< 1 Corinteni 11 >
1 Fiți urmași ai mei, așa cum și eu sunt al lui Cristos.
Ẹ máa tẹ̀lé àpẹẹrẹ mi, gẹ́gẹ́ bí èmi náà ti ń tẹ̀lé àpẹẹrẹ Kristi.
2 Acum vă laud, fraților, că vă amintiți de mine în toate și țineți rânduielile precum vi le-am dat.
Èmí yìn yín fún rírántí mi nínú ohun gbogbo àti fún dídi gbogbo ẹ̀kọ́ tí mo kọ́ ọ yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí mo ṣe fi lélẹ̀ fún un yín.
3 Dar voiesc să știți că Cristos este capul fiecărui bărbat, și capul femeii este bărbatul, și capul lui Cristos este Dumnezeu.
Ṣùgbọ́n mo fẹ́ kí ẹ̀yin mọ̀ pé, Kristi ni orí olúkúlùkù ọkùnrin, orí obìnrin sì ni ọkọ rẹ̀ àti orí Kristi sì ní Ọlọ́run.
4 Fiecare bărbat care se roagă sau profețește, având capul acoperit, își dezonorează capul.
Gbogbo ọkùnrin tó bá borí rẹ̀ nígbà tó bá ń gbàdúrà tàbí sọtẹ́lẹ̀ kò bọ̀wọ̀ fún orí rẹ̀.
5 Iar fiecare femeie care se roagă sau profețește, cu capul neacoperit, își dezonorează capul, fiindcă este unul și același lucru cu a fi rasă.
Bẹ́ẹ̀ náà ni obìnrin tí ó bá ń gbàdúrà tàbí tí ó bá ń sọtẹ́lẹ̀ láìbo orí rẹ̀, kò bu ọlá fún orí ara rẹ̀ nítorí ọ̀kan náà ni pẹ̀lú ẹni tí ó fárí.
6 Deoarece, dacă femeia nu este acoperită, să se și tundă de tot; dar dacă este rușine pentru o femeie să fie tunsă scurt sau rasă, să fie acoperită.
Ṣùgbọ́n tí obìnrin bá kọ̀ láti bo orí rẹ̀, ẹ jẹ́ kí ó gé irun rẹ̀. Bí ó bá sì jẹ́ nǹkan ìtìjú fún un láti gé irun orí rẹ́, nígbà náà kí ó fi gèlè bo orí rẹ̀.
7 Fiindcă un bărbat, într-adevăr, nu este dator să își acopere capul, întrucât el este chipul și gloria lui Dumnezeu, dar femeia este gloria bărbatului.
Ṣùgbọ́n ọkùnrin kò ní láti fi nǹkan bo orí rẹ́ nígbà tí ó bá ń sìn, nítorí àwòrán àti ògo Ọlọ́run ni òun í ṣe, ṣùgbọ́n ògo ọkùnrin ni obìnrin í ṣe.
8 Fiindcă nu bărbatul este din femeie, ci femeia din bărbat;
Ọkùnrin kò ti inú obìnrin wá, ṣùgbọ́n a yọ obìnrin jáde lára ọkùnrin,
9 Fiindcă bărbatul nu a fost creat pentru femeie, ci femeia pentru bărbat.
bẹ́ẹ̀ ni a kò dá ọkùnrin fún àǹfààní obìnrin ṣùgbọ́n a da obìnrin fún ọkùnrin.
10 Din această cauză femeia este datoare să aibă autoritate peste capul ei din cauza îngerilor.
Nítorí ìdí èyí àti nítorí àwọn angẹli, ni obìnrin ṣe gbọdọ̀ ní àmì àṣẹ rẹ̀ ní orí rẹ̀.
11 Totuși, în Domnul, nici bărbatul nu este fără femeie, nici femeia fără bărbat.
Ẹ rántí pé, nínú ètò Ọlọ́run obìnrin kò lè wà láìsí ọkùnrin, bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin kò lè wà láàsí obìnrin.
12 Fiindcă așa cum femeia este din bărbat, tot așa și bărbatul este prin femeie, iar toate din Dumnezeu.
Lóòtítọ́ láti ara ọkùnrin ni a ti yọ obìnrin jáde bẹ́ẹ̀ sì ni ọkùnrin tipasẹ̀ obìnrin wa. Ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ohun gbogbo ti wà.
