< 1 Crônicas 11 >

1 Então todo Israel se reuniu a David em Hebron, dizendo: “Eis que nós somos seus ossos e sua carne.
Gbogbo àwọn Israẹli kó ara wọn jọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa í ṣe.
2 Em tempos passados, mesmo quando Saul era rei, foi você quem conduziu e trouxe para Israel. Javé teu Deus te disse: “Serás pastor do meu povo Israel, e serás príncipe sobre o meu povo Israel”.
Ní àtijọ́, kódà nígbà tí Saulu jẹ ọba, ìwọ ni ẹni tí ó darí Israẹli ní ojú ogun wọn. Olúwa Ọlọ́run rẹ sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò sì jẹ́ olùṣọ́ Israẹli ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún wọn.’”
3 Então todos os anciãos de Israel vieram ao rei em Hebron; e Davi fez um pacto com eles em Hebron antes de Yahweh. Eles ungiram Davi rei sobre Israel, de acordo com a palavra de Iavé por Samuel.
Nígbà tí gbogbo àwọn ìjòyè Israẹli tí wọ́n ti wá sọ́dọ̀ ọba Dafidi ni Hebroni. Ó sì ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú wọn ní Hebroni níwájú Olúwa, wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba lórí Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa láti ọwọ́ Samuẹli.
4 David e todo Israel foram a Jerusalém (também chamada Jebus); e os jebusitas, os habitantes da terra, estavam lá.
Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jáde lọ sí Jerusalẹmu (tí ṣe Jebusi). Àwọn Jebusi ara ilẹ̀ náà ń gbé níbẹ̀.
5 Os habitantes de Jebus disseram a Davi: “Você não entrará aqui”! No entanto, Davi tomou o bastião de Sião. A mesma é a cidade de Davi.
Àwọn ará ìlú Jebusi sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò sì gbọdọ̀ wọ ìhín yìí wá.” Ṣùgbọ́n Dafidi kó ìlú odi Sioni—èyí tí í ṣe ìlú Dafidi.
6 David tinha dito: “Quem atacar primeiro os jebuseus será chefe e capitão”. Joab, filho de Zeruia, subiu primeiro, e foi nomeado chefe.
Dafidi ti wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá tètè kọlu àwọn ará Jebusi ni yóò di olórí àti balógun.” Joabu ọmọ Seruiah sì kọ́kọ́ gòkè lọ, bẹ́ẹ̀ ni ó sì gba olórí.
7 Davi vivia na fortaleza; por isso lhe chamavam a cidade de Davi.
Dafidi sì ń gbé inú ìlú odi, nítorí náà ni wọ́n fi ń pè é ni ìlú Dafidi.
8 Ele construiu a cidade ao redor, desde Millo até mesmo ao redor; e Joabe reparou o resto da cidade.
Ó sì kọ́ àwọn ìlú náà yíkákiri; láti Millo yíkákiri; Joabu sì tún ìyókù àwọn ìlú náà ṣe.
9 David cresceu cada vez mais, pois Yahweh de Exércitos estava com ele.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ń ga, ó sì pọ̀ sí i, nítorí pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú rẹ̀.
10 Now estes são os chefes dos homens poderosos que David teve, que se mostraram fortes com ele em seu reino, junto com todo Israel, para fazê-lo rei, de acordo com a palavra de Iavé a respeito de Israel.
Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè alágbára ọkùnrin Dafidi, àwọn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fún ìjọba rẹ̀ ní àtìlẹ́yìn tó lágbára láti mú un tàn káàkiri gbogbo ilẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí.
11 Este é o número dos homens poderosos que David tinha: Jashobeam, o filho de um hachmonita, o chefe dos trinta; ele levantou sua lança contra trezentos e os matou de uma só vez.
Èyí sì ni iye àwọn akọni ọkùnrin Dafidi: Jaṣobeamu ọmọ Hakumoni, òun sì ni olórí nínú àwọn ìjòyè, ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa ní ogun ẹ̀ẹ̀kan.
12 Depois dele foi Eleazar, o filho de Dodo, o Ahohite, que era um dos três homens poderosos.
Lẹ́yìn rẹ̀ sì ni Eleasari ọmọ Dodo àwọn ará Ahohi, ọ̀kan lára àwọn mẹ́ta ọkùnrin alágbára.
13 Ele estava com David em Pasdammim, e ali os filisteus estavam reunidos para a batalha, onde havia um terreno cheio de cevada; e o povo fugiu de antes dos filisteus.
