< 1 Samuel 30 >

1 Și s-a întâmplat, când David și oamenii săi au venit la Țiclag în a treia zi, că amaleciții invadaseră sudul și Țiclagul și loviseră Țiclagul și îl arseseră cu foc;
Ó sì ṣe nígbà ti Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì bọ̀ sí Siklagi ní ọjọ́ kẹta, àwọn ará Amaleki sì ti kọlu ìhà gúúsù, àti Siklagi, wọ́n sì ti kùn ún ní iná.
2 Și luaseră captive pe femeile care erau în el; nu au ucis pe niciuna, fie mare sau mică, ci le-au dus și au mers pe calea lor.
Wọ́n sì kó àwọn obìnrin tí ń bẹ nínú rẹ̀ ní ìgbèkùn, wọn kò sì pa ẹnìkan, ọmọdé tàbí àgbà, ṣùgbọ́n wọ́n kó wọn lọ, wọ́n sì bá ọ̀nà tiwọn lọ.
3 Astfel David și oamenii săi au venit în cetate și, iată, aceasta era arsă cu foc; și soțiile lor și fiii lor și fiicele lor, erau luate captive.
Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin sì wọ ìlú Siklagi, sì wò ó, a ti kùn ún ni iná; àti obìnrin wọn, àti ọmọkùnrin wọn àti ọmọbìnrin wọn ni a kó ni ìgbèkùn lọ.
4 Atunci David și poporul care era cu el și-au înălțat vocea și au plâns până nu au mai avut putere să plângă.
Dafidi àti àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún títí agbára kò fi sí fún wọn mọ́ láti sọkún.
5 Și cele două soții ale lui David erau luate captive: Ahinoam izreelita și Abigail carmelita, soția lui Nabal.
A sì kó àwọn aya Dafidi méjèèjì nígbèkùn lọ, Ahinoamu ará Jesreeli àti Abigaili aya Nabali ará Karmeli.
6 Și David era foarte strâmtorat, pentru că poporul vorbea să îl împroaște cu pietre deoarece sufletul întregului popor era mâhnit, fiecare om pentru fiii săi și pentru fiicele sale; dar David s-a încurajat în DOMNUL Dumnezeul său.
Dafidi sì banújẹ́ gidigidi, nítorí pé àwọn ènìyàn náà sì ń sọ̀rọ̀ láti sọ ọ́ lókùúta, nítorí ti inú gbogbo àwọn ènìyàn náà sì bàjẹ́, olúkúlùkù ọkùnrin nítorí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti nítorí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣùgbọ́n Dafidi mú ara rẹ̀ lọ́kàn le nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
7 Și David a spus preotului Abiatar, fiul lui Ahimelec: Te rog, adu-mi aici efodul. Și Abiatar a adus efodul acolo la David.
Dafidi sì wí fún Abiatari àlùfáà, ọmọ Ahimeleki pé, èmí bẹ̀ ọ́, mú efodu fún mi wá níhìn-ín yìí. Abiatari sì mú efodu náà wá fún Dafidi.
8 Și David a întrebat pe DOMNUL, spunând: Să urmăresc această ceată înarmată? Să o ajung? Și el i-a răspuns: Urmărește-i, pentru că într-adevăr îi vei ajunge și negreșit vei lua înapoi totul.
Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa wí pé, “Kí èmi ó lépa ogun yìí bi? Èmi lè bá wọn?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Lépa, nítorí pé ni bíbá ìwọ yóò bá wọn, ni gbígbà ìwọ yóò sì rí wọn gbà.”
9 Astfel David a mers, el și cei șase sute de oameni care erau cu el și au ajuns la pârâul Besor, unde cei care au rămas în urmă s-au oprit.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wá sí ibi àfonífojì Besori, apá kan sì dúró.
10 Dar David i-a urmărit, el și patru sute de oameni, pentru că două sute au rămas în urmă, cei care erau atât de obosiți încât nu puteau să treacă pârâul Besor.
Ṣùgbọ́n Dafidi àti irinwó ọmọkùnrin lépa wọn: igba ènìyàn tí àárẹ̀ mú, tiwọn kò lè kọjá odò Besori sì dúró lẹ́yìn.
11 Și au găsit un egiptean în câmp și l-au adus la David și i-au dat pâine și el a mâncat; și l-au făcut să bea apă;
Wọ́n sì rí ará Ejibiti kan ní oko, wọ́n sì mú un tọ Dafidi wá, wọ́n sì fún un ní oúnjẹ, ó sì jẹ; wọ́n sì fún un ní omi mu.