13 Judecați în voi înșivă, este cuvenit ca o femeie să se roage lui Dumnezeu neacoperită?
Kí ni ẹ̀yìn fúnra yín rò lórí ọ̀rọ̀ yìí? Ǹjẹ́ ó tọ̀nà fún obìnrin láti máa gbàdúrà Ọlọ́run ní gbangba láìbo orí rẹ̀ bí?
14 Nu vă învață chiar natura însăși că, dacă un bărbat are păr lung, este o rușine pentru el?
Ǹjẹ́ ìwà abínibí yín kò ha kọ́ yín pé, bí ọkùnrin bá ní irun gígùn, àbùkù ni ó jẹ́ fún un.
15 Dar dacă o femeie are păr lung este o glorie pentru ea. Pentru că părul i-a fost dat pentru învelitoare.
Ṣùgbọ́n bí obìnrin bá ní irun gígùn, ògo ni ó jẹ́ fún un nítorí irun gígùn tí a fi fún un jẹ́ ìbòrí fún un.
16 Dar dacă cineva pare a fi certăreț, noi nu avem un astfel de obicei, nici bisericile lui Dumnezeu.
Ṣùgbọ́n tí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ jiyàn lórí ọ̀rọ̀ yìí, ohun kan tí mo lè sọ sí gbogbo rẹ̀ ni pé, a kò ní ìlànà tí ó yàtọ̀ sí èyí tí mo ti sọ, pé obìnrin gbọdọ̀ fi gèlè bo orí rẹ̀ nígbà tí ó bá ń sọtẹ́lẹ̀ tàbí tí ó bá ń gbàdúrà láàrín ìjọ Ọlọ́run.
17 Acum, în ceea ce vă spun, nu vă laud, pentru că vă adunați nu spre mai bine, ci spre mai rău.
Nínú àwọn àlàkalẹ̀ èmi ko ni yìn yín nítorí pé bí ẹ bá péjọ kì í ṣe fún rere bí ko ṣe fún búburú.
18 Fiindcă, întâi de toate, când vă adunați în biserică, aud că sunt dezbinări între voi; și în parte o cred.
Lọ́nà kìn-ín-ní, mo gbọ́ pe ìyapa máa ń wà láàrín yín ní ìgbà tí ẹ bá péjọpọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìjọ, mo sì gba èyí gbọ́ dé ààyè ibìkan.
19 Fiindcă trebuie să fie și erezii printre voi, ca să fie arătați printre voi cei aprobați.
Kò sí àní àní, ìyàtọ̀ gbọdọ̀ wa láàrín yín, kí àwọn tí ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ Ọlọ́run láàrín yín le farahàn kedere.
20 De aceea când vă adunați în același loc, nu este ca să mâncați cina Domnului.
Nígbà tí ẹ bá pàdé láti jẹun, kì í ṣe oúnjẹ alẹ́ Olúwa ni ẹ máa ń jẹ.
21 Fiindcă la mâncare, fiecare își ia cina adusă de el, în fața altuia; și unul este flămând, iar altul este beat.
Ṣùgbọ́n tí ara yín, nígbà tí ẹ bá fẹ́ jẹun, olúkúlùkù yín a máa sáré jẹ oúnjẹ rẹ̀ láìdúró de ẹnìkejì rẹ̀. Ebi a sì máa pa wọ́n, ẹlòmíràn wọ́n sì ń mu àmuyó àti àmupara.
22 Ce? Nu aveți case unde să mâncați și să beți? Sau disprețuiți biserica lui Dumnezeu și îi faceți de rușine pe cei ce nu au? Ce să vă spun? Să vă laud în aceasta? Nu vă laud.
Ṣé ẹ̀yin kò ní ilé tí ẹ ti lè jẹ, tí ẹ sì ti lè mu ni? Tàbí ẹ̀yin ń gan ìjọ Ọlọ́run ni? Ẹ̀yin sì ń dójútì àwọn aláìní? Kín ni kí èmi ó wí fún un yín? Èmi yóò ha yìn yín nítorí èyí? A! Rárá o. Èmi kọ́, n kò ní yìn yín.
23 Fiindcă am primit de la Domnul ce v-am și dat: Că Domnul Isus, în noaptea în care a fost trădat, a luat pâine;
Nítorí èyí tí èmi gbà lọ́wọ́ Olúwa ni mo ti fi fún un yin. Ní alẹ́ ọjọ́ tí Judasi fihàn, Olúwa Jesu Kristi mú àkàrà.