Ó sì wà pẹ̀lú Dafidi ní Pasi-Dammimu nígbà tí àwọn ará Filistini kó ara wọn jọ láti jagun, níbi tí ilẹ̀ kan wà tí ó kún fún ọkà barle. Àwọn ènìyàn sì sálọ kúrò níwájú Filistini.
14 Eles ficaram no meio da trama, defenderam-na e mataram os filisteus; e Yahweh os salvou com uma grande vitória.
Ṣùgbọ́n wọ́n mú ìdúró wọn ní àárín pápá náà. Wọ́n sì gbà a wọ́n sì gún àwọn ará Filistini mọ́lẹ̀, Olúwa sì mú ìgbàlà ńlá fún wọn.
15 Três dos trinta chefes desceram à rocha para David, na caverna de Adullam; e o exército dos filisteus estava acampado no vale de Rephaim.
Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀ tọ́ Dafidi wá lọ sí orí àpáta nínú ihò Adullamu, nígbà tí àwọn ẹgbẹ́ Filistini sì dúró ní àfonífojì ní orí òkè Refaimu.
16 David estava então na fortaleza, e a guarnição dos filisteus estava em Belém naquela época.
Ní àsìkò náà Dafidi sì ń bẹ nínú ìlú odi, ẹgbẹ́ ogun àwọn ará Filistini sì ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu.
17 David ansiava, e disse: “Oh, que alguém me desse água para beber do poço de Belém, que está junto ao portão”!
Dafidi sí pòǹgbẹ fún omi ó sì wí pé, “Háà, ẹnìkan yóò ha bu omi láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu fún un mu?”
18 Os três romperam o exército dos filisteus e tiraram água do poço de Belém que estava junto ao portão, tomaram-na e trouxeram-na a David; mas David não quis beber nada dela, mas derramou-a para Iavé,
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn mẹ́ta náà sì là láti ogun ará Filistini, ó sì fa omi jáde láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu ó sì gbé padà tọ Dafidi wá. Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti mu ú: dípò, ó sì tú jáde níwájú Olúwa.
19 e disse: “Meu Deus me livre, que eu faça isso! Devo beber o sangue destes homens que colocaram suas vidas em perigo?” Pois eles arriscaram suas vidas para trazê-lo. Portanto, ele não o beberia. Os três homens poderosos fizeram estas coisas.
“Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí èmi ó má ṣe ṣe èyí!” ó wí pé. “Ṣé kí èmi kí ó mú ẹ̀jẹ̀ ọkùnrin yí ẹni tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu?” Nítorí wọ́n fi ẹ̀mí wọn wéwu láti mú padà wá, Dafidi kò ní mu ú. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn akọni mẹ́ta ọkùnrin náà ṣe ohun ìyanu ńlá.
20 Abishai, o irmão de Joab, era o chefe dos três; pois ele levantou sua lança contra trezentos e os matou, e tinha um nome entre os três.
Abiṣai arákùnrin Joabu ìjòyè àwọn mẹ́ta. Ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún àwọn ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn mẹ́ta.
21 Dos três, ele era mais honrado que os dois, e foi nomeado seu capitão; no entanto, ele não foi incluído nos três.
Ó sì gba ìlọ́po ọlá lórí àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ó sì di olórí wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ka kún ara wọn.
22 Benaiah, filho de Jehoiada, filho de um valente homem de Kabzeel, que tinha feito grandes feitos, matou os dois filhos de Ariel de Moab. Ele também desceu e matou um leão no meio de um poço em um dia de neve.
Benaiah ọmọ Jehoiada ó sì jẹ́ akọni oníjà láti Kabṣeeli, ẹni tí ó ṣe iṣẹ́ agbára ńlá. Ó sì pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu, ó sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí inú ihò lákokò yìnyín dídì, ó sì pa kìnnìún kan
23 Ele matou um egípcio, um homem de grande estatura, de cinco côvados de altura. Na mão do egípcio estava uma lança como uma trave de tecelão; e desceu até ele com um bastão, arrancou a lança da mão do egípcio, e o matou com sua própria lança.
Ó sì pa ara Ejibiti ẹni tí ó ga ní ìwọ̀n ẹsẹ̀ méje àti ààbọ̀ ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti wọn ní ọ̀kọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìdábùú igi ahunṣọ àti ọ̀pá ní ọwọ́ rẹ̀, Benaiah sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú kùmọ̀. Ó sì gba ọ̀kọ̀ náà láti ọwọ́ ará Ejibiti ó sì pa á pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀.
