< Gênesis 36 >

1 Now esta é a história das gerações de Esaú (ou seja, Edom).
Wọ̀nyí ni ìran Esau, ẹni tí a ń pè ní Edomu.
2 Esau tirou suas esposas das filhas de Canaã: Adah a filha de Elon, o hitita; e Oholibamah a filha de Anah, a filha de Zibeon, o Hivita;
Nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani ni Esau ti fẹ́ àwọn ìyàwó rẹ̀: Adah ọmọbìnrin Eloni ará Hiti àti Oholibama, ọmọbìnrin Ana, ọmọ ọmọ Sibeoni ará Hifi.
3 e Basemath, a filha de Ismael, irmã de Nebaioth.
Ó sì tún fẹ́ Basemati ọmọ Iṣmaeli arábìnrin Nebaioti.
4 Adah aborreceu a Esau Eliphaz. Basemath deu à luz a Reuel.
Adah bí Elifasi fún Esau, Basemati sì bí Reueli,
5 Oholibamah deu à luz Jeush, Jalam, e Korah. Estes são os filhos de Esaú, que nasceram para ele na terra de Canaã.
Oholibama pẹ̀lú sì bí Jeuṣi, Jalamu, àti Kora. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Esau bí ní Kenaani.
6 Esaú levou suas esposas, seus filhos, suas filhas e todos os membros de sua família, com seu gado, todos os seus animais e todos os seus bens, que ele havia reunido na terra de Canaã, e foi para uma terra longe de seu irmão Jacó.
Esau sì mú àwọn aya rẹ̀, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ àti àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn àti gbogbo ohun ìní mìíràn tí ó ní, ni Kenaani, ó sì kó lọ sí ilẹ̀ mìíràn, jìnà sí ibi tí Jakọbu arákùnrin rẹ̀ wà.
7 Pois sua substância era grande demais para que eles habitassem juntos, e a terra de suas viagens não podia suportá-los por causa de seu gado.
Ohun ìní wọn pọ̀ ju èyí tí àwọn méjèèjì lè máa gbé ní ojú kan lọ. Ilẹ̀ tí wọ́n wà kò le gba àwọn méjèèjì nítorí àwọn ohun ọ̀sìn wọn.
8 Esaú vivia na região montanhosa de Seir. Esau é Edom.
Báyìí ni Esau (tí a tún mọ̀ sí Edomu) tẹ̀dó sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè tí Seiri.
9 Esta é a história das gerações de Esaú, o pai dos Edomitas, na região montanhosa de Seir:
Èyí ni ìran Esau baba àwọn ará Edomu ní àwọn orílẹ̀-èdè olókè Seiri.
10 estes são os nomes dos filhos de Esaú: Elifaz, o filho de Adah, a esposa de Esaú; e Reuel, o filho de Basemath, a esposa de Esaú.
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Esau: Elifasi ọmọ Adah aya Esau àti Reueli, ọmọ Basemati tí í ṣe aya Esau pẹ̀lú.
11 Os filhos de Elifaz eram Teman, Omar, Zepho e Gatam, e Kenaz.
Àwọn ọmọ Elifasi ni ìwọ̀nyí: Temani, Omari, Sefi, Gatamu, àti Kenasi.
12 Timna foi concubina de Elifaz, filho de Esaú; e ela se aborreceu com Elifaz Amalek. Estes são os descendentes de Adah, a esposa de Esaú.
Elifasi ọmọ Esau sì tún ní àlè tí a ń pè ní Timna pẹ̀lú, òun ló bí Amaleki fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọ Adah aya Esau.
13 Estes são os filhos de Reuel: Nahath, Zerah, Shammah, e Mizzah. Estes são os descendentes de Basemath, a esposa de Esaú.
Àwọn ọmọ Reueli: Nahati, Sera, Ṣamma àti Missa. Àwọn ni ọmọ ọmọ Basemati aya Esau.
14 Estes foram os filhos de Oholibamah, a filha de Anah, a filha de Zibeon, a esposa de Esau: ela se aborreceu com Esau Jeush, Jalam, e Korah.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Oholibama ọmọbìnrin Ana ọmọ ọmọ Sibeoni: tí ó bí fún Esau: Jeuṣi, Jalamu àti Kora.
15 Estes são os chefes dos filhos de Esaú: os filhos de Eliphaz, o primogênito de Esaú: chefe Teman, chefe Omar, chefe Zepho, chefe Kenaz,
Àwọn wọ̀nyí ni olórí nínú àwọn ọmọ Esau: àwọn ọmọ Elifasi, àkọ́bí Esau, Temani, Omari, Sefi, Kenasi,
16 chefe Korah, chefe Gatam, chefe Amalek. Estes são os chefes que vieram de Elifaz na terra de Edom. Estes são os filhos de Adah.
Kora, Gatamu àti Amaleki. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Elifasi ní Edomu wá, wọ́n jẹ́ ọmọ ọmọ Adah.
17 Estes são os filhos de Reuel, filho de Esaú: chefe Nahath, chefe Zerah, chefe Shammah, chefe Mizzah. Estes são os chefes que vieram de Reuel, na terra de Edom. Estes são os filhos de Basemath, a esposa de Esaú.
Wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Esau, ọmọ Rueli: Nahati olórí, Sera olórí, Ṣamma olórí, Missa olórí. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Reueli jáde ní Edomu. Ọmọ ọmọ Basemati aya Esau ni wọ́n jẹ́.
18 Estes são os filhos de Oholibamah, esposa de Esaú: chefe Jeush, chefe Jalam, chefe Korah. Estes são os chefes que vieram de Oholibamah, filha de Anah, a esposa de Esaú.
Àwọn ọmọ Oholibama aya Esau: Jeuṣi, Jalamu, àti Kora, àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Oholibama ọmọ Ana, ìyàwó Esau wá.
19 Estes são os filhos de Esaú (isto é, Edom), e estes são seus chefes.
Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Esau (ti o túmọ̀ sí Edomu). Àwọn wọ̀nyí ni olórí wọn.
20 Estes são os filhos de Seir, o Horita, os habitantes da terra: Lotan, Shobal, Zibeon, Anah,
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Seiri ará Hori tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
21 Dishon, Ezer, e Dishan. Estes são os chefes que vieram dos Horitas, os filhos de Seir, na terra de Edom.
Diṣoni, Eseri, àti Diṣani, àwọn wọ̀nyí olórí ènìyàn Hori, àwọn ọmọ Seiri ni ilẹ̀ Edomu.
22 Os filhos de Lotan eram Hori e Heman. A irmã de Lotan era Timna.
Àwọn ọmọ Lotani: Hori àti Homamu: Timna sì ni arábìnrin Lotani.
23 Estes são os filhos de Shobal: Alvan, Manahath, Ebal, Shepho, e Onam.
Àwọn ọmọ Ṣobali: Alifani, Manahati, Ebali, Ṣefo àti Onamu.
24 Estes são os filhos de Zibeon: Aiah e Anah. Esta é Anah, que encontrou as fontes termais no deserto, enquanto alimentava os burros de Zibeon, seu pai.
Àwọn ọmọ Sibeoni: Aiah àti Ana. Èyí ni Ana tí ó rí ìsun omi gbígbóná ní inú aginjù bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣebeoni baba rẹ̀.
25 Estes são os filhos de Anah: Dishon e Oholibamah, a filha de Anah.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ana: Diṣoni àti Oholibama ọmọbìnrin Ana.
26 Estes são os filhos de Dishon: Hemdan, Eshban, Ithran, e Cheran.
Àwọn ọmọ Diṣoni ni: Hemdani, Eṣbani, Itrani àti Kerani.
27 Estes são os filhos de Ezer: Bilhan, Zaavan, e Akan.
Àwọn ọmọ Eseri: Bilhani, Saafani àti Akani.
28 Estes são os filhos de Dishan: Uz e Aran.
Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi àti Arani.
29 Estes são os chefes que vieram dos Horites: chefe Lotan, chefe Shobal, chefe Zibeon, chefe Anah,
Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hori: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
30 chefe Dishon, chefe Ezer, e chefe Dishan. Estes são os chefes que vieram dos horitas, de acordo com seus chefes na terra de Seir.
Diṣoni Eseri, àti Diṣani. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Hori gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Seiri.
31 Estes são os reis que reinaram na terra de Edom, antes que qualquer rei reinasse sobre os filhos de Israel.
Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli:
32 Bela, o filho de Beor, reinou em Edom. O nome de sua cidade era Dinhabah.
Bela ọmọ Beori jẹ ní Edomu. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.
33 Bela morreu, e Jobab, o filho de Zerah de Bozrah, reinou em seu lugar.
Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
34 Jobab morreu, e Husham, da terra dos Temanitas, reinou em seu lugar.
Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
35 Husham morreu, e Hadad, o filho de Bedad, que atingiu Midian no campo de Moab, reinou em seu lugar. O nome de sua cidade era Avith.
Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti.
36 Hadad morreu, e Samlah de Masrekah reinava em seu lugar.
Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
37 Samlah morreu, e Shaul de Rehoboth, junto ao rio, reinou em seu lugar.
Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti, létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
38 Shaul morreu, e Baal Hanan, filho de Achbor, reinou em seu lugar.
Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
39 Baal Hanan, o filho de Achbor, morreu, e Hadar reinou em seu lugar. O nome de sua cidade era Pau. O nome de sua esposa era Mehetabel, a filha de Matred, a filha de Mezahab.
Nígbà tí Baali-Hanani ọmọ Akbori kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau, orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu.
40 Estes são os nomes dos chefes que vieram de Esaú, de acordo com suas famílias, após seus lugares, e por seus nomes: chefe Timna, chefe Alvah, chefe Jetheth,
Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn baálẹ̀ tí ó ti ọ̀dọ̀ Esau jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti.
41 chefe Oholibamah, chefe Elah, chefe Pinon,
Baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni,
42 chefe Kenaz, chefe Teman, chefe Mibzar,
baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari,
43 chefe Magdiel, e chefe Iram. Estes são os chefes de Edom, de acordo com suas habitações na terra de sua posse. Este é Esaú, o pai dos edomitas.
Magdieli, àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà. Èyí ni Esau baba àwọn ará Edomu.

< Gênesis 36 >