< 2 Samuel 14 >

1 Agora Joab, filho de Zeruiah, percebeu que o coração do rei estava voltado para Absalom.
Joabu ọmọ Seruiah sì kíyèsi i, pé ọkàn ọba sì fà sí Absalomu.
2 Joabe enviou a Tekoa e trouxe uma mulher sábia de lá, e disse a ela: “Por favor, aja como uma mulher de luto, e vista roupas de luto, por favor, e não se unte com óleo; mas seja como uma mulher que chorou muito tempo pelos mortos”.
Joabu sì ránṣẹ́ sí Tekoa, ó sì mú ọlọ́gbọ́n obìnrin kan láti ibẹ̀ wá, ó sì wí fún un pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, ṣe bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀, kí o sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sára, kí o má sì ṣe fi òróró pa ara, kí o sì dàbí obìnrin ti ó ti ń ṣọ̀fọ̀ fún òkú lọ́jọ́ púpọ̀.
3 Vá até o rei e fale assim com ele”. Então Joab colocou as palavras em sua boca.
Kí o sì tọ ọba wá, kí o sọ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí.” Joabu sì fi ọ̀rọ̀ sí lẹ́nu.
4 Quando a mulher de Tekoa falou com o rei, ela caiu de cara para o chão, mostrou respeito e disse: “Socorro, ó rei!
Nígbà tí obìnrin àrá Tekoa sì ń fẹ́ sọ̀rọ̀ fún ọba, ó wólẹ̀, ó dojúbolẹ̀, o sí bu ọlá fún un, o sì wí pé, “Ọba, gbà mi.”
5 O rei disse-lhe: “O que te aflige?” Ela respondeu: “Realmente sou viúva e meu marido está morto”.
Ọba sì bi í léèrè pé, “Kín ni o ṣe ọ́?” Òun sì dáhùn wí pé, “Nítòótọ́ opó ni èmi ń ṣe, ọkọ mi sì kú.
6 Seu servo tinha dois filhos; e ambos lutaram juntos no campo, e não havia ninguém para separá-los, mas um golpeou o outro e o matou.
Ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ sì ti ní ọmọkùnrin méjì, àwọn méjèèjì sì jọ jà lóko, kò sì si ẹni tí yóò là wọ́n, èkínní sì lu èkejì, ó sì pa á.
7 Eis que toda a família se levantou contra seu servo, e eles dizem: 'Entreguem aquele que feriu seu irmão, para que possamos matá-lo pela vida de seu irmão que ele matou, e assim destruir também o herdeiro'. Assim, eles saciariam meu carvão que sobrou, e não deixariam para meu marido nem nome nem remanescente na superfície da terra”.
Sì wò ó, gbogbo ìdílé dìde sí ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀, wọ́n sì wí pé, ‘Fi ẹni tí ó pa arákùnrin rẹ fún wa, àwa ó sì pa á ní ipò ẹ̀mí arákùnrin rẹ̀ tí ó pa, àwa ó sì pa àrólé náà run pẹ̀lú.’ Wọn ó sì pa iná mi tí ó kù, wọn kì yóò sì fi orúkọ tàbí ẹni tí ó kú sílẹ̀ fún ọkọ mi ní ayé.”
8 O rei disse à mulher: “Vá para sua casa, e eu lhe darei uma ordem a seu respeito”.
Ọba sì wí fún obìnrin náà pé, “Lọ sí ilé rẹ̀, èmi ó sì kìlọ̀ nítorí rẹ.”
9 A mulher de Tecoa disse ao rei: “Meu senhor, ó rei, que a iniqüidade esteja sobre mim e sobre a casa de meu pai; e que o rei e seu trono sejam sem culpa”.
Obìnrin ará Tekoa náà sì wí fún ọba pé, “Olúwa mi, ọba, jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ náà wà lórí mi, àti lórí ìdílé baba mí; kí ọba àti ìtẹ́ rẹ̀ ó jẹ́ aláìlẹ́bi.”
10 O rei disse: “Quem lhe disser alguma coisa, traga-o até mim, e ele não o incomodará mais”.
Ọba sì wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀ sí ọ, mú ẹni náà tọ̀ mí wá, òun kì yóò sì tọ́ ọ mọ́.”
11 Então ela disse: “Por favor, que o rei se lembre de Yahweh seu Deus, que o vingador do sangue não destrua mais, para que eles não destruam meu filho”. Ele disse: “Como Javé vive, nem um cabelo de seu filho cairá na terra”.
Ó sì wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí ọba ó rántí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má ṣe ní ipá láti ṣe ìparun, kí wọn o má bá a pa ọmọ mi!” Òun sì wí pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè ọ̀kan nínú irun orí ọmọ rẹ ki yóò bọ sílẹ̀.”
12 Então a mulher disse: “Por favor, deixe seu servo falar uma palavra a meu senhor, o rei”. Ele disse: “Diga”.
Obìnrin náà sì wí pé, “Èmí bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ sọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi ọba.” Òun si wí pé, “Máa wí.”
13 A mulher disse: “Por que então você inventou tal coisa contra o povo de Deus? Pois ao falar esta palavra o rei é como alguém que é culpado, na medida em que o rei não traz para casa novamente o seu banido.
