< 1 Regii 2 >

1 Şi s-au apropiat zilele lui David să moară; şi el i-a poruncit lui Solomon, fiul său, spunând:
Nígbà tí ọjọ́ ikú Dafidi súnmọ́ etílé, ó pàṣẹ fún Solomoni ọmọ rẹ̀.
2 Eu merg pe calea întregului pământ; tu fii tare de aceea şi arată-te bărbat;
Ó sì wí pé, “Èmi ti fẹ́ lọ sí ọ̀nà gbogbo ayé, nítorí náà jẹ́ alágbára kí o sì fi ara rẹ hàn bí ọkùnrin,
3 Şi păzeşte porunca DOMNULUI Dumnezeul tău, de a umbla în căile lui, de a ţine statutele lui şi poruncile lui şi judecăţile lui şi mărturiile lui, precum este scris în legea lui Moise, ca să prosperi în tot ceea ce faci şi oriunde te întorci;
kí o sì wòye ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ béèrè, rìn ní ọ̀nà rẹ̀, kí o sì pa àṣẹ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti ìdájọ́ rẹ, àti ẹ̀rí rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé òfin Mose, nítorí kí ìwọ kí ó le è máa ṣe rere ní ohun gbogbo tí ìwọ ṣe, àti ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ,
4 Ca DOMNUL să continue cuvântul său pe care l-a vorbit referitor la mine, spunând: Dacă ai tăi copii vor lua seama la calea lor, pentru a umbla înaintea mea în adevăr cu toată inima lor şi cu tot sufletul lor, nu vei fi lipsit (a spus el) de un bărbat pe tronul lui Israel.
kí Olúwa kí ó lè pa ìlérí rẹ̀ tí ó sọ nípa tèmi mọ́ pé, ‘Bí àwọn ọmọ rẹ bá kíyèsi ọ̀nà wọn, tí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà wọn àti ọkàn wọn rìn níwájú mi ní òtítọ́, o kì yóò sì kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
5 Mai mult, tu ştii de asemenea ce mi-a făcut Ioab, fiul Ţeruiei, şi ce a făcut celor două căpetenii ale oştirilor lui Israel: lui Abner, fiul lui Ner, şi lui Amasa, fiul lui Ieter, pe care i-a ucis şi a vărsat sângele de război pe timp de pace, şi a pus sângele de război pe brâul lui, care era pe coapsele lui şi pe sandalele lui care erau în picioarele lui.
“Ìwọ pẹ̀lú sì mọ ohun tí Joabu ọmọ Seruiah ṣe sí mi àti ohun tí ó ṣe sí balógun méjì nínú àwọn ológun Israẹli, sí Abneri ọmọ Neri àti sí Amasa ọmọ Jeteri. Ó sì pa wọ́n, ó sì ta ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ ní ìgbà àlàáfíà bí í ti ojú ogun ó sì fi ẹ̀jẹ̀ náà sí ara àmùrè rẹ̀ tí ń bẹ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, àti sí ara sálúbàtà rẹ̀ tí ń bẹ ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
6 Fă de aceea conform înţelepciunii tale şi nu lăsa capul său alb să coboare în pace în mormânt. (Sheol h7585)
Ṣe sí í gẹ́gẹ́ bí ọgbọ́n rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
7 Dar arată bunătate faţă de fiii lui Barzilai galaaditul şi ei să fie dintre cei care mănâncă la masa ta, pentru că astfel ei au venit la mine când am fugit din faţa fratelui tău, Absalom.
“Ṣùgbọ́n fi inú rere hàn sí àwọn ọmọ Barsillai, ti Gileadi, jẹ́ kí wọn wà lára àwọn tí ó ń jẹun lórí tábìlì rẹ̀. Wọ́n dúró tì mí nígbà tí mo sá kúrò níwájú Absalomu arákùnrin rẹ.
8 Şi, iată, tu ai cu tine pe Şimei, fiul lui Ghera, un beniamit din Bahurim, care m-a blestemat cu un blestem apăsător în ziua când am mers la Mahanaim; dar el a coborât să mă întâlnească la Iordan şi i-am jurat pe DOMNUL, spunând: Nu te voi da la moarte prin sabie.
“Àti kí o rántí, Ṣimei ọmọ Gera ẹ̀yà Benjamini tí Bahurimu wà pẹ̀lú rẹ̀, tí ó bú mi ní èébú tí ó korò ní ọjọ́ tí mo lọ sí Mahanaimu. Nígbà tí ó sọ̀kalẹ̀ wá pàdé mi ní Jordani, mo fi Olúwa búra fún un pé, ‘Èmi kì yóò fi idà pa ọ́.’
