< Atos 13 >

1 Na igreja de Antioquia havia os seguintes profetas e mestres: Barnabé, Simeão, chamado “o Negro”, Lúcio de Cirene, Manaém (amigo de infância de Herodes, o tetrarca) e Saulo.
Àwọn wòlíì àti àwọn olùkọ́ni sì ń bẹ nínú ìjọ ti ó wà ni Antioku; Barnaba àti Simeoni tí a ń pè ni Nigeri, àti Lukiu ará Kirene, àti Manaeni (ẹni tí a tọ́ pọ̀ pẹ̀lú Herodu tetrarki) àti Saulu.
2 Enquanto eles estavam adorando o Senhor e jejuando, o Espírito Santo disse: “Separem Barnabé e Saulo para que façam o trabalho para o qual eu os chamei.”
Bí wọn sì ti ń jọ́sìn fún Olúwa, tí wọ́n sì ń gbààwẹ̀, Ẹ̀mí Mímọ́ wí pé, “Ẹ ya Barnaba àti Saulu sọ́tọ̀ fún mi fún iṣẹ́ ti mo ti pè wọ́n sí!”
3 Depois que eles jejuaram, oraram e colocaram as suas mãos sobre eles para abençoá-los, eles enviaram Barnabé e Saulo para a sua missão.
Nígbà tí wọ́n sì ti gbààwẹ̀, tí wọn sì ti gbàdúrà, wọ́n gbé ọwọ́ lé wọn, wọ́n sì rán wọn lọ.
4 Então, Barnabé e Saulo, orientados pelo Espírito Santo, foram para Selêucia. De lá, eles partiram de barco para a ilha de Chipre.
Ǹjẹ́ bí Ẹ̀mí Mímọ́ ti rán àwọn méjèèjì lọ, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Seleusia; láti ibẹ̀ wọ́n sì wọ ọkọ̀ ojú omi lọ sí Saipurọsi.
5 Chegando na cidade de Salamina, eles anunciaram a palavra de Deus nas sinagogas judaicas. João estava com eles como auxiliar.
Nígbà ti wọ́n sì wà ni Salami, wọ́n ń wàásù ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ní Sinagọgu àwọn Júù. Johanu náà sì wà pẹ̀lú wọn láti ràn wọ́n lọ́wọ́ fún ìránṣẹ́ wọn.
6 Eles viajaram por toda a ilha e finalmente chegaram a Pafos. Lá, encontraram um mágico judeu, um falso profeta, chamado Barjesus.
Nígbà tí wọ́n sì la gbogbo erékùṣù já dé Pafosi, wọ́n rí ọkùnrin oṣó àti wòlíì èké kan ti i ṣe Júù, orúkọ ẹni ti ó ń jẹ́ Bar-Jesu.
7 Ele era amigo do governador Sérgio Paulo, um homem inteligente. Sérgio Paulo convidou Barnabé e Saulo para visitá-lo, pois ele queria ouvir a palavra de Deus.
Ó wà lọ́dọ̀ Segiu Paulusi baálẹ̀ ìlú náà tí í ṣe amòye ènìyàn. Òun náà ni ó ránṣẹ́ pe Barnaba àti Saulu, nítorí tí ó fẹ́ gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
8 Mas, o mágico Elimas (este é o nome dele em grego) era contra os apóstolos e tentou evitar que o governador cresse em Deus.
Ṣùgbọ́n Elimu oṣó (nítorí bẹ́ẹ̀ ni ìtumọ̀ orúkọ rẹ̀) takò wọ́n, ó ń fẹ́ pa baálẹ̀ ni ọkàn dà kúrò ni ìgbàgbọ́.
9 Então, Saulo, também chamado Paulo, cheio do Espírito Santo, olhou direto para Elimas e disse:
Ṣùgbọ́n Saulu ti a ń pè ni Paulu, ó kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì tẹjúmọ́ Elimu, ó sì wí pé,
10 “Você está repleto de mentiras e de tudo o que é mau. Filho do diabo!, inimigo de tudo o que é justo!, você nunca desistirá de torcer os verdadeiros ensinamentos do Senhor?
