< 1 Samuel 9 >

1 Și era un om din Beniamin al cărui nume era Chiș, fiul lui Abiel, fiul lui Țeror, fiul lui Becorat, fiul lui Afiah, un beniamit, un bărbat puternic și viteaz.
Ará Benjamini kan wà, ẹni tí ó jẹ́ aláàánú ọlọ́rọ̀, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kiṣi, ọmọ Abieli, ọmọ Serori, ọmọ Bekorati, ọmọ Afiah ti Benjamini.
2 Și el avea un fiu, al cărui nume era Saul, un tânăr ales și frumos; și nu era printre copiii lui Israel o persoană mai frumoasă decât el; de la umerii săi în sus el era mai înalt decât oricine din popor.
Ó ní ọmọkùnrin kan tí à ń pè ní Saulu, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó yanjú, tí ó jẹ́ arẹwà, tí kò sí ẹni tó ní ẹwà jù ú lọ láàrín gbogbo àwọn ọmọ Israẹli—láti èjìká rẹ̀ lọ sí òkè, ó ga ju gbogbo àwọn ènìyàn tókù lọ.
3 Și măgărițele lui Chiș, tatăl lui Saul, se pierduseră. Și Chiș i-a spus lui Saul, fiul său: Ia acum cu tine pe unul dintre servitori și ridică-te, du-te să cauți măgărițele.
Nísinsin yìí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó jẹ́ ti Kiṣi baba Saulu sì sọnù. Nígbà náà, Kiṣi sọ fún Saulu ọmọ rẹ̀ pé, “Mú ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ pẹ̀lú rẹ kí ẹ lọ láti wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.”
4 Și el a trecut prin muntele Efraim și a trecut prin țara Șalișa, dar nu le-a găsit; apoi au trecut prin țara Șaalim și nu erau acolo; și a trecut prin țara beniamiților dar nu le-a găsit.
Bẹ́ẹ̀ ní ó kọjá láàrín àwọn ìlú olókè Efraimu, ó sì kọjá ní àyíká ilẹ̀ Ṣaliṣa, ṣùgbọ́n wọn kò rí wọn. Wọ́n sì kọjá lọ sí òpópó Ṣaalimu, ṣùgbọ́n àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kò sí níbẹ̀. Nígbà náà, ó kọjá ní agbègbè Benjamini, wọn kò sì rí wọn.
5 Și când au ajuns în țara Țuf, Saul a spus servitorului său care era cu el: Vino și să ne întoarcem, ca nu cumva tatălui meu să nu îi mai pese de măgărițe și să se îngrijoreze pentru noi.
Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Sufu, Saulu sọ fún ìránṣẹ́ tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí á padà sẹ́yìn, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, baba mi yóò dá ìrònú rẹ̀ dúró nípa àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ yóò sì bẹ̀rẹ̀ àníyàn nípa wa.”
6 Și el i-a spus: Iată acum, este în această cetate un om al lui Dumnezeu și el este un bărbat demn de cinste; tot ce spune el se întâmplă; acum să mergem acolo; s-ar putea să ne arate calea pe care să mergem.
Ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ náà fún un ní èsì pé, “Wò ó, ní inú ìlú yìí ọkùnrin ènìyàn Ọlọ́run kan wà; ó jẹ́ ẹni tí wọ́n ń bu ọlá fún, àti gbogbo ohun tí ó bá sọ ní ó máa ń jẹ́ òtítọ́. Jẹ́ kí á lọ síbẹ̀ nísinsin yìí, bóyá yóò sọ fún wá ọ̀nà tí a yóò gbà.”
7 Atunci Saul a spus servitorului său: Dar, iată, dacă mergem, ce să ducem omului acesta? Pentru că pâinea s-a terminat din sacii noștri și nu este vreun dar de adus omului lui Dumnezeu; ce avem noi?
Saulu sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀, “Tí àwa bá lọ, kín ni àwa lè fún ọkùnrin náà? Oúnjẹ inú àpò wa ti tán. A kò sì ní ẹ̀bùn láti mú lọ sọ́dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Kí ni a ní?”
8 Și servitorul a răspuns din nou lui Saul și a zis: Iată, am aici la îndemână a patra parte dintr-un șekel de argint; pe acesta îl voi da omului lui Dumnezeu, ca să ne spună calea.
Ìránṣẹ́ sì dá a lóhùn lẹ́ẹ̀kan sí i. “Wò ó,” ó wí pé, “Mo ní ìdámẹ́rin ṣékélì fàdákà lọ́wọ́. Èmi yóò fún ènìyàn Ọlọ́run náà kí ó lè fi ọ̀nà hàn wá.”
9 (Înainte, în Israel, când un om mergea să îl întrebe pe Dumnezeu, astfel vorbea: Veniți și să mergem la văzător, pentru că cel care este acum numit Profet înainte era numit Văzător.)
