< Romanos 13 >

1 Todos devem obedecer às autoridades, pois ninguém tem o poder para governar, a não ser que Deus assim permita. Essas autoridades foram colocadas em suas posições por Deus.
Kí olúkúlùkù ọkàn kí ó foríbalẹ̀ fún àwọn aláṣẹ tí ó wà ní ipò gíga. Nítorí kò sí àṣẹ kan, bí kò ṣe láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá; àwọn aláṣẹ tí ó sì wà, láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni a ti lànà rẹ̀ wá.
2 Quem resistir às autoridades se opõe a quem Deus escolheu para estar lá. E quem age desse modo será condenado.
Nítorí ẹni tí ó bá tàpá sí àṣẹ, ó tàpá sí ìlànà Ọlọ́run; àwọn ẹni tí ó ba sì ń tàpá, yóò gba ẹ̀bi fún ara wọn.
3 Pois, apenas os que fazem o mal, e não os que fazem o bem, devem temer os governantes. Se vocês não querem viver com medo das autoridades, então, façam o que é certo e, assim, terão a sua aprovação.
Nítorí àwọn ìjòyè kò wá láti dẹ́rùbà àwọn tí ń ṣe rere, bí kò ṣe àwọn tó ń ṣe búburú. Ǹjẹ́ ìwọ ha fẹ́ di òmìnira kúrò nínú ẹ̀rù ẹni tó wà ní ipò àṣẹ. Nítorí náà ṣe èyí tó ó dára, ìwọ yóò sì gba ìyìn láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
4 Os que estão no poder são servos de Deus, que foram colocados lá para o bem de vocês. Se vocês fizerem o que é errado, então, devem temer, pois as autoridades terão motivo e poder para punir. Eles são servos de Deus, que castigam os culpados.
Nítorí ìránṣẹ́ Ọlọ́run ni i ṣe fún ọ́ sí rere. Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá ń ṣé búburú, máa bẹ̀rù, nítorí kò gbé idà náà lásán. Nítorí ìránṣẹ́ Ọlọ́run ní í ṣe, olùgbẹ̀san láti ṣiṣẹ́ ìbínú lára ẹni tí ń ṣe búburú.
5 Então, é importante que vocês façam como lhes foi dito. Devem fazê-lo não apenas por causa da ameaça de punição, mas para seguir o que a sua consciência lhes manda fazer.
Nítorí náà, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ má tẹríba fún àwọn aláṣẹ, kì í ṣe nítorí ti ìbínú nìkan, ṣùgbọ́n nítorí ẹ̀rí ọkàn pẹ̀lú.
6 E é por isso que vocês devem pagar os impostos, pois as autoridades são servos de Deus que cuidam desse serviço.
Nítorí ìdí èyí, ẹ san owó òde pẹ̀lú, nítorí ìránṣẹ́ Ọlọ́run ni wọ́n, èyí náà ni wọ́n ń bojútó nígbà gbogbo.
7 Paguem tudo o que devem: impostos para as autoridades fiscais, tributos para os cobradores de impostos. Respeitem aqueles que devem ser respeitados. Honrem aqueles que devem ser honrados.
Ẹ san ohun tí ó tọ́ fún ẹni gbogbo: owó òde fún ẹni tí owó òde í ṣe tirẹ̀: owó bodè fún ẹni tí owó bodè í ṣe tirẹ̀: ẹ̀rù fún ẹni tí ẹ̀rù í ṣe tirẹ̀; ọlá fún ẹni tí ọlá í ṣe tirẹ̀.
8 Não devam nada a ninguém. A única dívida que devem ter é a de amar uns aos outros, pois quem ama o seu próximo cumpre a lei.
Ẹ má ṣe jẹ ẹnikẹ́ni ní gbèsè ohun kan, bí kò ṣe pé kí a fẹ́ ọmọ ẹnìkejì ẹni, nítorí ẹni tí ó bá fẹ́ ọmọnìkejì rẹ̀, ó kó òfin já.
9 “Não cometa adultério, não mate, não roube, não deseje com inveja as coisas dos outros.” Esses e outros mandamentos se resumem na afirmação: “Ame ao seu próximo como a si mesmo.”
Àwọn òfin, “Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà,” “Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn,” “Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè,” “Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké,” “Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò,” bí òfin mìíràn bá sì wà, ni a papọ̀ ṣọ̀kan nínú òfin kan yìí: “Fẹ́ ẹnìkéjì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ̀.”
10 O amor não faz o mal para ninguém; então, o amor cumpre a lei.
Ìfẹ́ kì í ṣe ohun búburú sí ọmọnìkejì rẹ̀, nítorí náà ìfẹ́ ni àkójá òfin.
11 Vocês devem fazer essas coisas porque compreendem o tempo em que vivemos. Essa é a hora para que vocês acordem do seu sono. Pois a nossa salvação está mais próxima agora do que quando nós colocamos a nossa fé em Deus pela primeira vez.
Àti èyí, bí ẹ̀yin ti mọ àkókò pé, ó ti tó wákàtí nísinsin yìí fún yín láti jí lójú orun, nítorí nísinsin yìí ni ìgbàlà wa súnmọ́ etílé ju ìgbà tí àwa ti gbàgbọ́ lọ.
12 A noite já está quase acabando, e o dia logo chegará! Então, vamos nos livrar das nossas ações das trevas e vamos colocar a armadura da luz.
Òru bù kọjá tan, ilẹ̀ sì fẹ́rẹ mọ́: nítorí náà ẹ jẹ́ kí a bọ́ ara iṣẹ́ òkùnkùn sílẹ̀, kí a sì gbé ìhámọ́ra ìmọ́lẹ̀ wọ̀.
13 Precisamos nos comportar de forma decente, mostrando que somos pessoas que vivem na luz. Não devemos gastar nosso tempo participando de farras e de bebedeiras. Deixemos de lado a imoralidade e a indecência. Parem as brigas e não sejam invejosos.
Jẹ́ kí a má rin ìrìn títọ́, bí ní ọ̀sán; kì í ṣe ní ìréde òru àti ní ìmutípara, kì í ṣe ni ìwà èérí àti wọ̀bìà, kì í ṣe ní ìjà àti ìlara.
14 Em vez disso, assumam o Senhor Jesus Cristo e deixem de seguir os desejos pecaminosos.
Ṣùgbọ́n ẹ gbé Jesu Kristi Olúwa wọ̀, kí ẹ má sì pèsè fún ara, láti máa mú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ ṣẹ.

< Romanos 13 >