24 Și după ce a adus mulțumiri, a frânt-o și a spus: Luați, mâncați, acesta este trupul meu, care este frânt pentru voi; faceți aceasta în amintirea mea.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run fún àkàrà náà tan, ó bù ú, ó fi fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ gbà kí ẹ sì jẹ, èyí ní ara mi tí a fi fún un yín. Ẹ máa ṣe eléyìí ni rántí mi.”
25 Tot astfel a luat și paharul după ce a mâncat, spunând: Acest pahar este testamentul cel nou în sângele meu; faceți aceasta, ori de câte ori îl beți, în amintirea mea.
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ lẹ́yìn oúnjẹ alẹ́, ó sì mú ago wáìnì, ó sì wí pé, “Ago yìí ni májẹ̀mú tuntun nínú ẹ̀jẹ̀ mi, ẹ máa ṣe èyí, nígbàkígbà ti ẹ̀yìn bá ń mu ú, ní ìrántí mi.”
26 Fiindcă ori de câte ori mâncați din pâinea aceasta și beți din acest pahar, arătați moartea Domnului până vine el.
Nítorí nígbàkígbà tí ẹ bá ń jẹ lára àkàrà yìí, tí ẹ sì ǹ mu nínú ago yìí, ni ẹ tún sọ nípa ikú Olúwa. Ẹ máa ṣe eléyìí títí yóò fi padà dé.
27 De aceea oricine mănâncă pâinea aceasta și bea paharul Domnului în mod nedemn, va fi vinovat de trupul și sângele Domnului.
Nítorí náà tí ẹnikẹ́ni bá jẹ lára àkàrà yìí, tí ẹ sì ń mu nínú ago Olúwa yìí, ní ọ̀nà tí kò bójúmu, yóò jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ sí ara àti ẹ̀jẹ̀ Olúwa.
28 Dar omul să se cerceteze pe sine însuși și astfel să mănânce din pâine și să bea din pahar.
Ìdí nìyìí tí ó fi yẹ kí ènìyàn yẹ ara rẹ̀ wò dáradára kí ó tó jẹ lára àkàrà nà án àti kí ó tó mu nínú ago náà.
29 Fiindcă cel ce mănâncă și bea în mod nedemn, își mănâncă și bea propria lui condamnare, [dacă] nu deosebește trupul Domnului.
Nítorí tí ẹ bá jẹ lára àkàrà, tí ẹ sì mu nínú ago láìyẹ, tí ẹ kò ronú ara Kristi àti nǹkan tí ó túmọ̀ sí, ẹ̀ ń jẹ, ẹ sì ń mú ẹ̀bi ìdájọ́ Ọlọ́run wá sórí ara yín.
30 Din cauza aceasta între voi sunt mulți slabi și bolnavi și mulți dorm.
Ìdí nìyìí tí ọ̀pọ̀ yín fi di ẹni tí kò lágbára mọ́, tí ọ̀pọ̀ yín sì ń ṣàìsàn, àwọn mìíràn nínú yín tilẹ̀ ti sùn.
31 Căci dacă ne-am judeca pe noi înșine, nu am fi judecați.
Ṣùgbọ́n tí ẹ bá yẹ ara yín wò dáradára, kí ẹ tó jẹ ẹ́, a kì yóò dá yín lẹ́jọ́.
32 Dar când suntem judecați, suntem disciplinați de Domnul, ca să nu fim condamnați cu lumea.
Ṣùgbọ́n nígbà tí a bá dá wa lẹ́jọ́, láti ọwọ́ Olúwa ni a ti nà wá, kí a má ba à dá wa lẹ́bi pẹ̀lú ayé.
33 De aceea, frații mei, când vă adunați să mâncați, așteptați-vă unii pe alții.
Nítorí náà, ẹ̀yin arákùnrin mi ọ̀wọ́n, nígbàkígbà ti ẹ bá péjọ láti jẹ́ oúnjẹ alẹ́ Olúwa, tàbí fún ìsìn oúnjẹ alẹ́ Olúwa, ẹ dúró de ara yín.
34 Și dacă flămânzește cineva, să mănânce acasă; ca nu cumva să vă adunați pentru condamnare. Iar restul le voi pune în ordine când voi veni.
Bí ebi bá ń pa ẹnikẹ́ni nínú yin, kí ó jẹun láti ilé wá, kí ó má ba á mú ìjìyà wá sórí ara rẹ̀ nígbà tí ẹ bá péjọ. Tí mo bá dé, èmi yóò máa sọ̀rọ̀ lórí àwọn kókó-ọ̀rọ̀ ìyókù tí n kò ì ti fẹnu bà lẹ́sẹẹsẹ.