24 Benaiah, o filho de Jehoiada, fez estas coisas e tinha um nome entre os três homens poderosos.
Nǹkan wọ̀nyí sì ní ìwà akin Benaiah ọmọ Jehoiada; ohun náà pẹ̀lú sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn akọni ọkùnrin mẹ́ta.
25 Eis que ele era mais honrado que os trinta, mas não chegou aos três; e David o colocou sobre sua guarda.
Ó sì ní ọlá púpọ̀ ju àwọn ọgbọ̀n lọ, ṣùgbọ́n a kò kà á láàrín àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta. Dafidi sì fi sí ìkáwọ́ àwọn ẹ̀ṣọ́.
26 Os homens poderosos dos exércitos também incluem Asahel o irmão de Joab, Elhanan o filho de Dodo de Belém,
Àwọn akọni ọkùnrin náà nìyí: Asaheli arákùnrin Joabu, Elhanani ọmọ Dodo láti Bẹtilẹhẹmu,
27 Shammoth o Harorita, Helez o Pelonita,
Ṣamotu ará Harori, Helesi ará Peloni
28 Ira o filho de Ikkesh o Tecoíta, Abiezer o Anatotita,
Ira ọmọ Ikẹsi láti Tekoa, Abieseri láti Anatoti,
29 Sibbecai o Hushathite, Ilai o Ahohite,
Sibekai ará Huṣati, láti ará Ahohi
30 Maharai o Netofatita, Heled o filho de Baanah o Netofatita,
Maharai ará Netofa, Heledi ọmọ Baanah ará Netofa,
31 Ithai o filho de Ribai de Gibeah dos filhos de Benjamim, Benaiah o Piratonita,
Itai ọmọ Ribai láti Gibeah ní Benjamini, Benaiah ará Piratoni,
32 Hurai dos riachos de Gaash, Abiel o Arbatita,
Hurai láti àfonífojì Gaaṣi, Abieli ará Arbati,
33 Azmaveth o Baharumita, Eliahba o Shaalbonita,
Asmafeti ará Bahurimu Eliaba ará Ṣaalboni.
34 os filhos de Hashem o Gizonita, Jonathan o filho de Shagee o Hararita,
Àwọn ọmọ Haṣemu ará Gisoni Jonatani ọmọ Ṣage ará Harari.
35 Ahiam o filho de Sacar o Hararita, Eliphal o filho de Ur,
Ahiamu ọmọ Sakari ará Harari, Elifali ọmọ Uri
36 Hepher o Mecheratita, Ahijah o Pelonita,
Heferi ará Mekerati, Ahijah ará Peloni,
37 Hezro o Carmelita, Naarai o filho de Ezbai,
Hesro ará Karmeli Naarai ọmọ Esbai,
38 Joel o irmão de Nathan, Mibhar o filho de Hagri,
Joẹli arákùnrin Natani Mibari ọmọ Hagari,
39 Zelek o amonita, Naharai o berotítico (o portador da armadura de Joab o filho de Zeruiah),
Seleki ará Ammoni, Naharai ará Beroti ẹni tí ó jẹ́ ẹni tí n ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah.
40 Ira o itrita, Gareb o itrita,
Ira ará Itri, Garebu ará Itri,
41 Uriah o hitita, Zabad o filho de Ahlai,
Uriah ará Hiti Sabadi ọmọ Ahlai.
42 Adina o filho de Shiza o reubenita (um chefe dos reubenitas), e trinta com ele,
Adina ọmọ Ṣisa ará Reubeni, ẹni tí ó jẹ́ ìjòyè ará Reubeni, àti pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀.
43 Hanan o filho de Maacah, Joshaphat o Mithnite,
Hanani ọmọ Maaka. Jehoṣafati ará Mitini.
44 Uzzia o Ashterathite, Shama e Jeiel os filhos de Hotham o Aroerite,
Ussia ará Asiterati, Ṣama àti Jeieli àwọn ọmọ Hotami ará Aroeri,
45 Jediael o filho de Shimri, e Joha seu irmão, o Tizite,
Jediaeli ọmọ Ṣimri, àti arákùnrin Joha ará Tisi
46 Eliel o Mahavite, e Jeribai, e Joshaviah, os filhos de Elnaam, e Ithmah o Moabite,
Elieli ará Mahafi Jeribai àti Joṣafia àwọn ọmọ Elnaamu, Itimah ará Moabu,
47 Eliel, Obed, e Jaasiel o Mezobaite.
Elieli, Obedi àti Jaasieli ará Mesoba.

< 1 Crônicas 11 >