< Lucas 6 >
1 Em um sábado, enquanto Jesus passeava pelos campos de trigo, seus discípulos começaram a colher e a debulhar algumas espigas e a comer os grãos.
Ní ọjọ́ ìsinmi kejì, Jesu ń kọjá láàrín oko ọkà; àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì ń ya ìpẹ́ ọkà, wọ́n sì ń jẹ ẹ́.
2 Alguns fariseus questionaram Jesus: “Por que vocês estão fazendo o que não é permitido fazer aos sábados?”
Àwọn kan nínú àwọn Farisi sì wí fún wọn pé, “Ki lo de tí ẹ̀yin fi ń ṣe èyí tí kò yẹ láti ṣe ní ọjọ́ ìsinmi?”
3 Jesus respondeu: “Vocês nunca leram o que Davi fez, quando ele e seus companheiros estavam com fome?
Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin kò kà nípa ohun tí Dafidi ṣe, nígbà tí ebi ń pa òun tìkára rẹ̀ àti àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀;
4 Como entrou na casa de Deus e pegou os pães consagrados? Ele comeu o pão e o deu para que os seus companheiros comessem também. Isso também não é permitido. Pois apenas os sacerdotes podem fazer isso.”
bi ó ti wọ ilé Ọlọ́run lọ, tí ó sì mú àkàrà ìfihàn tí ó sì jẹ ẹ́, tí ó sì fi fún àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú; tí kò yẹ fún un láti jẹ, bí kò ṣe fún àwọn àlùfáà nìkan ṣoṣo?”
5 Então, ele lhes disse: “O Filho do Homem é o Senhor do Sábado.”
Ó sì wí fún wọn pé, “Ọmọ Ènìyàn ni Olúwa Ọjọ́ Ìsinmi.”
6 Em um outro sábado, Jesus foi para a sinagoga ensinar. Havia um homem lá que tinha uma deficiência na mão direita.
Ní ọjọ́ ìsinmi mìíràn, ó wọ inú Sinagọgu lọ, ó sì ń kọ́ni, ọkùnrin kan sì ń bẹ níbẹ̀ tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ rọ.
7 Os educadores religiosos e os fariseus estavam observando Jesus bem de perto, para ver se ele iria curar alguém no sábado. Eles queriam encontrar alguma coisa para poder acusá-lo.
Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi ń ṣọ́ ọ, bóyá yóò mú un láradá ní ọjọ́ ìsinmi; kí wọn lè rí ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kàn án.
8 Mas, Jesus sabia o que eles tinham em mente. Ele disse ao homem que tinha o problema na mão: “Levante-se e fique diante de todos!” O homem fez como Jesus pediu.
Ṣùgbọ́n ó mọ èrò inú wọn, ó sì wí fún ọkùnrin náà tí ọwọ́ rẹ̀ rọ pé, “Dìde, kí o sì dúró láàrín.” Ó sì dìde dúró.
9 Então, Jesus se virou para as pessoas que lá estavam e disse: “Quero lhes fazer uma pergunta. Está de acordo com a lei fazer o bem aos sábados ou fazer o mal? Salvar vidas ou destruí-las?”
Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Èmi bi yín léèrè, Ó ha tọ́ láti máa ṣe rere ni ọjọ́ ìsinmi, tàbí láti máa ṣe búburú? Láti gba ọkàn là, tàbí láti pa á run?”
10 Ele olhou em volta para todos que lá estavam. Então, disse ao homem: “Estenda a sua mão!” O homem a estendeu e sua mão ficou curada.
Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká, ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀: ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ̀ sípò gẹ́gẹ́ bí èkejì.
11 Mas, os educadores religiosos e os fariseus ficaram furiosos e começaram a discutir sobre o que deveriam fazer com Jesus.
Wọ́n sì kún fún ìbínú gbígbóná; wọ́n sì bá ara wọn rò ohun tí àwọn ìbá ṣe sí Jesu.
12 No dia seguinte, Jesus subiu um monte para orar. Ele ficou lá a noite toda, orando a Deus.
Ni ọ̀kan nínú àwọn ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Jesu lọ sí orí òkè láti gbàdúrà, ó sì fi gbogbo òru náà gbàdúrà sí Ọlọ́run.
