< 1 Samuel 20 >

1 Și David a fugit din Naiot, din Rama, și a venit și a spus înaintea lui Ionatan: Ce am făcut? Care este nelegiuirea mea? Și care este păcatul meu înaintea tatălui tău, încât el îmi caută viața?
Nígbà náà ni Dafidi sá kúrò ní Naioti ti Rama ó sì lọ sọ́dọ̀ Jonatani ó sì béèrè pé, “Kí ni mo ṣe? Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Báwo ni mo ṣe ṣẹ baba rẹ, tí ó sì ń wá ọ̀nà láti gba ẹ̀mí mi?”
2 Și Ionatan i-a spus: Nicidecum; nu vei muri; Iată, tatăl meu nu va face niciun lucru mare sau mic fără să mi-l arate; și pentru ce ar ascunde tatăl meu acest lucru de mine? Nu este așa.
Jonatani dáhùn pé, “Kí a má rí i! Ìwọ kò ní kú! Wò ó baba mi kì í ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí tí ó kéré, láìfi lọ̀ mí. Èéṣe tí yóò fi fi èyí pamọ́ fún mi? Kò rí bẹ́ẹ̀.”
3 Și David a jurat din nou și a spus: Tatăl tău știe într-adevăr că am găsit favoare în ochii tăi; și spune: Să nu știe Ionatan aceasta, ca nu cumva să se mâhnească; Dar cu adevărat, precum DOMNUL trăiește și precum sufletul tău trăiește, nu este decât un pas între mine și moarte.
Ṣùgbọ́n Dafidi tún búra, ó sì wí pé, “Baba rẹ mọ̀ dáradára pé mo rí ojúrere ní ojú rẹ, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, ‘Jonatani kò gbọdọ̀ mọ èyí yóò sì bà á nínú jẹ́.’ Síbẹ̀ nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè àti gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà láààyè, ìgbésẹ̀ kan ni ó wà láàrín ìyè àti ikú.”
4 Atunci Ionatan i-a spus lui David: Orice dorește sufletul tău, voi face pentru tine.
Jonatani wí fún Dafidi pé, “Ohunkóhun tí ìwọ bá ń fẹ́ kí èmi kí ó ṣe, èmi yóò ṣe é fún ọ.”
5 Și David i-a spus lui Ionatan: Iată, mâine este lună nouă și nu trebuie să lipsesc de la a ședea cu împăratul la masă; dar tu lasă-mă să merg să mă ascund în câmp până în a treia zi seara.
Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Wò ó, ọ̀la ni oṣù tuntun, mo sì gbọdọ̀ bá ọba jẹun, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó lọ láti fi ara pamọ́ lórí pápá títí di àṣálẹ́ ọjọ́ kẹta.
6 Dacă îi voi lipsi cât de cât tatălui tău, atunci spune: David mi-a cerut insistent să alerge până la Betleem, cetatea sa, pentru că acolo este un sacrificiu anual pentru toată familia.
Bí ó bá sì ṣe pé baba rẹ bá fẹ́ mi kù, kí o sì wí fún un pé, ‘Dafidi fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ béèrè ààyè láti sáré lọ sí Bẹtilẹhẹmu ìlú rẹ̀ nítorí wọ́n ń ṣe ẹbọ ọdọọdún ní ibẹ̀ fún gbogbo ìdílé rẹ̀.’
7 Dacă el spune astfel: Este bine; servitorul tău va avea pace; dar dacă se va înfuria, atunci fii sigur că răul este hotărât de el.
Tí o bá wí pé, ‘Àlàáfíà ni,’ nígbà náà, ìránṣẹ́ rẹ wà láìléwu. Ṣùgbọ́n tí ó bá bínú gidigidi, ìwọ yóò mọ̀ dájú pé ó pinnu láti ṣe ìpalára mi.