“Ìwọ ti ó kún fún àrékérekè gbogbo, àti fún ìwà ìkà gbogbo, ìwọ ọmọ èṣù, ìwọ ọ̀tá ohun gbogbo, ìwọ kì yóò ha dẹ́kun láti máa yí ọ̀nà òtítọ́ Olúwa po?
11 Escute! A mão do Senhor está sobre você e o deixará cego. Você não verá o sol por algum tempo.” Imediatamente, névoa e escuridão cobriram os olhos de Elimas e ele precisou encontrar alguém que o guiasse pela mão.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí wò ó, ọwọ́ Olúwa ń bẹ lára rẹ̀, ìwọ ó sì fọjú ìwọ kì yóò rí oòrùn ní sá à kan!” Lójúkan náà, ìkùùkuu àti òkùnkùn sí bò ó; ó sì ń wá ènìyàn kiri láti fa òun lọ́wọ́ lọ.
12 Quando o governador viu o que havia acontecido, ele creu em Deus e ficou completamente maravilhado com os ensinamentos sobre o Senhor.
Nígbà tí baálẹ̀ rí ohun tí ó ṣe, ó gbàgbọ́, ẹnu sì yà á sì ẹ̀kọ́ Olúwa.
13 Então, Paulo e os que estavam com ele navegaram da cidade de Pafos para Perge, na região da Panfília. Enquanto isso, João os deixou e voltou para Jerusalém.
Nígbà tí Paulu àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ si ṣíkọ̀ ni Pafosi wọ́n wá sí Perga ni Pamfilia: Johanu sì fi wọ́n sílẹ̀, ó sì padà lọ sí Jerusalẹmu.
14 Eles passaram por Perge e continuaram até Antioquia da Pisídia. No sábado, eles entraram na sinagoga e se sentaram.
Nígbà ti wọ́n sì là Perga kọjá, wọ́n wá sí Pisidia ní Antioku. Wọ́n sì wọ inú Sinagọgu ní ọjọ́ ìsinmi, wọ́n sì jókòó.
15 Após a leitura da Lei e do livro dos Profetas, os líderes da sinagoga mandaram dizer-lhes: “Irmãos, por favor, compartilhem com o povo quaisquer palavras de encorajamento que possam ter.”
Lẹ́yìn kíka ìwé òfin àti ìwé àwọn wòlíì, àwọn olórí Sinagọgu ránṣẹ́ sí wọn, pé, “Ará, bí ẹ̀yin bá ni ọ̀rọ̀ ìyànjú kan fún àwọn ènìyàn, ẹ sọ ọ́!”
16 Paulo se levantou, fez um sinal com a mão, para pedir a atenção dos que lá estavam, e começou a falar: “Homens de Israel e todos os não-judeus que temem a Deus, ouçam-me!
Paulu sì dìde dúró, ó sì juwọ́ sí wọn, ó ní, “Ẹ̀yin Israẹli, àti ẹ̀yin ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ẹ fi etí sílẹ̀ sí mi!
17 O Deus do povo de Israel escolheu nossos antepassados e deu ao nosso povo prosperidade durante a sua permanência no Egito. Depois, com o seu grande poder, ele os tirou do Egito e,
Ọlọ́run àwọn ènìyàn Israẹli yìí yan àwọn baba wa, ó sì gbé àwọn ènìyàn náà lékè, nígbà tí wọ́n ṣe àtìpó ní ilẹ̀ Ejibiti, pẹ̀lú agbára ńlá ni ó sì fi mú wọn jáde kúrò nínú rẹ̀,
18 no deserto, aguentou aquela gente durante quarenta anos.
ní ìwọ̀n ìgbà ogójì ọdún ni ó fi mú sùúrù fún ìwà wọn ní ijù,
19 Após ter destruído sete nações que viviam na região de Canaã, Deus dividiu essa terra e deu-a como herança aos israelitas. Tudo isso levou cerca de quatrocentos e cinquenta anos.
nígbà tí ó sì ti run orílẹ̀-èdè méje ni ilẹ̀ Kenaani, ó sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ni ìní.
20 Então, Deus lhes deu juízes para serem seus líderes até o tempo do profeta Samuel.
Gbogbo èyí sì ṣẹlẹ̀ fún ìwọ̀n àádọ́ta lé ní irinwó ọdún. “Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run fi onídàájọ́ fún wọn, títí ó fi di ìgbà Samuẹli wòlíì.
