< Mateus 6 >

1 “Tenha cuidado para não fazer suas doações caridosas diante dos homens, para ser visto por eles, ou então você não terá nenhuma recompensa de seu Pai que está no céu”.
“Ẹ kíyèsára kí ẹ má ṣe iṣẹ́ rere yín níwájú àwọn ènìyàn nítorí kí a le rí yín, Bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin kò ni èrè kankan lọ́dọ̀ Baba yín ní ọ̀run.
2 Portanto, quando você fizer atos misericordiosos, não toque trombeta diante de si mesmo, como fazem os hipócritas nas sinagogas e nas ruas, para que eles possam obter glória dos homens. Certamente, eu lhe digo, eles receberam sua recompensa.
“Nítorí náà, nígbà ti ẹ́ bá ti ń fún aláìní, ẹ má ṣe fi fèrè kéde rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àwọn àgàbàgebè ti í ṣe ní Sinagọgu àti ní ìta gbangba; kí àwọn ènìyàn le yìn wọ́n. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, wọ́n ti gba èrè tí wọn ní kíkún.
3 Mas quando você fizer atos misericordiosos, não deixe sua mão esquerda saber o que sua mão direita faz,
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá ń fi fún aláìní, má ṣe jẹ́ kí ọwọ́ òsì rẹ mọ ohun tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ ń ṣe,
4 para que seus atos misericordiosos possam estar em segredo, então seu Pai, que vê em segredo, o recompensará abertamente.
kí ìfúnni rẹ má ṣe jẹ́ mí mọ̀. Nígbà náà ni Baba rẹ̀, tí ó sì mọ ohun ìkọ̀kọ̀ gbogbo, yóò san án fún ọ.
5 “Quando você rezar, não será como os hipócritas, pois eles adoram ficar de pé e rezar nas sinagogas e nos cantos das ruas, para que possam ser vistos pelos homens”. Certamente, eu lhes digo, eles receberam sua recompensa.
“Nígbà tí ìwọ bá ń gbàdúrà, má ṣe ṣe bí àwọn àgàbàgebè, nítorí wọn fẹ́ràn láti máa dúró gbàdúrà ní Sinagọgu àti ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà tí ènìyàn ti lè rí wọ́n. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, wọ́n ti gba èrè wọn ní kíkún.
6 Mas vós, quando rezardes, entrai em vosso quarto interior, e tendo fechado vossa porta, orai a vosso Pai que está em segredo; e vosso Pai que vê em segredo vos recompensará abertamente.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìwọ bá ń gbàdúrà, wọ inú iyàrá rẹ lọ, sé ìlẹ̀kùn mọ́ ara rẹ, gbàdúrà sí Baba rẹ ẹni tí ìwọ kò rí. Nígbà náà ni Baba rẹ tí ó mọ gbogbo ohun ìkọ̀kọ̀ rẹ, yóò san án fún ọ.
7 Ao rezar, não use repetições vãs como fazem os gentios; pois eles pensam que serão ouvidos por suas muitas palavras.
Ṣùgbọ́n nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbàdúrà, ẹ má ṣe àtúnwí asán bí àwọn aláìkọlà, nítorí wọn rò pé a ó tìtorí ọ̀pọ̀ ọ̀rọ̀ gbọ́ tiwọn.
8 Portanto, não seja como eles, pois seu Pai sabe o que você precisa antes de pedir-lhe.
Ẹ má ṣe dàbí i wọn, nítorí Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run mọ ohun tí ẹ ṣe aláìní, kí ẹ tilẹ̀ tó béèrè lọ́wọ́ rẹ̀.
9 Reze assim: “'Pai nosso que estais nos céus, que vosso nome seja santificado.
“Nítorí náà, báyìí ni kí ẹ ṣe máa gbàdúrà: “‘Baba wa tí ń bẹ ní ọ̀run, ọ̀wọ̀ fún orúkọ yín,
10 Deixe seu Reino vir. Que sua vontade seja feita na terra como no céu.
kí ìjọba yín dé, ìfẹ́ tiyín ni kí a ṣe ní ayé bí ti ọ̀run.
11 Dê-nos hoje nosso pão de cada dia.
Ẹ fún wa ní oúnjẹ òòjọ́ wa lónìí.