(Tẹ́lẹ̀ ní Israẹli tí ọkùnrin kan bá lọ béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run, yóò wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì náà,” nítorí àwọn alásọtẹ́lẹ̀ ìsinsin yìí ni wọ́n ń pè ní wòlíì).
10 Atunci Saul a spus servitorului său: Bine spus; vino, să mergem. Astfel au mers la cetatea unde era omul lui Dumnezeu.
Saulu sọ fún ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ pé ó dára, “Jẹ́ kí a lọ.” Wọ́n jáde lọ sí ìlú tí ènìyàn Ọlọ́run náà ń gbé.
11 Și cum urcau dealul cetății, au găsit niște tinere servitoare ieșind să scoată apă și le-au spus: Este văzătorul aici?
Bí wọ́n ṣe ń lọ ní orí òkè sí ìlú náà, wọ́n pàdé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin tí ó ń jáde í bọ̀ láti wá pọn omí. Wọ́n sì bi wọ́n, “Ṣé wòlíì náà wà níbí?”
12 Și ele le-au răspuns și au zis: Este, iată, el este înaintea voastră; grăbiți-vă acum, pentru că a venit astăzi în cetate, fiindcă poporul aduce un sacrificiu pe înălțime;
“Ó wà,” wọ́n dáhùn. “Ó ń bẹ níwájú u yín, múra nísinsin yìí, ó ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ wa lónìí ni, nítorí àwọn ènìyàn ní ẹbọ rírú ni ibi gíga.
13 Îndată ce veți fi intrat în cetate, îl veți găsi imediat, înainte să se urce la locul înalt să mănânce, pentru că poporul nu va mânca până când nu va veni el, deoarece el binecuvântează sacrificiul; și după aceea mănâncă cei chemați. De aceea acum, urcați-vă, căci pe la acest timp îl veți găsi.
Kété tí ẹ bá ti wọ ìlú, ẹ ó rí i kí ó tó lọ sí ibi gíga láti lọ jẹun. Àwọn ènìyàn kò sì ní bẹ̀rẹ̀ sí jẹun títí tí yóò fi dé. Torí ó gbọdọ̀ bùkún ẹbọ náà; lẹ́yìn náà, àwọn tí a pè yóò jẹun. Gòkè lọ nísinsin yìí, ó yẹ kí ẹ rí i ní àkókò yìí.”
14 Și s-au urcat în cetate; și când au intrat în cetate, iată, Samuel ieșea spre ei, ca să se urce la locul înalt.
Wọ́n gòkè lọ sí ìlú náà, bí wọ́n ti ń wọlé, níbẹ̀ ni Samuẹli, ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ wọn bí ó ti ń lọ ibi gíga náà.
15 Și DOMNUL îi spusese la ureche lui Samuel cu o zi înainte ca Saul să vină, zicând:
Olúwa ti sọ létí Samuẹli ní ọjọ́ kan kí Saulu ó tó dé pé,
16 Mâine, cam pe timpul acesta, voi trimite la tine un om din țara lui Beniamin și tu să îl ungi să fie căpetenie peste poporul meu Israel, ca să salveze pe poporul meu din mâna filistenilor, pentru că am privit la poporul meu, deoarece strigătul lor a ajuns până la mine.
“Ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò ran ọmọkùnrin kan sí ọ láti ilẹ̀ Benjamini. Fi òróró yàn án gẹ́gẹ́ bí olórí lórí àwọn ọmọ Israẹli, yóò gba àwọn ènìyàn mi kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Filistini. Mo ti bojú wo àwọn ènìyàn mi, nítorí igbe wọn ti dé ọ̀dọ̀ mi.”
17 Și când Samuel l-a văzut pe Saul, DOMNUL i-a spus: Iată, pe omul despre care ți-am vorbit! Acesta va domni peste poporul meu.
Nígbà tí Samuẹli fojúrí Saulu, Olúwa sọ fún un pé, “Èyí ni ọkùnrin tí mo sọ fún ọ nípa rẹ̀, yóò darí àwọn ènìyàn mi.”
18 Atunci Saul s-a apropiat de Samuel la poartă și a zis: Spune-mi, te rog, unde este casa văzătorului.
Saulu sì súnmọ́ Samuẹli ní ẹnu-ọ̀nà ìlú, ó sì wí pé, “Sọ fún mi èmi ń bẹ̀ ọ́ níbo ni ilé wòlíì náà wà.”
19 Și Samuel i-a răspuns lui Saul și a zis: Eu sunt văzătorul; urcă-te înaintea mea la locul înalt, fiindcă veți mânca astăzi cu mine; și mâine te voi lăsa să pleci și îți voi spune tot ce este în inima ta.