21 A partir daí, as pessoas pediram um rei, e Deus lhes deu Saul, filho de Quis, da tribo de Benjamim. Saul governou por quarenta anos.
Lẹ́yìn náà ni wọ́n sì béèrè ọba; Ọlọ́run sì fún wọn ní Saulu ọmọ Kiṣi, ọkùnrin kan nínú ẹ̀yà Benjamini, fún ogójì ọdún.
22 Depois, Deus rejeitou Saul e fez de Davi o novo rei. Deus aprovou Davi, dizendo: ‘Encontrei em Davi, filho de Jessé, um homem que está de acordo com o meu coração. Ele fará tudo o que eu quero.’
Nígbà ti ó sì mú Saulu kúrò, ó gbé Dafidi dìde ní ọba fún wọn, ẹni tí ó sì jẹ́rìí rẹ̀ pé, ‘Mo rí Dafidi ọmọ Jese ẹni bí ọkàn mi, ti yóò ṣe gbogbo ìfẹ́ mi.’
23 Jesus é descendente de Davi. Ele é o Salvador que Deus prometeu ao povo de Israel.
“Láti inú irú-ọmọ ọkùnrin yìí ni Ọlọ́run ti gbé Jesu Olùgbàlà dìde fún Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìlérí.
24 Antes de Jesus vir, João anunciou o batismo de arrependimento para todo o povo de Israel.
Ṣáájú wíwá Jesu ni Johanu ti wàásù bamitiisi ìrònúpìwàdà fún gbogbo ènìyàn Israẹli.
25 Quando João já estava quase terminando a sua missão, ele disse: ‘Quem vocês acham que eu sou? Eu não sou aquele que vocês procuram. Mas, depois de mim, virá aquele cujas sandálias eu nem mesmo sou digno de desamarrar.’
Bí Johanu sì ti ńlá ipa tirẹ̀ já, ó ni, ‘Ta ni ẹ̀yin ṣe bí èmi jẹ́? Èmi kì í ṣe òun. Ṣùgbọ́n ẹ kíyèsi í, ẹnìkan ń bọ̀ lẹ́yìn mi, bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó tú.’
26 Meus irmãos, descendentes de Abraão, e também vocês não-judeus, que são tementes a Deus: a mensagem desta salvação foi enviada para nós!
“Ará, ẹ̀yin ọmọ ìran Abrahamu, àti ẹ̀yin ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, àwa ni a rán ọ̀rọ̀ ìgbàlà yìí sí.
27 O povo que vive em Israel e os seus líderes não reconheceram Jesus e nem compreenderam as palavras dos profetas, que são lidas todos os sábados. Na verdade, eles cumpriram as profecias, ao condenar Jesus.
Nítorí àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu, àti àwọn olórí wọn, nítorí tiwọn kò mọ̀ Jesu, tí wọn kò sì ní òye ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì, tí a ń kà ní ọjọọjọ́ ìsinmi fún wọn, kò yé wọn, wọ́n mú ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì yìí ṣẹ nípa dídá a lẹ́bi.
28 Mesmo que eles não tenham conseguido encontrar qualquer prova para condená-lo, ainda assim, eles pediram para que Pilatos o matasse.
Àti bí wọn kò tilẹ̀ ti rí ọ̀ràn ikú sí i, síbẹ̀ wọn rọ Pilatu láti pa á.
29 Depois que fizeram tudo como estava previsto nas Sagradas Escrituras, tiraram Jesus da cruz e o puseram em um túmulo.
Bí wọ́n ti mú nǹkan gbogbo ṣẹ ti a kọ̀wé nítorí rẹ̀, wọn sì sọ̀ ọ́ kalẹ̀ kúrò lórí igi, wọ́n sì tẹ́ ẹ sí ibojì.
