< Jeremias 37 >

1 Zedequias, filho de Josias, reinou como rei em vez de Conias, filho de Jeoiaquim, a quem Nabucodonosor, rei da Babilônia, fez rei na terra de Judá.
Sedekiah ọmọ Josiah sì jẹ ọba ní ipò Jehoiakini ọmọ Jehoiakimu ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli fi jẹ ọba ní ilẹ̀ Juda.
2 Mas nem ele, nem seus servos, nem o povo da terra escutaram as palavras de Javé, que ele falou pelo profeta Jeremias.
Ṣùgbọ́n àti òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kò fetísí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípa wòlíì Jeremiah.
3 O rei Zedequias enviou Jehucal, filho de Selemias, e Sofonias, filho de Maaséias, o sacerdote, ao profeta Jeremias, dizendo: “Reza agora a Javé, nosso Deus, por nós”.
Sedekiah ọba sì rán Jehukali ọmọ Ṣelemiah àti Sefaniah ọmọ Maaseiah sí Jeremiah wòlíì wí pé, “Jọ̀wọ́ gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
4 Agora Jeremias entrou e saiu entre o povo, pois eles não o haviam colocado na prisão.
Nígbà yìí Jeremiah sì ń wọlé, ó sì ń jáde láàrín àwọn ènìyàn nítorí wọ́n ti fi sínú túbú.
5 O exército do Faraó tinha saído do Egito; e quando os caldeus que estavam sitiando Jerusalém ouviram notícias deles, eles se retiraram de Jerusalém.
Àwọn ọmọ-ogun Farao ti jáde kúrò nílẹ̀ Ejibiti àti nígbà tí àwọn ará Babeli tó ń ṣàtìpó ní Jerusalẹmu gbọ́ ìròyìn nípa wọn, wọ́n kúrò ní Jerusalẹmu.
6 Então veio a palavra de Javé ao profeta Jeremias, dizendo:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì Ọlọ́run wá:
7 “Javé, o Deus de Israel, diz: “Dirás ao rei de Judá, que te enviou a mim para me inquirir: “Eis que o exército do Faraó, que saiu para ajudá-lo, voltará para o Egito em sua própria terra”.
“Èyí ni, ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ fún ọba àwọn Juda tó rán ọ láti wádìí nípa mi. ‘Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáde láti kún ọ lọ́wọ́ yóò padà sílẹ̀ wọn sí Ejibiti.
8 Os caldeus virão novamente, e lutarão contra esta cidade. Eles a tomarão e a queimarão com fogo”.
Nígbà náà ni àwọn ará Babeli yóò padà láti gbógun ti ìlú. Wọn yóò mú wọn nígbèkùn, wọn yóò sì fi iná jó ìlú náà kanlẹ̀.’
9 “Yahweh diz: 'Não se iludam, dizendo: “Os caldeus certamente irão partir de nós;” pois eles não irão partir.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹ má ṣe tan ara yín jẹ ní èrò wí pé, ‘Àwọn ará Babeli yóò fi wá sílẹ̀ pẹ̀lú ìdánilójú.’ Wọn kò ní ṣe bẹ́ẹ̀.
10 Pois embora vocês tivessem atingido todo o exército dos caldeus que lutam contra vocês, e só ficassem entre eles homens feridos, cada um deles se levantaria em sua tenda e queimaria esta cidade com fogo””.
Kódà tó bá ṣe pé wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọmọ-ogun Babeli tí ń gbóguntì yín àti àwọn tí ìjàǹbá ṣe, tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ibùdó wọn; wọn yóò jáde láti jó ìlú náà kanlẹ̀.”
11 Quando o exército dos caldeus se retirou de Jerusalém por medo do exército do Faraó,
Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ-ogun Babeli ti kúrò ní Jerusalẹmu nítorí àwọn ọmọ-ogun Farao.
12 então Jeremias saiu de Jerusalém para ir para a terra de Benjamim, para receber sua porção lá, no meio do povo.
Jeremiah múra láti fi ìlú náà sílẹ̀, láti lọ sí olú ìlú Benjamini láti gba ẹ̀tọ́ rẹ̀ nínú ohun ìní láàrín àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀.
