< Ester 2 >

1 Depois destas coisas, quando a ira do rei Assuero foi pacificada, ele se lembrou de Vashti, do que ela havia feito e do que foi decretado contra ela.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Ahaswerusi ọba sì dáwọ́ ìbínú un rẹ̀ dúró, ó rántí i Faṣti àti ohun tí ó ti ṣe àti àṣẹ tí ó pa nípa tirẹ̀.
2 Então os servos do rei que o serviram disseram: “Que se procurem jovens virgens bonitas para o rei”.
Nígbà náà ni ìránṣẹ́ ọba tí ó wà ní ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a wá ọmọbìnrin arẹwà tí kò ì ti mọ ọkùnrin rí fún ọba.
3 Que o rei nomeie oficiais em todas as províncias de seu reino, para que reúnam todas as belas jovens virgens à cidadela de Susa, à casa das mulheres, à custódia de Hegai, o eunuco do rei, guardião das mulheres. Que lhes sejam dados cosméticos;
Àti pé kí ọba kí ó yan àwọn aláṣẹ ní gbogbo agbègbè ilẹ̀ ọba láti kó gbogbo àwọn arẹwà ọmọbìnrin wọ̀nyí jọ sí ilé àwọn obìnrin ní ilé ìṣọ́ Susa. Kí a kó wọn fún ìtọ́jú Hegai, ìwẹ̀fà ọba, ẹni tí ó ṣe olùtọ́jú àwọn obìnrin; kí a ṣe ìtọ́jú u wọn dáradára.
4 e que a donzela que agradar ao rei seja rainha em vez de Vashti”. A coisa agradou ao rei, e ele o fez.
Nígbà náà kí ọmọbìnrin tí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn kí ó jẹ́ ayaba dípò Faṣti.” Ìmọ̀ràn yìí tẹ́ ọba lọ́rùn, ó sì tẹ̀lé e.
5 Havia um certo judeu na cidadela de Susa cujo nome era Mordecai, filho de Jair, filho de Shimei, filho de Kish, um benjamita,
Ó sì ṣe ní ìgbà náà ará a Júù kan wà ní ilé ìṣọ́ ti Susa, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mordekai ọmọ Jairi, ọmọ Ṣimei, ọmọ Kiṣi, ẹ̀yà Benjamini,
6 que havia sido levado de Jerusalém com os cativos que haviam sido levados com Jeconias, rei de Judá, que Nabucodonosor, rei da Babilônia, havia levado.
ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti gbé lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu, lára àwọn tí wọ́n kó ní ìgbèkùn pẹ̀lú ọba Jekoniah ọba Juda.
7 Ele criou Hadassah, ou seja, Ester, a filha de seu tio; pois ela não tinha pai nem mãe. A donzela era bela e justa; e quando seu pai e sua mãe morreram, Mordecai a tomou por sua própria filha.
Mordekai ní arákùnrin kan ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Hadassa, ẹni tí ó tọ́ dàgbà nítorí tí kò ní baba bẹ́ẹ̀ sì ni kò ní ìyá. Obìnrin yìí, ẹni tí a tún mọ̀ sí Esteri, ó dára ó sì lẹ́wà, Mordekai mú u gẹ́gẹ́ bí ọmọ rẹ̀ nígbà tí baba àti ìyá rẹ̀ ti kú.
8 Assim, quando o mandamento do rei e seu decreto foi ouvido, e quando muitas donzelas foram reunidas na cidadela de Susa, à custódia de Hegai, Ester foi levada à casa do rei, à custódia de Hegai, guardiã das mulheres.
Nígbà tí a ti kéde òfin àti àṣẹ ọba, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọbìnrin ni a kó wá sí ilé ti ìṣọ́ Susa, sí abẹ́ ìtọ́jú Hegai. A sì mú Esteri náà wá sí ààfin ọba pẹ̀lú, a fà á lé Hegai lọ́wọ́, ẹni tí ó jẹ́ alábojútó ilé àwọn obìnrin.
