< 2 Cronici 31 >
1 Și, când toate acestea au fost terminate, tot Israelul, care era prezent, a plecat la cetățile lui Iuda și a spart idolii în bucăți și a retezat dumbrăvile și a dărâmat înălțimile și altarele din tot Iuda și Beniamin, de asemenea în Efraim și în Manase, până când le-au distrus în întregime pe toate. Apoi toți copiii lui Israel s-au întors, fiecare om la stăpânirea lui, în propriile lor cetăți.
Nígbà tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ti dé òpin, àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀ jáde lọ sí àwọn ìlú Juda, wọ́n fọ́ àwọn òkúta ìyàsọ́tọ̀ sí wẹ́wẹ́, wọ́n gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀. Wọ́n ba àwọn ibi gíga jẹ́ àti àwọn pẹpẹ jákèjádò Juda àti Benjamini àti ní Efraimu àti Manase. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti pa gbogbo wọn run, àwọn ọmọ Israẹli padà sí ìlú wọn àti sí nǹkan ìní wọn.
2 Și Ezechia a numit rândurile preoților și leviților după rândurile lor, fiecare om conform serviciului său, preoții și leviții pentru ofrande arse și ofrande de pace, să servească și să aducă mulțumiri și să laude în porțile taberelor DOMNULUI.
Hesekiah fi lé àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi lọ́wọ́ sí àwọn ìpín olúkúlùkù wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí ará Lefi láti tẹ́ ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ láti fi ọpẹ́ fún àti láti kọ àwọn orin ìyìn ní ẹnu-ọ̀nà ibùgbé Olúwa.
3 A rânduit de asemenea porția împăratului din averea lui pentru ofrande arse, adică, pentru ofrandele de dimineață și de seară și ofrandele pentru sabate și pentru lunile noi și pentru sărbătorile rânduite, precum este scris în legea DOMNULUI.
Ọba fi sílẹ̀ láti ara ohun ìní rẹ̀ fun ẹbọ sísun àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ àti fún ẹbọ sísun ní ọjọ́ ìsinmi, òṣùpá tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn gẹ́gẹ́ bi a ti ṣe kọ ọ́ nínú òfin Olúwa.
4 Mai mult, el a poruncit poporului, care locuia în Ierusalim, să dea porția preoților și leviților, ca să fie încurajați în legea DOMNULUI.
Ó pàṣẹ fún àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu láti fi ìpín tí ó yẹ fún àlùfáà fún un àti àwọn ará Lefi, kí wọn kí ó lè fi ara wọn jì fún òfin Olúwa.
5 Și imediat ce a ieșit porunca, copiii lui Israel au adus din abundență primele roade din grâne, vin și untdelemn și miere și din tot venitul câmpului; și zeciuiala tuturor lucrurilor au adus-o din abundență.
Ní kété tí àṣẹ náà jáde lọ, àwọn ọmọ Israẹli fi tìfẹ́tìfẹ́ fi àkọ́so ti ọkà wọn, ọtí tuntun, òróró àti oyin àti gbogbo ohun tí pápá mú jáde lélẹ̀. Wọ́n kó ọ̀pọ̀ iye, àti ìdámẹ́wàá gbogbo nǹkan wá.
6 Și copiii lui Israel și Iuda, care locuiau în cetățile lui Iuda, de asemenea au adus zeciuiala din boi și oi și zeciuiala din lucrurile sfinte, sfințite DOMNULUI Dumnezeul lor, și le-au așezat în grămezi.
Àwọn ọkùnrin Israẹli àti Juda ti gbe inú àwọn ìlú Juda pẹ̀lú mú ìdámẹ́wàá agbo ẹran àti ohun èlò àti ohun ọ̀sìn àti ìdámẹ́wàá ti àwọn nǹkan mímọ́ tí a ti yà sọ́tọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì kó wọn jọ ní òkìtì.
7 În a treia lună au început să pună temelia grămezilor și le-au terminat în a șaptea lună.
Wọ́n bẹ̀rẹ̀ ṣíṣe èyí ní oṣù kẹta, wọ́n sì parí ní oṣù keje.
8 Și când Ezechia și prinții au venit și au văzut grămezile, au binecuvântat pe DOMNUL și pe poporul său, Israel.
Nígbà tí Hesekiah àti àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ wá, tí wọ́n sì rí òkìtì náà, wọ́n yin Olúwa, pẹ̀lú ìbùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli.
9 Atunci Ezechia a întrebat pe prinți și pe leviți referitor la grămezi.
Hesekiah béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi nípa òkìtì;
10 Și Azaria, mai marele preot din casa lui Țadoc, i-a răspuns și a zis: De când poporul a început să aducă ofrande în casa DOMNULUI, am avut destul să mâncăm și a rămas mult, fiindcă DOMNUL a binecuvântat pe poporul său; și ceea ce a rămas este această mare bogăție.
àti Asariah olórí àlùfáà ti ìdílé Sadoku sì dáhùn pé, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní mú ìdáwó wọn wá sí ilé Olúwa àti ní èyí tí yóò tó jẹ àti ọ̀pọ̀ láti tọ́jú pamọ́ nítorí Olúwa ti bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ṣẹ́kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.”
11 Atunci Ezechia a poruncit să pregătească, în casa DOMNULUI, cămări; și ei le-au pregătit,
Hesekiah pàṣẹ láti tọ́jú àwọn yàrá ìṣúra nínú ilé Olúwa, wọ́n sì ṣe èyí.