Obìnrin náà sì wí pé, “Nítorí kín ni ìwọ sì ṣe ro irú nǹkan yìí sí àwọn ènìyàn Ọlọ́run? Nítorí pé ní sísọ nǹkan yìí ọba ní ẹ̀bi, nítorí pé ọba kò mú ìsáǹsá rẹ̀ bọ̀ wá ilé.
14 Pois devemos morrer, e somos como água derramada no chão, que não pode ser recolhida de novo; nem Deus tira a vida, mas inventa meios, para que aquele que é banido não seja um proscrito dele.
Nítorí pé àwa ó sá à kú, a ó sì dàbí omi tí a tú sílẹ̀ tí a kò sì lè ṣàjọ mọ́; nítorí bí Ọlọ́run kò ti gbà ẹ̀mí rẹ̀, ó sì ti ṣe ọ̀nà kí a má bá a lé ìsáǹsá rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
15 Agora, portanto, vendo que vim para dizer esta palavra a meu senhor, o rei, é porque o povo me fez temer. Seu servo disse: “Agora vou falar com o rei; pode ser que o rei faça o pedido de seu servo”.
“Ǹjẹ́ nítorí náà ni èmi sì ṣe wá sọ nǹkan yìí fún olúwa mi ọba, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn ti dẹ́rùbà mí; ìránṣẹ́bìnrin rẹ sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ èmi ó sọ fún ọba; ó lè rí bẹ́ẹ̀ pé ọba yóò ṣe ìfẹ́ ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ fún un.
16 Pois o rei ouvirá, para livrar seu servo da mão do homem que me destruiria a mim e a meu filho juntos da herança de Deus.
Nítorí pé ọba ò gbọ́, láti gbà ìránṣẹ́bìnrin rẹ sílẹ̀ lọ́wọ́ ọkùnrin náà tí ó ń fẹ́ gé èmi àti ọmọ mi pẹ̀lú kúrò nínú ilẹ̀ ìní Ọlọ́run.’
17 Então seu servo disse: 'Por favor, deixe a palavra do rei, meu senhor, trazer descanso; pois, como anjo de Deus, assim é meu senhor, o rei, para discernir o bem e o mal. Que Yahweh, vosso Deus, esteja convosco”.
“Ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ ọba olúwa mi yóò sì jásí ìtùnú; nítorí bí angẹli Ọlọ́run bẹ́ẹ̀ ni olúwa mi ọba láti mọ rere àti búburú: Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.’”
18 Então o rei respondeu à mulher: “Por favor, não me esconda nada do que eu lhe peço”. A mulher disse: “Deixe meu senhor, o rei, falar agora”.
Ọba sì dáhùn, ó sì wí fún obìnrin náà pé, “Má ṣe fi nǹkan tí èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ pamọ́ fún mi, èmi bẹ̀ ọ́.” Obìnrin náà wí pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba máa wí?”
19 O rei disse: “A mão de Joab está com você em tudo isso”? A mulher respondeu: “Como vive vossa alma, meu senhor rei, ninguém pode virar-se para a direita ou para a esquerda de nada do que o rei meu senhor falou; pois vosso servo Joabe me exortou, e ele pôs todas estas palavras na boca de vosso servo.
Ọba sì wí pé, “Ọwọ́ Joabu kò ha wà pẹ̀lú rẹ nínú gbogbo èyí?” Obìnrin náà sì dáhùn ó sì wí pé, “Bí ẹ̀mí rẹ ti ń bẹ láààyè, olúwa mi ọba, kò sí ìyípadà sí ọwọ́ ọ̀tún, tàbí sí ọwọ́ òsì nínú gbogbo èyí tí olúwa mi ọba ti wí, nítorí pé Joabu ìránṣẹ́ rẹ, òun ni ó rán mi, òun ni ó sì fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí ìránṣẹ́bìnrin rẹ lẹ́nu.
20 Seu servo Joab fez isso para mudar a face da questão. Meu senhor é sábio, de acordo com a sabedoria de um anjo de Deus, para conhecer todas as coisas que estão na terra”.
Láti mú irú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí wá ni Joabu ìránṣẹ́ rẹ ṣe ṣe nǹkan yìí: olúwa mi sì gbọ́n, gẹ́gẹ́ bí ọgbọ́n angẹli Ọlọ́run, láti mọ gbogbo nǹkan tí ń bẹ̀ ní ayé.”
21 O rei disse a Joab: “Eis que agora eu concedi isto. Ide, portanto, e trazei o jovem Absalom de volta”.
Ọba sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, èmi ó ṣe nǹkan yìí, nítorí náà lọ, kí o sì mú ọmọdékùnrin náà Absalomu padà wá.”
22 Joab caiu de cara no chão, mostrou respeito e abençoou o rei. Joab disse: “Hoje seu servo sabe que encontrei favor a seus olhos, meu senhor, ó rei, na medida em que o rei cumpriu o pedido de seu servo”.
