< Salmos 65 >
1 Salmo e cântico de Davi, para o regente: A ti, Deus, [pertence] a tranquilidade [e] o louvor em Sião; e a ti será pago o voto.
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Orin. Ìyìn ń dúró dè ọ́, Ọlọ́run, ní Sioni; sí ọ ni a ó mú ẹ̀jẹ́ wa ṣẹ.
2 Tu, que ouves as orações; toda carne virá a ti.
Ìwọ tí ó ń gbọ́ àdúrà, gbogbo ènìyàn yóò sì wá sọ́dọ̀ rẹ.
3 Perversidades têm me dominado, [porém] tu tiras a culpa de nossas transgressões.
Ọ̀ràn àìṣedéédéé borí mi bí ó ṣe ti ìrékọjá wa ni! Ìwọ ni yóò wẹ̀ wọ́n nù kúrò.
4 Bem-aventurado [é] aquele a quem tu escolhes, e [o] fazes aproximar, para que habite em teus cômodos; seremos fartos do bem de tua casa, [na] santidade de teu templo.
Ìbùkún ni fún àwọn tí o yàn tí o mú wa láti máa gbé àgọ́ rẹ! A tẹ́ wá lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere inú ilé rẹ, ti tẹmpili mímọ́ rẹ.
5 Tu nos responderá de forma justa [por meio de] coisas temíveis. O Deus de nossa salvação [é] a confiança de todos os limites da terra, e dos lugares mais distantes do mar.
Ìwọ dá wa lóhùn pẹ̀lú ohun ìyanu ti òdodo, Ọlọ́run olùgbàlà wa, ẹni tí ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé gbogbo òpin ayé àti àwọn tí ó jìnnà nínú òkun,
6 Ele [é] o que firma os montes com sua força, revestido de poder.
ìwọ tí ó dá òkè nípa agbára rẹ, tí odi ara rẹ ní àmùrè agbára,
7 Ele é o que amansa o ruído dos mares, o ruído de suas ondas, e o tumulto dos povos.
ẹni tí ó mú rírú omi òkun dákẹ́, ríru ariwo omi wọn, àti ìdágìrì àwọn ènìyàn.
8 [Até] os que habitam nos lugares mais distantes temem teus sinais; tu fazes alegres o nascer e o pôr do sol.
Àwọn tí ó ń gbé òkèrè bẹ̀rù, nítorí àmì rẹ wọ̀n-ọn-nì; ìwọ mú ìjáde òwúrọ̀ àti ti àṣálẹ́ yọ̀, ìwọ pè fún orin ayọ̀.
9 Tu visitas a terra, e a regas; tu a enriqueces; o rio de Deus [está] cheio de águas; tu preparas [a terra], e lhes dá trigo.
Ìwọ bẹ ayé wò, o sì bomirin; ìwọ mú un ọ̀rọ̀ púpọ̀. Odò Ọlọ́run kún fún omi láti pèsè ọkà fún àwọn ènìyàn, nítorí ibẹ̀ ni ìwọ ti yàn án.
10 Enche seus regos de [águas], fazendo-as descer em suas margens; com muita chuva a amoleces, [e] abençoas o que dela brota.
Ìwọ fi bomirin sí aporo rẹ̀ ìwọ tẹ́ ògúlùtu rẹ̀; ìwọ fi òjò mú ilẹ̀ rẹ̀ rọ̀, o sì bùkún ọ̀gbìn rẹ̀.
11 Coroas o ano com tua bondade; e teus caminhos transbordam fartura.
Ìwọ fi oore rẹ dé ọdún ní adé, ọ̀rá ń kán ní ipa ọ̀nà rẹ.
12 Eles são derramados [sobre] os pastos do deserto; e os morros se revestem de alegria.
Pápá tútù ní aginjù ń kan àwọn òkè kéékèèké fi ayọ̀ di ara wọn ní àmùrè.
13 Os campos se revestem de rebanhos, e os vales são cobertos de trigo; e por isso se alegram e cantam.
Agbo ẹran ni a fi wọ pápá tútù náà ní aṣọ; àfonífojì ni a fi ọkà bò mọ́lẹ̀, wọ́n hó fún ayọ̀, wọ́n ń kọrin pẹ̀lú.