12 Și i-au dat o bucată de turtă de smochine și doi ciorchini de stafide; și după ce a mâncat, duhul lui i-a revenit, pentru că nu mâncase pâine, nici nu băuse apă trei zile și trei nopți.
Wọ́n sì fún un ní àkàrà, èso ọ̀pọ̀tọ́ àti síírí àjàrà gbígbẹ́ méjì: nígbà tí ó sì jẹ ẹ́ tán, ẹ̀mí rẹ̀ sì sọjí: nítorí pé kò jẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi ní ọjọ́ mẹ́ta ní ọ̀sán, àti ní òru.
13 Și David i-a spus: Al cui ești? Și de unde ești? Și el a spus: Eu sunt un tânăr din Egipt, servitor al unui amalecit; și stăpânul meu m-a lăsat, pentru că acum trei zile am căzut bolnav.
Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ? Àti níbo ni ìwọ ti wá?” Òun sì wí pé, “Ọmọ ará Ejibiti ni èmi, ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin kan ará Amaleki. Olúwa mi fi mí sílẹ̀, nítorí pé láti ọjọ́ mẹ́ta ni èmi ti ṣe àìsàn.
14 Noi am invadat în partea de sud a cheretiților și în ținutul care aparține de Iuda și în partea de sud a lui Caleb; și am ars Țiclagul cu foc.
Àwa sì gbé ogun lọ sí ìhà gúúsù tí ará Kereti, àti sí ìhà ti Juda, àti sí ìhà gúúsù ti Kalebu; àwa sì kun Siklagi ní iná.”
15 Și David i-a spus: Poți să mă cobori la această ceată? Iar el a spus: Jură-mi pe Dumnezeu că nici nu mă vei ucide nici nu mă vei da în mâinile stăpânului meu și te voi coborî la această ceată.
Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ìwọ lè mú mí sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun yìí lọ bí?” Òun sì wí pé, “Fi Ọlọ́run búra fún mi pé, ìwọ kì yóò pa mí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò sì fi mi lé olúwa mi lọ́wọ́; èmi yóò sì mú ọ sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun náà lọ.”
16 Și după ce l-a coborât, iată, ei erau împrăștiați pe toată fața pământului, mâncând și bând și dansând, pentru toată prada cea mare pe care o luaseră din țara filistenilor și din țara lui Iuda.
Ó sì mú un sọ̀kalẹ̀, sì wò ó, wọ́n sì tàn ká ilẹ̀, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n sì ń jó, nítorí ìkógun púpọ̀ tí wọ́n kó láti ilẹ̀ àwọn Filistini wá, àti láti ilẹ̀ Juda.
17 Și David i-a lovit din amurg chiar până în seara zilei următoare; și nu a scăpat niciun om dintre ei, în afară de patru sute de tineri, care au călărit pe cămile și au fugit.
Dafidi sì pa wọ́n láti àfẹ̀mọ́júmọ́ títí ó fi di àṣálẹ́ ọjọ́ kejì: kò sí ẹnìkan tí ó là nínú wọn, bí kọ̀ ṣe irinwó ọmọkùnrin tí wọ́n gun ìbákasẹ tí wọ́n sì sá.
18 Și David a luat înapoi tot ceea ce amaleciții duseseră; și David și-a eliberat pe cele două soții.
Dafidi sì gbà gbogbo nǹkan tí àwọn ará Amaleki ti kó: Dafidi sì gba àwọn obìnrin rẹ̀ méjèèjì.
19 Și nimic nu le lipsea, fie mic sau mare, nici fii, nici fiice, nici pradă, nici vreun lucru pe care li-l luaseră: David a recuperat totul.
Kò sì ṣí nǹkan tí ó kù fún wọn, kékeré tàbí ńlá, ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin, tàbí ìkógun, tàbí gbogbo nǹkan tí wọ́n ti kó: Dafidi sì gba gbogbo wọn.
20 Și David a luat toate turmele și cirezile, pe care le-au mânat înaintea celorlalte vite și au spus: Aceasta este prada lui David.
Dafidi sì kó gbogbo àgùntàn, àti màlúù tí àwọn ènìyàn rẹ̀ dà ṣáájú àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn tí wọ́n gbà, wọ́n sì wí pé, “Èyí yìí ni ìkógun ti Dafidi.”
21 Și David a venit la cei două sute de bărbați, care erau atât de obosiți încât nu l-au putut urma pe David, pe care îi făcuseră să rămână la pârâul Besor; și ei au ieșit să îl întâmpine pe David și să întâlnească poporul care era cu el; și când David s-a apropiat de popor, i-a salutat.