30 Mas, Deus o ressuscitou dos mortos,
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jí i dìde kúrò nínú òkú,
31 e ele apareceu durante muitos dias para as pessoas que o tinham seguido da Galileia até Jerusalém. Esses seguidores agora são testemunhas que falam sobre Jesus para todos.
o sì farahàn lọ́jọ́ púpọ̀ fún àwọn tí ó bá a gòkè láti Galili wá sí Jerusalẹmu, àwọn tí í ṣe ẹlẹ́rìí rẹ̀ nísinsin yìí fún àwọn ènìyàn.
32 Nós estamos aqui para trazer a vocês as boas novas da promessa que Deus fez aos nossos antepassados.
“Àwa sì mú ìyìnrere wá fún yín pé, ìlérí èyí tí Ọlọ́run ti ṣe fún àwọn baba wa,
33 Promessa que ele cumpriu para nós, seus filhos, ao ressuscitar Jesus. Como está escrito no Salmo número dois: ‘Você é o meu Filho; hoje eu me tornei o seu Pai.’
èyí ni Ọlọ́run ti mú ṣẹ fún àwa ọmọ wọn, nípa gbígbé Jesu dìde, bí a sì ti kọ̀wé rẹ̀ nínú Saamu kejì pé, “‘Ìwọ ni Ọmọ mi; lónìí ni mo bí ọ.’
34 Deus o ressuscitou, para que ele nunca mais morresse, como indicou ao dizer: ‘Eu cumprirei em favor de vocês as santas e fiéis promessas feitas a Davi.’
Àti ni tí pé Ọlọ́run jí i dìde kúrò nínú òkú, ẹni tí kì yóò tún padà sí ìbàjẹ́ mọ́, ó wí báyìí pé: “‘Èmi ó fún yín ní ọ̀rẹ́ mímọ́ Dafidi, tí ó dájú.’
35 E, em outro salmo também é dito: ‘Não permitirá que o seu Santo apodreça no túmulo.’
Nítorí ó sì wí nínú Saamu mìíràn pẹ̀lú pé, “‘Ìwọ kí yóò jẹ́ kí Ẹni Mímọ́ rẹ rí ìdíbàjẹ́.’
36 Mas Davi morreu, após ter feito o que Deus queria. Ele foi, então, sepultado com os seus antepassados, e o seu corpo se decompôs.
“Nítorí lẹ́yìn ìgbà ti Dafidi ti sin ìran rẹ tan nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, ó sùn, a sì tẹ́ ẹ ti àwọn baba rẹ̀, ara rẹ̀ sì rí ìdíbàjẹ́.
37 Porém, aquele que Deus ressuscitou não experimentou a decadência do corpo.
Ṣùgbọ́n ẹni tí Ọlọ́run jí dìde kò rí ìdíbàjẹ́.
38 Meus irmãos, quero que entendam que nós estamos lhes dizendo que, por intermédio desse homem, podemos encontrar o perdão para os nossos pecados.
“Ǹjẹ́ kí ó yé yín, ará pé nípasẹ̀ Jesu yìí ni a ń wàásù ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ fún yín.
39 Ele torna os que creem nele moralmente justos, libertando-os de tudo que é errado. E isso é feito de uma maneira que nem mesmo a lei de Moisés conseguiria.
Nípa rẹ̀ ni a ń dá olúkúlùkù ẹni tí ó gbàgbọ́ láre kúrò nínú ohun gbogbo, tí a kò lè dá yín láre rẹ̀ nínú òfin Mose.
40 Tenham cuidado para que não aconteça com vocês o que os profetas disseram:
Nítorí náà, ẹ kíyèsára, kí èyí tí a ti sọ nínú ìwé àwọn wòlíì má ṣe dé bá yín pé:
41 ‘Vocês, que desprezam a Deus, olhem com espanto e morram! Pois eu farei coisas que vocês nunca acreditariam ser possível, mesmo se alguém lhes dissesse!’”
“‘Ẹ wò ó, ẹ̀yin ẹlẹ́gàn, kí ẹnu sì yà yín, kí a sì fẹ́ yín kù; nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín, tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́, bí a tilẹ̀ sọ fún yin.’”
42 Quando Paulo e Barnabé estavam saindo da sinagoga, as pessoas pediram que eles voltassem novamente no sábado seguinte, para lhes falar mais sobre essas coisas.