8 De aceea să te porți cu bunătate cu servitorul tău, pentru că ai adus pe servitorul tău într-un legământ al DOMNULUI cu tine; totuși, dacă este nelegiuire în mine, ucide-mă tu însuți, pentru că de ce m-ai aduce la tatăl tău?
Ṣùgbọ́n ní tìrẹ ìwọ, fi ojúrere wo ìránṣẹ́ rẹ; nítorí tí ìwọ ti bá a dá májẹ̀mú pẹ̀lú rẹ níwájú Olúwa. Tí mo bá jẹ̀bi, pa mí fún ara rẹ! Èéṣe tí ìwọ yóò fi fi mí lé baba rẹ lọ́wọ́?”
9 Și Ionatan a spus: Departe fie aceasta de tine; dacă aș fi știut într-adevăr că răul este hotărât de tatăl meu să vină asupra ta, nu ți-aș fi spus?
Jonatani wí pé, “Kí a má rí i! Ti mo bá ti gbọ́ tí baba mi ti pinnu láti pa ọ́ lára, ṣé èmi kò ní sọ fún ọ?”
10 Atunci David i-a spus lui Ionatan: Cine îmi va spune? Sau dacă tatăl tău îți va răspunde cu asprime?
Nígbà náà ni Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Ta ni yóò sọ fún mi tí baba rẹ̀ bá dá ọ lóhùn ní ohùn líle?”
11 Și Ionatan i-a spus lui David: Vino și să mergem în câmp. Și au ieșit amândoi în câmp.
Jonatani wí fún Dafidi pé, “Wá, jẹ́ kí a jáde lọ sórí pápá.” Nígbà náà wọ́n sì jáde lọ.
12 Și Ionatan i-a spus lui David: DOMNUL Dumnezeul lui Israel, când voi încerca pe tatăl meu mâine pe timpul acesta, sau poimâine, și, iată, dacă este bun față de David și nu voi trimite la tine și nu îți voi arăta,
Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Mo fi Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli búra pé, èmi yóò rí i dájú pé mo gbọ́ ti ẹnu baba mi ní ìwòyí ọ̀la tàbí ní ọ̀túnla! Bí ó bá sì ní inú dídùn sí ọ, èmi yóò ránṣẹ́ sí ọ, èmi yóò sì jẹ́ kí o mọ̀?
13 DOMNUL să facă astfel și mult mai mult lui Ionatan; dar dacă îi place tatălui meu să îți facă rău, îți voi arăta și te voi trimite, ca să mergi în pace; și DOMNUL fie cu tine, cum a fost cu tatăl meu.
Ṣùgbọ́n tí baba mi bá fẹ́ pa ọ́ lára, kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí Jonatani; tí èmi kò bá jẹ́ kí o mọ̀, kí n sì jẹ́ kí o lọ ní àlàáfíà. Kí Olúwa kí ó wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pẹ̀lú baba mi.
14 Și nu numai cât voi mai trăi să îmi arăți bunătatea DOMNULUI, ca să nu mor,
Ṣùgbọ́n fi àìkùnà inú rere hàn mí bí inú rere Olúwa, níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè kí wọ́n má ba à pa mí.
15 Ci de asemenea să nu stârpești niciodată bunătatea ta de la casa mea; nu, nici după ce DOMNUL va stârpi pe fiecare din dușmanii lui David, de pe fața pământului.
Má ṣe ké àánú rẹ kúrò lórí ìdílé mi títí láé. Bí Olúwa tilẹ̀ ké gbogbo ọ̀tá Dafidi kúrò lórí ilẹ̀.”
16 Astfel Ionatan a făcut un legământ cu casa lui David, spunând: Să ceară DOMNUL aceasta din mâna dușmanilor lui David.
Nígbà náà ni Jonatani bá ilé Dafidi dá májẹ̀mú wí pé, “Olúwa yóò pe àwọn àti Dafidi láti ṣírò.”
17 Și Ionatan l-a făcut pe David să jure din nou, deoarece îl iubea, pentru că îl iubea precum își iubea propriul suflet.