Dafidi sì wá sọ́dọ̀ igba ọkùnrin tí àárẹ̀ ti mú jú, tiwọn kò lè tọ́ Dafidi lẹ́yìn mọ́, ti òun ti fi sílẹ̀, ni àfonífojì Besori: wọ́n sì lọ pàdé Dafidi, àti láti pàdé àwọn ènìyàn tí ó lọ pẹ̀lú rẹ̀: Dafidi sì pàdé àwọn ènìyàn náà, ó sì kí wọn.
22 Atunci au răspuns toți oamenii stricați și ai lui Belial, dintre cei care au mers cu David și au zis: Căci ei nu au mers cu noi, nu le vom da nimic din prada pe care am luat-o înapoi, ci doar fiecărui bărbat soția sa și copiii săi, ca să îi ducă și să plece.
Gbogbo àwọn ènìyàn búburú àti àwọn ọmọ Beliali nínú àwọn tí o bá Dafidi lọ sì dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Bí wọn kò ti bá wa lọ, àwa ki yóò fi nǹkan kan fún wọn nínú ìkógun ti àwa rí gbà bí kò ṣe obìnrin olúkúlùkù wọn, àti ọmọ wọn; ki wọn sì mú wọn, ki wọn sì máa lọ.”
23 Atunci David a spus: Să nu faceți astfel, frații mei, cu ceea ce ne-a dat DOMNUL, care ne-a păstrat și a dat în mâna noastră ceata care a venit împotriva noastră.
Dafidi sì wí pé, “Ẹ má ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ara mi: Olúwa ni ó fi nǹkan yìí fún wa, òun ni ó sì pa wá mọ́, òun ni ó sì fi ẹgbẹ́ ogun ti ó dìde sí wa lé wa lọ́wọ́.
24 Fiindcă cine vă va da ascultare în acest lucru? Ci cum este partea celui care coboară la bătălie, tot astfel să fie partea celui care rămâne lângă lucruri, vor împărți la fel.
Ta ni yóò gbọ́ tiyín nínú ọ̀ràn yìí? Ṣùgbọ́n bi ìpín ẹni tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ si ìjà ti rí, bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ti ó dúró ti ẹrù; wọn ó sì pín in bákan náà.”
25 Și a fost astfel din acea zi înainte, că el a făcut din aceasta un statut și o rânduială pentru Israel până astăzi.
Láti ọjọ́ náà lọ, ó sì pàṣẹ, ó sì sọ ọ di òfin fún Israẹli títí di òní yìí.
26 Și când David a venit la Țiclag, a trimis din pradă bătrânilor lui Iuda, chiar prietenilor săi, spunând: Iată, un dar pentru voi, din prada dușmanilor DOMNULUI;
Dafidi sì padà sí Siklagi, ó sì rán nínú ìkógun náà si àwọn àgbàgbà Juda, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ni ẹ̀bùn fún un yín, láti inú ìkógun àwọn ọ̀tá Olúwa wa.”
27 Celor din Betel și celor din sudul Ramotului și celor din Iatir,
Ó sì rán an sí àwọn tí ó wà ni Beteli àti sí àwọn tí ó wà ní gúúsù tí Ramoti, àti sí àwọn tí ó wà ní Jattiri.
28 Și celor din Aroer și celor din Sifmot și din Eștemoa,
Àti sí àwọn tí ó wà ní Aroeri, àti sí àwọn tí ó wà ní Sifimoti, àti sí àwọn tí ó wà ni Eṣitemoa.
29 Și celor din Racal și celor din cetățile ierahmeeliților și celor din cetățile cheniților,
Àti si àwọn tí ó wà ni Rakeli, àti sí àwọn tí ó wà ní ìlú àwọn Jerahmeeli, àti sí àwọn tí ó wà ni ìlú àwọn ará Keni,
30 Și celor din Horma și celor din Cor-Așan și din Atac,
àti sí àwọn tí ó wà ni Horma, àti sí àwọn ti ó wà ní Bori-Aṣani, àti sí àwọn tí ó wà ni Ataki.
31 Și celor din Hebron și tuturor locurilor unde David însuși și oamenii săi aveau obiceiul să meargă.
Àti àwọn tí ó wà ni Hebroni, àti sí gbogbo àwọn ìlú ti Dafidi tìkára rẹ̀ àti tí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ máa ń rìn ká.

< 1 Samuel 30 >