Bí Paulu àti Barnaba sì ti ń jáde láti inú Sinagọgu, wọ́n bẹ̀bẹ̀ pé kí a sọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí i fún wọn lọ́jọ́ ìsinmi tí ń bọ̀.
43 Depois da reunião na sinagoga, muitos judeus e pessoas convertidas ao judaísmo seguiram Paulo e Barnabé, que falavam com eles, encorajando-os a continuarem firmes na graça de Deus.
Nígbà tí wọn sì jáde nínú Sinagọgu, ọ̀pọ̀ nínú àwọn Júù àti nínú àwọn olùfọkànsìn aláwọ̀ṣe Júù tẹ̀lé Paulu àti Barnaba, àwọn ẹni tí ó bá wọn sọ̀rọ̀ tí wọ́n sì rọ̀ wọ́n láti dúró nínú oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
44 No sábado seguinte, quase toda a cidade se reuniu para ouvi-los falar sobre a palavra de Deus.
Ní ọjọ́ ìsinmi kejì, gbogbo ìlú sí fẹ́rẹ̀ péjọ tan láti gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
45 No entanto, quando os judeus viram a multidão que estava lá reunida, ficaram com muita inveja e, então, começaram a dizer o contrário do que Paulo dizia e o insultaram.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Júù rí ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, wọ́n kún fún owú, wọ́n ń sọ̀rọ̀-òdì sí ohun ti Paulu ń sọ.
46 Então, cheios de coragem, Paulo e Barnabé disseram: “Nós precisávamos anunciar a palavra de Deus primeiro a vocês. Mas, já que a rejeitam, vocês mesmos estão decidindo que não são dignos da vida eterna e, por isso, iremos anunciar a mensagem de Deus para os não-judeus. (aiōnios g166)
Paulu àti Barnaba sì dá wọn lóhùn láìbẹ̀rù pé, “Ẹ̀yin ni ó tọ́ sí pé ki a kọ́kọ́ sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún yín, ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin ti ta á nù, tí ẹ sì ka ara yín sí aláìyẹ fún ìyè àìnípẹ̀kun, wò ó, àwa yípadà sọ́dọ̀ àwọn aláìkọlà. (aiōnios g166)
47 Isso é o que o Senhor nos disse: ‘Eu fiz de você uma luz para os não judeus e, por meio de você, a salvação será levada para todos os cantos do mundo.’”
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ṣa ti pàṣẹ fún wa pé: “‘Mo ti gbé ọ kalẹ̀ láti tan ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà, kí ìwọ lè mú ìgbàlà wá títí dé òpin ayé.’”
48 Quando os não-judeus ouviram o que os apóstolos disseram, eles ficaram muito felizes e começaram a louvar a palavra do Senhor. E, todos os que foram escolhidos para ter a vida eterna creram em Deus. (aiōnios g166)
Nígbà tí àwọn aláìkọlà sì gbọ́ èyí, wọ́n sì yín ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lógo: gbogbo àwọn tí a yàn sí ìyè àìnípẹ̀kun sì gbàgbọ́. (aiōnios g166)
49 Assim, a mensagem de Deus se espalhou por toda a região.
A sí tan ọ̀rọ̀ Olúwa ká gbogbo agbègbè náà.
50 Mas, os judeus incitaram as mulheres religiosas importantes e os líderes da cidade para que perseguissem Paulo e Barnabé. Eles conseguiram que os dois fossem expulsos daquelas terras.
Ṣùgbọ́n àwọn Júù rú àwọn obìnrin olùfọkànsìn àti ọlọ́lá sókè àti àwọn àgbà ìlú náà, wọ́n sì gbé inúnibíni dìde sí Paulu àti Barnaba, wọ́n sì le wọn kúrò ni agbègbè wọn.
51 Os apóstolos tiraram até o pó de suas sandálias, como um sinal de protesto contra eles, e se dirigiram para a cidade de Icônio.
Ṣùgbọ́n wọ́n gbọn eruku ẹsẹ̀ wọn sí wọn, wọn sì wá sí Ikoniomu.
52 E os cristãos de Antioquia da Pisídia transbordavam de alegria e eram cheios do Espírito Santo.
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn si kún fún ayọ̀ àti fún Ẹ̀mí Mímọ́.

< Atos 13 >