12 Și au adus ofrandele și zeciuielile și lucrurile dedicate cu credincioșie, peste care Conania, levitul, era conducător, iar Șimei, fratele său, era al doilea.
Nígbà náà wọ́n mú ọrẹ àti ìdámẹ́wàá àti àwọn ẹ̀bùn tí a yà sí mímọ́ wọ ilé náà wá nítòótọ́. Lórí èyí tí Konaniah ọmọ Lefi, ń ṣe olórí, Ṣimei arákùnrin rẹ̀ ni igbákejì rẹ̀.
13 Și Iehiel și Azazia și Nahat și Asael și Ierimot și Iozabad și Eliel și Ismachia și Mahat și Benaia, erau supraveghetori sub mâna lui Conania și Șimei, fratele său, la porunca împăratului Ezechia și a lui Azaria, conducătorul casei lui Dumnezeu.
Jehieli, Asasiah, Nahati, Asaheli, Jerimoti, Josabadi, Elieli, Ismakia, Mahati àti Benaiah jẹ́ àwọn alábojútó lábẹ́ Konaniah àti Ṣimei arákùnrin rẹ̀ nípa ipá ọba Hesekiah àti Asariah olórí ti ó wà ní ìkáwọ́ ilé Ọlọ́run.
14 Și Core, fiul lui Imna, levitul, portarul spre est, era peste ofrandele de bunăvoie ale lui Dumnezeu, pentru a distribui darurile DOMNULUI și lucrurile preasfinte.
Kore ọmọ Imina ará Lefi olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ìlà-oòrùn, wà ní ìkáwọ́ àwọn ọrẹ àtinúwá tí a fi fún Ọlọ́run, o ń pín ìdáwó tí a ṣe fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn tí a yà sọ́tọ̀
15 Și sub mâna lui erau Eden și Miniamin și Ieșua și Șemaia, Amaria și Șecania, în cetățile preoților, în serviciul lor de încredere, ca să dea fraților lor după cete, celui mai mare, ca și celui mai mic,
Edeni, Miniamini, Jeṣua, Ṣemaiah, Amariah àti Ṣekaniah ràn án lọ́wọ́ tọkàntọkàn nínú àwọn ìlú àwọn àlùfáà tí ń dáwó fún àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àgbà àti kékeré.
16 În afară de cei de parte bărbătească înscriși în genealogie, de la vârsta de trei ani în sus, tuturor celor care intrau în casa Domnului, după datoria cerută de fiecare zi, pentru serviciul lor, în îndatoririle lor, după cetele lor;
Ní àfikún, wọ́n pín sí àwọn ọkùnrin àgbà ọdún mẹ́ta tàbí ọ̀pọ̀ tí orúkọ wọn wà nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn. Gbogbo àwọn ti yóò wọ ilé Olúwa láti ṣe oríṣìí iṣẹ́ ti a gbà wọ́n fún gẹ́gẹ́ bí ìgbẹ́kẹ̀lé wọn àti ìpín wọn.
17 Tot așa preoților înscriși după casele lor părintești, și leviților, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, în îndatoririle lor, după cetele lor;
Wọ́n sì pín àwọn àlùfáà, wọn kọ orúkọ àwọn ìdílé wọn sínú ìtàn ìdílé àti sí àwọn ará Lefi ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu àti ìpín wọn.
18 Și tuturor pruncilor lor, soțiilor lor, și fiilor lor, și fiicelor lor, întregii adunări a celor înscriși în genealogie, pentru că în credincioșia lor s-au sfințit pe ei înșiși, ca să fie sfinți.
Wọ́n fi gbogbo àwọn ọmọ kéékèèké sí i, àwọn ìyàwó, àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin gbogbo ará ìlú tí a kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé ti baba ńlá wọn fún ìrántí. Nítorí tí wọ́n ṣe òtítọ́ ní yíya ara wọn sí ọ̀tọ̀.
19 Și pentru fiii lui Aaron, preoții, care erau în ținuturile din împrejurimile cetăților lor, în fiecare cetate erau bărbați chemați pe nume, ca să dea porții tuturor celor de parte bărbătească dintre preoți și tuturor care erau socotiți în genealogii, printre leviți.
Ní ti àwọn àlùfáà, àwọn ìran ọmọ Aaroni, tí ń gbé ni àwọn ilẹ̀ oko lẹ́bàá àwọn ìlú wọn tàbí ní àwọn ìlú mìíràn. A yan àwọn ọkùnrin pẹ̀lú orúkọ láti pín ìlú fún gbogbo ọkùnrin láàrín wọn àti sí gbogbo àwọn tí a kọ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá àwọn ará Lefi.
20 Și astfel a făcut Ezechia prin tot Iuda și a lucrat ceea ce era bun și drept înaintea DOMNULUI Dumnezeul său.
Èyí ni Hesekiah ṣe jákèjádò Juda, ó sì ṣe ohun tí ó dára àti tí ó tọ́ àti ohun òtítọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
21 Și în fiecare lucrare pe care a început-o în serviciul casei lui Dumnezeu, și în lege și în porunci, pentru a căuta pe Dumnezeul său, a făcut-o cu toată inima sa și a prosperat.
Nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé ní ti iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Ọlọ́run àti ní ìgbọ́ràn sí òfin àti àwọn àṣẹ. Ó wá Ọlọ́run rẹ̀, ó sì ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn. Ó sì ṣe rere.