< 2 Reis 5 >

1 Agora Naaman, capitão do exército do rei da Síria, era um grande homem com seu mestre, e honrado, porque por ele Yahweh havia dado a vitória à Síria; ele também era um homem poderoso e de valor, mas era um leproso.
Naamani jẹ́ olórí ogun ọba Aramu. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ ni Olúwa ti fi ìṣẹ́gun fún Aramu. Òun jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
2 Os sírios tinham saído em bandos, e tinham levado cativa da terra de Israel uma menina, e ela esperou pela esposa de Naaman.
Nísinsin yìí ẹgbẹgbẹ́ láti Aramu ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Israẹli, ó sì sin ìyàwó Naamani.
3 Ela disse a sua amante: “Gostaria que meu senhor estivesse com o profeta que está em Samaria! Então ele iria curá-lo de sua lepra”.
Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samaria! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
4 Someone entrou e disse a seu senhor, dizendo: “A moça que é da terra de Israel disse isto”.
Naamani lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Israẹli ti sọ.
5 O rei da Síria disse: “Vá agora, e eu enviarei uma carta ao rei de Israel”. Ele partiu, e levou consigo dez talentos de prata, seis mil peças de ouro e dez trocas de roupa.
“Ní gbogbo ọ̀nà, lọ,” ọba Aramu dá a lóhùn pé, “Èmi yóò fi ìwé ránṣẹ́ sí ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni Naamani lọ, ó sì mú pẹ̀lú rẹ̀ tálẹ́ǹtì fàdákà mẹ́wàá, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìwọ̀n wúrà àti ìpààrọ̀ aṣọ mẹ́wàá.
6 Ele trouxe a carta ao rei de Israel, dizendo: “Agora que esta carta chegou até vós, eis que eu vos enviei Naaman, meu servo, para que o cureis de sua lepra”.
Ìwé tí ó mú lọ sọ́dọ̀ ọba Israẹli kà pé, “Pẹ̀lú ìwé yìí èmi ń rán ìránṣẹ́ mi Naamani sí ọ pé o lè wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
7 Quando o rei de Israel leu a carta, rasgou suas roupas e disse: “Sou eu Deus, para matar e tornar vivo, que este homem me envia para curar um homem de sua hanseníase? Mas, por favor, considere e veja como ele procura uma briga contra mim”.
Bí ọba Israẹli ti ka ìwé náà ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wí pé, “Èmi ha jẹ́ Ọlọ́run? Ǹjẹ́ èmi le pa kí n sì mú wá sí ààyè padà? Kí ni ó dé tí eléyìí rán ènìyàn sí mi láti wo ààrùn ẹ̀tẹ̀ rẹ sàn, kí ẹ wo bí ó ti ń wá ọ̀nà láti wá ìjà pẹ̀lú mi!”
8 Foi assim, quando Eliseu, o homem de Deus, ouviu que o rei de Israel havia rasgado suas roupas, que ele enviou ao rei, dizendo: “Por que você rasgou suas roupas? Que venha agora até mim, e ele saberá que há um profeta em Israel”.
Nígbà tí Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run gbọ́ pé ọba Israẹli ti ya aṣọ rẹ̀, ó sì rán iṣẹ́ yìí sí i pé, “Kí ni ó dé tí o fi fa aṣọ rẹ ya? Jẹ́ kí ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi. Òun yóò sì mọ̀ pé wòlíì wà ní Israẹli.”
9 Então Naaman veio com seus cavalos e com suas carruagens, e ficou à porta da casa de Elisha.
Bẹ́ẹ̀ ni Naamani sì lọ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀ àti kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Eliṣa.
10 Elisha enviou um mensageiro a ele, dizendo: “Vai e lava-te no Jordão sete vezes, e tua carne voltará a ti, e ficarás limpo”.
Eliṣa rán ìránṣẹ́ láti lọ sọ fún un pé, “Lọ, wẹ̀ ara rẹ ní ìgbà méje ní odò Jordani, ẹran-ara rẹ yóò sì tún padà bọ̀ sípò, ìwọ yóò sì mọ́.”
11 Mas Naaman ficou zangado, e foi embora e disse: “Eis que eu pensei: 'Ele certamente virá até mim, e se levantará, e invocará o nome de Javé seu Deus, e acenará sua mão sobre o lugar, e curará o leproso'.
