< 1 Regii 20 >

1 Şi Ben-Hadad, împăratul Siriei, şi-a adunat toată oştirea lui; şi erau treizeci şi doi de împăraţi cu el, şi cai şi care; şi s-a urcat şi a asediat Samaria şi s-a războit împotriva ei.
Beni-Hadadi ọba Aramu sì gbá gbogbo ogun rẹ̀ jọ. Ọba méjìlélọ́gbọ̀n sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ àti ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó sì gòkè lọ, ó sì dó ti Samaria, ó sì kọlù ú.
2 Şi a trimis mesageri la Ahab, împăratul lui Israel, în cetate, şi i-a spus: Astfel spune Ben-Hadad:
Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí ìlú sí Ahabu ọba Israẹli wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi wí,
3 Argintul tău şi aurul tău sunt ale mele; soţiile tale de asemenea şi copiii tăi cei mai plăcuţi sunt ai mei.
‘Fàdákà àti wúrà rẹ tèmi ni, àti àwọn tí ó dára jùlọ nínú àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ tèmi ni wọ́n.’”
4 Şi împăratul lui Israel a răspuns şi a zis: Domnul meu, împărate, conform spusei tale, eu, şi tot ceea ce am, sunt al tău.
Ọba Israẹli sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìwọ ṣe wí olúwa mi ọba, èmi àti ohun gbogbo tí mo ní tìrẹ ni.”
5 Şi mesagerii s-au întors şi au zis: Astfel vorbeşte Ben-Hadad, spunând: Deşi am trimis la tine, spunând: Să îmi dai argintul tău şi aurul tău şi soţiile tale şi copiii tăi;
Àwọn oníṣẹ́ náà sì tún padà wá, wọ́n sì wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi sọ wí pé, ‘Mo ránṣẹ́ láti béèrè fún fàdákà rẹ àti wúrà rẹ, àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ.
6 Totuşi voi trimite pe servitorii mei la tine mâine, cam în acest timp, şi ei vor cerceta casa ta şi casele servitorilor tăi; şi va fi astfel: că orice este plăcut în ochii tăi, ei vor pune în mâna lor şi vor lua.
Ṣùgbọ́n ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò rán àwọn ìránṣẹ́ mi sí ọ láti wá ilé rẹ wò àti ilé àwọn ìránṣẹ́ rẹ. Wọn yóò gba gbogbo ohun tí ó bá dára lójú rẹ, wọn yóò sì kó o lọ.’”
7 Atunci împăratul lui Israel a chemat pe toţi bătrânii ţării şi a spus: Cunoaşteţi, vă rog, şi vedeţi cum acest om caută ticăloşie, pentru că a trimis la mine după soţiile mele şi după copiii mei şi după argintul meu şi după aurul meu şi nu l-am refuzat.
Nígbà náà ni ọba Israẹli pe gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wo bí ọkùnrin yìí ti ń fẹ́ ìyọnu! Nígbà tí ó ránṣẹ́ fún àwọn aya mi, àti fún àwọn ọmọ mi, àti fún fàdákà mi, àti fún wúrà mi, èmi kò sì fi dù ú.”
8 Şi toţi bătrânii şi tot poporul i-au zis: Să nu îi dai ascultare, nici să nu consimţi.
Àwọn àgbàgbà àti gbogbo ènìyàn dá a lóhùn pé, “Má ṣe fi etí sí tirẹ̀ tàbí kí ó gbà fún un.”
9 De aceea el a spus mesagerilor lui Ben-Hadad: Spuneţi domnului meu, împăratul: Pentru tot ce ai trimis la servitorul tău la început voi face; dar acest lucru nu pot să îl fac. Şi mesagerii au plecat şi i-au adus din nou cuvânt.
Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn oníṣẹ́ Beni-Hadadi pé, “Sọ fún olúwa mi ọba pé, ‘Ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe ohun gbogbo tí ó ránṣẹ́ fún látètèkọ́ṣe, ṣùgbọ́n nǹkan yìí ni èmi kò le ṣe.’” Wọ́n padà lọ, wọ́n sì mú èsì padà wá fún Beni-Hadadi.
10 Şi Ben-Hadad a trimis la el şi a spus: Astfel să îmi facă dumnezeii şi încă mai mult, dacă ţărâna Samariei va fi suficientă să umple mâna întregului popor care mă urmează.