9 De aceea acum, nu îl lăsa fără vină, pentru că tu eşti un om înţelept şi ştii ce trebuie să îi faci; dar capul său alb să îl cobori în mormânt cu sânge. (Sheol h7585)
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, má ṣe kíyèsi í gẹ́gẹ́ bí aláìlẹ́ṣẹ̀, ọkùnrin ọlọ́gbọ́n ni ìwọ ṣe; ìwọ yóò mọ ohun tí ìwọ yóò ṣe sí i. Mú ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sínú isà òkú pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀.” (Sheol h7585)
10 Astfel, David a adormit cu părinţii săi şi a fost îngropat în cetatea lui David.
Nígbà náà ni Dafidi sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi.
11 Şi zilele cât David a domnit peste Israel au fost patruzeci de ani: şapte ani a domnit în Hebron şi treizeci şi trei de ani a domnit în Ierusalim.
Dafidi ti jẹ ọba lórí Israẹli ní ogójì ọdún, ọdún méje ni Hebroni àti ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu.
12 Atunci Solomon a şezut pe tronul lui David, tatăl său; şi împărăţia a fost întemeiată, foarte mult.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀, ìjọba rẹ̀ sì fi ìdí múlẹ̀ gidigidi.
13 Şi Adonia, fiul lui Haghita, a venit la Bat-Şeba, mama lui Solomon. Şi ea a spus: Vii cu pace? Şi el a spus: Cu pace.
Wàyí, Adonijah ọmọ Haggiti tọ Batṣeba, ìyá Solomoni wá. Batṣeba sì bi í pé, “Àlàáfíà ni o bá wa bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni.”
14 Iar el a mai spus: Am ceva să îţi spun. Iar ea a zis: Spune.
Nígbà náà ni ó sì fi kún un pé, “Mo ní ohun kan láti sọ fún ọ.” Batṣeba sì wí pé, “Máa wí.”
15 Iar el a zis: Tu ştii că împărăţia era a mea şi că tot Israelul şi-a îndreptat faţa către mine, ca să domnesc; totuşi, împărăţia s-a întors şi a devenit a fratelui meu, pentru că era a lui de la DOMNUL.
Ó wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí o ti mọ̀, ti tèmi ni ìjọba náà. Gbogbo Israẹli ti wò mí bí ọba wọn. Ṣùgbọ́n nǹkan yípadà, ìjọba náà sì ti lọ sí ọ̀dọ̀ arákùnrin mi, nítorí ó ti wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti ọwọ́ Olúwa wá.
16 Şi acum am o singură rugăminte la tine, nu mă refuza. Iar ea i-a zis: Spune.
Nísinsin yìí mo ní ìbéèrè kan láti bi ọ́, má ṣe kọ̀ fún mi.” Ó wí pé, “O lè wí.”
17 Iar el a zis: Vorbeşte, te rog, împăratului Solomon, (pentru că el nu îţi va spune nu) ca să îmi dea pe sunamita Abişag de soţie.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ̀síwájú pé, “Mo bẹ̀ ọ́, jọ̀wọ́ sọ fún Solomoni ọba (òun kì yóò kọ̀ fún ọ́) kí ó fún mi ní Abiṣagi ará Ṣunemu ní aya.”
18 Şi Bat-Şeba a spus: Bine, voi vorbi împăratului pentru tine.
Batṣeba sì dáhùn pé, “Ó dára èmi yóò bá ọba sọ̀rọ̀ nítorí rẹ̀.”
19 Bat-Şeba de aceea a intrat la împăratul Solomon pentru a-i vorbi pentru Adonia. Şi împăratul s-a ridicat să o întâlnească şi s-a aplecat înaintea ei şi a şezut pe tronul său; şi a făcut să fie pus un tron pentru mama împăratului; şi ea a şezut la dreapta lui.
Nígbà tí Batṣeba sì tọ Solomoni ọba lọ láti bá a sọ̀rọ̀ nítorí Adonijah, ọba sì dìde láti pàdé rẹ̀, ó sì tẹríba fún un, ó sì jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀. Ó sì tẹ́ ìtẹ́ kan fún ìyá ọba, ó sì jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀.
20 Atunci ea a spus: Am o mică rugăminte la tine; te rog, nu îmi spune nu. Şi împăratul i-a zis: Cere, mama mea, pentru că nu îţi voi spune nu.