Ṣùgbọ́n Naamani lọ pẹ̀lú ìbínú ó sì wí pé, “Mo lérò pé yóò sì dìde jáde wá nítòótọ́ sí mi, yóò sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run, fi ọwọ́ rẹ̀ lórí ibẹ̀ kí ó sì wo ẹ̀tẹ̀ mi sàn.
12 Aren't Abanah e Pharpar, os rios de Damasco, não são melhores do que todas as águas de Israel? Não poderia eu me lavar neles e ficar limpo?”. Então ele se virou e foi embora em fúria.
Abana àti Fapari, odò Damasku kò ha dára ju gbogbo omi Israẹli lọ? Ṣé èmi kò le wẹ̀ nínú wọn kí n sì mọ́?” Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà, ó sì lọ pẹ̀lú ìrunú.
13 Seus servos se aproximaram e falaram com ele, e disseram: “Meu pai, se o profeta lhe tivesse pedido para fazer algo grandioso, você não teria feito isso? Quanto mais então, quando ele lhe disse: 'Lave-se e fique limpo'”?
Ìránṣẹ́ Naamani lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi, tí wòlíì bá ti sọ fún ọ láti ṣe ohun ńlá kan, ṣé ìwọ kì bá ti ṣe, mélòó mélòó nígbà náà, nígbà tí ó sọ fún ọ pé, ‘Wẹ̀ kí o sì mọ́’!”
14 Então ele desceu e mergulhou sete vezes no Jordão, segundo o ditado do homem de Deus; e sua carne foi restaurada como a carne de uma criança pequena, e ele estava limpo.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ ó sì tẹ ara rẹ̀ bọ inú odò Jordani ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún un, ẹran-ara rẹ̀ sì tún padà sí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọkùnrin kékeré.
15 Ele voltou ao homem de Deus, ele e toda a sua companhia, e veio, e ficou diante dele; e disse: “Veja agora, eu sei que não há Deus em toda a terra, mas em Israel”. Agora, portanto, por favor, aceite um presente de seu servo”.
Nígbà náà Naamani àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ padà lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Ó sì dúró níwájú rẹ̀ ó sì wí pé, “Nísinsin yìí èmi mọ̀ pé kò sí Ọlọ́run ní gbogbo àgbáyé àyàfi ní Israẹli nìkan. Jọ̀wọ́ gba ẹ̀bùn láti ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”
16 Mas ele disse: “Como Yahweh vive, diante de quem eu estou, não receberei nenhum”. Ele o exortou a aceitar; mas ele se recusou.
Wòlíì náà dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ẹni tí mo ń sìn, èmi kò nígbà ohun kan,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Naamani rọ̀ ọ́ láti gbà á, ó kọ̀.
17 Naaman disse: “Se não, então, por favor, que a carga de terra de duas mulas seja dada a seu servo; pois seu servo não oferecerá de agora em diante nem holocausto nem sacrifício a outros deuses, mas a Iavé”.
Naamani wí pé, “Tí o kò bá nígbà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fi fún èmi ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹrù erùpẹ̀ tí ìbáaka méjì le rù, nítorí láti òní lọ ìránṣẹ́ rẹ kì yóò rú ẹbọ sísun àti rú ẹbọ sí ọ̀kan lára àwọn ọlọ́run mìíràn mọ́ bí kò ṣe sí Olúwa.
18 Neste ponto, que Iavé perdoe seu servo: quando meu senhor entra na casa de Rimmon para adorar lá, e ele se inclina sobre minha mão, e eu me inclino na casa de Rimmon. Quando eu me curvo na casa de Rimmon, que Yahweh perdoe a seu servo nesta coisa”.
Ṣùgbọ́n kí Olúwa kí ó dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún nǹkan yìí. Nígbà tí ọ̀gá mi wọ inú ilé Rimoni láti fi orí balẹ̀ tí ó sì fi ara ti ọwọ́ mi tí mo sì tẹ ara mi ba pẹ̀lú níbẹ̀. Nígbà tí èmi tẹ ara mi ba ní ilé Rimoni, kí Olúwa dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún èyí.”
19 Ele lhe disse: “Vá em paz”. Então, ele se afastou um pouco dele.
Eliṣa wí pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Lẹ́yìn ìgbà tí Naamani tí rin ìrìnàjò tí ó jìnnà,
20 Mas Gehazi, o servo de Elisha, o homem de Deus, disse: “Eis que meu mestre poupou este Naaman, o sírio, ao não receber em suas mãos o que ele trouxe”. Como Yahweh vive, vou correr atrás dele, e tirar algo dele”.
