< 1 Regii 14 >

1 În timpul acela Abiia, fiul lui Ieroboam, s-a îmbolnăvit.
Ní àkókò náà Abijah ọmọ Jeroboamu sì ṣàìsàn,
2 Şi Ieroboam i-a spus soţiei sale: Ridică-te, te rog, şi deghizează-te, ca să nu fii cunoscută că eşti soţia lui Ieroboam; şi mergi la Şilo; iată, acolo este profetul Ahiia, care mi-a spus că voi fi împărat peste acest popor.
Jeroboamu sì wí fún aya rẹ̀ pé, “Lọ, sì pa ara rẹ dà, kí wọn kí ó má ba à mọ̀ ọ́n ní aya Jeroboamu. Nígbà náà ni kí o lọ sí Ṣilo. Ahijah wòlíì wà níbẹ̀; ẹni tí ó sọ fún mi pé, èmi yóò jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn yìí.
3 Şi ia cu tine zece pâini şi turte şi un urcior cu miere şi mergi la el: el îţi va spune ce i se va întâmpla copilului.
Mú ìṣù àkàrà mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, àti àkàrà wẹ́wẹ́ àti ìgò oyin, kí o sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Òun yóò sì sọ fún ọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọkùnrin náà.”
4 Şi soţia lui Ieroboam a făcut astfel şi s-a ridicat şi a mers la Şilo şi a venit la casa lui Ahiia. Dar Ahiia nu putea să vadă, pentru că ochii lui se întunecaseră din cauza bătrâneţii.
Bẹ́ẹ̀ ni aya Jeroboamu sì ṣe bí ó ti wí, ó sì lọ sí ilé Ahijah ní Ṣilo. Ahijah kò sì ríran; ojú rẹ̀ ti fọ́ nítorí ogbó rẹ̀.
5 Şi DOMNUL i-a spus lui Ahiia: Iată, soţia lui Ieroboam vine să te întrebe un lucru pentru fiul ei, pentru că este bolnav; şi aşa şi aşa să îi vorbeşti, pentru că atunci când va intra, se va preface a fi altă femeie.
Ṣùgbọ́n Olúwa ti sọ fún Ahijah pé, “Kíyèsi i, aya Jeroboamu ń bọ̀ wá béèrè nípa ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí ó ṣàìsàn, báyìí báyìí ni kí ìwọ kí ó wí fún un. Nígbà tí ó bá dé, yóò ṣe ara rẹ̀ bí ẹlòmíràn.”
6 Şi s-a întâmplat, când Ahiia a auzit sunetul picioarelor ei, pe când intra pe uşă, că el i-a spus: Intră, tu soţie a lui Ieroboam; de ce te prefaci a fi alta? Pentru că eu sunt trimis la tine cu veşti grele.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí, nígbà tí Ahijah sì gbọ́ ìró ẹsẹ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà, ó sì wí pé, “Wọlé wá, aya Jeroboamu. Kí ló dé tí ìwọ fi ṣe ara rẹ bí ẹlòmíràn? A ti fi iṣẹ́ búburú rán mi sí ọ.
7 Du-te, spune lui Ieroboam: Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Deşi te-am înălţat din mijlocul poporului şi te-am făcut prinţ peste poporul meu, Israel,
Lọ, sọ fún Jeroboamu pé báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi sì gbé ọ ga láti inú àwọn ènìyàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí lórí Israẹli ènìyàn mi.
8 Şi am rupt împărăţia de la casa lui David şi ţi-am dat-o ţie, totuşi nu ai fost ca servitorul meu David, care a păzit poruncile mele şi care m-a urmat cu toată inima sa, pentru a face numai ceea ce era drept în ochii mei;
Mo fa ìjọba náà ya kúrò ní ilé Dafidi, mo sì fi fún ọ ṣùgbọ́n, ìwọ kò dàbí Dafidi ìránṣẹ́ mi, tí ó pa àṣẹ mi mọ́, tí ó sì tọ̀ mí lẹ́yìn tọkàntọkàn rẹ̀, láti ṣe kìkì èyí tí ó tọ́ ní ojú mi.
9 Ci ai făcut rău mai mult decât toţi câţi au fost înaintea ta; fiindcă ai mers şi ţi-ai făcut alţi dumnezei şi chipuri turnate, pentru a mă provoca la mânie şi m-ai aruncat în spatele tău;
Ìwọ sì ti ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó ti wà ṣáájú rẹ lọ. Ìwọ sì ti ṣe àwọn ọlọ́run mìíràn fún ara rẹ, àwọn òrìṣà tí a gbẹ́; o sì ti mú mi bínú, o sì ti gbé mi sọ sí ẹ̀yìn rẹ.