Ó sì wí pé, “Mo ní ìbéèrè kékeré kan láti béèrè lọ́wọ́ rẹ, má ṣe kọ̀ fún mi.” Ọba sì dáhùn wí pé, “Béèrè, ìyá mi; èmi kì yóò kọ̀ ọ́.”
21 Şi ea a zis: Sunamita Abişag să îi fie dată lui Adonia, fratele tău, de soţie.
Nígbà náà ni ó wí pé, “Jẹ́ kí a fi Abiṣagi ará Ṣunemu fún Adonijah arákùnrin rẹ ní aya.”
22 Şi împăratul Solomon a răspuns şi i-a zis mamei sale: Şi pentru ce ceri pe sunamita Abişag pentru Adonia? Cere pentru el şi împărăţia, pentru că el este fratele meu mai mare; chiar pentru el şi pentru preotul Abiatar şi pentru Ioab, fiul Ţeruiei.
Solomoni ọba sì dá ìyá rẹ̀ lóhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ fi béèrè Abiṣagi ará Ṣunemu fún Adonijah! Ìwọ ìbá sì béèrè ìjọba fún un pẹ̀lú nítorí ẹ̀gbọ́n mi ní í ṣe, fún òun pàápàá àti fún Abiatari àlùfáà àti fun Joabu ọmọ Seruiah!”
23 Atunci împăratul Solomon a jurat pe DOMNUL, spunând: Dumnezeu să îmi facă astfel şi încă mai mult, dacă Adonia nu a vorbit acest cuvânt împotriva vieţii lui.
Nígbà náà ni Solomoni ọba fi Olúwa búra pé, “Kí Ọlọ́run ki ó jẹ mí ní yà, àti jù bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú, bí Adonijah kò bá ní fi ẹ̀mí rẹ̀ san ìbéèrè yìí!
24 De aceea acum, precum DOMNUL trăieşte, care m-a întemeiat şi m-a pus pe tronul lui David, tatăl meu, şi care mi-a făcut o casă, precum a promis, că Adonia va fi dat la moarte în această zi.
Àti nísinsin yìí, bí ó ti dájú pé Olúwa wà láààyè, ẹni tí ó ti mú mi jókòó lórí ìtẹ́ baba mi Dafidi, àti tí ó sì ti kọ́ ilé fún mi bí ó ti ṣèlérí, lónìí ni a ó pa Adonijah!”
25 Şi împăratul Solomon a trimis prin mâna lui Benaia, fiul lui Iehoiada; şi el a căzut asupra lui încât acela a murit.
Solomoni ọba sì pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada, ó sì kọlu Adonijah, ó sì kú.
26 Şi împăratul i-a spus preotului Abiatar: Du-te la Anatot, la câmpurile tale, pentru că tu eşti demn de moarte; dar în acest timp nu te voi da la moarte, pentru că ai purtat chivotul DOMNULUI DUMNEZEU înaintea lui David, tatăl meu, şi deoarece ai fost chinuit în tot ce s-a chinuit tatăl meu.
Ọba sì wí fún Abiatari àlùfáà pé, “Padà lọ sí pápá rẹ ni Anatoti, ó yẹ fún ọ láti kú, ṣùgbọ́n èmi kì yóò pa ọ́ nísinsin yìí, nítorí o ti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa Olódùmarè níwájú Dafidi baba mi, o sì ti ní ìpín nínú gbogbo ìyà tí baba mi jẹ.”
27 Astfel Solomon l-a alungat pe Abiatar din a fi un preot DOMNULUI, ca să împlinească cuvântul DOMNULUI, pe care l-a spus referitor la casa lui Eli în Şilo.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni yọ Abiatari kúrò nínú iṣẹ́ àlùfáà Olúwa, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ nípa ilé Eli ní Ṣilo ṣẹ.
28 Atunci veştile au venit la Ioab, pentru că Ioab se întorsese după Adonia, deşi nu se întorsese după Absalom. Şi Ioab a fugit la tabernacolul DOMNULUI şi a apucat coarnele altarului.
Nígbà tí ìròyìn sì dé ọ̀dọ̀ Joabu, ẹni tí ó ti dìtẹ̀ pẹ̀lú Adonijah bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò wà pẹ̀lú Absalomu, ó sì sálọ sínú àgọ́ Olúwa, ó sì di ìwo pẹpẹ mú.
