< 1 Samuel 16 >
1 Și DOMNUL i-a spus lui Samuel: Cât timp vei jeli pentru Saul, văzând că l-am lepădat de la a domni peste Israel? Umple-ți cornul cu untdelemn și mergi, te voi trimite la Isai betleemitul, pentru că mi-am pregătit un împărat dintre fiii săi.
Olúwa sọ fún Samuẹli pé, “Yóò ha ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa dárò Saulu, nígbà tí ó jẹ́ pé mo ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli? Rọ òróró kún inú ìwo rẹ, kí o sì mú ọ̀nà rẹ pọ̀n, Èmi rán ọ sí Jese ará Bẹtilẹhẹmu. Èmi ti yan ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ ọba.”
2 Și Samuel a spus: Cum să mă duc? Dacă Saul aude aceasta, mă va ucide. Și DOMNUL a spus: Ia o vițea cu tine și spune: Am venit să sacrific DOMNULUI.
Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Báwo ni èmi yóò ṣe lọ? Bí Saulu bá gbọ́ nípa rẹ̀, yóò pa mi.” Olúwa wí pé, “Mú abo ẹgbọrọ màlúù kan pẹ̀lú rẹ, kí o sì wí pé, ‘Èmi wá láti wá rú ẹbọ sí Olúwa.’
3 Și cheamă pe Isai la sacrificiu; și eu îți voi arăta ce să faci; și să îmi ungi pe acela pe care ți-l voi numi.
Pe Jese wá sí ibi ìrúbọ náà, Èmi yóò sì fi ohun tí ìwọ yóò ṣe hàn ọ́. Ìwọ yóò fi òróró yàn fún mi, ẹni tí èmi bá fihàn ọ́.”
4 Și Samuel a făcut ceea ce DOMNUL a spus și a venit la Betleem. Și bătrânii orașului au tremurat la venirea lui și au spus: Vii cu pace?
Samuẹli ṣe ohun tí Olúwa sọ. Nígbà tí ó dé Bẹtilẹhẹmu, àyà gbogbo àgbàgbà ìlú já, nígbà tí wọ́n pàdé rẹ̀. Wọ́n béèrè pé, “Ṣé àlàáfíà ní ìwọ bá wá?”
5 Și el a spus: Cu pace; Am venit să sacrific DOMNULUI; sfințiți-vă și veniți cu mine la sacrificiu. Și a sfințit pe Isai și pe fiii săi și i-a chemat la sacrificiu.
Samuẹli sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni àlàáfíà ni; mo wá láti wá rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ ya ara yín sí mímọ́, kí ẹ sì wá rú ẹbọ pẹ̀lú mi.” Nígbà náà ni ó sì ya Jese sí mímọ́ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì pè wọ́n wá sí ibi ìrúbọ náà.
6 Și s-a întâmplat, după ce ei au venit, că s-a uitat la Eliab și a spus: Cu siguranță unsul DOMNULUI este înaintea DOMNULUI.
Nígbà tí wọ́n dé, Samuẹli rí Eliabu, ó rò nínú ara rẹ̀ pé lóòótọ́ ẹni òróró Olúwa dúró níbí níwájú Olúwa.
7 Dar DOMNUL i-a spus lui Samuel: Nu privi la înfățișarea lui, sau la înălțimea staturii lui, pentru că l-am lepădat; fiindcă DOMNUL nu se uită cum se uită omul, pentru că omul se uită la înfățișare, dar DOMNUL se uită la inimă.
Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Samuẹli pé, “Má ṣe wo ti ìrísí rẹ̀ tàbí ti gíga rẹ̀, nítorí èmi ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Olúwa kì í wo ohun tí ènìyàn máa ń wò. Ènìyàn máa ń wo òde ara ṣùgbọ́n Olúwa máa ń wo ọkàn.”
8 Atunci Isai a chemat pe Abinadab și l-a trecut înaintea lui Samuel. Și el a spus: Nici pe acesta nu l-a ales DOMNUL.
Nígbà náà ni Jese pe Abinadabu, ó sì jẹ́ kí ó rìn kọjá ní iwájú Samuẹli. Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Olúwa kò yan ẹni yìí.”
9 Atunci Isai l-a trecut pe Șama. Și el a spus: Nici pe acesta nu l-a ales DOMNUL.
Jese sì jẹ́ kí Ṣamma rìn kọjá ní iwájú Samuẹli, ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Olúwa kò yan ẹni yìí náà.”
10 Din nou, Isai i-a trecut pe șapte dintre fiii săi pe dinaintea lui Samuel. Și Samuel i-a spus lui Isai: DOMNUL nu i-a ales pe aceștia.
Jese jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ méje rìn kọjá ní iwájú Samuẹli ṣùgbọ́n Samuẹli sọ fún un pé, “Olúwa kò yan àwọn wọ̀nyí.”
11 Și Samuel i-a spus lui Isai: Sunt aici toți copiii tăi? Iar el a spus: A mai rămas cel mai tânăr și, iată, el păzește oile. Și Samuel i-a spus lui Isai: Trimite și adu-l, pentru că nu vom ședea până nu va veni el aici.