Gehasi, ìránṣẹ́ Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run, ó wí fún ara rẹ̀ pé, “Ọ̀gá mi jẹ́ ẹni tí ó rọ́nú lórí Naamani, ará Aramu, nípa pé kò gba ohunkóhun ní ọwọ́ rẹ̀ ohun tí ó mú wá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, èmi yóò sá tẹ̀lé e èmi yóò sì gba ohun kan ní ọwọ́ rẹ̀.”
21 Então Gehazi seguiu depois de Naaman. Quando Naaman viu um correndo atrás dele, desceu da carruagem para encontrá-lo e disse: “Está tudo bem?”.
Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi sáré tẹ̀lé Naamani. Nígbà tí Naamani rí i tí ó ń sáré tẹ̀lé e, ó sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ̀. “Ṣé gbogbo nǹkan wà dáradára?” ó béèrè.
22 Ele disse: “Tudo está bem”. Meu mestre me enviou, dizendo: “Eis que mesmo agora dois jovens dos filhos dos profetas vieram até mim da região montanhosa de Efraim. Por favor, dê-lhes um talento de prata e duas trocas de roupa”.
“Gbogbo nǹkan wà dáradára,” Gehasi dá a lóhùn. “Ọ̀gá mi rán mi láti sọ wí pé, ‘Àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin méjì láti ọ̀dọ̀ ọmọ wòlíì wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi láti orí òkè ìlú ti Efraimu. Jọ̀wọ́ fún wọn ní ẹ̀bùn fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ méjì.’”
23 Naaman disse: “Tenha o prazer de aceitar dois talentos”. Ele o incentivou, e amarrou dois talentos de prata em duas bolsas, com duas trocas de roupa, e os colocou em dois de seus criados; e eles os carregaram diante dele.
Naamani wí pé, “Ní gbogbo ọ̀nà, mú ẹ̀bùn méjì.” Ó sì rọ Gehasi láti gbà wọ́n, ó sì di ẹ̀bùn méjì náà ti fàdákà ní inú àpò méjì, pẹ̀lú ìpààrọ̀ aṣọ méjì, ó sì fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì, wọ́n sì kó wọn lọ sọ́dọ̀ Gehasi.
24 Quando ele chegou à colina, tirou-os da mão deles, e os guardou em casa. Então ele soltou os homens, e eles partiram.
Nígbà tí Gehasi sì dé ibi ilé ìṣọ́, ó gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn, ó sì tó wọ́n sínú ilé, ó sì jọ̀wọ́ àwọn ọkùnrin náà lọ́wọ́ lọ, wọ́n sì jáde lọ.
25 Mas ele entrou, e ficou diante de seu senhor. Elisha lhe disse: “De onde você veio, Gehazi?”. Ele disse: “Seu criado não foi a lugar nenhum”.
Nígbà náà ó sì wọlé wá ó sì dúró níwájú ọ̀gá rẹ̀ Eliṣa. “Níbo ni o ti wà Gehasi?” Eliṣa béèrè. “Ìránṣẹ́ rẹ kò lọ sí ibìkan kan.” Gehasi dá a lóhùn.
26 Ele lhe disse: “Meu coração não foi com você quando o homem se virou de sua carruagem para conhecê-lo? É hora de receber dinheiro, de receber roupas, olivais e vinhedos, e ovelhas e gado, e servos e servos e servas?
Ṣùgbọ́n Eliṣa wí fún un pé, “Ẹ̀mí mi kò ha wà pẹ̀lú rẹ nígbà tí ọkùnrin náà sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ? Ṣé àsìkò tí ó yẹ láti gba owó nìyìí, tàbí láti gba aṣọ, ọgbà olifi, ọgbà àjàrà, àgùntàn, màlúù tàbí ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin?
27 Therefore a lepra de Naaman se agarrará a você e à sua prole para sempre”. Saiu de sua presença um leproso, branco como a neve.
Ẹ̀tẹ̀ Naamani yóò lẹ̀ mọ́ ọ àti sí irú-ọmọ rẹ títí láé.” Nígbà náà Gehasi kúrò níwájú Eliṣa, ó sì di adẹ́tẹ̀, ó sì funfun gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.

< 2 Reis 5 >