< Filipenses 1 >

1 Esta carta é escrita por Paulo e Timóteo, servos de Cristo Jesus, para todo o povo de Deus unido a Cristo Jesus que vive em Filipos e para os líderes da igreja e seus auxiliares.
Paulu àti Timotiu, àwọn ìránṣẹ́ Jesu Kristi, Sí gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ nínú Kristi Jesu tí ó wà ní Filipi, pẹ̀lú àwọn alábojútó àti àwọn díákónì:
2 Que a graça e a paz de Deus, nosso Pai, e do Senhor Jesus Cristo estejam com vocês!
Oore-ọ̀fẹ́ sí yín, àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa, àti Olúwa wa Jesu Kristi.
3 Quando penso em vocês, eu agradeço ao meu Deus
Mo ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run mi ní gbogbo ìgbà tí mo bá rántí yín.
4 e sempre fico contente ao lembrar de todos vocês em minhas orações,
Nínú gbogbo àdúrà mi fún un yín, èmi ń fi ayọ̀ gbàdúrà,
5 pois, desde o início, vocês foram meus parceiros no anúncio do evangelho.
nítorí ìdàpọ̀ yín nínú ìyìnrere láti ọjọ́ kìn-ín-ní wá títí di ìsinsin yìí.
6 Eu estou absolutamente certo de que Deus, que começou este bom trabalho em suas vidas, continuará trabalhando e irá terminá-lo, de forma bem sucedida, quando Jesus Cristo retornar.
Ohun kan yìí sá à dá mi lójú pé, ẹni tí ó ti bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere nínú yín, yóò ṣe àṣepé rẹ̀ títí di ọjọ́ náà tí Jesu Kristi yóò dé.
7 É justo que eu pense dessa forma a respeito de todos vocês, pois vocês significam muito para mim. É isto que estão fazendo agora que estou preso e foi o mesmo que fizeram quando eu estava fora da cadeia, defendendo e anunciando o evangelho, pois vocês são participantes da graça de Deus junto comigo.
Gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ fún mi láti ro èyí nípa gbogbo yín, nítorí tí mo fi yín sọ́kàn, bí mo tilẹ̀ wà nínú ìdè tàbí ìdáhùn ẹjọ́, àti ìfẹsẹ̀múlẹ̀ ìyìnrere, gbogbo yín jẹ́ alábápín oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run pẹ̀lú mi.
8 Deus é minha testemunha da saudade que tenho de todos vocês, no amor afetuoso de Cristo Jesus.
Nítorí Ọlọ́run ni ẹlẹ́rìí mi, bí mo ti ń ṣàfẹ́rí yín gidigidi nínú ìfẹ́ Jesu Kristi.
9 Minha oração é para que o amor de vocês possa crescer ainda mais em conhecimento e entendimento,
Èyí sì ni àdúrà mi: pé kí ìfẹ́ yín lè máa pọ̀ síwájú àti síwájú sí i nínú ìfẹ́ àti ìmọ̀ ìjìnlẹ̀,
10 fazendo com que desenvolvam o que é realmente importante. Para que, assim, no dia em que Cristo voltar, vocês possam ser verdadeiros e estarem livres de culpa.
kí ẹ̀yin kí ó lè ní òye ohun tí ó dára jùlọ; kí ó sì jásí òdodo àti aláìjẹ́ ohun ìkọ̀sẹ̀ títí di ọjọ́ dídé Jesu Kristi,
11 E vocês terão uma vida cheia dos frutos da justiça que vêm por meio de Jesus Cristo, para a glória e o louvor a Deus.
lẹ́yìn ìgbà ti ẹ ti kún fún àwọn ìwà òdodo láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi, fún ògo àti ìyìn Ọlọ́run.
12 Meus irmãos e minhas irmãs, quero que saibam que todas as experiências que eu tive me ajudaram a seguir em frente na tarefa de anunciar o evangelho.
Ǹjẹ́ èmi fẹ́ kí ẹ̀yin kí ó mọ̀, ará, pé ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí mi jásí àtẹ̀gùn sí ìlọsíwájú ìyìnrere.
13 Pois todos, inclusive toda a guarda pretoriana, agora sabem que estou preso por ser um servo de Cristo.
Nítorí ìdí èyí, ó ti hàn gbangba sí gbogbo àwọn ẹ̀ṣọ́ ààfin àti sí àwọn ẹlòmíràn wí pé mo wà nínú ìdè fún Kristi.
14 E por causa da minha prisão, muitos dos cristãos daqui sentiram-se encorajados para anunciar a palavra de Deus sem medo!
Nítorí ìdè mi, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ará nínú Olúwa ni a ti mú lọ́kàn le láti sọ̀rọ̀ Ọlọ́run sí i pẹ̀lú ìgboyà àti láìbẹ̀rù.
15 Sim, alguns anunciam a palavra de Deus por inveja e rivalidade. No entanto, há aqueles que anunciam por bons motivos.
Òtítọ́ ni pé àwọn ẹlòmíràn tilẹ̀ ń fi ìjà àti ìlara wàásù Kristi, ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn sì ń fi inú rere ṣe é.
16 Eles fazem isso por amor, pois sabem que eu estava destinado a estar aqui para defender o evangelho.
Àwọn kan ń fi ìjà wàásù Kristi, kì í ṣe pẹ̀lú òtítọ́ inú, wọ́n ń gbèrò láti fi ìpọ́njú kún ìdè mi.
17 Aqueles outros não apresentam Cristo de uma forma sincera, porque suas ambições são egoístas e eles tentam me causar ainda mais problemas enquanto estou preso.
