
17 Deoarece ei m-au părăsit și au ars tămâie altor dumnezei, ca să mă provoace la mânie cu toate lucrările mâinilor lor; de aceea furia mea se va aprinde împotriva acestui loc și nu se va stinge.
Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì tún sun tùràrí fún ọlọ́run mìíràn. Wọ́n sì mú mi bínú nípa gbogbo àwọn òrìṣà tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn dá. Ìbínú mi yóò ru sí ibí yìí, kì yóò sì rọlẹ̀.’
18 Dar împăratului lui Iuda, care v-a trimis să întrebați pe DOMNUL, astfel să îi spuneți: Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel cu privire la cuvintele pe care le-ai auzit;
Sọ fún ọba Juda tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí nípa ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí ìwọ ti gbọ́.
19 Pentru că inima ta a fost moale și te-ai umilit înaintea DOMNULUI când ai auzit ce am vorbit împotriva acestui loc și împotriva locuitorilor săi, că vor deveni o pustiire și un blestem, și ți-ai rupt hainele și ai plâns înaintea mea eu de asemenea te-am ascultat, spune DOMNUL.
Nítorí tí ọkàn rẹ rọ̀, tí ìwọ sì ti rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa, nígbà tí ìwọ gbọ́ èyí tí mo sọ sí ibí yìí àti sí àwọn ènìyàn rẹ pé wọn yóò di ahoro àti ẹni ègún tí ìwọ sì fa aṣọ ọ̀ rẹ ya pẹ̀lú níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ, ni Olúwa wí.
20 De aceea, iată, te voi aduna la părinții tăi și vei fi adunat în mormântul tău în pace; și ochii tăi nu vor vedea tot răul pe care îl voi aduce asupra acestui loc. Și au adus acest răspuns împăratului.
Nítorí náà èmi yóò kó ọ jọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baba à rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kì yóò rí gbogbo àwọn ibi tí èmi yóò mú wá bá ibí yìí.’” Bẹ́ẹ̀ wọ́n mú èsì rẹ̀ padà tọ ọba wá.

< 2 Regii 22 >