13 Quando o dia amanheceu, chamou os seus discípulos e escolheu doze deles. Estes são os nomes dos apóstolos:
Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ó pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; nínú wọn ni ó sì yan méjìlá, tí ó sì sọ ní aposteli:
14 Simão (também chamado de Pedro por Jesus) e o seu irmão André; Tiago e o seu irmão João; Filipe e Bartolomeu;
Simoni (ẹni tí a pè ní Peteru) àti Anderu arákùnrin rẹ̀, Jakọbu, Johanu, Filipi, Bartolomeu,
15 Mateus e Tomé; Tiago, filho de Alfeu, e Simão, o revolucionário;
Matiu, Tomasi, Jakọbu ọmọ Alfeu, Simoni tí a ń pè ní Sealoti,
16 Judas, filho de Tiago e Judas Iscariotes (o traidor de Jesus).
Judea arákùnrin Jakọbu, àti Judasi Iskariotu tí ó di ọ̀dàlẹ̀.
17 Jesus desceu do monte com eles e parou em um lugar plano. Havia uma grande multidão, na qual se encontravam muitos dos seus seguidores e muitas outras pessoas vindas da Judeia, de Jerusalém e do litoral de Tiro e Sidom, que se reuniu para ouvir Jesus e para ser curada de suas doenças.
Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀, ó sì dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn, láti gbogbo Judea, àti Jerusalẹmu, àti agbègbè Tire àti Sidoni, tí wọ́n wá láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àti láti gba ìmúláradá kúrò nínú ààrùn wọn;
18 As pessoas atormentadas por espíritos maus também foram curadas.
àti àwọn tí ara wọn kún fún ẹ̀mí àìmọ́ ni ó sì mú láradá.
19 Todos na multidão tentavam tocar em Jesus, pois havia poder saindo dele e curando a todos.
Gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń fẹ́ láti fọwọ́ kàn án, nítorí tí àṣẹ ń jáde lára rẹ̀, ó sì mú gbogbo wọn láradá.
20 Olhando para os seus discípulos, Jesus lhes disse:
Nígbà tí ó sì gbé ojú rẹ̀ sókè sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó ní: “Alábùkún fún ni ẹ̀yin òtòṣì, nítorí tiyín ni ìjọba Ọlọ́run.
21 “Felizes são vocês, os pobres, pois o Reino de Deus é de vocês. Felizes são vocês que agora sentem fome, pois comerão até se satisfazer. Felizes são vocês que agora choram, pois irão rir.
Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ebi ń pa nísinsin yìí; nítorí tí ẹ ó yóò. Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ń sọkún nísinsin yìí: nítorí tí ẹ̀yin ó rẹ́rìn-ín.
22 Felizes são vocês quando as pessoas os odiarem, excluirem, insultarem e disserem que são maus, por seguirem o Filho do Homem.
Alábùkún fún ni ẹ̀yin, nígbà tí àwọn ènìyàn bá kórìíra yín, tí wọ́n bá yà yín kúrò nínú ẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n bá gàn yín, tí wọ́n bá ta orúkọ yín nù bí ohun búburú, nítorí Ọmọ Ènìyàn.
23 No dia em que essas coisas acontecerem, fiquem felizes. Pulem de alegria, pois será grande a recompensa que os espera no céu. Não se esqueçam de que os seus antepassados maltrataram os profetas exatamente dessa forma.
“Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, kí ẹ sì fò fún ayọ̀, nítorí púpọ̀ ní èrè yín ni ọ̀run. Báyìí ni àwọn baba yín ṣe ṣe sí àwọn wòlíì.
24 Mas, infelizes são vocês que são ricos, pois já receberam a sua recompensa.
“Ègbé ni fún ẹ̀yin ọlọ́rọ̀ nítorí ẹ ti gba ìtùnú yín.
25 Infelizes são vocês que estão satisfeitos agora, pois sentirão fome. Infelizes são vocês que riem agora, pois irão se lamentar e chorar.
Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ó yó, nítorí ebi yóò pa yín, Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń rẹ́rìn-ín nísinsin yìí, nítorí tí ẹ̀yin ó ṣọ̀fọ̀, ẹ̀yin ó sì sọkún.
26 Infelizes são vocês a quem todos elogiam. Não se esqueçam de que os seus antepassados elogiaram os falsos profetas exatamente da mesma maneira.
Ègbé ni fún yín, nígbà tí gbogbo ènìyàn bá ń sọ̀rọ̀ yín ní rere, nítorí bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn baba wọn ṣe sí àwọn wòlíì èké.
27 Mas, eu digo para aqueles que estão me ouvindo: Amem os seus inimigos. Façam o bem para aqueles que os odeiam.
“Ṣùgbọ́n mo wí fún ẹ̀yin tí ń gbọ́ mi, ẹ fẹ́ àwọn ọ̀tá yín, ṣoore fún àwọn tí ó kórìíra yín.
28 Queiram o bem daqueles que os amaldiçoam. Orem por aqueles que os maltratam.
Súre fún àwọn tí ń fi yín ré, sì gbàdúrà fún àwọn tí ń kẹ́gàn yín.
