< 1 Cronici 17 >
1 Și s-a întâmplat, precum David ședea în casa lui, că David i-a spus profetului Natan: Iată, eu locuiesc într-o casă de cedri, dar chivotul legământului DOMNULUI rămâne sub covoare.
Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti fi ìdí kalẹ̀ sínú ààfin rẹ̀, ó sọ fún Natani wòlíì pé, “Èmi nìyí, tí ń gbé inú ààfin kedari nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wà lábẹ́ àgọ́.”
2 Atunci Natan i-a spus lui David: Fă tot ce este în inima ta, fiindcă Dumnezeu este cu tine.
Natani dá Dafidi lóhùn pé, “Ohunkóhun tí o bá ní lọ́kàn, ṣe é nítorí tí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.”
3 Și s-a întâmplat, că în aceeași noapte, cuvântul lui Dumnezeu a venit la Natan, spunând:
Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà, ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Natani wá, wí pé:
4 Du-te și spune-i lui David, servitorul meu: Astfel spune DOMNUL: Să nu îmi construiești o casă de locuit;
“Lọ sọ fún ìránṣẹ́ mi Dafidi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ ilé fún mi láti máa gbé.
5 Fiindcă nu am locuit într-o casă din ziua în care am scos pe Israel până în această zi; ci am mers din cort în cort și dintr-un tabernacol în altul.
Èmi kò tí ì gbé nínú ilé láti ọjọ́ tí mo ti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti títí di òní yìí. Èmi ń lọ láti àgọ́ dé àgọ́ àti láti ibùgbé dé ibùgbé.
6 Orișiunde am umblat cu tot Israelul, am vorbit eu un cuvânt vreunui judecător din Israel, căruia i-am poruncit să pască poporul meu, spunând: De ce nu mi-ați construit o casă de cedri?
Ni ibi gbogbo tí mo ti bá gbogbo Israẹli rìn dé, ǹjẹ́ mo wí nǹkan kan sí ọ̀kan nínú àwọn adarí Israẹli, tí èmí pàṣẹ fún láti máa jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn mi, wí pé, “Kí ní ṣe tí ẹ̀yin kò fi kọ́ ilé tí a fi igi kedari kọ́ fún mi?”’
7 Și acum, astfel să spui servitorului meu David: Astfel spune DOMNUL oștirilor: Te-am luat de la staulul oilor, din urma oilor, ca să fii conducător peste poporul meu Israel;
“Nígbà náà, sọ fún ìránṣẹ́ mi Dafidi pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: Èmi mú ọ kúrò ní pápá oko tútù wá, àní kúrò lẹ́yìn agbo àgùntàn, kí ìwọ kí ó lè máa ṣe olórí àwọn ènìyàn mi Israẹli.
8 Și am fost cu tine pretutindeni unde ai umblat și am stârpit pe toți dușmanii tăi dinaintea ta și ți-am făcut numele ca numele oamenilor mari care sunt pe pământ.
Èmi ti wà pẹ̀lú rẹ ní, ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmí sì ti gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ. Nísinsin yìí Èmi yóò mú kí orúkọ rẹ kí ó dàbí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá jùlọ tí ó wà ní ayé.
9 De asemenea voi rândui un loc pentru poporul meu Israel și îi voi sădi și vor locui în locul lor și nu vor mai fi mutați; nici copiii stricăciunii nu îi vor mai risipi, ca la început,
Èmi yóò sì pèsè ààyè kan fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, kí wọn kí ó lè ní ilé tiwọn, kí a má sì ṣe dààmú wọn mọ́. Àwọn ènìyàn búburú kì yóò ni wọ́n lára mọ́, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe ní ìbẹ̀rẹ̀.
10 De când am poruncit să fie judecători peste poporul meu Israel. Mai mult, voi supune toți dușmanii tăi. Și mai mult, îți spun că DOMNUL îți va construi o casă.
Bí wọ́n sì ti ṣe láti ìgbà tí mo ti yan àwọn aṣáájú lórí àwọn ènìyàn mi Israẹli. Èmi pẹ̀lú yóò ṣẹ́gun gbogbo àwọn ọ̀tá yín. “‘Èmi sọ fún yín pé Olúwa yóò kọ́ ilé kan fún yín,
11 Și se va întâmpla, când zilele tale se vor sfârși, și vei merge să fii cu părinții tăi, că voi ridica sămânța ta după tine, care va fi dintre fiii tăi și voi întemeia împărăția sa.
nígbà ti ọjọ́ rẹ bá kọjá, tí ìwọ bá lọ láti lọ bá àwọn baba à rẹ, Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ sókè láti rọ́pò rẹ, ọ̀kan lára àwọn ọmọ tìrẹ, Èmi yóò sì fìdí ìjọba rẹ̀ kalẹ̀.
12 El îmi va construi o casă și eu îi voi întemeia tronul pentru totdeauna.
Òun ni ẹni tí yóò kọ́ ilé fún mi, èmi yóò sí fi ìdí ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ títí láé.
13 Voi fi tatăl lui și el va fi fiul meu și nu îmi voi lua mila de la el, precum am luat-o de la cel care a fost înaintea ta;
Èmi yóò jẹ́ baba rẹ̀, Òun yóò sì jẹ́ ọmọ mi. Èmi kì yóò mú ìfẹ́ mi kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ láéláé gẹ́gẹ́ bí mo ṣe mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn aṣáájú rẹ̀.
14 Ci îl voi așeza în casa mea și în împărăția mea pentru totdeauna; și tronul său va fi întemeiat pentru totdeauna.
Èmi yóò gbé e ka orí ilé mi àti ìjọba mi títí láé; ìtẹ́ rẹ̀ ni a ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.’”
