< 1 Petru 2 >
1 De aceea, lăsând deoparte toată răutatea și toată viclenia și fățărniciile și invidiile și toate vorbirile rele,
Nítorí náà, ẹ fi àrankàn gbogbo sílẹ̀ ni apá kan, àti ẹ̀tàn gbogbo, àti àgàbàgebè, àti ìlara, àti sísọ ọ̀rọ̀ búburú gbogbo.
2 Ca prunci nou născuți, doriți laptele neprefăcut al cuvântului, ca să creșteți prin el,
Bí ọmọ ọwọ́ tuntun, kí ẹ máa fẹ́ wàrà ti Ẹ̀mí, èyí tí kò lẹ́tàn, kí ẹ̀yin lè máa tipasẹ̀ rẹ̀ dàgbà sí ìgbàlà,
3 Dacă într-adevăr ați gustat că Domnul este cu har.
nísinsin yìí tí ẹ̀yin ti tọ́ ọ wò pé rere ni Olúwa.
4 La care veniți, ca la o piatră vie, respinsă într-adevăr de oameni, dar aleasă de Dumnezeu și prețioasă;
Ẹni tí ẹ̀yin ń tọ̀ bọ̀, sí bi òkúta ààyè náà, èyí ti a ti ọwọ́ ènìyàn kọ̀ sílẹ̀ nítòótọ́, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ Ọlọ́run, àṣàyàn òkúta iyebíye.
5 Și voi, ca pietre vii, sunteți zidiți o casă spirituală, o preoție sfântă pentru a oferi sacrificii spirituale, acceptabile lui Dumnezeu, prin Isus Cristos.
Ẹ̀yin pẹ̀lú, bí òkúta ààyè, ni a kọ́ ní ilé ẹ̀mí, àlùfáà mímọ́, láti máa rú ẹbọ ẹ̀mí, tí i ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ Ọlọ́run nípa Jesu Kristi.
6 De aceea și este cuprins în scriptură: Iată, pun în Sion o piatră unghiulară a temeliei, aleasă, prețioasă, și cel ce crede în el nu va fi încurcat.
Nítorí nínú Ìwé Mímọ́, ó wí pe: “Kíyèsi i, mo fi pàtàkì òkúta igun ilé àṣàyàn, iyebíye, lélẹ̀ ni Sioni: ẹni tí ó bá sì gbà á gbọ́ ojú kì yóò tì í.”
7 De aceea vouă, care credeți, el vă este prețios; dar celor neascultători, piatra pe care constructorii au respins-o, aceasta a fost făcută capul colțului temeliei,
Báyìí fún ẹ̀yin ti ẹ gbà á gbọ́, ó ṣe iyebíye; ṣùgbọ́n fún àwọn tí kò gbà á gbọ́, “Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, òun ni ó di pàtàkì igun ilé,”
8 Și o piatră de cădere și o stâncă de poticnire, celor care se împiedică de cuvânt, fiind neascultători: la aceasta au și fost rânduiți.
àti pẹ̀lú, “Òkúta ìdìgbòlù, àti àpáta ìkọ̀sẹ̀.” Nítorí wọ́n kọsẹ̀ nípa ṣíṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ náà, sínú èyí tí a gbé yàn wọ́n sí pẹ̀lú.
9 Dar voi sunteți generație aleasă, preoție împărătească, națiune sfântă, popor deosebit, ca să arătați laudele celui ce v-a chemat din întuneric în lumina lui minunată;
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni ìran tí a yàn olú àlùfáà, Orílẹ̀-èdè mímọ́, ènìyàn ọ̀tọ̀ ki ẹ̀yin lè fi ọláńlá ẹni tí ó pè yín jáde kúrò nínú òkùnkùn sínú ìmọ́lẹ̀ ìyanu rẹ̀ hàn.
10 Voi, care odinioară nu erați popor, dar sunteți acum poporul lui Dumnezeu, care nu ați obținut milă, dar acum ați obținut milă.
Ẹ̀yin tí kì í ṣe ènìyàn nígbà kan rí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin ti di ènìyàn Ọlọ́run, ẹ̀yin tí kò rí àánú gbà rí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ ti rí àánú gbà.
11 Preaiubiților, vă implor, ca străini și locuitori temporari în țară străină, abțineți-vă de la poftele carnale care se războiesc împotriva sufletului,
Olùfẹ́ ọ̀wọ́n, mo bẹ̀ yín, bí àjèjì àti àtìpó, láti fàsẹ́yìn kúrò nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara, tí ń ba ọkàn jagun.
12 Având comportarea voastră bună printre neamuri, pentru ca în ceea ce vorbesc de rău împotriva voastră ca [de niște] făcători de rele, prin faptele voastre bune pe care le vor vedea să glorifice pe Dumnezeu în ziua cercetării.
Kí ìwà yín láàrín àwọn aláìkọlà dára; pé, bí wọ́n ti ń sọ̀rọ̀ yín bí olùṣe búburú, nípa iṣẹ́ rere yín tí wọn ó máa kíyèsi, kí wọ́n lè máa yin Ọlọ́run lógo lọ́jọ́ ti òun ba bẹ̀ wá wò.