Beni-Hadadi sì tún rán oníṣẹ́ mìíràn sí Ahabu wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú bí eruku Samaria yóò tó fún ìkúnwọ́ fún gbogbo ènìyàn tí ń tẹ̀lé mi.”
11 Şi împăratul lui Israel a răspuns şi a zis: Spuneţi-i: Să nu se fălească cel care îşi încinge armura ca cel care şi-o dă jos.
Ọba Israẹli sì dáhùn wí pé, “Sọ fún un pé, ‘Má jẹ́ kí ẹni tí ń hámọ́ra halẹ̀ bí ẹni tí ń bọ́ ọ sílẹ̀.’”
12 Şi s-a întâmplat, când Ben-Hadad a auzit acest mesaj, pe când el bea, el şi împăraţii lui în corturi, că a spus servitorilor săi: Desfăşuraţi-vă de bătălie. Şi ei s-au desfăşurat de bătălie împotriva cetăţii.
Beni-Hadadi sì gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí nígbà tí òun àti àwọn ọba ń mu ọtí nínú àgọ́ wọn, ó sì pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Ẹ ṣígun sí ìlú náà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe tan láti kọlu ìlú náà.
13 Şi, iată, a venit un profet la Ahab, împăratul lui Israel, spunând: Astfel spune DOMNUL: Ai văzut tu toată această mare mulţime? Iată, o voi da în mâna ta în această zi; şi tu vei cunoaşte că eu sunt DOMNUL.
Sì kíyèsi i, wòlíì kan tọ Ahabu ọba Israẹli wá, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ rí gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun yìí? Èmi yóò fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ lónìí, nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’”
14 Şi Ahab a spus: Prin cine? Iar el a spus: Astfel spune DOMNUL: Prin tinerii prinţilor provinciilor. Apoi el a spus: Cine va începe bătălia? Iar el a răspuns: Tu.
Ahabu sì béèrè pé, “Ṣùgbọ́n ta ni yóò ṣe èyí?” Wòlíì náà sì dáhùn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Nípa ìpẹ́ẹ̀rẹ̀ àwọn ìjòyè ìgbèríko.’” Nígbà náà ni ó wí pé. “Ta ni yóò bẹ̀rẹ̀ ogun náà?” Wòlíì sì dalóhùn pé, “Ìwọ ni yóò ṣe é.”
15 Atunci el a numărat pe tinerii prinţilor provinciilor, şi ei au fost două sute treizeci şi doi; şi, după ei a numărat tot poporul, pe toţi copiii lui Israel, şapte mii.
Nígbà náà ni Ahabu ka àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko, wọ́n sì jẹ́ igba ó lé méjìlélọ́gbọ̀n. Nígbà náà ni ó sì kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tókù jọ, gbogbo wọn sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin.
16 Şi au ieşit la amiază. Dar Ben-Hadad bea şi se îmbăta în corturi, el şi împăraţii, cei treizeci şi doi de împăraţi, care îl ajutau.
Wọ́n sì jáde lọ ní ọ̀sán gangan, nígbà tí Beni-Hadadi àti àwọn ọba méjìlélọ́gbọ̀n tí ń ràn án lọ́wọ́ ń mu àmupara nínú àgọ́.
17 Şi tinerii prinţilor provinciilor au ieşit cei dintâi; şi Ben-Hadad a trimis şi i-au spus, zicând: Au ieşit nişte bărbaţi din Samaria.
Àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko tètè kọ́ jáde lọ. Beni-Hadadi sì ránṣẹ́ jáde, wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Àwọn ọkùnrin ń ti Samaria jáde wá.”
18 Şi el a spus: Dacă au ieşit pentru pace, prindeţi-i vii; şi dacă au ieşit pentru război, prindeţi-i vii.
Ó sì wí pé, “Bí wọ́n bá bá ti àlàáfíà jáde wá, ẹ mú wọn láààyè; bí ti ogun ni wọ́n bá bá jáde, ẹ mú wọn láààyè.”
19 Astfel, aceşti tineri ai prinţilor provinciilor au ieşit din cetate, ei şi armata care îi urma.
Àwọn ìjòyè kéékèèké wọ̀nyí ti àwọn ìjòyè ìgbèríko jáde ti ìlú wá, àti ogun tí ó tẹ̀lé wọn.