12 Perdoe-nos nossas dívidas, como também perdoamos a nossos devedores.
Ẹ dárí gbèsè wa jì wá, Bí àwa ti ń dáríji àwọn ajigbèsè wa,
13 Não nos deixe cair em tentação, mas livra-nos do maligno. Pois seu é o Reino, o poder e a glória para sempre. Amém”.
Ẹ má ṣe fà wá sínú ìdánwò, ṣùgbọ́n ẹ gbà wá lọ́wọ́ ibi. Nítorí ìjọba ni tiyín, àti agbára àti ògo, láéláé, Àmín.’
14 “Porque, se perdoardes aos homens suas ofensas, vosso Pai celestial também vos perdoará”.
Nítorí náà, bí ẹ̀yin bá dárí jí àwọn tó ṣẹ̀ yín, baba yín ọ̀run náà yóò dáríjì yín.
15 Mas se vós não perdoardes aos homens suas ofensas, vosso Pai celestial também não perdoará vossas ofensas.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá kọ̀ láti dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn jì wọ́n, baba yín kò ní í dárí ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.
16 “Além disso, quando você jejuar, não seja como os hipócritas, com caras tristes. Pois eles desfiguram seus rostos para que possam ser vistos pelos homens para jejuar. Certamente, eu lhes digo, eles receberam sua recompensa.
“Nígbà tí ẹ̀yin bá gbààwẹ̀, ẹ má ṣe fa ojú ro bí àwọn àgàbàgebè ṣe máa ń ṣe nítorí wọn máa ń fa ojú ro láti fihàn àwọn ènìyàn pé àwọn ń gbààwẹ̀. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín wọn ti gba èrè wọn ní kíkún.
17 Mas vós, quando jejuardes, ungireis a cabeça e lavareis o rosto,
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìwọ bá gbààwẹ̀, bu òróró sí orí rẹ, kí ó sì tún ojú rẹ ṣe dáradára.
18 para que não sejais vistos pelos homens para jejuar, mas por vosso Pai que está em segredo; e vosso Pai, que vê em segredo, vos recompensará.
Kí ó má ṣe hàn sí ènìyàn pé ìwọ ń gbààwẹ̀, bí kò ṣe sì í Baba rẹ, ẹni tí ìwọ kò rí, àti pé, Baba rẹ tí ó rí ohun tí o ṣe ni ìkọ̀kọ̀, yóò san án fún ọ.
19 “Não coloquem tesouros para vocês mesmos na terra, onde a traça e a ferrugem consomem, e onde os ladrões invadem e roubam;
“Má ṣe to àwọn ìṣúra jọ fún ara rẹ ní ayé yìí, níbi tí kòkòrò ti le jẹ ẹ́, tí ó sì ti le bàjẹ́ àti ibi tí àwọn olè lè fọ́ tí wọ́n yóò sì jí i lọ.
20 mas coloquem tesouros para vocês mesmos no céu, onde nem a traça nem a ferrugem consomem, e onde os ladrões não invadem e roubam;
Dípò bẹ́ẹ̀ to ìṣúra rẹ jọ sí ọ̀run, níbi ti kòkòrò àti ìpáàrà kò ti lè bà á jẹ́, àti ní ibi tí àwọn olè kò le fọ́ wọlé láti jí í lọ.
21 pois onde estiver seu tesouro, lá estará também seu coração.
Nítorí ibi tí ìṣúra yín bá wà níbẹ̀ náà ni ọkàn yín yóò wà pẹ̀lú.
22 “A lâmpada do corpo é o olho”. Se, portanto, seu olho estiver são, todo o seu corpo estará cheio de luz.
“Ojú ni fìtílà ara. Bí ojú rẹ bá mọ́lẹ̀ kedere, gbogbo ara rẹ yóò jẹ́ kìkì ìmọ́lẹ̀.
23 Mas se seu olho for mau, todo o seu corpo estará cheio de escuridão. Se, portanto, a luz que está em você é a escuridão, quão grande é a escuridão!
Ṣùgbọ́n bí ojú rẹ kò bá dára, gbogbo ara rẹ ni yóò kún fún òkùnkùn. Bí ìmọ́lẹ̀ ti ó wà nínú rẹ bá wá jẹ́ òkùnkùn, òkùnkùn náà yóò ti pọ̀ tó!
24 “Ninguém pode servir a dois senhores, pois ou ele vai odiar um e amar o outro, ou então ele vai se dedicar a um e desprezar o outro. Não se pode servir tanto a Deus como a Mammon.