13 Quando ele estava no portão de Benjamim, estava lá um capitão da guarda, cujo nome era Irijah, o filho de Selemias, filho de Hananias; e ele agarrou Jeremias, o profeta, dizendo: “Você está desertando para os caldeus”!
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé ẹnu ibodè Benjamini, olórí àwọn olùṣọ́ tí orúkọ rẹ ń jẹ́ Irijah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Hananiah mú un, ó wí pé, “Ìwọ ń fi ara mọ́ àwọn ará Babeli.”
14 Então Jeremias disse: “Isso é falso! Eu não estou desertando para os caldeus”. Mas ele não o ouviu; então Irijah apreendeu Jeremias e o trouxe até os príncipes.
Jeremiah sọ wí pé, “Èyí kì í ṣe òtítọ́! Èmi kò yapa sí àwọn ará Babeli.” Ṣùgbọ́n Irijah ko gbọ́ tirẹ̀, dípò èyí a mú Jeremiah, ó sì mú un lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ìjòyè.
15 Os príncipes ficaram zangados com Jeremias, e o golpearam, e o colocaram na prisão na casa de Jonathan, o escriba; pois eles tinham feito isso na prisão.
Nítorí náà ni àwọn ìjòyè ṣe bínú sí Jeremiah, wọ́n jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n tún fi sí túbú nílé Jonatani akọ̀wé nítorí wọ́n ti fi èyí ṣe ilé túbú.
16 Quando Jeremias entrou na casa do calabouço e nas celas, e Jeremias ficou lá muitos dias,
Wọ́n fi Jeremiah sínú túbú tí ó ṣókùnkùn biribiri; níbi tí ó wà fún ìgbà pípẹ́.
17 então Zedequias, o rei, enviou e mandou trazê-lo para fora. O rei perguntou-lhe secretamente em sua casa: “Há alguma palavra de Javé? Jeremiah disse: “Há”. Ele também disse: “Você será entregue na mão do rei da Babilônia”.
Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ sí i, tí ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n mú wá sí ààfin níbi tí ó ti bi í ní ìkọ̀kọ̀ pé, “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ kan wà láti ọ̀dọ̀ Olúwa?” Jeremiah fèsì pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, wọn ó fi ọ́ lé ọwọ́ ọba Babeli.”
18 Moreover Jeremias disse ao rei Zedequias: “Como pequei contra você, contra seus servos, ou contra este povo, que você me colocou na prisão?
Nígbà náà, Jeremiah sọ fún ọba Sedekiah pé, “Irú ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ yín, àwọn ìjòyè yín pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ẹ fi sọ mí sínú túbú?
19 Agora, onde estão teus profetas que te profetizaram, dizendo: 'O rei da Babilônia não virá contra ti, nem contra esta terra?
Níbo ni àwọn wòlíì yín tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín wí pé ọba Babeli kò ní gbóguntì yín wá?
20 Agora, por favor, ouve, meu senhor, o rei: por favor, que minha súplica seja apresentada diante de ti, para que não me faças voltar à casa de Jonathan, o escriba, para que eu não morra lá”.
Ṣùgbọ́n ní báyìí, olúwa mi ọba, èmí bẹ̀ ọ. Jẹ́ kí n mú ẹ̀dùn ọkàn mi tọ̀ ọ́ wá; má ṣe rán mi padà sí ilé Jonatani akọ̀wé, àfi kí n kú síbẹ̀.”
21 Então Zedequias, o rei, ordenou, e eles internaram Jeremias na corte da guarda. Davam-lhe diariamente um pão fora da rua dos padeiros, até que todo o pão da cidade tivesse desaparecido. Assim, Jeremias permaneceu na corte da guarda.
Ọba Sedekiah wá pàṣẹ pé kí wọ́n fi Jeremiah sínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́, àti kí wọn sì fún ní àkàrà ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan títí tí àkàrà tó wà ní ìlú yóò fi tán; bẹ́ẹ̀ ni Jeremiah wà nínú àgbàlá náà.

< Jeremias 37 >