20 Şi au ucis, fiecare pe omul lui; şi sirienii au fugit; şi Israel i-a urmărit; şi Ben-Hadad, împăratul Siriei, a scăpat pe un cal cu călăreţii.
Olúkúlùkù sì pa ọkùnrin kọ̀ọ̀kan. Àwọn ará Aramu sì sá, Israẹli sì lépa wọn. Ṣùgbọ́n Beni-Hadadi ọba Aramu sì sálà lórí ẹṣin pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin.
21 Şi împăratul lui Israel a ieşit şi a lovit caii şi carele şi a ucis pe sirieni cu un mare măcel.
Ọba Israẹli sì jáde lọ, ó sì kọlu àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó pa àwọn ará Aramu ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
22 Şi profetul a venit la împăratul lui Israel şi i-a spus: Du-te, întăreşte-te şi însemnează şi vezi ce faci, pentru că la întoarcerea anului împăratul Siriei se va urca împotriva ta.
Lẹ́yìn náà, wòlíì náà sì wá sọ́dọ̀ ọba Israẹli, ó sì wí pé, “Lọ, mú ara rẹ gírí, kí o sì mọ̀, kí o sì wo ohun tí ìwọ yóò ṣe, nítorí ní àmọ́dún ọba Aramu yóò tún gòkè tọ̀ ọ́ wá.”
23 Şi servitorii împăratului Siriei i-au spus: Dumnezeii lor sunt dumnezei ai dealurilor; de aceea au fost mai tari decât noi; dar să luptăm împotriva lor în câmpie şi cu siguranţă noi vom fi mai tari decât ei.
Àwọn ìránṣẹ́ ọba Aramu sì wí fún un pé, “Ọlọ́run wọn, ọlọ́run òkè ni. Ìdí nìyìí tí wọ́n ṣe ní agbára jù wá lọ. Ṣùgbọ́n bí a bá bá wọn jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ dájúdájú.
24 Şi fă acest lucru: Scoate pe împăraţi, pe fiecare om din locul său, şi pune căpetenii în locul lor;
Nǹkan yìí ni kí o sì ṣe, mú àwọn ọba kúrò, olúkúlùkù kúrò ní ipò rẹ̀, kí o sì fi baálẹ̀ sí ipò wọn.
25 Şi numără-ţi o armată, ca armata pe care ai pierdut-o, cal pentru cal şi car pentru car; şi vom lupta împotriva lor în câmpie şi cu siguranţă noi vom fi mai tari decât ei. Şi el a dat ascultare vocii lor şi a făcut astfel.
Kí o sì tún kó ogun jọ fún ara rẹ bí èyí tí ó ti sọnù; ẹṣin fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ fún kẹ̀kẹ́; kí a bá lè bá Israẹli jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Nítòótọ́ àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ.” Ó sì gba tiwọn, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.
26 Şi s-a întâmplat, la întoarcerea anului, că Ben-Hadad a numărat pe sirieni şi s-a urcat la Afec, pentru a lupta împotriva lui Israel.
Ó sì ṣe ní àmọ́dún, Beni-Hadadi ka iye àwọn ará Aramu, ó sì gòkè lọ sí Afeki, láti bá Israẹli jagun.
27 Şi copiii lui Israel au fost număraţi şi erau toţi prezenţi şi au mers împotriva lor; şi copiii lui Israel şi-au înălţat corturile în faţa lor ca două turme mici de iezi, dar sirienii umpleau ţara.
Nígbà tí a sì ka àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì pèsè oúnjẹ, wọ́n sì lọ pàdé wọn. Àwọn ọmọ Israẹli sì dó ní òdìkejì wọn gẹ́gẹ́ bí agbo ọmọ ewúrẹ́ kékeré méjì, nígbà tí àwọn ará Aramu kún ilẹ̀ náà.
28 Şi a venit un om al lui Dumnezeu şi a vorbit împăratului lui Israel şi a spus: Astfel spune DOMNUL: Pentru că sirienii au zis: DOMNUL este Dumnezeu al dealurilor dar nu este Dumnezeu al văilor, de aceea voi da toată această mare mulţime în mâna ta şi veţi cunoaşte că eu sunt DOMNUL.