9 A donzela lhe agradou, e obteve dele a bondade. Ele rapidamente deu a ela cosméticos e suas porções de comida, e as sete donzelas escolhidas que deveriam recebê-la fora da casa do rei. Ele a transferiu e suas donzelas para o melhor lugar da casa das mulheres.
Ọmọbìnrin náà sì wù ú, ó sì rí ojúrere rẹ̀, lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ó pèsè àwọn ohun tí ó dára àti oúnjẹ pàtàkì fún un. Ó sì yan àwọn ìránṣẹ́bìnrin wúńdíá méje láti ààfin ọba òun àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin náà lọ sí ibi tí ó dára jù nínú ilé àwọn obìnrin.
10 Esther não havia dado a conhecer seu povo nem seus parentes, porque Mordecai lhe havia instruído para que não a desse a conhecer.
Esteri kò tí ì sọ nípa àwọn ènìyàn àti ìdílé e rẹ̀, nítorí Mordekai ti pàṣẹ fún un pé kí ó má ṣe sọ ọ́.
11 Mordecai caminhava todos os dias em frente ao tribunal da casa das mulheres, para saber como Esther estava se saindo e o que seria dela.
Ní ojoojúmọ́ ni Mordekai máa ń rìn ní iwájú ilé àwọn obìnrin láti wo bí Esteri ṣe wà ní àlàáfíà àti ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí i.
12 A vez de cada jovem mulher chegou para ir ao rei Assuero depois de sua purificação por doze meses (pois assim foram os dias de sua purificação, seis meses com óleo de mirra e seis meses com fragrâncias doces e com preparações para embelezar as mulheres).
Kí àkókò tó tó fún obìnrin kọ̀ọ̀kan láti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Ahaswerusi, ó ní láti lo ohun èlò tí ń mú ara lẹ́wà tí a yàn fún àwọn obìnrin fún oṣù méjìlá, yóò lo òróró òjìá fún oṣù mẹ́fà, yóò sì lo ohun èlò olóòórùn dídùn tùràrí àti ìpara fún oṣù mẹ́fà pẹ̀lú.
13 A jovem mulher veio então ao rei assim: o que ela desejava era dado a ela para ir com ela para fora da casa da mulher para a casa do rei.
Báyìí ni yóò ṣe lọ síwájú ọba: ohunkóhun tí ó bá béèrè ni wọ́n fi fún un láti inú ilé àwọn obìnrin lọ sí ààfin ọba.
14 À noite ela foi, e no dia seguinte voltou para a segunda casa feminina, à custódia de Shaashgaz, o eunuco do rei, que mantinha as concubinas. Ela não chegou mais ao rei, a menos que o rei se deleitasse com ela, e foi chamada pelo nome.
Ní alẹ́ ni yóò lọ síbẹ̀, tí ó bá sì di òwúrọ̀ yóò padà sí ilé kejì nínú ilé àwọn obìnrin ní abẹ́ ìtọ́jú Ṣaaṣigasi ìwẹ̀fà ọba ẹni tí ó máa ń ṣe ìtọ́jú àwọn àlè. Òun kò ní lọ sí ọ̀dọ̀ ọba mọ́ àyàfi tí inú ọba bá dùn sí i, tí ó sì ránṣẹ́ pé ó ní orúkọ obìnrin.
15 Agora quando chegou a vez de Ester, a filha de Abihail, o tio de Mordecai, que a tinha tomado por sua filha, ir ao rei, ela não precisava de nada além do que Hegai, o eunuco do rei, o guardião das mulheres, aconselhou. Ester obteve favor à vista de todos aqueles que a olhavam.
Nígbà tí ó kan Esteri (ọmọbìnrin tí Mordekai gbà ṣe ọmọ, ọmọbìnrin arákùnrin rẹ̀ tí ó ń jẹ́ Abihaili) láti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba, wọn kò béèrè fún ohunkóhun ju èyí tí Hegai, ìwẹ̀fà ọba ẹni tí ó jẹ́ olùtọ́jú ilé àwọn obìnrin sọ pé kí ó ṣe lọ. Esteri sì rí ojúrere lọ́dọ̀ gbogbo àwọn tí ó rí i.