“Kò sì í ẹnìkan tí ó lè sin ọ̀gá méjì. Òun yóò yà kórìíra ọ̀kan tí yóò fẹ́ràn èkejì, tàbí kí ó fi ara mọ́ ọ̀kan kí ó sì yan èkejì ní ìpọ̀sí. Ẹ̀yin kò lè sin Ọlọ́run àti owó papọ̀.
25 Portanto, eu lhe digo, não esteja ansioso por sua vida: o que vai comer, ou o que vai beber; nem ainda pelo seu corpo, o que vai vestir. A vida não é mais do que comida, e o corpo mais do que roupa?
“Nítorí náà, mo wí fún yín, ẹ má ṣe ṣe àníyàn nípa ẹ̀mí yín, ohun tí ẹ ó jẹ àti èyí tí ẹ ó mu; tàbí nípa ara yín, ohun tí ẹ ó wọ̀. Ṣé ẹ̀mí kò ha ṣe pàtàkì ju oúnjẹ lọ tàbí ara ni kò ha ṣe pàtàkì ju aṣọ lọ?
26 Veja as aves do céu, que elas não semeiam, nem colhem, nem se reúnem em celeiros. Vosso Pai celestial as alimenta. Você não tem muito mais valor do que elas?
Ẹ wo àwọn ẹyẹ ojú ọrun; wọn kì í gbìn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í kórè, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í kójọ sínú àká, síbẹ̀ Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run ń bọ́ wọn. Ẹ̀yin kò ha níye lórí jù wọ́n lọ bí?
27 “Qual de vocês, por estar ansioso, pode acrescentar um momento à sua vida?
Ta ni nínú gbogbo yín nípa àníyàn ṣíṣe ti ó lè fi ìṣẹ́jú kan kún ọjọ́ ayé rẹ̀?
28 Por que você está ansioso com as roupas? Considere os lírios do campo, como eles crescem. Eles não labutam, nem giram,
“Kí ni ìdí ti ẹ fi ń ṣe àníyàn ní ti aṣọ? Ẹ wo bí àwọn lílì tí ń bẹ ní igbó ti ń dàgbà. Wọn kì í ṣiṣẹ́ bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í rànwú.
29 ainda assim eu lhes digo que mesmo Salomão em toda sua glória não estava vestido como um desses.
Bẹ́ẹ̀ ni mo wí fún yín pé, a kò ṣe Solomoni lọ́ṣọ̀ọ́ nínú gbogbo ògo rẹ̀ tó ọ̀kan nínú àwọn nǹkan wọ̀nyí.
30 Mas se Deus assim veste a grama do campo, que hoje existe e amanhã é jogada no forno, não vestirá muito mais você, você de pouca fé?
Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run bá wọ koríko igbó ní aṣọ bẹ́ẹ̀, èyí tí ó wà níhìn-ín lónìí ti a sì gbà sínú iná lọ́la, kò ha ṣe ni ṣe yín lọ́ṣọ̀ọ́ tó bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, ẹ̀yin tí ìgbàgbọ́ yín kéré?
31 “Portanto, não estejais ansiosos, dizendo: 'O que comeremos?', 'O que beberemos?' ou, 'Com o que nos vestiremos?'
Nítorí náà, ẹ má ṣe ṣe àníyàn kí ẹ sì máa wí pé, ‘Kí ni àwa yóò jẹ?’ tàbí ‘Kí ni àwa yóò mu?’ tàbí ‘Irú aṣọ wo ni àwa yóò wọ̀?’
32 Pois os gentios buscam todas estas coisas; pois vosso Pai celestial sabe que precisais de todas estas coisas.
Nítorí àwọn kèfèrí ń fi ìwọra wá àwọn nǹkan wọ̀nyí bẹ́ẹ̀ ni Baba yín ní ọ̀run mọ̀ dájúdájú pé ẹ ní ìlò àwọn nǹkan wọ̀nyí.
33 Mas buscai primeiro o Reino de Deus e sua justiça; e todas estas coisas vos serão dadas também.
Ṣùgbọ́n, ẹ kọ́kọ́ wá ìjọba Ọlọ́run ná àti òdodo rẹ̀, yóò sì fi gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí kún un fún yín pẹ̀lú.
34 Portanto, não estejais ansiosos pelo amanhã, pois o amanhã será ansioso por si mesmo. O próprio mal de cada dia é suficiente.
Nítorí náà, ẹ má ṣe àníyàn ọ̀la, ọ̀la ni yóò ṣe àníyàn ara rẹ̀. Wàhálà ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ti tó fún un.

< Mateus 6 >