10 De aceea, iată, voi aduce răul asupra casei lui Ieroboam şi voi stârpi de la Ieroboam, pe cel care urinează la perete şi pe cel închis şi pe cel rămas în Israel, şi voi îndepărta rămăşiţa casei lui Ieroboam, precum omul îndepărtează balega, până când se duce toată.
“‘Nítorí èyí, Èmi yóò mú ibi wá sí ilé Jeroboamu. Èmi yóò ké gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ Jeroboamu, àti ọmọ ọ̀dọ̀ àti òmìnira ní Israẹli. Èmi yóò mú ilé Jeroboamu kúrò bí ènìyàn ti ń kó ìgbẹ́ kúrò, títí gbogbo rẹ̀ yóò fi tán.
11 Pe cel ce moare din Ieroboam în cetate, câinii îl vor mânca; şi pe cel care moare în câmp îl vor mânca păsările cerului, pentru că DOMNUL a vorbit aceasta.
Ajá yóò jẹ ẹni Jeroboamu tí ó bá kú ní ìlú, àti ẹni tí ó bá kú ní igbó ni àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ. Olúwa ti sọ ọ́!’
12 Ridică-te de aceea, mergi acasă; şi când picioarele tale vor intra în cetate, copilul va muri.
“Ní ti ìwọ, padà lọ ilé, nígbà tí o bá sì fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ ìlú, ọmọ náà yóò kú.
13 Şi tot Israelul va jeli pentru el şi îl vor îngropa, pentru că numai el din Ieroboam va intra în mormânt, pentru că numai în el s-a găsit ceva bun faţă de DOMNUL Dumnezeul lui Israel, în casa lui Ieroboam.
Gbogbo Israẹli yóò sì ṣọ̀fọ̀ fún un, wọn yóò sì sin ín. Òun nìkan ni a ó sì sin nínú ẹni tí ń ṣe ti Jeroboamu, nítorí lọ́dọ̀ rẹ̀ nìkan ni a ti rí ohun rere díẹ̀ sípa Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ní ilé Jeroboamu.
14 Mai mult, DOMNUL îşi va ridica un împărat peste Israel, care va stârpi casa lui Ieroboam în acea zi, dar ce spun? Chiar acum.
“Olúwa yóò gbé ọba kan dìde fúnra rẹ̀ lórí Israẹli tí yóò ké ilé Jeroboamu kúrò. Ọjọ́ náà nìyìí! Kí ni? Àní nísinsin yìí.
15 Fiindcă DOMNUL va lovi pe Israel, precum o trestie este scuturată în apă şi va dezrădăcina pe Israel din această ţară bună, pe care a dat-o părinţilor lor şi îi va împrăştia dincolo de râu, deoarece şi-au făcut dumbrăvi, provocând pe DOMNUL la mânie.
Olúwa yóò kọlu Israẹli, yóò sì dàbí koríko ti ń mì nínú omi. Yóò sì fa Israẹli tu kúrò ní ilẹ̀ rere yìí, tí ó ti fi fún àwọn baba wọn, yóò sì fọ́n wọn ká kọjá odò Eufurate, nítorí wọ́n ti rú ìbínú Olúwa nípa ṣíṣe ère Aṣerah.
16 Şi el va părăsi pe Israel din cauza păcatelor lui Ieroboam, care a păcătuit şi care a făcut pe Israel să păcătuiască.
Yóò sì kọ Israẹli sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀.”
17 Şi soţia lui Ieroboam s-a ridicat şi a plecat şi a venit la Tirţa; şi când a ajuns la pragul uşii, copilul a murit.
Nígbà náà ni aya Jeroboamu sì dìde, ó sì lọ, ó sì lọ sí Tirsa. Bí ó sì ti fi ẹsẹ̀ tẹ ìloro ilé, ọmọdé náà sì kú.
18 Şi l-au îngropat; şi tot Israelul a jelit pentru el, conform cuvântului DOMNULUI, pe care el îl vorbise prin mâna servitorului său, profetul Ahiia.
Wọ́n sì sin ín, gbogbo Israẹli sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí láti ẹnu ìránṣẹ́ rẹ̀, Ahijah wòlíì.