29 Se alguém lhes bater na cara, virem o outro lado, para que bata também. Se alguém tomar o casaco de vocês, não o impeça de levar a sua camisa também.
Ẹni tí ó bá sì lù ọ́ ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ kan, yí kejì sí i pẹ̀lú; àti ẹni tí ó gba agbádá rẹ, má ṣe dá a dúró láti gba ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ pẹ̀lú.
30 Deem a qualquer um que lhes pedir. Se alguém tirar algo de vocês, não peçam que devolva.
Sì fi fún gbogbo ẹni tí ó tọrọ lọ́dọ̀ rẹ; lọ́dọ̀ ẹni tí ó sì kó ọ ní ẹrù, má sì ṣe padà béèrè.
31 Façam aos outros o que gostariam que eles fizessem a vocês.
Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin sì ti fẹ́ kí ènìyàn ṣe sí yín, kí ẹ̀yin sì ṣe bẹ́ẹ̀ sí wọn pẹ̀lú.
32 Se vocês amarem apenas quem os ama, por que deveriam merecer qualquer crédito por isso? Até mesmo os pecadores amam aqueles que os amam.
“Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin bá fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ yín, ọpẹ́ kí ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ wọn.
33 Se vocês fizerem o bem apenas para aqueles que fazem coisas boas para vocês, por que deveriam merecer qualquer crédito por isso? Os pecadores fazem isso também.
Bí ẹ̀yin sì ṣoore fún àwọn tí ó ṣoore fún yín, ọpẹ́ kín ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
34 Se vocês emprestarem dinheiro, esperando que seja devolvido, por que deveriam merecer qualquer crédito por isso? Os pecadores também emprestam dinheiro a outros pecadores, esperando receber o que foi emprestado.
Bí ẹ̀yin bá fi fún ẹni tí ẹ̀yin ń retí láti rí gbà padà, ọpẹ́ kín ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń yá ẹlẹ́ṣẹ̀, kí wọn lè gba ìwọ̀n bẹ́ẹ̀ padà.
35 Não! Porém façam diferente: amem os seus inimigos e façam boas coisas para eles e emprestem sem esperar receber o que foi emprestado. Assim, vocês irão receber uma grande recompensa e serão filhos do Deus Altíssimo, pois ele é bom também para as pessoas ingratas e más.
Ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin fẹ́ àwọn ọ̀tá yín kí ẹ sì ṣoore, kí ẹ̀yin sì yá ẹlòmíràn, kí ẹ̀yin má ṣe retí láti rí nǹkan gbà padà; èrè yín yóò sì pọ̀, àwọn ọmọ Ọ̀gá-ògo ni a ó sì máa pè yín: nítorí tí ó ṣe rere fún aláìmoore àti fún ẹni búburú.
36 Sejam misericordiosos, tal como o seu Pai é misericordioso.
Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin ní àánú, gẹ́gẹ́ bí Baba yín sì ti ní àánú.
37 Não julguem, e vocês não serão julgados. Não condenem, e vocês não serão condenados. Perdoem, e vocês serão perdoados.
“Ẹ má ṣe dá ni lẹ́jọ́, a kì yóò sì dá yín lẹ́jọ́: ẹ má ṣe dá ni lẹ́bi, a kì yóò sì dá yín lẹ́bi: ẹ dáríjì, a ó sì dáríjì yín.
38 Deem, e vocês receberão muito mais em troca. O que lhes é dado em troca é medido de tal forma para que mais possa lhes ser dado, derramando bênçãos que se espalham a sua volta. O quanto vocês dão, determinará o quanto irão receber.”
Ẹ fi fún ni, a ó sì fi fún yín; òsùwọ̀n dáradára, àkìmọ́lẹ̀, àti àmìpọ̀, àkúnwọ́sílẹ̀, ni a ó wọ́n si àyà yín: nítorí òsùwọ̀n náà tí ẹ̀yin fi wọ́n, òun ni a ó padà fi wọ́n fún yín.”
39 Então, Jesus fez as seguintes comparações: “Um cego pode guiar outro? Os dois não cairiam em um buraco?
Ó sì pa òwe kan fún wọn wí pé, “Afọ́jú ha lè ṣe amọ̀nà afọ́jú bí? Àwọn méjèèjì kọ́ ni yóò ṣubú sínú ihò bí?
40 Os alunos sabem mais do que o professor? Apenas quando eles aprenderem tudo o que lhes foi ensinado serão semelhantes ao seu professor.