Àwọn kan ẹ̀wẹ̀ si ń fi ìfẹ́ ṣe é, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé a gbé mi dìde láti dá ààbò bo iṣẹ́ ìyìnrere.
18 Mas, e então? Tudo o que me importa é que Cristo está sendo apresentado de todas as formas, seja por maus ou bons motivos. E isso me deixa muito feliz e, assim, continuarei!
Kí ló tún kù? Kìkì í pé níbi gbogbo, ìbá à ní ìfẹ̀tànṣe tàbí ni ti òtítọ́ a sá à n wàásù Kristi, èmi sì ń yọ̀ nítorí èyí. Nítòótọ́, èmi ó sì máa yọ̀,
19 Por quê? Porque estou convencido de que, por suas orações por mim e pela ajuda do Espírito de Jesus Cristo, isso se tornará a minha salvação.
nítorí tí mo mọ̀ pé èyí ni yóò yọrí sí ìgbàlà fún mi láti inú àdúrà yín wá, àti ìfikún ẹ̀mí Jesu Kristi.
20 Pois tenho grande esperança e muita expectativa de não fazer algo de que possa me envergonhar. Pelo contrário, a minha esperança, como sempre, é que, mesmo agora, Cristo seja muito engrandecido em meu corpo, esteja eu vivo ou morto.
Gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn àti ìrètí mi pé kí ojú kí ó má ṣe ti mi ní ohunkóhun, ṣùgbọ́n kí èmi kí ó le máa ni ìgboyà ní ìgbà gbogbo àti nísinsin yìí, kí a lè ti ipasẹ̀ mi gbé Kristi ga lára mi, ìbá à ṣe pé mo wà láààyè, tàbí mo kú.
21 Pois, para mim, o viver é Cristo e o morrer é ganho.
Nítorí, ní ti èmi, láti wa láààyè jẹ́ Kristi, láti kú pẹ̀lú sì jẹ́ èrè fún mi.
22 Mas, se for para eu viver aqui e, se, assim, meu trabalho for produtivo, então, eu realmente não sei qual seria a melhor escolha!
Ṣùgbọ́n bí èmi bá le è ṣe iṣẹ́ ti ó ni àpẹẹrẹ nípa wíwà láààyè nínú ara, ṣùgbọ́n ohun ti èmi ó yàn, èmi kò mọ̀.
23 Pois eu estou em um dilema. O que realmente quero é partir e estar com Cristo, o que seria muito melhor;
Ṣùgbọ́n èmi n ṣiyèméjì, nítorí ti èmi fẹ́ láti lọ kúrò nínú ayé yìí, láti wà lọ́dọ̀ Kristi; nítorí ó dára púpọ̀ jù:
24 no entanto, permanecer fisicamente aqui é mais importante no que diz respeito a vocês.
síbẹ̀ láti wà láààyè jẹ́ àǹfààní nítorí tiyín.
25 Como eu estou absolutamente certo disso, eu sei que ficarei aqui, permanecendo com vocês, para ajudá-los enquanto a sua fé e a sua alegria em Deus crescem.
Bí èyí sì ti dá mi lójú, mo mọ̀ pé èmi ó dúró, èmi ó sì máa wà pẹ̀lú yín fún ìtẹ̀síwájú àti ayọ̀ yín nínú ìgbàgbọ́,
26 Assim, quando eu for visitá-los novamente, vocês louvem com mais entusiasmo ainda a Cristo Jesus por minha causa.
kí ìṣògo yín kí ó lè di púpọ̀ gidigidi nínú Jesu Kristi, àti nínú mi nípa ìpadà wá mi sọ́dọ̀ yín.
27 Apenas estejam certos de estarem vivendo como o evangelho de Cristo nos mostra, para que, se eu puder visitá-los ou estiver ausente, eu possa ouvir como vocês permanecem firmes, em total harmonia uns com os outros, espiritualmente unidos, enquanto trabalham juntos pela fé verdadeira no evangelho.
Ohun yówù kó ṣẹlẹ̀, ẹ jẹ́ kí ìgbé ayé yín ri gẹ́gẹ́ bí ìyìnrere Kristi: pé yálà bi mo tilẹ̀ wá wò yín, tàbí bí èmi kò wá, kí èmi kí ó lè máa gbúròó bí ẹ ti ń ṣe, pé ẹ̀yin dúró ṣinṣin nínú Ẹ̀mí kan, ẹ̀yin jùmọ̀ jìjàkadì nítorí ìgbàgbọ́ ìyìnrere, pẹ̀lú ọkàn kan.
28 Não deixem que os seus inimigos lhes causem medo. Ao serem corajosos, vocês demonstrarão que eles estarão perdidos, mas que o próprio Deus salvará vocês.
Kí ẹ má sì jẹ́ ki àwọn ọ̀tá dẹ́rùbà yin ni ohunkóhun: èyí tí í ṣe àmì tí ó dájú pé a ó pa wọ́n run, ṣùgbọ́n Ọlọ́run tìkára rẹ̀ ni yóò gbà yin là.
29 Porque vocês receberam não apenas o privilégio de crer em Jesus, mas também o de sofrer por ele.
Nítorí tí a ti fún yin ni àǹfààní, kì í ṣe láti gba Kristi gbọ́ nìkan, ṣùgbọ́n láti jìyà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú.
30 Vocês estão passando pela mesma luta na qual também já me viram; uma luta em que ainda batalho, como agora vocês sabem.
Ẹ sì máa ja ìjà kan náà, èyí ti ẹ̀yin ti ri, ti ẹ sì ti gbọ́ pé èmi n jà pẹ̀lú.

< Filipenses 1 >