Joabu sì wólẹ̀ ó dojú rẹ̀ bolẹ̀, ó sì tẹríba fún un, ó sì súre fún ọba. Joabu sì wí pé, “Lónìí ni ìránṣẹ́ rẹ mọ̀ pé, èmi rí oore-ọ̀fẹ́ gbà lójú rẹ, olúwa mi, ọba, nítorí pé ọba ṣe ìfẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀.”
23 Então Joab se levantou e foi para Geshur, e trouxe Absalom para Jerusalém.
Joabu sì dìde, ó sì lọ sí Geṣuri, ó sì mú Absalomu wá sí Jerusalẹmu.
24 O rei disse: “Deixe-o voltar para sua própria casa, mas não deixe que ele veja meu rosto”. Então Absalão voltou para sua própria casa, e não viu o rosto do rei.
Ọba sì wí pé, “Jẹ́ kí ó yípadà lọ sí ilé rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ó rí ojú mi.” Absalomu sì yípadà sí ilé rẹ̀, kò sì rí ojú ọba.
25 Agora em todo Israel não havia ninguém que fosse tão elogiado como Absalão por sua beleza. Desde a planta de seu pé até a coroa de sua cabeça, não havia nenhum defeito nele.
Kó sì sí arẹwà kan ní gbogbo Israẹli tí à bá yìn bí Absalomu: láti àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀ títí dé àtàrí rẹ̀ kò sí àbùkù kan lára rẹ̀.
26 Quando ele cortou o cabelo de sua cabeça (agora era no final de cada ano que ele o cortava; porque era pesado para ele, portanto ele o cortava), ele pesava o cabelo de sua cabeça a duzentos siclos, depois do peso do rei.
Nígbà tí ó bá sì rẹ́ irun orí rẹ̀ (nítorí pé lọ́dọọdún ni òun máa ń rẹ́ ẹ. Nígbà tí ó bá wúwo fún un, òun a sì máa rẹ́ ẹ) òun sì wọn irun orí rẹ̀, ó sì jásí igba ṣékélì nínú òsùwọ̀n ọba.
27 Três filhos nasceram de Absalom, e uma filha, cujo nome era Tamar. Ela era uma mulher com um rosto lindo.
A sì bí ọmọkùnrin mẹ́ta fún Absalomu àti ọmọbìnrin kan ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tamari: òun sì jẹ́ obìnrin tí ó lẹ́wà lójú.
28 Absalom viveu dois anos inteiros em Jerusalém, e não viu o rosto do rei.
Absalomu sì gbé ni ọdún méjì ní Jerusalẹmu kò sì rí ojú ọba.
29 Então Absalão mandou chamar Joab, para mandá-lo ao rei, mas ele não quis vir até ele. Depois mandou novamente uma segunda vez, mas ele não viria.
Absalomu sì ránṣẹ́ sí Joabu, láti rán an sí ọba, ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ wá sọ́dọ̀ rẹ̀; ó sì ránṣẹ́ lẹ́ẹ̀kejì òun kò sì fẹ́ wá.
30 Therefore ele disse a seus servos: “Eis que o campo de Joab está perto do meu, e ele tem cevada lá”. Vá e pegue fogo a ela”. Então os servos de Absalom pegaram fogo ao campo.
Ó sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, oko Joabu gbé ti èmi, ó sì ní ọkà barle níbẹ̀; ẹ lọ kí ẹ sì ti iná bọ̀ ọ́.” Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì tiná bọ oko náà.
31 Então Joab levantou-se e veio a Absalom, em sua casa, e lhe disse: “Por que seus servos incendiaram meu campo”?
Joabu sì dìde, ó sì tọ Absalomu wá ní ilé, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ fi tiná bọ oko mi?”
32 Absalom respondeu a Joab: “Eis que eu te enviei, dizendo: 'Vem aqui, para que eu te envie ao rei, para dizer: “Por que vim de Geshur? Seria melhor para mim estar lá ainda”. Agora, portanto, deixai-me ver o rosto do rei; e se há iniqüidade em mim, deixai-o matar-me””.
Absalomu sì dá Joabu lóhùn pé, “Wò ó, èmi ránṣẹ́ sí ọ, wí pé, ‘Wá níhìn-ín yìí, èmi ó sì rán ọ lọ sọ́dọ̀ ọba, láti béèrè pé, “Kí ni èmi ti Geṣuri wá si? Ìbá sàn fún mí bí ó ṣe pé èmi wà lọ́hùn ún síbẹ̀!”’ Ǹjẹ́ nísinsin yìí jẹ́ kí èmi lọ síwájú ọba bí ó bá sì ṣe ẹ̀bi ń bẹ nínú mi, kí ó pa mí.”
33 Então Joab veio ao rei e lhe disse; e quando chamou por Absalom, ele veio ao rei e se inclinou com o rosto no chão diante do rei; e o rei beijou Absalom.
Joabu sì tọ ọba wá, ó sì rò fún un: ó sì ránṣẹ́ pe Absalomu, òun sì wá sọ́dọ̀ ọba, ó tẹríba fún un, ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀ níwájú ọba, ọba sì fi ẹnu ko Absalomu lẹ́nu.

< 2 Samuel 14 >