Jonatani mú kí Dafidi tún ìbúra ṣe nítorí ìfẹ́ tí ó ní sí i, nítorí tí ó fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti fẹ́ràn ara rẹ̀.
18 Atunci Ionatan i-a spus lui David: Mâine este lună nouă; și lipsa ta va fi observată, pentru că scaunul tău va fi gol.
Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Lọ́la ní ibi àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun, a yóò fẹ́ ọ kù, nítorí ààyè rẹ yóò ṣófo.
19 Și după ce vei sta trei zile, să cobori repede și să vii la locul unde te-ai ascuns când acel lucru s-a întâmplat, și să rămâi lângă piatra Ezel.
Ní ọ̀túnla lọ́wọ́ alẹ́ lọ sí ibi tí o sá pamọ́ sí nígbà tí ìṣòro yìí bẹ̀rẹ̀, kí o sì dúró níbi òkúta Eselu.
20 Și voi trage trei săgeți lângă aceasta, ca și când aș trage la țintă.
Èmi yóò ta ọfà mẹ́ta sí ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀, gẹ́gẹ́ bí i pé mo ta á sí àmì ibìkan.
21 Și, iată, voi trimite un băiat, spunând: Du-te, găsește săgețile. Dacă spun clar băiatului: Iată, săgețile sunt în această parte a ta, ia-le; atunci vino, pentru că este pace pentru tine și nicio vătămare, precum DOMNUL trăiește.
Èmi yóò rán ọmọdékùnrin kan èmi yóò wí fún un wí pé, ‘Lọ, kí o lọ wá ọfà náà.’ Tí mo bá sọ fún un wí pé, ‘Wò ó, ọfà wọ̀nyí wà ní ibi báyìí ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ rẹ; kó wọn wá síbí,’ kí o sì wá, nítorí pé, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wà ní ààyè, o wà ní àlàáfíà; kò sí ewu.
22 Dar, dacă spun astfel tânărului: Iată, săgețile sunt dincolo de tine; mergi pe calea ta, pentru că DOMNUL te-a trimis.
Ṣùgbọ́n tí mo bá sọ fún ọmọdékùnrin náà pé, ‘Wò ó, àwọn ọfà náà ń bẹ níwájú rẹ,’ ǹjẹ́ máa bá tìrẹ lọ, nítorí Olúwa ni ó rán ọ lọ.
23 Și referitor la acest lucru despre care am vorbit eu și cu tine, iată, DOMNUL este între tine și mine pentru totdeauna.
Nípa ọ̀rọ̀ tí èmi àti ìwọ jọ sọ, rántí Olúwa jẹ́ ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti èmi títí láéláé.”
24 Astfel David s-a ascuns în câmp; și luna nouă a venit, iar împăratul s-a așezat să mănânce mâncare.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sá pamọ́ sínú pápá. Nígbà tí àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun sì dé, ọba sì jókòó láti jẹun.
25 Și împăratul a șezut pe scaunul său, ca în alte dăți, pe un scaun de lângă perete; și Ionatan s-a ridicat și Abner a șezut lângă Saul și locul lui David era gol.
Ọba sì jókòó gẹ́gẹ́ bí ipò o rẹ̀ ní ibi tí ó máa ń jókòó lórí ìjókòó tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri, ní òdìkejì Jonatani, Abneri sì jókòó ti Saulu, ṣùgbọ́n ààyè Dafidi sì ṣófo.
26 Totuși Saul nu a vorbit nimic în acea zi, pentru că se gândea: I s-a întâmplat ceva, el nu este curat; cu siguranță nu este curat.
Saulu kò sọ nǹkan kan ní ọjọ́ náà, nítorí ó rò pé, “Nǹkan kan ti ṣẹlẹ̀ sí Dafidi láti jẹ́ kí ó di aláìmọ́ lóòtítọ́ ó jẹ́ aláìmọ́.”