15 Conform cu toate aceste cuvinte și conform cu toată această viziune, astfel i-a vorbit Natan lui David.
Natani ròyìn fún Dafidi gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ ti ìfihàn yí.
16 Și împăratul David a venit și a șezut înaintea DOMNULUI și a spus: Cine sunt eu, DOAMNE Dumnezeule și ce este casa mea, că m-ai adus până aici?
Nígbà náà, ọba Dafidi wọlé lọ, ó sì jókòó níwájú Olúwa ó sì wí pé, “Ta ni èmi, Olúwa Ọlọ́run, àti ki ni ìdílé mi, tí ìwọ mú mi dé ibí?
17 Și totuși acesta a fost un lucru mic în ochii tăi, Dumnezeule; căci tu de asemenea ai vorbit de mult timp despre casa servitorului tău ce va veni; și m-ai privit conform cu starea unui om de rang înalt, DOAMNE Dumnezeule.
Pẹ̀lú bí ẹni pé èyí kò tó lójú rẹ, Ọlọ́run, ìwọ ti sọ̀rọ̀ nípa ọjọ́ iwájú ilé ìránṣẹ́ rẹ. Ìwọ ti wò mí bí ẹni pé èmi ni ẹni gbígbéga jù láàrín àwọn ọkùnrin Olúwa Ọlọ́run.
18 Ce să îți mai spună David pentru onoarea dată servitorului tău? căci tu cunoști pe servitorul tău.
“Kí ni ohun tí Dafidi tún lè sọ nítorí ọlá tí o bù fún ìránṣẹ́ rẹ? Nítorí tí ìwọ mọ ìránṣẹ́ rẹ,
19 DOAMNE, de dragul servitorului tău și conform cu inima ta, ai făcut toată această măreție, făcând cunoscute toate aceste lucruri mari.
Olúwa. Nítorí ti ìránṣẹ́ rẹ àti gẹ́gẹ́ bí àṣẹ rẹ, ìwọ ti ṣe ohun ńlá yìí àti láti fi gbogbo ìlérí ńlá yìí hàn.
20 DOAMNE, nu este nimeni ca tine, nici nu este vreun alt Dumnezeu în afară de tine, conform cu tot ce am auzit cu urechile noastre.
“Kò sí ẹnìkan bí rẹ Olúwa, kò sì sí Ọlọ́run kan àfi ìwọ, gẹ́gẹ́ bí à ti gbọ́ pẹ̀lú etí ara wa.
21 Și ce națiune pe pământ este ca poporul tău Israel, pe care Dumnezeu a mers să îl răscumpere pentru a fi propriul său popor, pentru a-ți face un nume de măreție și de înspăimântare, alungând națiuni dinaintea poporului tău, pe care l-ai răscumpărat din Egipt?
Pẹ̀lú ta ni ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ Israẹli—orílẹ̀-èdè kan ní ayé, tí Ọlọ́run jáde lọ láti ra àwọn ènìyàn kan padà fún ara rẹ̀, àti láti lè ṣe orúkọ fún ara à rẹ, àti láti ṣe ohun ńlá àti ọwọ́ ìyanu nípa lílé àwọn orílẹ̀-èdè kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀, ẹni tí ó gbàlà láti Ejibiti?
22 Pentru că pe poporul tău Israel l-ai făcut propriul tău popor pentru totdeauna; și tu, DOAMNE, tu ai devenit Dumnezeul lor.
Ìwọ ṣe àwọn ènìyàn rẹ Israẹli ní tìrẹ láéláé ìwọ Olúwa sì ti di Ọlọ́run wọn.
23 Și acum, DOAMNE, să fie întemeiat, pentru totdeauna, acest lucru pe care l-ai vorbit referitor la servitorul tău și referitor la casa lui și să faci precum ai spus.
“Nísinsin yìí, Olúwa, jẹ́ kí ìlérí tí ìwọ ti ṣe fún ìránṣẹ́ rẹ àti ilé rẹ̀ di fífi ìdí múlẹ̀ títí láé. Ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe ìlérí.
24 Să fie întemeiat ca numele tău să fie preamărit pentru totdeauna, spunând: DOMNUL oștirilor este Dumnezeul lui Israel, un Dumnezeu pentru Israel; și să fie întemeiată, înaintea ta casa lui David, servitorul tău.
Kí ó lè di fífi ìdí múlẹ̀ àti kí orúkọ rẹ di gbígbéga títí láé. Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin yóò wí pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni Ọlọ́run Israẹli.’ Ilé ìránṣẹ́ rẹ Dafidi sì ni a ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ níwájú rẹ.
25 Fiindcă tu, Dumnezeul meu, ai spus servitorului tău că îi vei construi o casă; de aceea servitorul tău a găsit în inima lui să se roage în fața ta.
“Ìwọ, Ọlọ́run mi, ti fihan ìránṣẹ́ rẹ pé, ìwọ yóò kọ́ ilé fún un. Bẹ́ẹ̀ ni ìránṣẹ́ rẹ ti ní ìgboyà láti gbàdúrà sí ọ.
26 Și acum, DOAMNE, tu ești Dumnezeu și ai promis această bunătate servitorului tău;
Olúwa, ìwọ ni Ọlọ́run. Ìwọ ti fi ìlérí dídára yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
27 Și acum, binevoiește să binecuvântezi casa servitorului tău, ca să fie înaintea ta pentru totdeauna; căci tu ești cel care binecuvântează, DOAMNE și va fi binecuvântată pentru totdeauna.
Nísinsin yìí ó ti tẹ́ ọ lọ́rùn láti bùkún ilé ìránṣẹ́ rẹ kí ó lè tẹ̀síwájú ní ojú rẹ; nítorí ìwọ, Olúwa, ti bùkún un, a ó sì bùkún un títí láéláé.”