29 Şi i s-a spus împăratului Solomon că Ioab a fugit la tabernacolul DOMNULUI; şi, iată, el este lângă altar. Atunci Solomon a trimis pe Benaia, fiul lui Iehoiada, spunând: Du-te, cazi asupra lui.
A sì sọ fún Solomoni ọba pé Joabu ti sálọ sínú àgọ́ Olúwa àti pé ó wà ní ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ. Nígbà náà ni Solomoni pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada pé, “Lọ, kí o sì kọlù ú.”
30 Şi Benaia a venit la tabernacolul DOMNULUI şi i-a zis: Astfel spune împăratul: Ieşi afară. Iar el a spus: Nu, ci voi muri aici. Şi Benaia a adus din nou cuvânt împăratului, spunând: Astfel a zis Ioab şi astfel mi-a răspuns.
Benaiah sì wọ inú àgọ́ Olúwa, ó sì wí fún Joabu pé, “Ọba sọ wí pé, ‘Jáde wá.’” Ṣùgbọ́n ó dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, èmi yóò kú níhìn-ín.” Benaiah sì mú èsì fún ọba, “Báyìí ni Joabu ṣe dá mi lóhùn.”
31 Şi împăratul i-a zis: Fă precum a spus şi cazi asupra lui şi îngroapă-l; ca să îndepărtezi de la mine şi de la casa tatălui meu, sângele nevinovat, pe care l-a vărsat Ioab.
Ọba sì pàṣẹ fún Benaiah pé, “Ṣe bí ó ti wí. Kọlù ú, kí o sì sin ín, kí o sì mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi àti kúrò lọ́dọ̀ ilé baba mi, tí Joabu ti ta sílẹ̀.
32 Şi DOMNUL să întoarcă sângele lui asupra capului său, care a căzut asupra a doi bărbaţi mai drepţi şi mai buni decât el şi i-a ucis cu sabia, tatăl meu, David, neştiind de aceasta, adică pe Abner, fiul lui Ner, căpetenia oştirii lui Israel şi pe Amasa, fiul lui Ieter, căpetenia oştirii lui Iuda.
Olúwa yóò sì san ẹ̀jẹ̀ tí ó ti ta sílẹ̀ padà fún un, nítorí tí ó kọlu ọkùnrin méjì, ó sì fi idà rẹ̀ pa wọ́n, Dafidi baba mi kò sì mọ̀. Àwọn méjèèjì ni Abneri ọmọ Neri olórí ogun Israẹli, àti Amasa ọmọ Jeteri olórí ogun Juda, wọ́n jẹ́ olódodo, wọ́n sì sàn ju òun fúnra rẹ̀ lọ.
33 Sângele lor să se întoarcă asupra capului lui Ioab şi asupra capului seminţei lui pentru totdeauna; dar asupra lui David şi asupra seminţei lui şi asupra casei lui şi asupra tronului său, să fie pace de la DOMNUL pentru totdeauna.
Kí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn wá sórí Joabu àti sórí irú-ọmọ rẹ̀ títí láé. Ṣùgbọ́n sórí Dafidi àti irú-ọmọ rẹ̀, sí ilé rẹ̀ àti sí ìtẹ́ rẹ̀, ni kí àlàáfíà Olúwa wà títí láé.”
34 Astfel Benaia, fiul lui Iehoiada, s-a urcat şi a căzut asupra lui şi l-a ucis; iar el a fost îngropat în casa lui în pustie.
Bẹ́ẹ̀ ni Benaiah ọmọ Jehoiada sì gòkè lọ, ó sì kọlu Joabu, ó sì pa á, a sì sin ín ní ilẹ̀ ibojì ara rẹ̀ ní aginjù.
35 Şi împăratul l-a pus pe Benaia, fiul lui Iehoiada, în locul lui peste oştire; şi pe preotul Ţadoc, împăratul l-a pus în locul lui Abiatar.
Ọba sì fi Benaiah ọmọ Jehoiada jẹ olórí ogun ní ipò Joabu àti Sadoku àlùfáà ní ipò Abiatari.
36 Şi împăratul a trimis şi l-a chemat pe Şimei şi i-a spus: Zideşte-ţi o casă în Ierusalim şi locuieşte acolo şi să nu ieşi de acolo nici încoace nici încolo.
Nígbà náà ni ọba ránṣẹ́ sí Ṣimei, ó sì wí fún un pé, “Kọ́ ilé fún ara rẹ ní Jerusalẹmu, kí o sì máa gbé ibẹ̀, ṣùgbọ́n kí o má sì ṣe lọ sí ibòmíràn.