27 Și s-a întâmplat a doua zi, a doua zi a lunii, că locul lui David era gol; și Saul a spus fiului său, Ionatan: De ce nu a venit fiul lui Isai să mănânce, nici ieri, nici astăzi?
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì, ní ọjọ́ kejì oṣù, ààyè Dafidi sì tún ṣófo. Nígbà náà ni Saulu wí fún ọmọ rẹ̀ Jonatani pé, “Kí ni ó dé tí ọmọ Jese kò fi wá sí ibi oúnjẹ, lánàá àti lónìí?”
28 Și Ionatan a răspuns lui Saul: David mi-a cerut insistent să meargă la Betleem;
Jonatani sì dáhùn pé, “Dafidi bẹ̀ mí tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ fún ààyè láti lọ sí Bẹtilẹhẹmu.
29 Și a spus: Lasă-mă să merg, te rog, pentru că avem un sacrificiu al familiei în cetate; și fratele meu, el mi-a poruncit să fiu acolo; și acum, dacă am găsit favoare în ochii tăi, lasă-mă să plec, te rog, și să văd pe frații mei. De aceea nu vine la masa împăratului.
Ó wí pé, ‘Jẹ́ kí n lọ, nítorí pé ìdílé wa ń ṣe ìrúbọ ní ìlú, àwọn ẹ̀gbọ́n ọ̀n mi sì ti pàṣẹ fún mi láti wà níbẹ̀; tí èmi bá rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí n lọ láti lọ rí àwọn ẹ̀gbọ́n mi.’ Ìdí nìyìí tí kò fi wá sí orí tábìlì oúnjẹ ọba.”
30 Atunci mânia lui Saul s-a aprins împotriva lui Ionatan și i-a spus: Tu, fiu de femeie perversă și răzvrătită, nu știu eu că ți-ai ales pe fiul lui Isai spre rușinea ta și spre rușinea goliciunii mamei tale?
Ìbínú Saulu sì ru sí Jonatani ó sì wí fún un pé, “Ìwọ ọmọ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀ búburú yìí, ṣé èmi kò ti mọ̀ pé, ìwọ ti yan ọmọ Jese fún ìtìjú ti ara rẹ àti fún ìtìjú màmá rẹ tí ó bí ọ?
31 Fiindcă atât cât fiul lui Isai trăiește pe pământ, tu nu vei fi întemeiat, nici tu, nici împărăția ta. De aceea acum, trimite și adu-l la mine, pentru că negreșit va muri.
Níwọ́n ìgbà tí ọmọ Jese bá wà láààyè lórí ilẹ̀ ayé, a kì yóò fi ẹsẹ̀ ìwọ tàbí ti ìjọba rẹ múlẹ̀. Nísinsin yìí ránṣẹ́ kí o sì lọ mú un wá fún mi, nítorí ó gbọdọ̀ kú!”
32 Și Ionatan i-a răspuns tatălui său Saul și i-a zis: Pentru ce să fie ucis? Ce a făcut?
Jonatani béèrè lọ́wọ́ baba rẹ̀ pé, “Èéṣe tí àwa yóò fi pa á? Kí ni ó ṣe?”
33 Și Saul a aruncat o suliță spre el ca să îl lovească; prin aceasta Ionatan a cunoscut că este hotărât de tatăl său să ucidă pe David.
Ṣùgbọ́n Saulu ju ọ̀kọ̀ rẹ̀ sí Jonatani láti gún un pa. Nígbà náà ni Jonatani mọ̀ pé baba rẹ̀ mọ̀ ọ́n mọ̀ fẹ́ pa Dafidi ni.
34 Astfel Ionatan s-a ridicat de la masă în mânie înverșunată și nu a mâncat pâine în a doua zi a lunii, pentru că era mâhnit pentru David, deoarece tatăl său îi făcuse rușine.