Nígbà náà ni ó béèrè lọ́wọ́ Jese pé, “Ṣé èyí ni gbogbo àwọn ọmọ rẹ?” Jese dáhùn pé, “Ó ku àbíkẹ́yìn wọn, ó ń tọ́jú agbo àgùntàn.” Samuẹli sì wí pé, “Rán ìránṣẹ́ lọ pè é wá; àwa kò ní jókòó títí òun yóò fi dé.”
12 Și a trimis și a fost adus. Și el era rumen și cu o înfățișare de asemenea minunată și frumos la privit. Și DOMNUL a spus: Ridică-te, unge-l, pentru că acesta este.
Ó sì ránṣẹ́ sí i, wọ́n sì mú un wọlé wá, ó jẹ́ ẹni tó mọ́ra, àwọ̀ ara rẹ̀ dùn ún wò, ó jẹ́ arẹwà gidigidi. Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Dìde kí o sì fi òróró yàn án, òun ni ẹni náà.”
13 Atunci Samuel a luat cornul cu untdelemn și l-a uns în mijlocul fraților săi; și Duhul DOMNULUI a venit peste David începând din acea zi. Astfel Samuel s-a ridicat și a mers la Rama.
Nígbà náà ni Samuẹli mú ìwo òróró, ó sì ta á sí i ní orí ní iwájú àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀, láti ọjọ́ náà lọ, Ẹ̀mí Mímọ́ Olúwa wá sí orí Dafidi nínú agbára. Samuẹli sì lọ sí Rama.
14 Dar Duhul DOMNULUI s-a depărtat de la Saul și un duh rău de la DOMNUL îl tulbura.
Nísinsin yìí, ẹ̀mí Olúwa ti kúrò lára Saulu, ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Olúwa sì ń yọ ọ́ lẹ́nu.
15 Și servitorii lui Saul i-au spus: Iată acum, un duh rău de la Dumnezeu te tulbură.
Àwọn ìránṣẹ́ Saulu sì wí fún un pé, “Wò ó, ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ń yọ ọ́ lẹ́nu.
16 Să poruncească acum domnul nostru servitorilor tăi, care sunt înaintea ta, să caute un bărbat, care este un iscusit cântăreț la harpă; și se va întâmpla, când duhul cel rău de la Dumnezeu este asupra ta, că el va cânta cu mâna sa și tu vei fi bine.
Jẹ́ kí olúwa wa pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó wà níhìn-ín láti wa ẹnìkan tí ó lè fi dùùrù kọrin. Yóò sì ṣe é nígbà tí ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run bá bà lé ọ, ìwọ yóò sì sàn.”
17 Și Saul a spus servitorilor săi: Aduceți-mi acum un bărbat care poate cânta bine și aduceți-l la mine.
Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ wá ẹnìkan tí ó lè kọrin dáradára kí ẹ sì mú u wá fún mi.”
18 Atunci a răspuns unul dintre servitori și a spus: Iată, am văzut pe un fiu al lui Isai betleemitul, care este iscusit în cântare și un bărbat puternic și viteaz și un bărbat de război și chibzuit în toate lucrurile și o persoană frumoasă la vedere și DOMNUL este cu el.
Ọ̀kan nínú ìránṣẹ́ náà dáhùn pé, “Èmi ti ri ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Jese ti Bẹtilẹhẹmu tí ó mọ orin kọ, ó jẹ́ alágbára àti ológun. Ó ní ọgbọ́n ọ̀rọ̀ òun sì dára ní wíwò. Olúwa sì wà pẹ̀lú u rẹ̀.”
19 De aceea Saul a trimis mesageri la Isai și a spus: Trimite-mi pe David, fiul tău, care este cu oile.
Saulu sì rán oníṣẹ́ sí Jese wí pé, “Rán Dafidi ọmọ rẹ sí mi, ẹni tí ó ń ṣọ́ àgùntàn.”
20 Și Isai a luat un măgar încărcat cu pâine și un burduf cu vin și un ied și le-a trimis prin David, fiul său, lui Saul.
Jese sì mú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti a di ẹrù lé àti ìgò ọtí wáìnì àti ọmọ ewúrẹ́; ó sì rán wọn nípa ọwọ́ Dafidi ọmọ rẹ̀ sí Saulu.
21 Și David a venit la Saul și a stat în picioare înaintea lui; și Saul l-a iubit mult; și el a devenit purtătorul său de arme.
Dafidi sì tọ Saulu lọ, ó sì dúró níwájú rẹ̀, òun sì fẹ́ ẹ gidigidi, Dafidi sì wá di ọ̀kan nínú àwọn tí ń ru ìhámọ́ra rẹ̀.
22 Și Saul a trimis la Isai, spunând: Să rămână David, te rog, înaintea mea, pentru că a găsit favoare înaintea ochilor mei.
Nígbà náà ni Saulu ránṣẹ́ sí Jese pé, “Jẹ́ kí Dafidi dúró níwájú mi, nítorí tí ó wù mí.”
23 Și s-a întâmplat, când duhul rău de la Dumnezeu era peste Saul, că David lua harpa și cânta cu mâna sa; astfel Saul era înviorat și era bine și duhul rău se depărta de la el.
Ó sì ṣe, nígbà tí ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá bá dé sí Saulu, Dafidi a sì fi ọwọ́ rẹ̀ kọrin lára dùùrù: a sì san fún Saulu, ara rẹ̀ a sì dá; ẹ̀mí búburú náà a sì fi sílẹ̀.