37 Pentru că va fi, că în ziua când ieşi afară şi treci peste pârâul Chedron, să ştii într-adevăr că vei muri negreşit; sângele tău va fi asupra capului tău.
Ọjọ́ tí ìwọ bá jáde, tí o sì kọjá àfonífojì Kidironi, kí ìwọ kí ó mọ̀ dájúdájú pé ìwọ yóò kú; ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wà lórí ara rẹ.”
38 Şi Şimei i-a zis împăratului: Spusa este bună; precum domnul meu împăratul a spus, astfel servitorul tău va face. Şi Şimei a locuit în Ierusalim multe zile.
Ṣimei sì dá ọba lóhùn pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára. Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe bí olúwa mi ọba ti wí.” Ṣimei sì gbé ní Jerusalẹmu fún ìgbà pípẹ́.
39 Şi s-a întâmplat, la sfârşitul a trei ani, că doi dintre servitorii lui Şimei au fugit la Achiş, fiul lui Maaca, împăratul din Gat. Şi ei i-au spus lui Şimei, zicând: Iată, servitorii tăi sunt în Gat.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ Ṣimei méjì sì sálọ sọ́dọ̀ Akiṣi ọmọ Maaka, ọba Gati, a sì sọ fún Ṣimei pé, “Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ méjì wà ní Gati.”
40 Şi Şimei s-a ridicat şi şi-a înşeuat măgarul şi a mers la Gat, la Achiş, să îi caute pe servitorii săi; şi Şimei a mers şi i-a adus pe servitorii săi din Gat.
Fún ìdí èyí, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì lọ sọ́dọ̀ Akiṣi ní Gati láti wá àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni Ṣimei sì lọ, ó sì mú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ padà bọ̀ láti Gati.
41 Şi i s-a spus lui Solomon că Şimei mersese din Ierusalim la Gat şi s-a întors.
Nígbà tí a sì sọ fún Solomoni pé Ṣimei ti lọ láti Jerusalẹmu sí Gati, ó sì ti padà.
42 Şi împăratul a trimis şi l-a chemat pe Şimei şi i-a spus: Nu te-am pus eu să juri pe DOMNUL şi nu te-am avertizat, spunând: Să ştii negreşit, că în ziua când vei ieşi afară şi vei umbla încoace şi încolo, vei muri negreşit? Şi tu mi-ai spus: Cuvântul pe care l-am auzit este bun.
Ọba pe Ṣimei lẹ́jọ́, ó wí fún un pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ti mú ọ búra ní ti Olúwa, èmi sì ti kìlọ̀ fún ọ pé, ‘Ní ọjọ́ tí ìwọ bá kúrò láti lọ sí ibikíbi, kí o mọ̀ dájú pé ìwọ yóò kú.’ Nígbà náà ni ìwọ sì sọ fún mi pé, ‘Ohun tí ìwọ sọ dára. Èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn.’
43 De ce atunci nu ai păzit jurământul DOMNULUI şi porunca pe care ţi-am poruncit-o?
Èéṣe, nígbà náà tí ìwọ kò pa ìbúra Olúwa mọ́, àti kí o sì ṣe ìgbọ́ràn sí àṣẹ tí mo pa fún ọ?”
44 Împăratul i-a mai spus lui Şimei: Cunoşti toată stricăciunea, la care inima ta este martoră, pe care i-ai făcut-o lui David, tatăl meu: de aceea DOMNUL să întoarcă răutatea ta asupra capului tău;
Ọba sì tún wí fún Ṣimei pé, “Ìwọ mọ̀ ní ọkàn rẹ gbogbo búburú tí ìwọ ti ṣe sí Dafidi baba mi. Báyìí, Olúwa yóò san gbogbo ìṣe búburú rẹ padà fún ọ.
45 Şi împăratul Solomon să fie binecuvântat şi tronul lui David să fie întemeiat înaintea DOMNULUI pentru totdeauna.
Ṣùgbọ́n a ó sì bùkún fún Solomoni ọba, ìtẹ́ Dafidi yóò sì wà láìfòyà níwájú Olúwa títí láéláé.”
46 Astfel împăratul i-a poruncit lui Benaia, fiul lui Iehoiada, şi el a fost acela care a ieşit şi a căzut asupra lui şi acela a murit. Şi împărăţia a fost întemeiată, în mâna lui Solomon.
Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada, ó sì jáde lọ, ó sì kọlu Ṣimei, ó sì pa á. Ìjọba náà sì wá fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ Solomoni.

< 1 Regii 2 >