< Salmos 139 >

1 Para o músico chefe. Um Salmo de David. Yahweh, você me procurou, e você me conhece.
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Olúwa, ìwọ tí wádìí mi, ìwọ sì ti mọ̀ mí.
2 Vocês conhecem meu sentar e meu levantar. Você percebe meus pensamentos de longe.
Ìwọ mọ̀ ìjókòó mi àti ìdìde mi, ìwọ mọ̀ èrò mi ní ọ̀nà jíjìn réré.
3 Você busca meu caminho e meu deitado, e conheço todos os meus caminhos.
Ìwọ yí ipa ọ̀nà mi ká àti ìdùbúlẹ̀ mi, gbogbo ọ̀nà mi sì di mí mọ̀ fún ọ.
4 Pois não há uma palavra em minha língua, mas eis que Yahweh, você sabe disso perfeitamente.
Nítorí tí kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ahọ́n mi, kíyèsi i, Olúwa, ìwọ mọ̀ ọ́n pátápátá.
5 Você me bainha atrás e antes. Você colocou sua mão em mim.
Ìwọ sé mi mọ́ lẹ́yìn àti níwájú, ìwọ sì fi ọwọ́ rẹ lé mi.
6 This o conhecimento está além de mim. É sublime. Não posso alcançá-lo.
Irú ìmọ̀ yìí jẹ ohun ìyanu fún mi jù; ó ga, èmi kò le mọ̀ ọ́n.
7 Para onde eu poderia ir de seu Espírito? Ou onde eu poderia fugir de sua presença?
Níbo ní èmi yóò gbé lọ kúrò ni ọwọ́ ẹ̀mí rẹ? Tàbí níbo ni èmi yóò sáré kúrò níwájú rẹ?
8 Se eu ascender ao céu, você está lá. Se eu fizer minha cama no Sheol, eis que você está lá! (Sheol h7585)
Bí èmi bá gòkè lọ sí ọ̀run, ìwọ wà níbẹ̀; bí èmí ba sì tẹ́ ẹní mi ní ipò òkú, kíyèsi i, ìwọ wà níbẹ̀ pẹ̀lú. (Sheol h7585)
9 If Tomo as asas do amanhecer, e estabelecer-se nas partes mais remotas do mar,
Èmi ìbá mú ìyẹ́ apá òwúrọ̀, kí èmi sì lọ jókòó ní ìhà òpin Òkun,
10 mesmo aí sua mão me conduzirá, e sua mão direita vai me segurar.
àní, níbẹ̀ náà ni ọwọ́ rẹ̀ yóò fà mí ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì dì mímú.
11 If Eu digo: “Certamente a escuridão me esmagará”. A luz ao meu redor será noite”.
Bí mo bá wí pé, “Ǹjẹ́ kí òkùnkùn kí ó bò mí mọ́lẹ̀; kí ìmọ́lẹ̀ kí ó di òru yí mi ká.”
12 mesmo a escuridão não se esconde de você, mas a noite brilha como o dia. A escuridão é como a luz para você.
Nítòótọ́ òkùnkùn kì í ṣú lọ́dọ̀ rẹ; ṣùgbọ́n òru tan ìmọ́lẹ̀ bí ọ̀sán; àti òkùnkùn àti ọ̀sán, méjèèjì bákan náà ní fún ọ.
13 Pois você formou o meu ser mais íntimo. Vocês me uniram no ventre de minha mãe.
Nítorí ìwọ ni ó dá ọkàn mi; ìwọ ni ó bò mí mọ́lẹ̀ nínú ìyá mi.
14 Agradeço a vocês, pois sou temerosa e maravilhosamente feita. Seus trabalhos são maravilhosos. Minha alma sabe disso muito bem.
Èmi yóò yìn ọ, nítorí tẹ̀rù tẹ̀rù àti tìyanu tìyanu ní a dá mi; ìyanu ní iṣẹ́ rẹ; èyí nì ni ọkàn mi sì mọ̀ dájúdájú.
15 Minha moldura não foi escondida de você, quando eu era feito em segredo, entrelaçados nas profundezas da terra.
Ẹ̀dá ara mi kò pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ, nígbà tí a dá mi ní ìkọ̀kọ̀. Tí a sì ń ṣiṣẹ́ ní àràbarà ní ìhà ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,
16 Seus olhos viram meu corpo. Em seu livro, todos eles foram escritos, os dias que foram ordenados para mim, quando ainda não havia nenhum deles.
ojú rẹ ti rí ohun ara mi nígbà tí a kò tí ì ṣe mí pé, àti nínú ìwé rẹ ni a ti kọ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sí, ní ọjọ́ tí a dá wọn, nígbà tí wọn kò tilẹ̀ tí ì sí.
17 Como são preciosos para mim seus pensamentos, Deus! Quão vasta é a soma deles!
Ọlọ́run, èrò inú rẹ tí ṣe iyebíye tó fún mi, iye wọn ti pọ̀ tó!
18 If Eu os contaria, eles são em maior número do que a areia. Quando acordo, ainda estou com você.
Èmi ìbá kà wọ́n, wọ́n ju iyanrìn lọ ní iye: nígbà tí mo bá jí, èmi yóò wà lọ́dọ̀ rẹ síbẹ̀.
19 Se apenas você, Deus, matasse os ímpios. Afastem-se de mim, seus homens sedentos de sangue!
Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa àwọn ènìyàn búburú nítòótọ́; nítorí náà kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin ọkùnrin ẹlẹ́jẹ̀.
20 Pois eles falam contra você de forma perversa. Seus inimigos levam seu nome em vão.
Ẹni tí ń fi inú búburú sọ̀rọ̀ sí ọ, àwọn ọ̀tá rẹ ń pe orúkọ rẹ ní asán!
21 Yahweh, eu não odeio aqueles que te odeiam? Não estou contristado com aqueles que se levantam contra você?
Olúwa, ǹjẹ́ èmi kò kórìíra àwọn tó kórìíra rẹ? Ǹjẹ́ inú mi kò a sì bàjẹ́ sí àwọn tí ó dìde sí ọ?
22 Eu os odeio com ódio perfeito. Eles se tornaram meus inimigos.
Èmi kórìíra wọn ní àkótán; èmi kà wọ́n sí ọ̀tá mi.
23 Procure em mim, Deus, e conheça meu coração. Experimente-me, e conheça meus pensamentos.
Ọlọ́run, wádìí mi, kí o sì mọ ọkàn mí; dán mi wò, kí o sì mọ ìrò inú mi.
24 Veja se há algum modo maligno em mim, e me conduzir da maneira eterna.
Kí ó sì wò ó bí ipa ọ̀nà búburú kan bá wà nínú mi kí ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé ọ̀nà àìnípẹ̀kun.

< Salmos 139 >