19 Şi restul faptelor lui Ieroboam, cum s-a războit şi cum a domnit, iată, ele sunt scrise în cartea cronicilor împăraţilor lui Israel.
Ìyókù ìṣe Jeroboamu, bí ó ti jagun, àti bí ó ti jẹ ọba, ni a kọ sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli.
20 Şi zilele cât Ieroboam a domnit au fost douăzeci şi doi de ani; şi a adormit cu părinţii săi şi Nadab, fiul său, a domnit în locul său.
Jeroboamu sì jẹ ọba fún ọdún méjìlélógún, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Nadabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
21 Şi Roboam, fiul lui Solomon, a domnit în Iuda. Roboam era în vârstă de patruzeci şi unu de ani când a început să domnească şi a domnit şaptesprezece ani în Ierusalim, cetatea pe care DOMNUL a ales-o dintre toate triburile lui Israel, ca să îşi pună numele său acolo. Şi numele mamei lui era Naama, o amonită.
Rehoboamu ọmọ Solomoni sì jẹ ọba ní Juda. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní ọdún mọ́kànlélógún ní Jerusalẹmu, ìlú tí Olúwa ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama, ará Ammoni.
22 Şi Iuda a făcut ce este rău în ochii DOMNULUI; şi l-au provocat la gelozie cu păcatele lor pe care le-au făcut, mai mult decât tot ce făcuseră părinţii lor.
Juda sì ṣe búburú níwájú Olúwa nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí wọ́n ti dá, wọ́n sì mú u jowú ju gbogbo èyí tí baba wọn ti ṣe lọ.
23 Fiindcă ei şi-au zidit de asemenea înălţimi şi idoli şi dumbrăvi pe fiecare deal înalt şi sub fiecare copac verde.
Wọ́n sì tún kọ́ ibi gíga fún ara wọn, àti ère òkúta àti òpó Aṣerah lórí gbogbo òkè gíga, àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
24 Şi erau de asemenea sodomiţi în ţară, care au făcut conform cu toate urâciunile naţiunilor pe care DOMNUL le alungase dinaintea copiilor lui Israel.
Àwọn tí wọn jẹ́ ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà wà ní ilẹ̀ náà, àwọn ènìyàn náà sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde kúrò níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
25 Şi s-a întâmplat, în al cincilea an al împăratului Roboam, că Şişac, împăratul Egiptului, s-a urcat împotriva Ierusalimului;
Ó sì ṣe ní ọdún karùn-ún Rehoboamu, Ṣiṣaki ọba Ejibiti kọlu Jerusalẹmu.
26 Şi a luat tezaurele casei DOMNULUI şi tezaurele casei împăratului; a luat chiar tot; şi a luat toate scuturile de aur pe care Solomon le făcuse.
Ó sì kó ìṣúra ilé Olúwa lọ àti ìṣúra ilé ọba. Gbogbo rẹ̀ ni ó kó lọ, pẹ̀lú asà wúrà tí Solomoni ti ṣe.
27 Şi împăratul Roboam a făcut în locul lor scuturi de aramă şi le-a încredinţat în mâinile mai marelui gărzii, care păzea uşa casei împăratului.
Rehoboamu ọba sì ṣe asà idẹ ní ipò wọn, ó sì fi wọ́n sí ọwọ́ olórí àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlẹ̀kùn ilé ọba.
28 Şi s-a întâmplat când împăratul intra în casa DOMNULUI, că garda le purta şi le aducea înapoi în camera gărzii.
Nígbàkígbà tí ọba bá sì lọ sí ilé Olúwa, wọ́n á rù wọ́n, wọ́n á sì mú wọn padà sínú yàrá olùṣọ́.
29 Şi restul faptelor lui Roboam şi tot ce a făcut, nu sunt ele scrise în cartea cronicilor împăraţilor lui Iuda?
Ní ti ìyókù ìṣe Rehoboamu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ǹjẹ́ a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda bí?
30 Şi a fost război între Roboam şi Ieroboam, în toate zilele lor.
Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní ọjọ́ wọn gbogbo.
31 Şi Roboam a adormit cu părinţii săi şi a fost îngropat cu părinţii săi în cetatea lui David. Şi numele mamei lui era Naama, o amonită. Şi Abiiam, fiul său, a domnit în locul său.
Rehoboamu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama; ará Ammoni. Abijah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< 1 Regii 14 >