< Isaías 16 >
1 Envie os cordeiros para o governante da terra de Selah para o deserto, para a montanha da filha de Sião.
Fi ọ̀dọ́-àgùntàn ṣe ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí aláṣẹ ilẹ̀ náà, láti Sela, kọjá ní aginjù, lọ sí orí òkè ọ̀dọ́mọbìnrin Sioni.
2 Pois será que como aves errantes, como um ninho disperso, também as filhas de Moab estarão nos vaus do Arnon.
Gẹ́gẹ́ bí alárìnkiri ẹyẹ tí a tì jáde kúrò nínú ìtẹ́, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn obìnrin Moabu ní àwọn ìwọdò Arnoni.
3 Dê conselhos! Executar a justiça! Faça sua sombra como a noite no meio do meio-dia! Escondam os marginais! Não traiam os fugitivos!
“Fún wa ní ìmọ̀ràn ṣe ìpinnu fún wa. Jẹ́ kí òjìji rẹ dàbí òru, ní ọ̀sán gangan. Fi àwọn ìsáǹsá pamọ́, má ṣe fi àwọn aṣàtìpó han.
4 Let meus párias moram com vocês! Quanto a Moab, seja um esconderijo para ele da face do destruidor. Pois o extorsionista é levado a nada. A destruição cessa. Os opressores são consumidos fora da terra.
Jẹ́ kí àwọn ìsáǹsá Moabu gbé pẹ̀lú rẹ, jẹ́ ààbò fún wọn kúrò lọ́wọ́ ìparun.” Aninilára yóò wá sí òpin, ìparun yóò dáwọ́ dúró; òfinràn yóò pòórá kúrò lórí ilẹ̀.
5 Um trono será estabelecido em amorosa bondade. Sentar-se-á nele na verdade, na tenda de Davi, julgando, buscando justiça, e rapidamente fazendo justiça.
Nínú ìfẹ́ a ó fi ìdí ìjọba kan múlẹ̀, ní òdodo ọkùnrin kan yóò jókòó lórí rẹ̀ ẹnìkan láti ilé Dafidi wá. Ẹni yóò ṣe ìdájọ́, yóò sì máa wá ìdájọ́, yóò sì máa yára wá ohun tí í ṣe òdodo.
6 Ouvimos falar do orgulho de Moab, que ele é muito orgulhoso; até mesmo de sua arrogância, seu orgulho e sua ira. Suas vanglórias não são nada.
Àwa ti gbọ́ nípa ìgbéraga Moabu, ìwọ̀sí ìgbéraga rẹ̀ àti fùlenge fùlenge, gààrù rẹ̀ àti àfojúdi rẹ̀, ṣùgbọ́n ìfọ́nnu rẹ̀ jẹ́ ìmúlẹ̀mófo.
7 Portanto, Moab lamentará por Moab. Todos irão lamentar. Lamentarão pelos bolos de uva passa de Kir Hareseth, totalmente abatidos.
Nítorí náà ni àwọn ará Moabu hu, wọ́n jùmọ̀ hu lórí Moabu. Sọkún kí o sì banújẹ́ fún àkàrà díndín Kiri-Hareseti.
8 Pois os campos de Heshbon definham com a videira de Sibmah. Os senhores das nações derrubaram seus ramos de escolha, que chegaram até Jazer, que perambulou pelo deserto. Seus rebentos foram espalhados no exterior. Eles passaram por cima do mar.
Gbogbo pápá oko Heṣboni ti gbẹ, bákan náà ni àjàrà Sibma rí. Àwọn aláṣẹ àwọn orílẹ̀-èdè wọ́n tẹ àwọn àyànfẹ́ àjàrà mọ́lẹ̀, èyí tí ó ti fà dé Jaseri ó sì ti tàn dé agbègbè aginjù. Àwọn èhíhù rẹ̀ fọ́n jáde, ó sì lọ títí ó fi dé Òkun.
9 Portanto, vou chorar com o pranto de Jazer pela videira de Sibmah. Eu vos regarei com minhas lágrimas, Heshbon e Elealeh: pois em suas frutas de verão e em sua colheita o grito de batalha caiu.
Nítorí náà mo sọkún, gẹ́gẹ́ bí Jaseri ṣe sọkún, fún àwọn àjàrà Sibma. Ìwọ Heṣboni, ìwọ Eleale, mo bomirin ọ́ pẹ̀lú omi ojú! Igbe ayọ̀ lórí àwọn èso pípọ́n rẹ àti lórí ìkórè èyí tí o ti mọ́wọ́ dúró.
10 A alegria é tirada, e a alegria do campo frutífero; e nos vinhedos não haverá cantoria, nem barulho de alegria. Ninguém vai pisar o vinho nas prensas. Eu fiz parar a gritaria.
Ayọ̀ àti ìdùnnú ni a ti mú kúrò nínú ọgbà-igi eléso rẹ; kò sí ẹnìkan tí ó kọrin tàbí kígbe nínú ọgbà àjàrà: ẹnikẹ́ni kò fún ọtí níbi ìfúntí, nítorí mo ti fi òpin sí gbogbo igbe.
11 Portanto, meu coração soa como uma harpa para Moab, e minhas partes íntimas para Kir Heres.
Ọkàn mi kérora fún Moabu gẹ́gẹ́ bí i dùùrù, àní tọkàntọkàn mi fún ìlú Kiri-Hareseti.
12 Acontecerá que quando Moab se apresentar, quando se cansar no alto, e vier ao seu santuário para rezar, que ele não prevalecerá.
Nígbà tí Moabu farahàn ní ibi gíga rẹ̀, ó ṣe ara rẹ̀ ní wàhálà lásán; nígbà tí ó lọ sí ojúbọ rẹ̀ láti gbàdúrà òfo ni ó jásí.
13 Esta é a palavra que Yahweh falou a respeito de Moab no passado.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa Moabu.
14 Mas agora Javé falou, dizendo: “Dentro de três anos, como um trabalhador vinculado por contrato os contaria, a glória de Moab será desprezada, com toda sua grande multidão; e o restante será muito pequeno e débil”.
Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí Olúwa wí pé, “Láàrín ọdún mẹ́ta gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ìdè ọgbà rẹ̀ ti máa kà á, ògo Moabu àti àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn rẹ̀ ni a ó kẹ́gàn, àwọn tí ó sálà nínú rẹ̀ yóò kéré níye, wọn yóò sì jẹ́ akúrẹtẹ̀.”