Samuẹli dáhùn pé, “Èmi ni wòlíì náà. Ẹ máa gòkè lọ ṣáájú mi, ní ibi gíga, ẹ ó sì bá mi jẹun lónìí. Ní òwúrọ̀ ni èmi yóò tó jẹ́ kí ẹ lọ, gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ ní èmi yóò sọ fún ọ.
20 Și cât despre măgărițele care s-au pierdut cu trei zile în urmă, nu te mai gândi la ele, pentru că s-au găsit. Și asupra cui este toată dorința lui Israel? Nu este asupra ta și asupra întregii case a tatălui tău?
Fún ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sọnù fún ọjọ́ mẹ́ta sẹ́yìn, má ṣe dààmú nípa wọ́n: a ti rí wọn. Sí ta ni gbogbo ìfẹ́ Israẹli wà? Bí kì í ṣe sí ìwọ àti sí gbogbo ilé baba à rẹ.”
21 Și Saul a răspuns și a zis: Nu sunt eu un beniamit, din cel mai mic dintre triburile lui Israel, și familia mea este cea mai mică dintre toate familiile tribului lui Beniamin? Pentru ce atunci îmi vorbești astfel?
Saulu dáhùn pé, “Ṣùgbọ́n èmi kì í há ṣe ẹ̀yà Benjamini? Kékeré nínú ẹ̀yà Israẹli. Ìdílé mi kò ha rẹ̀yìn jùlọ nínú gbogbo ẹ̀yà Benjamini? Èéṣì ti ṣe tí ìwọ sọ̀rọ̀ yìí sí mi?”
22 Și Samuel l-a luat pe Saul și pe servitorul său și i-a dus în cameră și i-a pus să șadă în locul cel mai important printre cei chemați, care erau cam treizeci de persoane.
Nígbà náà ni Samuẹli mú Saulu pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ inú gbọ̀ngán, ó sì mú wọn jókòó sí iwájú àwọn tí a pè—tí wọn tó ọgbọ̀n.
23 Și Samuel a spus bucătarului: Adu porția pe care ți-am dat-o, despre care ți-am spus: Pune-o lângă tine.
Samuẹli sọ fún alásè pé, “Mú ìpín ẹran tí mo fún ọ wá, èyí tí mo sọ fún ọ pé kí o yà sọ́tọ̀.”
24 Și bucătarul a ridicat spata și ceea ce era pe ea și a pus-o înaintea lui Saul. Și Samuel a zis: Iată, ceea ce a fost păstrat! Pune-o înaintea ta, mănâncă, pentru că a fost păstrată pentru tine, pentru acest timp, de când am spus: Voi invita poporul. Și Saul a mâncat cu Samuel în acea zi.
Alásè náà sì gbé ẹsẹ̀ náà pẹ̀lú ohun tí ó wà lórí i rẹ̀, ó sì gbé e síwájú Saulu. Samuẹli wí pé, “Èyí ni ohun tí a fi pamọ́ fún ọ. Jẹ, nítorí a yà á sọ́tọ̀ fún ọ, fún ìdí yìí, láti ìgbà tí mo ti wí pé, ‘Mo ní àlejò tí a pè.’” Saulu sì jẹun pẹ̀lú Samuẹli ní ọjọ́ náà.
25 Și după ce au coborât de pe locul înalt în cetate, Samuel a vorbit îndeaproape cu Saul pe acoperișul casei.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọn ti sọ̀kalẹ̀ láti ibí gíga náà wá sí inú ìlú, Samuẹli sì bá Saulu sọ̀rọ̀ lórí òrùlé ilé e rẹ̀.
26 Și s-au sculat devreme; și s-a întâmplat, pe când se revărsau zorile, că Samuel l-a chemat pe Saul pe acoperișul casei, spunând: Sus, ca să te trimit. Și Saul s-a sculat și au ieșit amândoi, el și Samuel, afară.
Wọ́n sì dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́, ó pe Saulu sórí òrùlé pé, “Múra, èmi yóò rán ọ lọ.” Nígbà tí Saulu múra tán òun àti Samuẹli jọ jáde lọ síta.
27 Și pe când coborau la marginea cetății, Samuel i-a spus lui Saul: Spune servitorului să treacă înaintea noastră (și el a trecut) dar tu stai pe loc un timp, ca să îți arăt cuvântul lui Dumnezeu.
Bí wọ́n ti ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìpẹ̀kun ìlú náà, Samuẹli wí fún Saulu pé, “Sọ fún ìránṣẹ́ náà kí ó máa lọ ṣáájú u wa,” ìránṣẹ́ náà sì ṣe bẹ́ẹ̀, “Ṣùgbọ́n kí ìwọ kí ó dúró díẹ̀, kí èmi kí ó lè sọ ọrọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún ọ.”

< 1 Samuel 9 >