Bẹ́ẹ̀ ni Jonatani sì fi ìbínú dìde kúrò ni ibi oúnjẹ, kò sì jẹun ni ọjọ́ kejì oṣù náà, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ gidigidi fún Dafidi, nítorí pé baba rẹ̀ dójútì í.
35 Și s-a întâmplat dimineața, că Ionatan a ieșit la câmp la timpul rânduit cu David și un băiețel a ieșit cu el.
Ó sì ṣe, ní òwúrọ̀ ni Jonatani jáde lọ sí oko ní àkókò tí òun àti Dafidi ti fi àdéhùn sí, ọmọdékùnrin kan sì wá pẹ̀lú rẹ̀.
36 Și a spus băiatului său: Aleargă, găsește acum săgețile pe care le trag. Și pe când a alergat băiatul, el a tras o săgeată dincolo de el.
Ó si wí fún ọmọdékùnrin rẹ̀ pé, “Sáré, kí o si wá àwọn ọfà tí èmi ó ta.” Bí ọmọdé náà sì ti ń sáré, òun sì tafà rékọjá rẹ̀.
37 Și când băiatul a ajuns la locul săgeții pe care o trăsese Ionatan, Ionatan a strigat după băiat și a spus: Nu este săgeata dincolo de tine?
Nígbà tí ọmọdékùnrin náà sì dé ibi ọfà tí Jonatani ta, Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà ó sì wí pé, “Ọfà náà kò ha wà níwájú rẹ bi?”
38 Și Ionatan a strigat după băiat: Iute, grăbește, nu sta. Și băiatul lui Ionatan a adunat săgețile și a venit la stăpânul său.
Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà pé, “Sáré! Yára! Má ṣe dúró!” Ọmọdékùnrin Jonatani sì ṣa àwọn ọfà náà, ó sì tọ olúwa rẹ̀ wá.
39 Dar băiatul nu știa nimic; numai Ionatan și David cunoșteau lucrul acesta.
(Ọmọdékùnrin náà kò sì mọ̀ nǹkan; ṣùgbọ́n Jonatani àti Dafidi ni ó mọ ọ̀ràn náà.)
40 Și Ionatan a dat armele sale băiatului său și i-a spus: Du-te, du-le în cetate.
Jonatani sì fi apó àti ọrun rẹ̀ fún ọmọdékùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Lọ, kí o sì mú wọn lọ sí ìlú.”
41 Și imediat ce băiatul a plecat, David s-a ridicat dintr-un loc dinspre sud și a căzut cu fața la pământ și s-a plecat de trei ori; și s-au sărutat unul pe altul și au plâns unul cu altul, până când David l-a întrecut.
Bí ọmọdékùnrin náà ti lọ tán, Dafidi sì dìde láti ibi ìhà gúúsù òkúta náà, ó sì wólẹ̀, ó sì tẹríba ní ìdojúbolẹ̀ lẹ́ẹ̀mẹ́ta fún Jonatani, wọ́n sì fi ẹnu ko ara wọn lẹ́nu, wọ́n sì jùmọ̀ sọkún, èkínní pẹ̀lú èkejì rẹ̀, ṣùgbọ́n Dafidi sọkún púpọ̀ jù.
42 Și Ionatan i-a spus lui David: Du-te în pace, pentru că am jurat amândoi în numele DOMNULUI, spunând: DOMNUL să fie între mine și tine și între sămânța mea și sămânța ta pentru totdeauna. Și s-a ridicat și a plecat; și Ionatan a mers în cetate.
Jonatani sì wí fún Dafidi pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, bí o ti jẹ́ pé àwa méjèèjì tí jùmọ̀ búra ni orúkọ Olúwa pé, ‘Ki Olúwa ó wà láàrín èmi àti ìwọ, láàrín irú-ọmọ mi àti láàrín irú-ọmọ rẹ̀ láéláé.’” Òun sì dìde, ó sì lọ kúrò: Jonatani sì lọ sí ìlú.

< 1 Samuel 20 >