16 Então Ester foi levada ao rei Assuero em sua casa real no décimo mês, que é o mês de Tebeth, no sétimo ano de seu reinado.
A mú Esteri lọ síwájú ọba Ahaswerusi ní ibùgbé ọba ní oṣù kẹwàá, tí ó jẹ́ oṣù Tebeti, ní ọdún keje ìjọba rẹ̀.
17 O rei amava Ester mais do que todas as mulheres, e ela obteve favor e bondade à vista dele mais do que todas as virgens; de modo que ele colocou a coroa real na cabeça dela, e a fez rainha em vez de Vashti.
Esteri sì wu ọba ju àwọn obìnrin tókù lọ, Ó sì rí ojúrere àti oore-ọ̀fẹ́ gbà ju ti àwọn wúńdíá tókù lọ. Nítorí náà ó fi adé ọba dé e ní orí ó sì fi ṣe ayaba dípò Faṣti.
18 Então o rei fez uma grande festa para todos os seus príncipes e seus servos, até mesmo a festa de Ester; e proclamou um feriado nas províncias, e deu presentes de acordo com a generosidade do rei.
Ọba sì ṣe àsè ńlá, àsè Esteri, fún gbogbo àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè e rẹ̀. Ó sì kéde ìsinmi jákèjádò ìgbèríko ó sì pín ẹ̀bùn fún wọn pẹ̀lú bí ọba ṣe lawọ́ tó.
19 Quando as virgens foram reunidas pela segunda vez, Mordecai estava sentado no portão do rei.
Nígbà tí àwọn wúńdíá tún péjọ ní ìgbà kejì, Mordekai jókòó sí ẹnu-ọ̀nà ọba.
20 Esther ainda não havia dado a conhecer seus parentes nem seu povo, como Mordecai lhe ordenara; pois Esther obedeceu a Mordecai, como ela fez quando foi criada por ele.
Ṣùgbọ́n Esteri pa àṣírí ìdílé e rẹ̀ àti ibi tí ó ti wá mọ́ gẹ́gẹ́ bí Mordekai ṣe sọ fún un pé kí ó ṣe, nítorí tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ tí Mordekai fún un gẹ́gẹ́ bí ó ṣe máa ń ṣe nígbà tí ó wà ní ọ̀dọ̀ Mordekai.
21 Naqueles dias, enquanto Mordecai estava sentado no portão do rei, dois dos eunucos do rei, Bigthan e Teresh, que eram porteiros, estavam zangados, e procuravam impor as mãos ao rei Ahasuerus.
Ní àsìkò tí Mordekai jókòó sí ẹnu-ọ̀nà ọba, Bigitana àti Tereṣi, àwọn ìjòyè ọba méjì tí wọ́n máa ń ṣọ́ ẹnu-ọ̀nà, wọ́n bínú, wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa ọba Ahaswerusi.
22 Esta coisa ficou conhecida de Mordecai, que informou Ester a rainha; e Ester informou o rei em nome de Mordecai.
Ṣùgbọ́n Mordekai sì mọ̀ nípa ọ̀tẹ̀ náà, ó sọ̀ fún ayaba Esteri, Esteri sì sọ fún ọba, wọ́n sì fi ọlá fún Mordekai.
23 Quando este assunto foi investigado, e se descobriu que assim era, ambos foram pendurados numa forca; e foi escrito no livro das crônicas na presença do rei.
Nígbà tí wọ́n sì wádìí ọ̀rọ̀ náà tí ó sì jásí òtítọ́, a sì so àwọn ìjòyè méjèèjì náà kọ́. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni a kọ sínú ìwé ìtàn ní iwájú ọba.

< Ester 2 >