Ènìyàn Ọlọ́run kan sì gòkè wá, ó sì sọ fún ọba Israẹli pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Nítorí tí àwọn ará Aramu rò pé Olúwa, Ọlọ́run òkè ni, ṣùgbọ́n òun kì í ṣe Ọlọ́run àfonífojì, nítorí náà èmi ó fi gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn yìí lé ọ lọ́wọ́, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
29 Şi şi-au înălţat corturile unii în faţa altora şapte zile. Şi astfel a fost, că în ziua a şaptea bătălia a început; şi copiii lui Israel au ucis dintre sirieni o sută de mii de pedeştri într-o singură zi.
Wọ́n sì dó sí òdìkejì ara wọn fún ọjọ́ méje, àti ní ọjọ́ keje, wọ́n pàdé ogun. Àwọn ọmọ Israẹli sì pa ọ̀kẹ́ márùn-ún ẹlẹ́ṣẹ̀ nínú àwọn ará Aramu ní ọjọ́ kan.
30 Dar restul au fugit la Afec în cetate; şi acolo un zid a căzut peste douăzeci şi şapte de mii dintre bărbaţii care erau rămaşi. Şi Ben-Hadad a fugit şi a intrat în cetate într-o cameră dinăuntru.
Àwọn tókù sì sá àsálà lọ sí Afeki, sínú ìlú tí odi ti wó lù ẹgbàá mẹ́tàlá lé ẹgbẹ̀rún nínú wọn. Beni-Hadadi sì sálọ sínú ìlú, ó sì fi ara pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.
31 Şi servitorii săi i-au spus: Iată acum, am auzit că împăraţii casei lui Israel sunt împăraţi milostivi; să ne punem, te rog, sac peste coapse şi funii pe capete şi să ieşim înaintea împăratului lui Israel; poate că te va lăsa cu viaţă.
Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, a ti gbọ́ pé àwọn ọba ilẹ̀ Israẹli jẹ́ ọba aláàánú, mo bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí àwa kí ó tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú aṣọ ọ̀fọ̀ ní ẹ̀gbẹ́ wa, àti okùn yí orí wa ká. Bóyá òun yóò gba ẹ̀mí rẹ là.”
32 Astfel s-au încins cu sac peste coapsele lor şi au pus funii pe capetele lor şi au venit la împăratul lui Israel şi au spus: Servitorul tău Ben-Hadad spune: Te rog, lasă-mă să trăiesc. Iar el a spus: Mai este încă în viaţă? El este fratele meu.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ wọn, wọ́n sì fi okùn yí orí wọn ká, wọ́n sì tọ ọba Israẹli wá, wọ́n sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ Beni-Hadadi wí pé, ‘Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí èmi kí ó yè.’” Ọba sì dáhùn wí pé, “Ó ń bẹ láààyè bí? Arákùnrin mi ni òun.”
33 Şi oamenii au căutat cu atenţie la cuvintele lui, dacă vreun lucru va ieşi de la el, şi au prins în grabă aceasta şi au zis: Fratele tău, Ben-Hadad. Atunci el a spus: Mergeţi, aduceţi-l. Atunci Ben-Hadad a ieşit la el, iar el l-a făcut să se urce în car.
Àwọn ọkùnrin náà sì ṣe àkíyèsí gidigidi, wọ́n sì yára gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, wọ́n sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, Beni-Hadadi arákùnrin rẹ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ lọ mú u wá.” Nígbà tí Beni-Hadadi jáde tọ̀ ọ́ wá, Ahabu sì mú u gòkè wá sínú kẹ̀kẹ́.
34 Şi Ben-Hadad i-a spus: Cetăţile, pe care le-a luat tatăl meu de la tatăl tău, le voi înapoia; şi îţi vei face străzi în Damasc, precum tatăl meu a făcut în Samaria. Atunci, Ahab a spus: Eu te voi trimite cu acest legământ. Astfel el a făcut legământ cu el şi l-a trimis.
Beni-Hadadi sì wí pé, “Èmi yóò dá àwọn ìlú tí baba mi ti gbà lọ́wọ́ baba rẹ padà, ìwọ sì le la ọ̀nà fún ara rẹ ní Damasku, bí baba mi ti ṣe ní Samaria.” Ahabu sì wí pé, “Èmi yóò rán ọ lọ pẹ̀lú májẹ̀mú yìí.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ba dá májẹ̀mú, ó sì rán an lọ.