Ẹni tí a ń kọ́ kì í ju olùkọ́ rẹ̀ lọ: ṣùgbọ́n olúkúlùkù ẹni tí a bá kọ dáradára, yóò dàbí olùkọ́ rẹ̀.
41 Por que você está tão preocupado com o cisco que está no olho do seu irmão, quando não nota nem mesmo a trave de madeira que está em seu próprio olho?
“Èétiṣe tí ìwọ fi ń wo ẹ̀rún igi tí ń bẹ ní ojú arákùnrin rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kò kíyèsi ìtì igi tí ń bẹ ní ojú ara rẹ?
42 Como você pode dizer a seu irmão: ‘Irmão, deixe-me ajudá-lo a tirar o cisco que está em seu olho.’ Se não consegue perceber nem mesmo a trave que está em seu próprio olho? Hipócrita! Primeiro, tire a trave do seu olho e, então, será capaz de ver bem o bastante para tirar o cisco que está no olho do seu irmão.
Tàbí ìwọ ó ti ṣe lè wí fún arákùnrin rẹ pé, ‘Arákùnrin, jẹ́ kí èmi yọ ẹ̀rún igi tí ń bẹ lójú rẹ,’ nígbà tí ìwọ tìkára rẹ kò kíyèsi ìtì igi tí ń bẹ lójú rẹ? Ìwọ àgàbàgebè, kọ́kọ́ yọ ìtí igi jáde kúrò lójú ara rẹ ná, nígbà náà ni ìwọ ó sì tó ríran gbangba láti yọ èérún igi tí ń bẹ lójú arákùnrin rẹ kúrò.
43 Uma boa árvore não produz frutos ruins. E uma árvore ruim não produz frutos bons.
“Nítorí igi rere kì í so èso búburú; bẹ́ẹ̀ ni igi búburú kì í so èso rere.
44 As árvores são conhecidas pelos frutos que elas produzem. Não há como colher figos de espinheiros ou uvas de ervas daninhas.
Olúkúlùkù igi ni a ń fi èso rẹ̀ mọ̀ ọn; nítorí lórí ẹ̀gún òṣùṣú, ènìyàn kì í ká èso ọ̀pọ̀tọ́ bẹ́ẹ̀ ni lórí ẹ̀gún ọ̀gàn a kì í ká èso àjàrà.
45 Pessoas boas produzem o que é bom, pois há bons sentimentos e pensamentos guardados dentro delas. Pessoas más produzem o que é ruim, pois há sentimentos e pensamentos ruins guardados dentro delas. As pessoas simplesmente colocam para fora, quando falam, o que está dentro delas.
Ènìyàn rere láti inú yàrá ìṣúra rere ọkàn rẹ̀ ní mú ohun rere jáde wá; àti ènìyàn búburú láti inú ìṣúra búburú ọkàn rẹ̀ ní í mú ohun búburú jáde wá: nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ọkàn ní ẹnu ti máa sọ jáde.
46 Então, por que vocês me chamam ‘Senhor, Senhor,’ mas não fazem o que eu digo?
“Nítorí náà, èéṣe tí ẹ̀yin ń pè mí ní, ‘Olúwa, Olúwa,’ tí ẹ̀yin kò sì ṣe ohun tí mo wí?
47 Eu darei a vocês um exemplo de alguém que vem até mim, ouve as minhas orientações e as segue.
Ẹnikẹ́ni tí ó tọ̀ mí wá, tí ó sì ń gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí ó sì ń ṣe é, èmi yóò fi ẹni tí ó jọ hàn yín.
48 Essa pessoa é como um homem que constrói uma casa. Ele cava bem fundo e coloca o alicerce em uma rocha sólida. Quando o rio transborda e a enchente alcança a casa, ela não se danifica, porque foi muito bem construída.
Ó jọ ọkùnrin kan, tí ó kọ́ ilé, tí ó sì wa ilẹ̀ jìn, tí ó sì fi ìpìlẹ̀ sọlẹ̀ lórí àpáta, nígbà tí kíkún omi sì dé, ìgbì omi kọlu ilé náà, kò sì lè mì ín nítorí tí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ lórí àpáta.
49 A pessoa que me ouve, mas não faz o que eu digo, é como um homem que constrói a sua casa sem o alicerce. Quando a enchente alcança a casa, ela cai imediatamente e fica destruída por completo.”
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́, tí kò sì ṣe é, ó dàbí ọkùnrin tí ó kọ́ ilé sí orí ilẹ̀ láìní ìpìlẹ̀; nígbà tí ìgbì omi kọlù ú, lọ́gán, ó sì wó; wíwó ilé náà sì pọ̀ púpọ̀.”