13 Supuneți-vă fiecărei rânduieli omenești pentru Domnul, fie împăratului ca [autoritate] supremă,
Ẹ máa tẹríba fún gbogbo ìlànà ènìyàn nítorí ti Olúwa, ìbá à ṣe fún ọba tàbí fún olórí.
14 Sau guvernatorilor, ca celor trimiși de el pentru pedepsirea făcătorilor de rele și pentru lauda celor ce fac bine.
Tàbí fún àwọn baálẹ̀, fún àwọn tí a rán láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti gbẹ̀san lára àwọn tí ń ṣe búburú, àti fún ìyìn àwọn tí ń ṣe rere.
15 Pentru că astfel este voia lui Dumnezeu, ca făcând bine să amuțiți ignoranța oamenilor fără minte;
Ìfẹ́ Ọlọ́run sá ni èyí pé, ní rere í ṣe, kí ẹ lè dẹ́kun ọ̀rọ̀ àìmọ̀kan òmùgọ̀ ènìyàn.
16 Ca oameni liberi, dar nu folosind libertatea voastră ca pe o manta a răutății, ci ca servitori ai lui Dumnezeu.
Ẹ máa gbé gẹ́gẹ́ bí ẹni òmìnira, ṣùgbọ́n ẹ ma ṣe lo òmìnira yín láti bo ibi mọ́lẹ̀; ṣùgbọ́n kí ẹ gbé gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ Ọlọ́run.
17 Onorați pe toți. Iubiți pe frați. Temeți-vă de Dumnezeu. Onorați pe împărat.
Ẹ bọ̀wọ̀ fún gbogbo ènìyàn, ẹ fẹ́ àwọn ará, ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run, ẹ bọ̀wọ̀ fún ọba.
18 Servitorilor, fiți supuși stăpânilor voștri cu toată teama, nu numai celor buni și blânzi, dar și celor perverși.
Ẹ̀yin ọmọ ọ̀dọ̀, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọ̀gá yín pẹ̀lú ìbẹ̀rù gbogbo, kì í ṣe fún àwọn ẹni rere àti oníwà tútù nìkan, ṣùgbọ́n fún àwọn òǹrorò pẹ̀lú.
19 Fiindcă acest [lucru] este demn de mulțumire, dacă cineva, datorită conștiinței către Dumnezeu, îndură întristare, suferind pe nedrept.
Nítorí pé èyí ní ìgbóríyìn fún, bí ènìyàn bá fi ara da ìrora, ìjìyà lọ́nà àìtọ́, nítorí ọkàn rere sí Ọlọ́run.
20 Fiindcă ce glorie este, dacă veți îndura când sunteți loviți cu pumnul pentru păcatele voastre? Dar dacă faceți bine și suferiți și îndurați, acest [lucru] este plăcut lui Dumnezeu.
Ṣùgbọ́n ògo kín ni ó jẹ́, nígbà tí ẹ ba ṣẹ̀ tí a sì lù yín, bí ẹ bá fi sùúrù gbà á? Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá ń ṣe rere tí ẹ sì ń jìyà, bí ẹ bá fi sùúrù gbà á, ẹ̀yín ní ọpẹ́ lọ́dọ̀ Ọlọ́run.
21 Fiindcă la aceasta ați fost chemați, pentru că și Cristos a suferit pentru noi, lăsându-ne un exemplu, ca să urmați pașii lui.
Sí èyí ni a pè yín: nítorí Kristi pẹ̀lú jìyà fún un yin, ó fi àpẹẹrẹ sílẹ̀ fún un yín, kí ẹ̀yin lè máa tọ ipasẹ̀ rẹ̀:
22 El, care nu a făcut păcat, nici nu a fost găsită viclenie în gura lui,
“Òun kò dẹ́ṣẹ̀ kankan, bẹ́ẹ̀ sì ni, a kò rí ẹ̀tàn kan lẹ́nu rẹ̀.”
23 Care, fiind ocărât, nu a ocărât; când a suferit, nu a amenințat, ci s-a încredințat aceluia ce judecă cu dreptate.
Ẹni, nígbà tí a kẹ́gàn rẹ̀, tí kò sì padà kẹ́gàn; nígbà tí ó jìyà tí kò sì halẹ̀; ṣùgbọ́n ó fi ọ̀ràn rẹ̀ lé ẹni ti ń ṣe ìdájọ́ òdodo lọ́wọ́.
24 El însuși care a purtat păcatele noastre în trupul său pe lemn, ca noi, fiind morți față de păcate, să trăim pentru dreptate; prin ale cărui lovituri ați fost vindecați.
Ẹni tí òun tìkára rẹ̀ fi ara rẹ̀ ru ẹ̀ṣẹ̀ wa lórí igi àgbélébùú, pé kí àwa lè di òkú sí ẹ̀ṣẹ̀, ki a sì di ààyè sí òdodo, nípa ìjìyà ẹni tí ó mú yín láradá.
25 Fiindcă erați ca oi care rătăceau, dar acum v-ați întors la Păstorul și Episcopul sufletelor voastre.
Nítorí tí ẹ̀yin ń ṣáko lọ bí àgùntàn, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ẹ̀yin ti padà sí ọ̀dọ̀ olùṣọ́-àgùntàn àti bíṣọ́ọ̀bù ọkàn yín.