35 Şi un anume bărbat dintre fiii profeţilor a spus aproapelui său în cuvântul DOMNULUI: Loveşte-mă, te rog. Şi bărbatul a refuzat să îl lovească.
Nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, ọkùnrin kan nínú àwọn ọmọ àwọn wòlíì sì wí fún èkejì rẹ̀ pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí,” ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti lù ú.
36 Atunci i-a spus: Pentru că nu ai ascultat de vocea DOMNULUI, iată, imediat ce te vei fi depărtat de la mine, un leu te va ucide. Şi imediat ce s-a depărtat de la el, un leu l-a găsit şi l-a ucis.
Nígbà náà ni ó wí pé, “Nítorí tí ìwọ kò gba ohùn Olúwa gbọ́, kíyèsi i, bí ìwọ bá kúrò ní ọ̀dọ̀ mi, kìnnìún yóò pa ọ́.” Bí ó ti jáde lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kìnnìún kan rí i, ó sì pa á.
37 Apoi a găsit un alt bărbat şi i-a spus: Loveşte-mă, te rog. Şi bărbatul l-a lovit, astfel încât prin lovire l-a rănit.
Wòlíì náà sì rí ọkùnrin mìíràn, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí.” Bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin náà sì lù ú, ó sì pa á lára.
38 Astfel, profetul a plecat şi l-a aşteptat pe împărat pe cale şi s-a deghizat cu cenuşă pe faţa lui.
Wòlíì náà sì lọ, ó sì dúró de ọba ní ojú ọ̀nà. Ó pa ara rẹ̀ dà ní fífi eérú bo ojú.
39 Şi pe când trecea împăratul, a strigat către împărat şi a spus: Servitorul tău a ieşit în mijlocul luptei; şi, iată, un om s-a abătut şi a adus la mine un om şi a spus: Păzeşte pe acest om; dacă va lipsi cumva, atunci viaţa ta va fi pentru viaţa lui sau altfel îmi vei plăti un talant de argint.
Bí ọba sì ti ń rékọjá, wòlíì náà ké sí i, ó sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ jáde wọ àárín ogun lọ, ẹnìkan sì wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ìgbèkùn kan, ó sì wí pé, ‘Pa ọkùnrin yìí mọ́. Bí a bá fẹ́ ẹ kù, ẹ̀mí rẹ yóò lọ dípò ẹ̀mí rẹ̀, tàbí kí ìwọ san tálẹ́ǹtì fàdákà kan.’
40 Şi pe când servitorul tău era ocupat încoace şi încolo, el a dispărut. Şi împăratul lui Israel i-a spus: Aceasta îţi este judecata; tu însuţi ai hotărât-o.
Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ìṣe níhìn-ín àti lọ́hùn ún, a fẹ́ ẹ kù.” Ọba Israẹli sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ìdájọ́ rẹ yóò rí, ìwọ fúnra rẹ̀ ti dá a.”
41 Şi el s-a grăbit şi şi-a luat cenuşa de pe faţa lui; şi împăratul lui Israel l-a recunoscut că era dintre profeţi.
Nígbà náà ni wòlíì náà yára, ó sì mú eérú kúrò ní ojú rẹ̀, ọba Israẹli sì mọ̀ ọ́n pé ọ̀kan nínú àwọn wòlíì ni ó ń ṣe.
42 Iar el i-a spus: Astfel spune DOMNUL: Pentru că ai dat drumul din mâna ta unui om pe care l-am rânduit în întregime nimicirii, de aceea viaţa ta va merge pentru viaţa lui şi poporul tău pentru poporul lui.
Ó sì wí fún ọba pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti jọ̀wọ́ ọkùnrin tí èmi ti yàn sí ìparun pátápátá lọ́wọ́ lọ. Nítorí náà, ẹ̀mí rẹ yóò lọ fún ẹ̀mí rẹ, ènìyàn rẹ fún ènìyàn rẹ̀.’”
43 Şi împăratul lui Israel a mers la casa lui trist şi nemulţumit şi a venit în Samaria.
Ọba Israẹli sì lọ sí ilé rẹ̀ ní wíwú gbọ́, inú rẹ sì bàjẹ́, ó sì wá sí Samaria.

< 1 Regii 20 >